< Joshua 20 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Joṣua pé,
Och HERREN talade till Josua och sade:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn yan àwọn ìlú ààbò, gẹ́gẹ́ bí mo ti pàṣẹ fún ọ láti ẹnu Mose,
"Tala till Israels barn och säg: Utsen åt eder de fristäder om vilka jag har talat till eder genom Mose,
3 kí ẹni tí ó bá ṣèèṣì pa ènìyàn tàbí tí ó bá pa ènìyàn láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ lè sálọ sí ibẹ̀, fún ààbò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó pa.
de städer till vilka en dråpare som ouppsåtligen, utan vett och vilja, har dödat någon må kunna fly; och I skolen hava dem såsom tillflyktsorter undan blodshämnaren.
4 Nígbà tí ó bá sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú wọ̀nyí, yóò sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àtiwọ ibodè ìlú, kí ó sì ṣe àlàyé ara rẹ̀ ní iwájú àwọn àgbàgbà ìlú náà. Nígbà náà ni wọn yóò gbà á sí ìlú wọn, wọn yóò sì fun ní ibùgbé láàrín wọn.
Och när någon flyr till en av dessa städer, skall han stanna vid ingången till stadsporten och omtala sin sak för de äldste i den staden; därefter må de taga honom in i staden till sig och giva honom en plats där han får bo ibland dem.
5 Bí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ bá ń lépa rẹ̀, wọn kò gbọdọ̀ fi àwọn ọ̀daràn náà lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí ó pa aládùúgbò rẹ̀ láìmọ̀, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí.
Och om blodshämnaren förföljer honom, skola de icke överlämna dråparen i hans hand, eftersom han utan vett och vilja har dödat sin nästa, och utan att förut hava burit hat till honom.
6 Òun ó sì máa gbé inú ìlú náà, títí yóò fi jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn àti títí ikú olórí àlùfáà tí ó ń ṣiṣẹ́ ìsìn nígbà náà. Nígbà náà ó lè padà sí ilé rẹ̀ ní ìlú tí ó ti sá wá.”
Och han skall stanna kvar där i staden, till dess han har stått till rätta inför menigheten, och till dess den dåvarande översteprästen har dött; sedan må dråparen vända tillbaka och komma till sin stad från vilken han har flytt."
7 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan Kedeṣi ní Galili ní ìlú òkè Naftali, Ṣekemu ní ìlú òkè Efraimu, àti Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) ní ìlú òkè Juda.
Så helgade de då därtill Kedes i Galileen, i Naftali bergsbygd, Sikem i Efraims bergsbygd och Kirjat-Arba, det är Hebron, i Juda bergsbygd.
8 Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani ti Jeriko, wọ́n ya Beseri ní aginjù ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ẹ̀yà Reubeni, Ramoti ní Gileadi ní ẹ̀yà Gadi, àti Golani ní Baṣani ní ẹ̀yà Manase.
Och på andra sidan Jordan mitt emot Jeriko, på östra sidan, utsågo de därtill inom Rubens stam Beser i öknen på slätten, inom Gads stam Ramot i Gilead, och inom Manasse stam Golan i Basan.
9 Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé ní àárín wọn tí ó ṣèèṣì pa ẹnìkan lè sálọ sí àwọn ìlú tí a yà sọ́tọ̀ wọ̀nyí, kí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má sì ṣe pa á kí ó to di àkókò tí yóò jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn.
Dessa voro de städer som för alla Israels barn, och för de främlingar som bodde ibland dem, bestämdes att vara orter till vilka var och en som ouppsåtligen hade dödat någon finge fly, så att han skulle slippa dö för blodshämnarens hand, innan han hade stått till rätta inför menigheten.

< Joshua 20 >