< Joshua 2 >
1 Nígbà náà ni Joṣua ọmọ Nuni rán àwọn ayọ́lẹ̀wò méjì jáde ní àṣírí láti Ṣittimu. Ó sì wí pé, “Ẹ lọ wo ilẹ̀ náà, pàápàá Jeriko.” Wọ́n sì lọ, wọ́n wọ ilé panṣágà kan, tí à ń pè ní Rahabu wọ́n sì dúró síbẹ̀.
És Józsué, a Nún fia, elkülde Sittimből titkon két férfiút kémekül, mondván: Menjetek el, tekintsétek meg azt a földet és Jérikhót. Azok pedig elmenének, és bemenének egy parázna asszonynak házába, a kinek Ráháb vala neve, és ott hálának.
2 A sì sọ fún ọba Jeriko, “Wò ó! Àwọn ará Israẹli kan wá ibí ní alẹ́ yìí láti wá yọ́ ilẹ̀ yí wò.”
Mikor pedig megjelentették ezt Jérikhó királyának, mondván: Íme, férfiak jöttek ide ez éjszaka az Izráel fiai közül e földnek kémlelésére;
3 Ọba Jeriko sì ránṣẹ́ sí Rahabu pé, “Mú àwọn ọkùnrin nì tí ó tọ̀ ọ́ wá, tí ó wọ inú ilé rẹ jáde wá, nítorí wọ́n wá láti yọ́ gbogbo ilẹ̀ yìí wò ni.”
Akkor külde Jérikhó királya Ráhábhoz, mondván: Hozd ki a férfiakat, a kik bementek hozzád, a kik házadba mentek, mert azért jöttek, hogy kikémleljék az egész földet.
4 Ṣùgbọ́n obìnrin náà ti mú àwọn ọkùnrin méjì náà o sì fi wọ́n pamọ́. Ó sì wí pé, “Lóòtítọ́ ní àwọn ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ibi tí wọ́n ti wá.
Az asszony pedig fogá a két férfiút, és elrejté vala őket, és monda: Úgy van! Bejöttek hozzám a férfiak, de azt sem tudom, honnan valók voltak.
5 Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, nígbà tí ó tó àkókò láti ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè, àwọn ọkùnrin náà sì jáde lọ. Èmi kò sì mọ ọ̀nà tí wọ́n gbà lọ. Ẹ lépa wọn kíákíá. Ẹ̀yin yóò bá wọn.”
És kimentek e férfiak kapuzáráskor a setétben; nem tudom, hová mentek a férfiak; siessetek gyorsan utánok, mert utólérhetitek őket.
6 (Ṣùgbọ́n ó ti mú wọn gòkè àjà ó sì fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ pòròpòrò ọkà tó tò jọ sí orí àjà.)
Pedig ő felhágatta őket a házhéjára, és elbujtatta őket a száras len közé, a mely néki a házhéjára volt kirakva.
7 Àwọn ọkùnrin náà jáde lọ láti lépa àwọn ayọ́lẹ̀wò náà ní ọ̀nà tí ó lọ sí ìwọdò Jordani, bí àwọn tí ń lépa wọn sì ti jáde, wọ́n ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè.
És utánok sietének a férfiak a Jordánhoz vivő úton a rév felé; a kaput pedig bezárták, azután, hogy kimenének azok, a kik őket üldözik vala.
8 Kí àwọn ayọ́lẹ̀wò náà tó sùn ní alẹ́, ó gòkè tọ̀ wọ́n lọ lókè àjà.
Ők pedig még le sem feküvének, a mikor felméne ő hozzájok az asszony a házhéjára,
9 Ó sì sọ fún wọn, “Èmi mọ̀ pé Olúwa ti fún un yín ní ilẹ̀ yìí àti pé ẹ̀rù u yín ti sọ wá di ojo dé ibi pé ìdí gbogbo àwọn tí ó n gbé ilẹ̀ yìí ti di omi nítorí i yín.
És monda a férfiaknak: Tudom, hogy az Úr néktek adta ezt a földet, és hogy megszállt minket a félelem miattatok, és hogy e földnek minden lakosa megolvad előttetek.
10 Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Sihoni àti Ogu, àwọn ọba méjèèjì ti Amori ti ìlà-oòrùn Jordani, tí ẹ̀yin parun pátápátá.
Mert hallottuk, hogy megszárította az Úr a Veres tenger vizét előttetek, a mikor kijöttetek Égyiptomból, és hogy mit cselekedtetek az Emoreusok két királyával, a kik túl voltak a Jordánon, Szíhonnal és Óggal, a kiket megöltetek.
11 Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ọkàn wa pami kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé.
És a mint hallottuk, megolvadott a mi szívünk, és nem támadt többé bátorság senkiben sem miattatok. Bizony az Úr, a ti Istenetek az Isten fenn az égben és alant a földön!
12 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ jọ̀wọ́ ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ̀yin yóò fún mi ní àmì tó dájú:
Most azért esküdjetek meg kérlek, nékem az Úrra, hogy a mint én irgalmasságot cselekedtem veletek, ti is irgalmasságot cselekesztek majd az én atyámnak házával, és igaz jelt adtok nékem,
13 pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábìnrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”
Hogy életben hagyjátok az én atyámat és anyámat, férfi és nőtestvéreimet, és mindent, a mi az övék, és megmentitek a mi lelkünket a haláltól.
14 “Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”
És mondának néki a férfiak: A mi lelkünket érje helyettetek a halál, ha meg nem jelentitek ezt a mi dolgunkat. És ha nékünk adja az Úr ezt a földet, irgalmasságot és igazságot cselekszünk veled.
15 Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú.
Alábocsátá azért őket kötélen az ablakon (mert az ő háza a kőkerítés falán vala, és ő a kőkerítésen lakik vala).
16 Ó sì ti sọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má ba à rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”
És monda nékik: A hegyre menjetek, hogy rátok ne találjanak az üldözők, és ott rejtőzködjetek három napig, a míg visszatérnek az üldözők; azután pedig menjetek a magatok útján.
17 Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa ba à lè mọ́ kúrò nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí.
A férfiak pedig mondának néki: Ártatlanok leszünk ezen te esketésedtől, a melylyel te megeskettél minket!
18 Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò so okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ.
Ha bejövünk mi erre a földre, kösd e veres fonalú zsinórt ahhoz az ablakhoz, a melyen alábocsátottál minket; atyádat, anyádat és atyádfiait pedig, és atyádnak egész háznépét gyűjtsd be magadhoz a házba.
19 Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án.
És akkor, ha akárki kijön a te házadnak ajtain, annak vére az ő fején lesz, mi pedig ártatlanok leszünk; mindannak vére pedig, a ki te veled lesz a házban, a mi fejünkön legyen, ha valakinek keze lenne azon.
20 Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò bọ́ nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú.”
Ha pedig megjelented ezt a mi dolgunkat, akkor mi fel leszünk oldva az eskü alól, a melylyel te megeskettél minket.
21 Ó dáhùn pé, “Ó dára bẹ́ẹ̀. Ẹ jẹ́ kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí sọ.” Ó sì rán wọn lọ wọ́n sì lọ. Ó sì so okùn òdòdó náà sí ojú fèrèsé.
Monda pedig amaz: A mint szólottatok, úgy legyen! Ekkor elbocsátá őket, és elmenének; a veres zsinórt pedig reáköté az ablakra.
22 Nígbà tí wọ́n kúrò, wọ́n sì lọ sí orí òkè wọ́n sì dúró ní ibẹ̀ ní ọjọ́ mẹ́ta, títí àwọn alépa fi wá wọn ní gbogbo ọ̀nà wọ́n sì padà láìrí wọn.
És elmenének és eljutának a hegyre, és ott maradának három nap, mígnem visszatérének az üldözők. Keresék ugyanis őket az üldözők minden úton, de nem találták vala.
23 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin méjì náà padà. Wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, wọ odò, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ọmọ Nuni wọ́n sì sọ fún un gbogbo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wọn.
Akkor a két férfiú visszatére, és leszállának a hegyről, és átmenének a Jordánon, és eljutának Józsuéhoz, a Nún fiához, és elbeszélének néki mindent, a mi történt vala velök.
24 Wọ́n sì sọ fún Joṣua, “Nítòótọ́ ni Olúwa tí fi gbogbo ilẹ̀ náà lé wa lọ́wọ́; gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà ni ìbẹ̀rùbojo ti mú nítorí i wa.”
És mondának Józsuénak: Bizony kezünkbe adta az Úr azt az egész földet; meg is olvadt már a földnek minden lakosa miattunk.