< Joshua 20 >

1 Nígbà náà ni Olúwa sọ fún Joṣua pé,
To naah Angraeng mah Joshua khaeah,
2 “Sọ fún àwọn ọmọ Israẹli pé kí wọn yan àwọn ìlú ààbò, gẹ́gẹ́ bí mo ti pàṣẹ fún ọ láti ẹnu Mose,
Mosi patohhaih rang hoiah kang thuih o ih baktih toengah, Israel kaminawk mah abuephaih vangpui tarukto pahoe o hanah thui paeh;
3 kí ẹni tí ó bá ṣèèṣì pa ènìyàn tàbí tí ó bá pa ènìyàn láìmọ̀-ọ́n-mọ̀ lè sálọ sí ibẹ̀, fún ààbò lọ́wọ́ olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ ẹni tí ó pa.
to tiah ni kami maeto mah poek ai pui hoi kami hum moeng naah, athii tho lu lak koeh kami ban thung hoi loih thai hanah abuephaih vangpui ah om tih.
4 Nígbà tí ó bá sálọ sí ọ̀kan nínú àwọn ìlú wọ̀nyí, yóò sì dúró ní ẹnu-ọ̀nà àtiwọ ibodè ìlú, kí ó sì ṣe àlàyé ara rẹ̀ ní iwájú àwọn àgbàgbà ìlú náà. Nígbà náà ni wọn yóò gbà á sí ìlú wọn, wọn yóò sì fun ní ibùgbé láàrín wọn.
Hae vangpuinawk thung ih vangpui maeto ah a cawnh naah, vangpui thung akunhaih khogkha taengah angdoe ueloe, to vangpui thungah kaom kacoehtanawk hmaa ah angmah kawng to taphong tih; to tiah a thuih pacoengah ni anih to vangpui thungah akunsak ueloe, nihcae hoi nawnto oh hanah anih han ohhaih ahmuen to paek o tih.
5 Bí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ bá ń lépa rẹ̀, wọn kò gbọdọ̀ fi àwọn ọ̀daràn náà lé wọn lọ́wọ́, nítorí tí ó pa aládùúgbò rẹ̀ láìmọ̀, tí kò sì kórìíra rẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí.
Athii tho lu lak koeh kami mah anih to patom nahaeloe, anih loe canghniah a imtaeng kami hnukmahaih tawn ai, kami hum koehhaih palungthin hoiah hum ai pongah, vangpui thungah kaom kaminawk mah anih to lu lak koeh kami ban ah paek o mak ai.
6 Òun ó sì máa gbé inú ìlú náà, títí yóò fi jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn àti títí ikú olórí àlùfáà tí ó ń ṣiṣẹ́ ìsìn nígbà náà. Nígbà náà ó lè padà sí ilé rẹ̀ ní ìlú tí ó ti sá wá.”
Anih to rangpui lokcaekhaih hmaa ah angdoe ai karoek to, to atue thuemah toksah qaima dueh ai karoek to, to vangpui thungah om tih; qaima duek pacoengah ni poek ai pui hoiah kami hum moeng kami to a ohhaih vangpui ah amlaem thai let vop tih, tiah a naa.
7 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n yan Kedeṣi ní Galili ní ìlú òkè Naftali, Ṣekemu ní ìlú òkè Efraimu, àti Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) ní ìlú òkè Juda.
To pongah nihcae mah Kalili prae ih Naphtali mae nuiah Kedesh vangpui, Ephraim mae nuiah Shekem vangpui, Judah mae nuiah Hebron, tiah kawk ih Kirjath-Arba vangpui,
8 Ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani ti Jeriko, wọ́n ya Beseri ní aginjù ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ẹ̀yà Reubeni, Ramoti ní Gileadi ní ẹ̀yà Gadi, àti Golani ní Baṣani ní ẹ̀yà Manase.
Jordan vapui yaeh, Jeriko vangpui ni angyae bang ih Reuben acaengnawk ohhaih ahmuen ah kaom praezaek azawn ih Bezer vangpui, Gad acaengnawk ohhaih ahmuen ih Gilead prae ih Ramoth vangpui, Manasseh acaengnawk ohhaih ahmuen Bashan prae ih Golan vangpui to a qoih o.
9 Ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli tàbí àlejò tí ń gbé ní àárín wọn tí ó ṣèèṣì pa ẹnìkan lè sálọ sí àwọn ìlú tí a yà sọ́tọ̀ wọ̀nyí, kí olùgbẹ̀san ẹ̀jẹ̀ má sì ṣe pa á kí ó to di àkókò tí yóò jẹ́jọ́ níwájú ìjọ ènìyàn.
Hae loe Israel kaminawk hoi nihcae salakah khosah angvinnawk mah, poek ai pui hoiah kami hum moeng naah, hae vangpuinawk ah cawnh o moe, rangpui lokcaekhaih hmaa ah angdoe ai karoek to, athii tho lu lak koeh kami ban thung hoi loih thai hanah, kacawn kaminawk abuephaih vangpui ah oh o.

< Joshua 20 >