< Joshua 2 >
1 Nígbà náà ni Joṣua ọmọ Nuni rán àwọn ayọ́lẹ̀wò méjì jáde ní àṣírí láti Ṣittimu. Ó sì wí pé, “Ẹ lọ wo ilẹ̀ náà, pàápàá Jeriko.” Wọ́n sì lọ, wọ́n wọ ilé panṣágà kan, tí à ń pè ní Rahabu wọ́n sì dúró síbẹ̀.
Josua, Nuns son, sände hemliga ut två spejare ifrå Sittim, och sade dem: Går och beser landet, och Jericho. De gingo åstad, och kommo in uti ene skökos hus, som het Rahab, och der lågo de.
2 A sì sọ fún ọba Jeriko, “Wò ó! Àwọn ará Israẹli kan wá ibí ní alẹ́ yìí láti wá yọ́ ilẹ̀ yí wò.”
Då vardt Konungenom i Jericho sagdt: Si, i denna nattene äro någre män inkomne ifrån Israels barn, till att bespeja landet.
3 Ọba Jeriko sì ránṣẹ́ sí Rahabu pé, “Mú àwọn ọkùnrin nì tí ó tọ̀ ọ́ wá, tí ó wọ inú ilé rẹ jáde wá, nítorí wọ́n wá láti yọ́ gbogbo ilẹ̀ yìí wò ni.”
Då sände Konungen i Jericho till Rahab, och lät säga henne: Få oss ut de män, som till dig i ditt hus komne äro; ty de äro komne till att bespeja allt landet.
4 Ṣùgbọ́n obìnrin náà ti mú àwọn ọkùnrin méjì náà o sì fi wọ́n pamọ́. Ó sì wí pé, “Lóòtítọ́ ní àwọn ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ibi tí wọ́n ti wá.
Men qvinnan fördolde de två männerna, och sade: Här äro väl två män inkomne till mig; men jag visste icke hvadan de voro.
5 Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, nígbà tí ó tó àkókò láti ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè, àwọn ọkùnrin náà sì jáde lọ. Èmi kò sì mọ ọ̀nà tí wọ́n gbà lọ. Ẹ lépa wọn kíákíá. Ẹ̀yin yóò bá wọn.”
Och då jag ville låta dörrena igen, då mörkt vardt, gingo de ut, så att jag icke vet hvart de gingo; söker med hast efter dem, I fån dem väl fatt.
6 (Ṣùgbọ́n ó ti mú wọn gòkè àjà ó sì fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ pòròpòrò ọkà tó tò jọ sí orí àjà.)
Men hon lät dem stiga upp på taket, och öfvertäckte dem med linstjelkar, som hon der på taket utbredt hade.
7 Àwọn ọkùnrin náà jáde lọ láti lépa àwọn ayọ́lẹ̀wò náà ní ọ̀nà tí ó lọ sí ìwọdò Jordani, bí àwọn tí ń lépa wọn sì ti jáde, wọ́n ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè.
Men männerna sökte efter dem på den vägen till Jordan, allt intill färjostaden; och porten vardt tilläster straxt de utkomne voro, som efter dem jagade.
8 Kí àwọn ayọ́lẹ̀wò náà tó sùn ní alẹ́, ó gòkè tọ̀ wọ́n lọ lókè àjà.
Och förra än männerna lade sig till sofva, steg hon upp på taket;
9 Ó sì sọ fún wọn, “Èmi mọ̀ pé Olúwa ti fún un yín ní ilẹ̀ yìí àti pé ẹ̀rù u yín ti sọ wá di ojo dé ibi pé ìdí gbogbo àwọn tí ó n gbé ilẹ̀ yìí ti di omi nítorí i yín.
Och sade till dem: Jag vet, att Herren hafver gifvit eder detta landet; ty en förskräckelse för eder är fallen öfver oss, och alle landsens inbyggare äro bäfvande vordne för edor tillkommelse.
10 Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Sihoni àti Ogu, àwọn ọba méjèèjì ti Amori ti ìlà-oòrùn Jordani, tí ẹ̀yin parun pátápátá.
Ty vi hafve hört, huru Herren uttorkade vattnet i röda hafvet för eder, då I drogen utur Egypten; och hvad I gjort hafven de två Amoreers Konungar, Sihon och Og, på hinsidon Jordan, huru I gåfven dem tillspillo.
11 Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ọkàn wa pami kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé.
Och sedan vi det hörde, vardt vårt hjerta förtvifladt, och intet mod är mer i någon man för edor tillkommelse; ty Herren edar Gud han är Gud, både uppe i himmelen, och nedre på jordene.
12 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ jọ̀wọ́ ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ̀yin yóò fún mi ní àmì tó dájú:
Så svärjer mig nu vid Herran, efter jag hafver gjort barmhertighet med eder, att I ock gören barmhertighet med mins faders hus, och gifver mig ett vårdtecken;
13 pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábìnrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”
Att I låten lefva min fader, mina moder, mina bröder, och mina systrar, och allt det de hafva; och frälser våra själar ifrå döden.
14 “Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”
Männerna sade till henne: Om vi icke göre barmhertighet och trohet med dig, då Herren gifver oss landet, så skall vår själ vara döden skyldig för eder, såframt du icke förråder vårt ärende.
15 Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú.
Så släppte hon dem neder med ett tåg genom ett fenster; ty hennes hus var i stadsmurenom; och hon bodde desslikes på murenom.
16 Ó sì ti sọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má ba à rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”
Och hon sade till dem: Går uppåt berget, att de, som söka efter eder, icke möta eder, och gömmer eder der i tre dagar, så länge de komma igen, som efter eder fara; sedan går edar väg.
17 Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa ba à lè mọ́ kúrò nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí.
Männerna sade till henne: Vi vilje vara denna eden qvitte, som du af oss tagit hafver;
18 Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò so okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ.
När vi komme i landet, och du icke binder detta rosenröda tåget i fenstret, med hvilko du oss nedersläppt hafver: och hafver församlat till dig i huset din fader, dina moder, dina bröder, och hela dins faders hus;
19 Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án.
Och hvilken som går utom dörrena af ditt hus, hans blod vare öfver hans hufvud, och vi oskyldige; men alle de som i dino huse äro, om en hand kommer vid dem, så skall deras blod vara öfver vårt hufvud.
20 Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò bọ́ nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú.”
Och om du något af denna vår ärende utröjer, så vilje vi vara den eden qvitte, som du af oss tagit hafver.
21 Ó dáhùn pé, “Ó dára bẹ́ẹ̀. Ẹ jẹ́ kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí sọ.” Ó sì rán wọn lọ wọ́n sì lọ. Ó sì so okùn òdòdó náà sí ojú fèrèsé.
Hon sade: Vare som I sägen: och lät gå dem; och de gingo sin väg, och hon band det rosenröda tåget i fenstret.
22 Nígbà tí wọ́n kúrò, wọ́n sì lọ sí orí òkè wọ́n sì dúró ní ibẹ̀ ní ọjọ́ mẹ́ta, títí àwọn alépa fi wá wọn ní gbogbo ọ̀nà wọ́n sì padà láìrí wọn.
Och de gingo sin väg, och kommo upp på berget, och blefvo der i tre dagar, tilldess de kommo igen, som efter dem foro: ty de hade sökt dem på alla vägar, och dock intet funnit dem.
23 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin méjì náà padà. Wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, wọ odò, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ọmọ Nuni wọ́n sì sọ fún un gbogbo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wọn.
Så vände de två männerna tillbaka, gingo ned af berget, och foro utöfver, och kommo till Josua, Nuns son, och förtäljde honom allt, såsom de det funnit hade;
24 Wọ́n sì sọ fún Joṣua, “Nítòótọ́ ni Olúwa tí fi gbogbo ilẹ̀ náà lé wa lọ́wọ́; gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà ni ìbẹ̀rùbojo ti mú nítorí i wa.”
Och sade till Josua: Herren hafver gifvit oss allt landet i våra händer, alle landsens inbyggare äro förskräckte för oss.