< Joshua 20 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Joṣua pé,
Joshua te BOEIPA a voek tih,
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn yan àwọn ìlú ààbò, gẹ́gẹ́ bí mo ti pàṣẹ fún ọ láti ẹnu Mose,
“Israel ca rhoek te thui pah lamtah, Moses kut dongah nangmih ham ka thui vabangla, 'Hlipyingnah khopuei te namamih ham khueh uh,’ ti nah.
3 kí ẹni tí ó bá ṣèèṣì pa ènìyàn tàbí tí ó bá pa ènìyàn láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ lè sálọ sí ibẹ̀, fún ààbò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó pa.
A ming mueh ah tohtamaeh la hinglu aka ngawn, aka ngawn tah te lam te rhaelrham saeh. Te vaengah thii phu aka suk taeng lamloh nangmih ham hlipyingnah la om saeh.
4 Nígbà tí ó bá sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú wọ̀nyí, yóò sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àtiwọ ibodè ìlú, kí ó sì ṣe àlàyé ara rẹ̀ ní iwájú àwọn àgbàgbà ìlú náà. Nígbà náà ni wọn yóò gbà á sí ìlú wọn, wọn yóò sì fun ní ibùgbé láàrín wọn.
Te khopuei khuikah pakhat pakhat la a rhaelrham vaengah khopuei vongka kah thohka ah pai saeh lamtah a dum a lai te khopuei kah a hamca rhoek hna ah thui pah saeh. Te vaengah anih te a kho khuila khoem uh saeh, anih te a hmuen pae uh van saeh lamtah amih taengah khosa saeh.
5 Bí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ bá ń lépa rẹ̀, wọn kò gbọdọ̀ fi àwọn ọ̀daràn náà lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí ó pa aládùúgbò rẹ̀ láìmọ̀, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí.
Te vaengah thii phu aka suk loh a hnuk han hloem mai cakhaw hlaem hlavai ah anih te a hmuhuet moenih, a hui te poek mueh la a ngawn oeh dongah hlang aka ngawn te phu aka suk kut ah tloeng uh boel saeh.
6 Òun ó sì máa gbé inú ìlú náà, títí yóò fi jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn àti títí ikú olórí àlùfáà tí ó ń ṣiṣẹ́ ìsìn nígbà náà. Nígbà náà ó lè padà sí ilé rẹ̀ ní ìlú tí ó ti sá wá.”
Laitloeknah ham rhaengpuei mikhmuh ah pai hlan tih, te vaeng tue ah aka om khosoih puei loh a duek hlan khuiah tah te khopuei ah te khosa saeh. Hlang aka ngawn te a mael vaengah tah te lamkah a rhaelrham khopuei lamloh amah kho neh amah im te paan saeh,” a ti nah.
7 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan Kedeṣi ní Galili ní ìlú òkè Naftali, Ṣekemu ní ìlú òkè Efraimu, àti Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) ní ìlú òkè Juda.
Te dongah Galilee, Naphtali tlang kah Kedesh, Ephraim tlang ah Shekhem, Judah tlang Hebron ah Kiriatharba,
8 Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani ti Jeriko, wọ́n ya Beseri ní aginjù ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ẹ̀yà Reubeni, Ramoti ní Gileadi ní ẹ̀yà Gadi, àti Golani ní Baṣani ní ẹ̀yà Manase.
rhalvangan ah Jordan kah khocuk Jerikho te a hoep uh. Khosoek tlangkol, Reuben koca khuiah ah Bezer, Gilead kah Gad koca khuiah Ramoth, Bashan kah Manasseh koca khuiah Golan te a khueh uh.
9 Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé ní àárín wọn tí ó ṣèèṣì pa ẹnìkan lè sálọ sí àwọn ìlú tí a yà sọ́tọ̀ wọ̀nyí, kí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má sì ṣe pa á kí ó to di àkókò tí yóò jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn.
Tohtamaeh ah hinglu aka ngawn boeih loh te la a rhaelrham ham, amih lakli ah aka bakuep Israel ca rhoek boeih neh yinlai ham khaw te rhoek te khopuei khoyaeh la om coeng. Te daengah ni rhaengpuei mikhmuh ah a pai hlan atah thii phu aka suk kut loh a ngawn pawt eh.

< Joshua 20 >