< Joshua 19 >

1 Kèké kejì jáde fún ẹ̀yà Simeoni, ní agbo ilé, ní agbo ilé. Ìní wọn sì wà ní àárín ilẹ̀ Juda.
Potem padł drugi los dla Symeona, dla pokolenia synów Symeona według ich rodzin, a ich dziedzictwo znajdowało się pośród dziedzictwa synów Judy.
2 Lára ìpín wọn ní: Beerṣeba (tàbí Ṣeba), Molada,
A otrzymali oni w dziedzictwie: Beer-Szeba, Szeba, Molada;
3 Hasari-Ṣuali, Bala, Esemu,
Chasar-Szual, Bala, Esem;
4 Eltoladi, Betuli, Horma,
Eltolad, Betul, Chorma;
5 Siklagi, Beti-Markaboti, Hasari Susa,
Siklag, Bet-Markabot, Chasar-Susa;
6 Beti-Lebaoti àti Ṣarueli, ìlú wọn jẹ́ mẹ́tàlá àti ìletò wọn.
Bet-Lebaot i Szaruchen: trzynaście miast wraz z przyległymi do nich wioskami.
7 Aini, Rimoni, Eteri àti Aṣani, ìlú wọn jẹ́ mẹ́rin àti ìletò wọn,
Ain, Rimmon, Eter, Aszan: cztery miasta wraz z przyległymi do nich wioskami.
8 àti gbogbo àwọn agbègbè ìlú wọ̀nyí títí dé Baalati-Beeri (Rama ní gúúsù). Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Simeoni, agbo ilé, ní agbo ilé.
Oraz wszystkie wioski, które były dokoła tych miast, aż do Baalat-Beer, Ramat południowy. To było dziedzictwo pokolenia synów Symeona według ich rodzin.
9 A mú ogún ìní àwọn ọmọ Simeoni láti ìpín Juda, nítorí ìpín Juda pọ̀ ju èyí tí wọ́n nílò lọ. Báyìí ni àwọn ọmọ Simeoni gba ìní wọn ní àárín ilẹ̀ Juda.
Dziedzictwo synów Symeona zostało wzięte z działu synów Judy, ponieważ dział synów Judy był dla nich zbyt wielki. Synowie Symeona otrzymali więc dziedzictwo pośród ich dziedzictwa.
10 Kèké kẹta jáde fún Sebuluni, ní agbo ilé ní agbo ilé ààlà ìní wọn sì lọ títí dé Saridi.
Potem padł trzeci los dla synów Zebulona według ich rodzin, a granica ich dziedzictwa sięgała aż do Sarid.
11 Ó sì lọ sí ìwọ̀-oòrùn ní Marala, ó sì dé Dabbeṣeti, ó sì lọ títí dé odo ní ẹ̀bá Jokneamu.
A ich granica wznosiła się w kierunku morza do Marala, dochodziła do Dabbeszet i ciągnęła się aż do potoku, który jest naprzeciw Jokneam.
12 Ó sì yípadà sí ìlà-oòrùn láti Saridi sí ìhà ìlà-oòrùn dé ilẹ̀ Kisiloti-Tabori, ó sì lọ sí Daberati, ó sì gòkè lọ sí Jafia.
I zwracała się od Sarid na wschód do granicy Kislot-Tabor, a [stamtąd] biegła do Daberat i wznosiła się [do] Jafia;
13 Nígbà náà ní o lọ sí ìhà ìlà-oòrùn lọ sí Gati-Heferi àti Eti-Kaṣini, ó sì jáde ní Rimoni, ó sì yí sí ìhà Nea.
Stamtąd biegła na wschód do Gat-Chefer, do Et-Kasin, dochodziła do Rimmon i skręcała do Nea.
14 Ní ibẹ̀, ààlà sì yíká ní ìhà àríwá lọ sí Hnatoni ó sì pín ní àfonífojì Ifita-Eli.
Następnie granica otaczała od północy do Channaton i kończyła się w dolinie Jiftach-El.
15 Lára wọn ni Katati, Nahalali, Ṣimroni, Idala àti Bẹtilẹhẹmu. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
[Obejmowała] również Kattat, Nahalal, Szimron, Idala i Betlejem: dwanaście miast wraz z przyległymi do nich wioskami.
16 Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní Sebuluni, ní agbo ilé agbo ilé.
Oto dziedzictwo synów Zebulona według ich rodzin, te miasta i przyległe do nich wioski.
17 Kèké kẹrin jáde fún Isakari, agbo ilé ní agbo ilé.
Czwarty los przypadł Issacharowi, [czyli] synom Issachara według ich rodzin.
18 Lára ilẹ̀ wọn ni èyí: Jesreeli, Kesuloti, Ṣunemu,
A ich granica obejmowała: Jizreel, Kesulot, Szunem;
19 Hafraimu, Ṣihoni, Anaharati,
Chafaraim, Szijon, Anacharat;
20 Rabiti, Kiṣioni, Ebesi,
Rabbit, Kiszjon, Ebes;
21 Remeti, Eni-Gannimu, Eni-Hada àti Beti-Pasesi.
Remet, En-Gannim, En-Chadda i Bet-Passes.
22 Ààlà náà sì dé Tabori, Ṣahasuma, àti Beti-Ṣemeṣi, ó sì pin ní Jordani. Wọ́n sì jẹ́ ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
A [ich] granica dochodziła do Taboru, Szachasima i Bet-Szemesz, a kończyła się przy Jordanie: szesnaście miast i przyległe do nich wioski.
23 Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní ẹ̀yà Isakari, ní agbo ilé agbo ilé.
Oto dziedzictwo pokolenia synów Issachara według ich rodzin, te miasta oraz przyległe do nich wioski.
24 Kèké karùn-ún jáde fún ẹ̀yà Aṣeri, ní agbo ilé agbo ilé.
Potem padł piąty los dla pokolenia synów Aszera według ich rodzin.
25 Lára ilẹ̀ wọn ni èyí: Helikati, Hali, Beteni, Akṣafu,
I ich granica obejmowała: Chelkat, Chali, Beten, Akszaf;
26 Allameleki, Amadi, àti Miṣali. Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ààlà náà dé Karmeli àti Ṣihori-Libinati.
Alammelek, Amad i Miszal, a dochodziła do Karmelu na zachodzie i do Szichor-Libnat.
27 Nígbà náà ni o yí sí ìhà ìlà-oòrùn Beti-Dagoni, dé Sebuluni àti àfonífojì Ifita-Eli, ó sì lọ sí àríwá sí Beti-Emeki àti Neieli, ó sì kọjá lọ sí Kabulu ní apá òsì.
Stamtąd skręcała na wschód do Bet-Dagon i biegła aż do Zebulona i do doliny Jiftach-El na północ od Bet-Emek i Neiel i wychodziła do Kabulu po lewej stronie;
28 Ó sì lọ sí Abdoni, Rehobu, Hammoni àti Kana títí dé Sidoni ńlá.
I [do] Ebronu, Rechobu, Chammonu i Kany aż do Wielkiego Sydonu.
29 Ààlà náà sì tẹ̀ sí ìhà Rama, ó sì lọ sí ìlú olódi Tire, ó sì yà sí Hosa, ó sì jáde ní Òkun Ńlá ní ilẹ̀ Aksibu,
Potem granica skręcała do Rama aż do warownego miasta Tyr; stamtąd skręcała do Chosa i kończyła się przy morzu, od wybrzeża do Akzibu.
30 Uma, Afeki àti Rehobu. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlélógún àti ìletò wọn.
[Obejmowała] również Umma, Afek i Rechob: dwadzieścia dwa miasta oraz przyległe do nich wioski.
31 Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Aṣeri, ní agbo ilé agbo ilé.
Oto dziedzictwo pokolenia synów Aszera według ich rodzin, te miasta i przyległe do nich wioski.
32 Ìpín kẹfà jáde fún Naftali, agbo ilé ní agbo ilé,
[Potem] dla synów Neftalego padł szósty los, dla synów Neftalego według ich rodzin.
33 ààlà wọn lọ láti Helefi àti igi ńlá ní Saananimu nímù; kọjá lọ sí Adami Nekebu àti Jabneeli dé Lakkumu, ó sì pín ní Jordani.
Ich granica biegła od Chelef, od Helon do Saanannim, Adami, czyli Nekeb, oraz Jabneel aż do Lakum i kończyła się [przy] Jordanie.
34 Ààlà náà gba ìhà ìwọ̀-oòrùn lọ sí Asnoti-Tabori ó sì jáde ní Hukoki. Ó sì dé Sebuluni, ní ìhà gúúsù Aṣeri ní ìhà ìwọ̀-oòrùn àti Juda ní Jordani ní ìhà ìlà-oòrùn.
Następnie ta granica skręcała na zachód [do] Aznot-Tabor, a stamtąd biegła do Chukkok i ciągnęła się na południe do Zebulona, na zachodzie dochodziła do Aszera, a do Judy nad Jordanem na wschodzie.
35 Àwọn ìlú olódi sì Siddimu, Seri, Hamati, Rakàti, Kinnereti,
A miastami warownymi [są]: Siddim, Ser, Chammat, Rakkat, Kinneret;
36 Adama, Rama Hasori,
Adama, Rama, Chasor;
37 Kedeṣi, Edrei, Eni-Aṣọri,
Kedesz, Edrei, En-Chasor;
38 Ironi, Migdali-Eli, Horemu, Beti-Anati àti Beti-Ṣemeṣi. Wọ́n sì jẹ́ ìlú mọ́kàndínlógún àti ìletò wọn.
Jereon, Migdal-El, Chorem, Bet-Anat i Bet-Szemesz: dziewiętnaście miast oraz przyległe do nich wioski.
39 Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Naftali, ní agbo ilé sí agbo ilé.
Oto dziedzictwo pokolenia synów Neftalego według ich rodzin, te miasta oraz przyległe do nich wioski.
40 Ìbò kéje jáde fún ẹ̀yà Dani, ní agbo ilé ní agbo ilé.
[Potem] padł siódmy los dla pokolenia synów Dana według ich rodzin.
41 Ilẹ̀ ìní wọn nìwọ̀nyí: Sora, Eṣtaoli, Iri-Ṣemesi,
A granica ich dziedzictwa obejmowała: Sorea, Esztaol, Ir-Szemesz;
42 Ṣaalabini, Aijaloni, Itila,
Szaalabin, Ajjalon, Jitla;
43 Eloni, Timna, Ekroni,
Elon, Timna, Ekron;
44 Elteke, Gibetoni, Baalati,
Elteke, Gibbeton, Baalat;
45 Jehudu, Bene-Beraki, Gati-Rimoni,
Jehud, Bene-Berak, Gat-Rimmon;
46 Me Jakoni àti Rakkoni, pẹ̀lú ilẹ̀ tí ó kọjú sí Joppa.
Me-Jarkon i Rakkon z granicą naprzeciw Jafy.
47 (Ṣùgbọ́n àwọn ará Dani ní ìṣòro láti gba ilẹ̀ ìní wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gòkè lọ, wọ́n sì kọlu Leṣemu, wọ́n sì gbà á, wọ́n sì fi idà kọlù ú, wọ́n sì ń gbé ibẹ̀. Wọ́n sì ń gbé ní Leṣemu, wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Dani orúkọ baba ńlá wọn).
Lecz obszar synów Dana był zbyt mały. Synowie Dana wyruszyli więc do walki z Leszem, zdobyli je, pobili je ostrzem miecza, wzięli je w dziedzictwo i mieszkali w nim. I nazwali Leszem Dan, od imienia swego ojca.
48 Àwọn ìlú wọ́n yí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Dani, ní agbo ilé agbo ilé.
Oto dziedzictwo pokolenia synów Dana według ich rodzin, te miasta oraz przyległe do nich wioski.
49 Nígbà tí wọ́n ti parí pínpín ilẹ̀ náà ní ìpín ti olúkúlùkù, àwọn ará Israẹli fún Joṣua ọmọ Nuni ní ìní ní àárín wọn,
A gdy dokończyli dzielenie ziemi według jej granic, synowie Izraela dali spośród siebie dziedzictwo Jozuemu, synowi Nuna.
50 bí Olúwa ti pàṣẹ, wọ́n fún un ni ìlú tí ó béèrè fún, Timnati Serah ní ìlú òkè Efraimu. Ó sì kọ́ ìlú náà, ó sì ń gbé ibẹ̀.
Zgodnie z rozkazem PANA dali mu miasto, o które poprosił, Timnat-Serach na górze Efraim, gdzie zbudował miasto i mieszkał w nim.
51 Wọ̀nyí ni àwọn ilẹ̀ tí Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti àwọn olórí ẹ̀yà agbo ilé Israẹli fi ìbò pín ní Ṣilo ní iwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Báyìí ni wọ́n parí pínpín ilẹ̀ náà.
Oto dziedzictwa, które losem podzielili w posiadanie kapłan Eleazar, Jozue, syn Nuna, i naczelnicy ojców pokoleń synów Izraela w Szilo przed PANEM, u wejścia do Namiotu Zgromadzenia, i dokończyli podział ziemi.

< Joshua 19 >