< Joshua 20 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Joṣua pé,
Și DOMNUL a vorbit lui Iosua, spunând:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn yan àwọn ìlú ààbò, gẹ́gẹ́ bí mo ti pàṣẹ fún ọ láti ẹnu Mose,
Vorbește fiilor lui Israel, spunând: Rânduiți-vă cetățile de scăpare despre care v-am vorbit prin mâna lui Moise,
3 kí ẹni tí ó bá ṣèèṣì pa ènìyàn tàbí tí ó bá pa ènìyàn láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ lè sálọ sí ibẹ̀, fún ààbò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó pa.
Ca să fugă acolo ucigașul, care a ucis fără intenție și fără premeditare pe un om; și ele vă vor fi pentru a scăpa de răzbunătorul sângelui.
4 Nígbà tí ó bá sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú wọ̀nyí, yóò sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àtiwọ ibodè ìlú, kí ó sì ṣe àlàyé ara rẹ̀ ní iwájú àwọn àgbàgbà ìlú náà. Nígbà náà ni wọn yóò gbà á sí ìlú wọn, wọn yóò sì fun ní ibùgbé láàrín wọn.
Și când cel care fuge la una din cetățile acestea va sta la intrarea porții cetății și va spune cauza lui în auzul bătrânilor acelei cetăți, să-l primească la ei în cetate și să îi dea un loc ca să locuiască între ei.
5 Bí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ bá ń lépa rẹ̀, wọn kò gbọdọ̀ fi àwọn ọ̀daràn náà lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí ó pa aládùúgbò rẹ̀ láìmọ̀, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí.
Și dacă răzbunătorul sângelui îl urmărește, ei să nu-l dea pe ucigaș în mâna lui, pentru că el l-a ucis pe aproapele său fără premeditare și nu l-a urât mai înainte.
6 Òun ó sì máa gbé inú ìlú náà, títí yóò fi jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn àti títí ikú olórí àlùfáà tí ó ń ṣiṣẹ́ ìsìn nígbà náà. Nígbà náà ó lè padà sí ilé rẹ̀ ní ìlú tí ó ti sá wá.”
Și să locuiască în cetatea aceasta până va sta înaintea adunării pentru judecată, până la moartea marelui preot care va fi în zilele acelea; atunci ucigașul să se întoarcă și să vină în cetatea sa și în casa sa, în cetatea de unde a fugit.
7 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan Kedeṣi ní Galili ní ìlú òkè Naftali, Ṣekemu ní ìlú òkè Efraimu, àti Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) ní ìlú òkè Juda.
Și au rânduit Chedeșul, în Galileea, în muntele lui Neftali, și Sihemul, în muntele lui Efraim, și Chiriat-Arba, adică Hebronul, în muntele lui Iuda.
8 Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani ti Jeriko, wọ́n ya Beseri ní aginjù ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ẹ̀yà Reubeni, Ramoti ní Gileadi ní ẹ̀yà Gadi, àti Golani ní Baṣani ní ẹ̀yà Manase.
Și dincolo de Iordan, lângă Ierihon, spre est, au rânduit Bețerul, în pustiu, în câmpie, din tribul lui Ruben; și Ramot, în Galaad, din tribul lui Gad; și Golan, în Basan, din tribul lui Manase.
9 Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé ní àárín wọn tí ó ṣèèṣì pa ẹnìkan lè sálọ sí àwọn ìlú tí a yà sọ́tọ̀ wọ̀nyí, kí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má sì ṣe pa á kí ó to di àkókò tí yóò jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn.
Acestea au fost cetățile rânduite pentru toți copiii lui Israel și pentru străinul care locuiește temporar printre ei, ca oricine ucide fără intenție pe un om să fugă acolo și să nu moară de mâna răzbunătorului sângelui, până va sta înaintea adunării.

< Joshua 20 >