< Joshua 20 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Joṣua pé,
And Yahweh spake unto Joshua, saying:
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn yan àwọn ìlú ààbò, gẹ́gẹ́ bí mo ti pàṣẹ fún ọ láti ẹnu Mose,
Speak unto the sons of Israel, saying, —Set out for you the cities of refuge, whereof I spake unto you, by the hand of Moses:
3 kí ẹni tí ó bá ṣèèṣì pa ènìyàn tàbí tí ó bá pa ènìyàn láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ lè sálọ sí ibẹ̀, fún ààbò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó pa.
that the manslayer who slayeth a person by mistake, unwittingly, may flee thither, —so shall they be unto you for refuge from the blood-redeemer,
4 Nígbà tí ó bá sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú wọ̀nyí, yóò sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àtiwọ ibodè ìlú, kí ó sì ṣe àlàyé ara rẹ̀ ní iwájú àwọn àgbàgbà ìlú náà. Nígbà náà ni wọn yóò gbà á sí ìlú wọn, wọn yóò sì fun ní ibùgbé láàrín wọn.
and he shall flee unto one of these cities and present himself at the entrance of the gate of the city, and shall speak, in the ears of the elders of that city, his defence, —and they shall take him for protection into the city unto them, and shall give him a place, so shall he dwell with them.
5 Bí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ bá ń lépa rẹ̀, wọn kò gbọdọ̀ fi àwọn ọ̀daràn náà lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí ó pa aládùúgbò rẹ̀ láìmọ̀, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí.
And, when the blood-redeemer pursueth after him, then shall they not deliver up the manslayer, into his hand, —because, unwittingly, it was that he slew his neighbour, and had not been, cherishing hatred, towards him, aforetime;
6 Òun ó sì máa gbé inú ìlú náà, títí yóò fi jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn àti títí ikú olórí àlùfáà tí ó ń ṣiṣẹ́ ìsìn nígbà náà. Nígbà náà ó lè padà sí ilé rẹ̀ ní ìlú tí ó ti sá wá.”
so shall he remain in that city, until he standeth before the assembly, for judgment, until the death of the high-priest who shall be in those days, —then, shall the manslayer return, and enter into his own city, and into his own house, within the city from whence he fled.
7 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan Kedeṣi ní Galili ní ìlú òkè Naftali, Ṣekemu ní ìlú òkè Efraimu, àti Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) ní ìlú òkè Juda.
So then they set apart Kadesh in Galilee, in the hill country of Naphtali, and Shechem, in the hill country of Ephraim, and Kiriath-arba, the same, is Hebron, in the hill country of Judah.
8 Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani ti Jeriko, wọ́n ya Beseri ní aginjù ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ẹ̀yà Reubeni, Ramoti ní Gileadi ní ẹ̀yà Gadi, àti Golani ní Baṣani ní ẹ̀yà Manase.
And, beyond the Jordan, by Jericho eastward, they appointed Bezer in the wilderness, in the table-land, out of the tribe of Reuben, —and Ramoth in Gilead, out of the tribe of Gad, and Golan in Bashan, out of the tribe of Manasseh.
9 Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé ní àárín wọn tí ó ṣèèṣì pa ẹnìkan lè sálọ sí àwọn ìlú tí a yà sọ́tọ̀ wọ̀nyí, kí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má sì ṣe pa á kí ó to di àkókò tí yóò jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn.
These, were the cities appointed for all the sons of Israel, and for the sojourner who sojourneth in their midst, that whosoever should slay a person by mistake, might flee thither, —and not die by the hand of the blood-redeemer, until he should stand before the assembly.

< Joshua 20 >