< Joshua 2 >

1 Nígbà náà ni Joṣua ọmọ Nuni rán àwọn ayọ́lẹ̀wò méjì jáde ní àṣírí láti Ṣittimu. Ó sì wí pé, “Ẹ lọ wo ilẹ̀ náà, pàápàá Jeriko.” Wọ́n sì lọ, wọ́n wọ ilé panṣágà kan, tí à ń pè ní Rahabu wọ́n sì dúró síbẹ̀.
Josua, Nuns son, sände hemligen ut två spejare från Sittim och sade: "Gån och besen landet och Jeriko." De gingo åstad och kommo in i ett hus där en sköka bodde, vid namn Rahab, och där lade de sig till vila.
2 A sì sọ fún ọba Jeriko, “Wò ó! Àwọn ará Israẹli kan wá ibí ní alẹ́ yìí láti wá yọ́ ilẹ̀ yí wò.”
Men för konungen i Jeriko blev inberättat: "I natt hava några män kommit hit från Israels barn för att utforska landet."
3 Ọba Jeriko sì ránṣẹ́ sí Rahabu pé, “Mú àwọn ọkùnrin nì tí ó tọ̀ ọ́ wá, tí ó wọ inú ilé rẹ jáde wá, nítorí wọ́n wá láti yọ́ gbogbo ilẹ̀ yìí wò ni.”
Då sände konungen i Jeriko till Rahab och lät säga: "Lämna ut de män som hava kommit till dig och tagit in i ditt hus, ty de hava kommit hit för att utforska hela landet."
4 Ṣùgbọ́n obìnrin náà ti mú àwọn ọkùnrin méjì náà o sì fi wọ́n pamọ́. Ó sì wí pé, “Lóòtítọ́ ní àwọn ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ibi tí wọ́n ti wá.
Men kvinnan tog de båda männen och dolde dem; sedan svarade hon: "Ja, männen kommo till mig, men jag visste icke varifrån de voro;
5 Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, nígbà tí ó tó àkókò láti ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè, àwọn ọkùnrin náà sì jáde lọ. Èmi kò sì mọ ọ̀nà tí wọ́n gbà lọ. Ẹ lépa wọn kíákíá. Ẹ̀yin yóò bá wọn.”
och när porten skulle stängas, sedan det hade blivit mörkt, gingo männen ut, och jag vet icke vart de togo vägen; skynden eder att sätta efter dem, så fån I nog fatt i dem."
6 (Ṣùgbọ́n ó ti mú wọn gòkè àjà ó sì fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ pòròpòrò ọkà tó tò jọ sí orí àjà.)
Men hon hade fört dem upp på taket och gömt dem under linstjälkar, som hon hade där, utbredda på taket.
7 Àwọn ọkùnrin náà jáde lọ láti lépa àwọn ayọ́lẹ̀wò náà ní ọ̀nà tí ó lọ sí ìwọdò Jordani, bí àwọn tí ń lépa wọn sì ti jáde, wọ́n ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè.
Så satte nu männen efter dem åt Jordan till, bort emot vadställena; och man stängde stadsporten så snart förföljarna hade begivit sig åstad.
8 Kí àwọn ayọ́lẹ̀wò náà tó sùn ní alẹ́, ó gòkè tọ̀ wọ́n lọ lókè àjà.
Men innan de främmande männen hade lagt sig, steg hon upp till dem på taket
9 Ó sì sọ fún wọn, “Èmi mọ̀ pé Olúwa ti fún un yín ní ilẹ̀ yìí àti pé ẹ̀rù u yín ti sọ wá di ojo dé ibi pé ìdí gbogbo àwọn tí ó n gbé ilẹ̀ yìí ti di omi nítorí i yín.
och sade till dem: "Jag vet att HERREN har givit eder detta land, och att förskräckelse för eder har fallit över oss, ja, att alla landets inbyggare äro i ångest för eder.
10 Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Sihoni àti Ogu, àwọn ọba méjèèjì ti Amori ti ìlà-oòrùn Jordani, tí ẹ̀yin parun pátápátá.
Ty vi hava hört huru HERREN lät vattnet i Röda havet torka ut framför eder, när I drogen ut ur Egypten, och vad I haven gjort med amoréernas konungar, de två på andra sidan Jordan, Sihon och Og, huru I gåven dem till spillo.
11 Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ọkàn wa pami kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé.
Då vi hörde detta, blevo våra hjärtan förfärade, och numera har ingen mod att stå eder emot; ty HERREN, eder Gud, är Gud, uppe i himmelen och nere på jorden.
12 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ jọ̀wọ́ ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ̀yin yóò fún mi ní àmì tó dájú:
Så loven mig nu med ed vid HERREN, att eftersom jag har gjort barmhärtighet med min faders hus och giva mig ett säkert tecken därpå,
13 pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábìnrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”
och låta min fader och min moder, mina bröder och mina systrar leva, så ock alla som tillhöra dem, och rädda oss från döden."
14 “Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”
Männen sade till henne: "Med vårt eget liv svara vi för edert, såframt I icke förråden vårt förehavande; när HERREN giver oss landet, skola vi bevisa dig barmhärtighet och trofasthet."
15 Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú.
Då släppte hon ned dem genom fönstret med ett tåg; ty hennes hus låg invid stadsmuren, så att hon bodde invid själva muren.
16 Ó sì ti sọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má ba à rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”
Och hon sade till dem: "Gån upp i bergsbygden, så att edra förföljare icke träffa på eder; och hållen eder gömda där i tre dagar, till dess edra förföljare hava kommit tillbaka, så kunnen I sedan fortsätta eder färd."
17 Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa ba à lè mọ́ kúrò nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí.
Och männen sade till henne: "Vi vilja likväl vara fria ifrån den ed som du nu har tagit av oss,
18 Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò so okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ.
om du, när vi komma in i landet, underlåter att binda detta röda snöre i det fönster genom vilket du har släppt ned oss, och likaledes om du icke har din fader och din moder och dina bröder, alla av din faders hus, samlade hemma hos dig.
19 Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án.
Dock, om någon går åstad, utom dörrarna till ditt hus, så komme hans blod över hans huvud, och vi äro utan skuld; om däremot någons hand kommer vid en av dem som äro inne i ditt hus, så må dennes blod komma över vårt huvud.
20 Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò bọ́ nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú.”
Och om du förråder vårt förehavande, så äro vi likaledes fria ifrån den ed som du har tagit av oss."
21 Ó dáhùn pé, “Ó dára bẹ́ẹ̀. Ẹ jẹ́ kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí sọ.” Ó sì rán wọn lọ wọ́n sì lọ. Ó sì so okùn òdòdó náà sí ojú fèrèsé.
Hon svarade: "Vare det såsom I haven sagt." Och så lät hon dem gå, och de drogo åstad. Men hon band det röda snöret i fönstret.
22 Nígbà tí wọ́n kúrò, wọ́n sì lọ sí orí òkè wọ́n sì dúró ní ibẹ̀ ní ọjọ́ mẹ́ta, títí àwọn alépa fi wá wọn ní gbogbo ọ̀nà wọ́n sì padà láìrí wọn.
Så drogo de nu åstad och kommo upp i bergsbygden och stannade där i tre dagar, till dess att deras förföljare hade vänt tillbaka; ty dessa hade sökt efter dem överallt på vägarna, men hade icke funnit dem.
23 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin méjì náà padà. Wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, wọ odò, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ọmọ Nuni wọ́n sì sọ fún un gbogbo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wọn.
Sedan vände de båda männen tillbaka och kommo ned från bergsbygden och gingo över floden och kommo så till Josua, Nuns son; och de förtäljde för honom allt vad som hade vederfarits dem.
24 Wọ́n sì sọ fún Joṣua, “Nítòótọ́ ni Olúwa tí fi gbogbo ilẹ̀ náà lé wa lọ́wọ́; gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà ni ìbẹ̀rùbojo ti mú nítorí i wa.”
Och de sade till Josua: "HERREN har givit hela landet i vår hand; alla landets inbyggare äro i ångest för oss."

< Joshua 2 >