< Joshua 2 >

1 Nígbà náà ni Joṣua ọmọ Nuni rán àwọn ayọ́lẹ̀wò méjì jáde ní àṣírí láti Ṣittimu. Ó sì wí pé, “Ẹ lọ wo ilẹ̀ náà, pàápàá Jeriko.” Wọ́n sì lọ, wọ́n wọ ilé panṣágà kan, tí à ń pè ní Rahabu wọ́n sì dúró síbẹ̀.
Og Josva, Nuns Søn, sendte hemmelig to Mænd som Spejdere fra Sittim og sagde: Gaar hen, beser Landet og Jeriko; og de gik hen og kom ind i en Kvindes, en Skøges Hus, og hendes Navn var Rahab, og de laa der.
2 A sì sọ fún ọba Jeriko, “Wò ó! Àwọn ará Israẹli kan wá ibí ní alẹ́ yìí láti wá yọ́ ilẹ̀ yí wò.”
Da blev der sagt til Kongen af Jeriko saaledes: Se, i Nat er der komne Mænd hid af Israels Børn for at udforske Landet.
3 Ọba Jeriko sì ránṣẹ́ sí Rahabu pé, “Mú àwọn ọkùnrin nì tí ó tọ̀ ọ́ wá, tí ó wọ inú ilé rẹ jáde wá, nítorí wọ́n wá láti yọ́ gbogbo ilẹ̀ yìí wò ni.”
Da sendte Kongen af Jeriko Bud til Rahab og lod sige: Før de Mænd ud, som kom til dig, som kom til dit Hus; thi de ere komne til at udforske alt Landet.
4 Ṣùgbọ́n obìnrin náà ti mú àwọn ọkùnrin méjì náà o sì fi wọ́n pamọ́. Ó sì wí pé, “Lóòtítọ́ ní àwọn ọkùnrin náà wá sí ọ̀dọ̀ mi, ṣùgbọ́n èmi kò mọ ibi tí wọ́n ti wá.
Men Kvinden havde taget de to Mænd og skjult dem; og hun sagde saaledes: Mændene kom til mig, men jeg vidste ikke, hvorfra de vare.
5 Nígbà tí ilẹ̀ ṣú, nígbà tí ó tó àkókò láti ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè, àwọn ọkùnrin náà sì jáde lọ. Èmi kò sì mọ ọ̀nà tí wọ́n gbà lọ. Ẹ lépa wọn kíákíá. Ẹ̀yin yóò bá wọn.”
Og det skete, der de vilde lukke Porten, da det var mørkt, gik Mændene ud, jeg ved ikke, hvor de Mænd gik hen; forfølger dem snart, thi saa skulle I naa dem.
6 (Ṣùgbọ́n ó ti mú wọn gòkè àjà ó sì fi wọ́n pamọ́ sí abẹ́ pòròpòrò ọkà tó tò jọ sí orí àjà.)
Men hun havde ladet dem stige op paa Taget og skjult dem under Hørstilkene, som vare udbredte af hende paa Taget.
7 Àwọn ọkùnrin náà jáde lọ láti lépa àwọn ayọ́lẹ̀wò náà ní ọ̀nà tí ó lọ sí ìwọdò Jordani, bí àwọn tí ń lépa wọn sì ti jáde, wọ́n ti ìlẹ̀kùn ẹnu ibodè.
Og Mændene forfulgte dem paa Vejen til Jordanen indtil Færgestederne, og man lukkede Porten til, efter at de, som forfulgte dem, vare udgangne.
8 Kí àwọn ayọ́lẹ̀wò náà tó sùn ní alẹ́, ó gòkè tọ̀ wọ́n lọ lókè àjà.
Og førend de havde lagt sig, gik hun op til dem paa Taget,
9 Ó sì sọ fún wọn, “Èmi mọ̀ pé Olúwa ti fún un yín ní ilẹ̀ yìí àti pé ẹ̀rù u yín ti sọ wá di ojo dé ibi pé ìdí gbogbo àwọn tí ó n gbé ilẹ̀ yìí ti di omi nítorí i yín.
og hun sagde til Mændene: Jeg ved, at Herren har givet eder Landet, og at Forfærdelse for eder er falden paa os, og at Landets Indbyggere ere mistrøstige for eders Ansigt.
10 Àwa ti gbọ́ bí Olúwa ti mú omi Òkun Pupa gbẹ níwájú u yín nígbà tí ẹ̀yin jáde kúrò ní ilẹ̀ Ejibiti, àti ohun tí ẹ̀yin ṣe sí Sihoni àti Ogu, àwọn ọba méjèèjì ti Amori ti ìlà-oòrùn Jordani, tí ẹ̀yin parun pátápátá.
Thi vi have hørt, at Herren udtørrede Vandet i det røde Hav for eders Ansigt, der I gik ud af Ægypten, og hvad I gjorde ved Amoriternes to Konger, som vare paa hin Side Jordanen, Sihon og Og, hvilke I ødelagde.
11 Bí a ti gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ọkàn wa pami kò sì sí okun kankan fún wa mọ́ nítorí i yín, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run yín ni Ọlọ́run ní òkè ọ̀run àti ní ayé.
Og vi have hørt det, og vort Hjerte er mistrøstigt, og intet Mod bestaar ydermere i nogen for eders Ansigt; thi Herren eders Gud, han er en Gud i Himmelen oventil og paa Jorden nedentil.
12 Ǹjẹ́ nísinsin yìí, ẹ jọ̀wọ́ ẹ búra fún mi ní ti Olúwa pé ẹ̀yin yóò ṣe àánú fún ìdílé mi, nítorí pé mo ti ṣe yín ní oore. Ẹ̀yin yóò fún mi ní àmì tó dájú:
Og nu, kære, sværger mig ved Herren, efterdi jeg gjorde Miskundhed mod eder, at I og ville gøre Miskundhed imod min Faders Hus og give mig et sikkert Tegn,
13 pé ẹ̀yin yóò dá ẹ̀mí baba àti ìyá mi sí; arákùnrin mi àti arábìnrin mi, àti ohun gbogbo tí wọ́n ní, àti pé ẹ̀yin yóò gbà wá là lọ́wọ́ ikú.”
at I ville lade min Fader og min Moder og mine Brødre og mine Søstre leve, og alt det, de have, og fri vore Sjæle fra Døden.
14 “Ẹ̀mí wa fún ẹ̀mí in yín!” àwọn ọkùnrin náà mú dá a lójú. “Tí ìwọ kò bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò sì fi òtítọ́ àti àánú bá ọ lò nígbà tí Olúwa bá fún wa ní ilẹ̀ náà.”
Og Mændene sagde til hende: Vore Sjæle skulle være i Stedet for eders til at dø, naar I kun ikke kundgør denne vor Handel; og det skal ske, naar Herren giver os Landet, da ville vi vise Miskundhed og Troskab imod dig.
15 Nígbà náà ní ó fi okùn sọ̀ wọ́n kalẹ̀ ní ojú u fèrèsé, nítorí ilé tí ó ń gbé wà ní ara odi ìlú.
Saa lod hun dem ned ved et Reb igennem Vinduet; thi hendes Hus var ved Stadens Mur, og hun boede ved Muren.
16 Ó sì ti sọ fún wọn pé, “Ẹ lọ sí orí òkè, kí ẹ sì fi ara pamọ́ níbẹ̀ fún ọjọ́ mẹ́ta kí àwọn tí ń lépa yín má ba à rí i yín títí tí wọn yóò fi darí. Lẹ́yìn náà kí ẹ máa bá ọ̀nà yín lọ.”
Og hun sagde til dem: Gaar op paa Bjerget, at de, som forfølge eder, ikke skulle møde eder, og skjuler eder der i tre Dage, indtil de komme igen, som forfølge eder, og siden kunne I gaa eders Vej.
17 Àwọn arákùnrin náà sì sọ fún un pé, “Kí ọrùn un wa ba à lè mọ́ kúrò nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú yìí.
Og Mændene sagde til hende: Vi ville være løste fra denne din Ed, som du kom os til at sværge:
18 Nígbà tí àwa bá wọ ilé è rẹ, ìwọ yóò so okùn aláwọ̀ aró yìí sí ojú fèrèsé èyí tí ìwọ fi sọ̀ wá kalẹ̀, kí ìwọ kí ó mú baba rẹ, ìyá rẹ, àwọn arákùnrin in rẹ àti gbogbo ìdílé è rẹ kí wọ́n wá sí inú ilé è rẹ.
Se, naar vi komme ind i Landet, da skal du binde denne Skarlagens Snor i Vinduet, igennem hvilket du har ladet os ned, og du skal samle til dig i Huset din Fader og din Moder og dine Brødre og din Faders ganske Hus;
19 Bí ẹnikẹ́ni bá jáde sí ìta láti inú ilé è rẹ sí inú ìgboro ìlú, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò sì wà ní orí ara rẹ̀; ẹ̀bi rẹ̀ yóò sì wà lórí i rẹ̀. Fún ẹnikẹ́ni tí ó bá wà nínú ilé pẹ̀lú rẹ, ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ yóò wà ní orí i wa bí ẹnikẹ́ni bá fi ọwọ́ kàn án.
og det skal ske, hver den, som gaar ud af dit Huses Døre udenfor, hans Blod skal være paa hans Hoved, og vi skulle være uskyldige; men hver den, som er med dig i Huset, hans Blod skal være paa vort Hoved, dersom der bliver lagt Haand paa ham.
20 Ṣùgbọ́n bí ìwọ bá sọ ohun tí àwa ń ṣe, àwa yóò bọ́ nínú ìbúra tí ìwọ mú wa bú.”
Men dersom du kundgør denne vor Handel, da ville vi være løste fra den Ed, som du kom os til at sværge.
21 Ó dáhùn pé, “Ó dára bẹ́ẹ̀. Ẹ jẹ́ kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yin tí sọ.” Ó sì rán wọn lọ wọ́n sì lọ. Ó sì so okùn òdòdó náà sí ojú fèrèsé.
Og hun sagde: Det skal saa være efter eders Ord, og hun lod dem gaa, og de gik; og hun bandt den Skarlagens Snor i Vinduet.
22 Nígbà tí wọ́n kúrò, wọ́n sì lọ sí orí òkè wọ́n sì dúró ní ibẹ̀ ní ọjọ́ mẹ́ta, títí àwọn alépa fi wá wọn ní gbogbo ọ̀nà wọ́n sì padà láìrí wọn.
Saa gik de hen og kom paa Bjerget og bleve der tre Dage, indtil de, som forfulgte dem, vendte tilbage; men Forfølgerne ledte paa hele Vejen og fandt dem ikke.
23 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin méjì náà padà. Wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ láti orí òkè, wọ odò, wọ́n sì wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ọmọ Nuni wọ́n sì sọ fún un gbogbo ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀ sí wọn.
Saa vendte de to Mænd tilbage og gik ned ad Bjerget og for over og kom til Josva, Nuns Søn, og de fortalte ham alting, som havde rammet dem.
24 Wọ́n sì sọ fún Joṣua, “Nítòótọ́ ni Olúwa tí fi gbogbo ilẹ̀ náà lé wa lọ́wọ́; gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà ni ìbẹ̀rùbojo ti mú nítorí i wa.”
Og de sagde til Josva: Herren har givet alt Landet i vor Haand, ja ogsaa alle Landets Indbyggere ere mistrøstige for vort Ansigt.

< Joshua 2 >