< Joshua 21 >

1 Báyìí ni olórí ìdílé àwọn ọmọ Lefi lọ bá Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn ìdílé ẹ̀yà Israẹli.
Přistoupili pak přední z otců Levítského pokolení k Eleazarovi knězi, a k Jozue, synu Nun, a k předním z otců pokolení synů Izraelských,
2 Ní Ṣilo, ní Kenaani, wọn sọ fún wọn pé, “Olúwa pàṣẹ nípasẹ̀ Mose pé kí wọn fún wa ní ìlú láti máa gbé àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún ẹran ọ̀sìn wa.”
A mluvili k nim v Sílo, v zemi Kananejské, řkouce: Hospodin přikázal skrze Mojžíše, abyste nám dali města k přebývání, i podměstí jejich pro dobytky naše.
3 Àwọn ọmọ Israẹli sì fún àwọn ọmọ Lefi ní àwọn ìlú wọ̀nyí, àti ilẹ̀ pápá oko tútù lára ilẹ̀ ìní tiwọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Dali tedy synové Izraelští Levítům z dědictví svého, vedlé rozkázaní Hospodinova, města tato i podměstí jejich.
4 Ìpín kìn-ín-ní wà fún àwọn ọmọ Kohati, ní agbo ilé, agbo ilé. Àwọn ọmọ Lefi tí wọ́n jẹ́ ọmọ Aaroni àlùfáà ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini.
Padl pak los čeledem Kahat, i dáno losem synům Arona kněze, Levítům, z pokolení Juda, a z pokolení Simeon, i z pokolení Beniaminova měst třinácte.
5 Ìyókù àwọn ọmọ Kohati ni a pín ìlú mẹ́wàá fún láti ara ẹ̀yà Efraimu, Dani àti ìdajì Manase.
A jiným synům Kahat, z čeledí pokolení Efraimova, a z pokolení Danova, a z polovice pokolení Manassesova losem dáno měst deset.
6 Àwọn ẹ̀yà Gerṣoni ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ara ẹ̀yà Isakari, Aṣeri, Naftali àti ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani.
Synům pak Gerson, z čeledí pokolení Izacharova, a z pokolení Asserova, též z pokolení Neftalímova, a z polovice pokolení Manassesova v Bázan losem dáno měst třinácte.
7 Àwọn ọmọ Merari ní agbo ilé, agbo ilé ni wọ́n fún ní ìlú méjìlá láti ara ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
Synům Merari po čeledech jejich, z pokolení Rubenova a z pokolení Gádova, též z pokolení Zabulonova měst dvanácte.
8 Báyìí ni àwọn ọmọ Israẹli pín ìlú wọ̀nyí àti ilẹ̀ pápá oko tútù fún àwọn ọmọ Lefi gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ẹnu Mose.
Dali tedy synové Izraelští Levítům ta města i předměstí jejich, (jakož přikázal Hospodin skrze Mojžíše, ) losem.
9 Láti ara ẹ̀yà Juda àti ẹ̀yà Simeoni ni wọ́n ti pín àwọn ìlú tí a dárúkọ wọ̀nyí,
A tak z pokolení synů Judových, a z pokolení synů Simeonových dána jsou města, kterýchž tuto jména jsou položena.
10 (ìlú wọ̀nyí ni a fún àwọn ọmọ Aaroni tí ó jẹ́ ọ̀kan nínú ìdílé Kohati tí í ṣe ọmọ Lefi, nítorí tí ìpín àkọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
A dostal se první díl synům Aronovým, z čeledí Kahat, z synů Léví; nebo jim padl los první.
11 Wọ́n fún wọn ní Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni), pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù tí ó yí wọn ká, ní ilẹ̀ òkè Juda. (Arba ni baba ńlá Anaki.)
Dáno jest tedy jim město Arbe, otce Enakova, (jenž jest Hebron, ) na hoře Juda, a předměstí jeho vůkol něho.
12 Ṣùgbọ́n àwọn oko àti àwọn abúlé ní agbègbè ìlú náà ni wọ́n ti fi fún Kalebu ọmọ Jefunne gẹ́gẹ́ bí ohun ìní rẹ̀.
Ale pole města toho i vsi jeho dali Kálefovi synu Jefone k vládařství jeho.
13 Ní àfikún wọ́n sì fún àwọn ọmọ Aaroni tí í ṣe àlùfáà ní Hebroni (ọ̀kan nínú ìlú ààbò fún àwọn apànìyàn) pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù rẹ̀, Libina,
Synům tedy Arona kněze dali město útočišťné vražedlníku, Hebron i předměstí jeho, a Lebno i předměstí jeho;
14 Jattiri, Eṣitemoa,
A Jeter s předměstím jeho, též Estemo a předměstí jeho;
15 Holoni àti Debiri,
Holon i předměstí jeho, a Dabir s podměstím jeho;
16 Aini, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn. Ìlú mẹ́sàn-án láti ara ẹ̀yà méjì wọ̀nyí.
Také Ain s předměstím jeho, a Juta s podměstím jeho, i Betsemes a předměstí jeho, měst devět z toho dvojího pokolení.
17 Láti ara ẹ̀yà Benjamini ni wọ́n ti fún wọn ní: Gibeoni, Geba,
Z pokolení pak Beniaminova dali Gabaon a předměstí jeho, a Gaba s předměstím jeho;
18 Anatoti àti Almoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Též Anatot a podměstí jeho, i Almon s předměstím jeho, města čtyři.
19 Gbogbo ìlú àwọn àlùfáà, ìran Aaroni jẹ́ mẹ́tàlá pẹ̀lú ilẹ̀ pápá wọn.
Všech měst synů Aronových kněží třinácte měst s předměstími jejich.
20 Ìyókù ìdílé Kohati tí ó jẹ́ ọmọ Lefi ní a pín ìlú fún láti ara ẹ̀yà Efraimu.
Èeledem pak synů Kahat, Levítům, kteříž pozůstali z synů Kahat, (byla pak města losu jejich z pokolení Efraim, )
21 Ní ilẹ̀ òkè Efraimu wọ́n fún wọn ní: Ṣekemu (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Geseri,
Dali jim město útočišťné vražedlníku, Sichem i předměstí jeho, na hoře Efraim, a Gázer s předměstím jeho.
22 Kibasaimu àti Beti-Horoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Též Kibsaim a předměstí jeho, a Betoron s předměstím jeho, města čtyři.
23 Láti ara ẹ̀yà Dani ni wọ́n ti fún wọn ní: Elteke, Gibetoni,
Z pokolení pak Dan: Elteke a předměstí jeho, a Gebbeton s předměstím jeho;
24 Aijaloni àti Gati-Rimoni, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Též Aialon a předměstí jeho, a Getremmon s podměstím jeho, města čtyři.
25 Láti ara ìdajì ẹ̀yà Manase ni wọ́n ti fún wọn ní: Taanaki àti Gati-Rimoni pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn jẹ́ ìlú méjì.
Z polovice pak pokolení Manassesova: Tanach a podměstí jeho, a Getremmon s předměstím jeho, města dvě.
26 Gbogbo ìlú mẹ́wẹ̀ẹ̀wá yìí àti ilẹ̀ pápá wọn ni a fi fún ìyókù ìdílé Kohati.
Všech měst deset s předměstími jejich čeledem synům Kahat ostatním.
27 Àwọn ọmọ Gerṣoni ìdílé àwọn ọmọ Lefi ni wọ́n fún lára: ìdajì ẹ̀yà Manase, Golani ní Baṣani (ìlú ààbò fún apànìyàn) àti Be-Eṣterah pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọ́n jẹ́ méjì.
Synům také Gersonovým, z čeledí Levítských, z polovice pokolení Manassesova dali město útočišťné vražedlníku, Golan v Bázan a předměstí jeho, a Bozran s předměstím jeho, města dvě.
28 Láti ara ẹ̀yà Isakari ni wọ́n ti fún wọn ní, Kiṣioni Daberati,
Z pokolení Izacharova: Kesion a podměstí jeho, a Daberet s předměstím jeho;
29 Jarmatu àti Eni-Gannimu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Jarmut a předměstí jeho, a Engannim s předměstím jeho, města čtyři.
30 Láti ara ẹ̀yà Aṣeri ni wọ́n ti fún wọn ní Miṣali, àti Abdoni,
Z pokolení pak Asserova: Mesal a předměstí jeho, též Abdon a podměstí jeho;
31 Helikati àti Rehobu, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Helkat s předměstím jeho, a Rohob s podměstím jeho, města čtyři.
32 Láti ara ẹ̀yà Naftali ni a ti fún wọn ní: Kedeṣi ní Galili (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Hamoti Dori àti Karitani, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́ta.
Z pokolení také Neftalímova: Město útočišťné vražedlníku, Kedes v Galilei a předměstí jeho, a Hamotdor s předměstím jeho, a Kartam s předměstím jeho, města tři.
33 Gbogbo ìlú tí ó jẹ́ ti ọmọ Gerṣoni jẹ́ mẹ́tàlá, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn.
Všech měst Gersonitských po čeledech jejich, třinácte měst s předměstími jejich.
34 Láti ara ẹ̀yà Sebuluni ni a ti fún ìdílé Merari (tí í ṣe ìyókù ọmọ Lefi) ní: Jokneamu, Karta,
Èeledem pak synů Merari, Levítům ostatním, dali z pokolení Zabulonova Jekonam a předměstí jeho, Karta a předměstí jeho;
35 Dimina àti Nahalali, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọn, wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Damna a předměstí jeho, Naalol a předměstí jeho, města čtyři.
36 Láti ara ẹ̀yà Reubeni ni wọ́n ti fún wọn ní Beseri, àti Jahisa,
Z pokolení pak Rubenova: Bozor a předměstí jeho, a Jasa a předměstí jeho;
37 Kedemoti àti Mefaati, pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Kedemot a předměstí jeho, a Mefat s podměstím jeho, města čtyři.
38 Láti ara ẹ̀yà Gadi ni wọ́n ti fún wọn ní Ramoti ní Gileadi (tí ó jẹ́ ìlú ààbò fún apànìyàn), Mahanaimu,
A z pokolení Gádova: Město útočišťné vražedlníku, Rámot v Galád a předměstí jeho, a Mahanaim s předměstím jeho;
39 Heṣboni àti Jaseri, e pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko wọ́n jẹ́ ìlú mẹ́rin.
Ezebon a podměstí jeho, Jazer s podměstím jeho, města čtyři.
40 Gbogbo ìlú tí wọ́n pín fún àwọn ọmọ Merari tí wọ́n jẹ́ ìyókù àwọn ọmọ Lefi jẹ́ méjìlá.
Všech měst synů Merari po čeledech jejich, kteříž ostatní byli z čeledí Levítských, bylo podlé losu jejich měst dvanácte.
41 Gbogbo ìlú àwọn ọmọ Lefi tó wà láàrín ara ilẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli jẹ́ méjìdínláàádọ́ta lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko wọn.
A tak všech měst Levítských u prostřed vládařství synů Izraelských měst čtyřidceti osm s předměstími svými.
42 Ọ̀kọ̀ọ̀kan ìlú wọ̀nyí ni ó ni ilẹ̀ pápá oko tí ó yí ì ká, bẹ́ẹ̀ náà ló rí fún gbogbo ìlú wọ̀nyí.
Mělo pak to město jedno každé obzvláštně svá předměstí vůkol sebe, a taková byla všecka ta města.
43 Báyìí ni Olúwa fún Israẹli ní gbogbo ilẹ̀ tí ó ṣèlérí láti fi fún àwọn baba ńlá wọn. Nígbà tí wọ́n sì gbà á tan wọ́n sì tẹ̀dó síbẹ̀.
Dal tedy Hospodin Izraelovi všecku tu zemi, kterouž s přísahou zaslíbil dáti otcům jejich; i opanovali ji dědičně, a bydlili v ní.
44 Olúwa sì fún wọn ní ìsinmi ní gbogbo ọ̀nà, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí fún baba ńlá wọn. Kò sì sí ọ̀kankan nínú àwọn ọ̀tá wọn tí ó lè dojúkọ wọ́n. Olúwa sì fi gbogbo àwọn ọ̀tá wọn lé wọn ní ọwọ́.
Dal také Hospodin jim odpočinutí se všech stran podlé všeho, jakž byl s přísahou zaslíbil otcům jejich, aniž kdo byl, ješto by ostál proti nim ze všech nepřátel jejich; všecky nepřátely jejich dal Hospodin v ruku jejich.
45 Kò sí ọ̀kan nínú ìlérí rere tí Olúwa ṣe fún ilé Israẹli tí ó kùnà, gbogbo rẹ̀ ni ó ṣe.
Nepominulo ani jedno slovo ze všelikého slova dobrého, kteréž mluvil Hospodin k domu Izraelskému, ale všecko se tak stalo.

< Joshua 21 >