< Joshua 19 >

1 Kèké kejì jáde fún ẹ̀yà Simeoni, ní agbo ilé, ní agbo ilé. Ìní wọn sì wà ní àárín ilẹ̀ Juda.
Et egressa est sors secunda filiorum Simeon per cognationes suas: fuitque hereditas
2 Lára ìpín wọn ní: Beerṣeba (tàbí Ṣeba), Molada,
eorum in medio possessionis filiorum Iuda: Bersabee et Sabee et Molada
3 Hasari-Ṣuali, Bala, Esemu,
et Hasersual, Bala et Asem
4 Eltoladi, Betuli, Horma,
et Eltholad, Bethul et Harma
5 Siklagi, Beti-Markaboti, Hasari Susa,
et Siceleg et Bethmarchaboth et Hasersusa
6 Beti-Lebaoti àti Ṣarueli, ìlú wọn jẹ́ mẹ́tàlá àti ìletò wọn.
et Bethlebaoth et Sarohen: civitates tredecim, et villae earum.
7 Aini, Rimoni, Eteri àti Aṣani, ìlú wọn jẹ́ mẹ́rin àti ìletò wọn,
Ain et Remmon et Athar et Asan: civitates quattuor, et villae earum:
8 àti gbogbo àwọn agbègbè ìlú wọ̀nyí títí dé Baalati-Beeri (Rama ní gúúsù). Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Simeoni, agbo ilé, ní agbo ilé.
omnes viculi per circuitum urbium istarum usque ad Baalath Beer Ramath contra australem plagam. Haec est hereditas filiorum Simeon iuxta cognationes suas,
9 A mú ogún ìní àwọn ọmọ Simeoni láti ìpín Juda, nítorí ìpín Juda pọ̀ ju èyí tí wọ́n nílò lọ. Báyìí ni àwọn ọmọ Simeoni gba ìní wọn ní àárín ilẹ̀ Juda.
in possessione et funiculo filiorum Iuda: quia maior erat. et idcirco filii Simeon possederunt in medio hereditatis eorum.
10 Kèké kẹta jáde fún Sebuluni, ní agbo ilé ní agbo ilé ààlà ìní wọn sì lọ títí dé Saridi.
Ceciditque sors tertia filiorum Zabulon per cognationes suas: factus est terminus possessionis eorum usque Sarid.
11 Ó sì lọ sí ìwọ̀-oòrùn ní Marala, ó sì dé Dabbeṣeti, ó sì lọ títí dé odo ní ẹ̀bá Jokneamu.
Ascenditque de Mari et Medalaa, et pervenit in Debbaseth, usque ad torrentem qui est contra Ieconam.
12 Ó sì yípadà sí ìlà-oòrùn láti Saridi sí ìhà ìlà-oòrùn dé ilẹ̀ Kisiloti-Tabori, ó sì lọ sí Daberati, ó sì gòkè lọ sí Jafia.
Et revertitur de Sared contra Orientem in fines Ceseleththabor: et egreditur ad Dabereth, ascenditque contra Iaphie.
13 Nígbà náà ní o lọ sí ìhà ìlà-oòrùn lọ sí Gati-Heferi àti Eti-Kaṣini, ó sì jáde ní Rimoni, ó sì yí sí ìhà Nea.
Et inde pertransit usque ad orientalem plagam Gethhepher et Thacasin: et egreditur in Remmon, Amthar et Noa.
14 Ní ibẹ̀, ààlà sì yíká ní ìhà àríwá lọ sí Hnatoni ó sì pín ní àfonífojì Ifita-Eli.
Et circuit ad Aquilonem Hanathon: suntque egressus eius Vallis Iephthael,
15 Lára wọn ni Katati, Nahalali, Ṣimroni, Idala àti Bẹtilẹhẹmu. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
et Cateth et Naalol et Semeron et Iedala et Bethlehem: civitates duodecim, et villae earum.
16 Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní Sebuluni, ní agbo ilé agbo ilé.
Haec est hereditas tribus filiorum Zabulon per cognationes suas, urbes et viculi earum.
17 Kèké kẹrin jáde fún Isakari, agbo ilé ní agbo ilé.
Issachar egressa est sors quarta per cognationes suas.
18 Lára ilẹ̀ wọn ni èyí: Jesreeli, Kesuloti, Ṣunemu,
fuitque eius hereditas Iezrael et Casaloth et Sunem
19 Hafraimu, Ṣihoni, Anaharati,
et Hapharaim et Seon, et Anaharath
20 Rabiti, Kiṣioni, Ebesi,
et Rabboth et Cesion, Abes,
21 Remeti, Eni-Gannimu, Eni-Hada àti Beti-Pasesi.
et Rameth, et Engannim, et Enhadda et Bethpheses.
22 Ààlà náà sì dé Tabori, Ṣahasuma, àti Beti-Ṣemeṣi, ó sì pin ní Jordani. Wọ́n sì jẹ́ ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
Et pervenit terminus eius usque Thabor et Sehesima et Bethsames: eruntque exitus eius Iordanis: civitates sedecim, et villae earum.
23 Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní ẹ̀yà Isakari, ní agbo ilé agbo ilé.
Haec est possessio filiorum Issachar per cognationes suas, urbes, et viculi earum.
24 Kèké karùn-ún jáde fún ẹ̀yà Aṣeri, ní agbo ilé agbo ilé.
Ceciditque sors quinta tribui filiorum Aser per cognationes suas:
25 Lára ilẹ̀ wọn ni èyí: Helikati, Hali, Beteni, Akṣafu,
fuitque terminus eorum Halcath et Chali et Beten et Axaph
26 Allameleki, Amadi, àti Miṣali. Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ààlà náà dé Karmeli àti Ṣihori-Libinati.
et Elmelech et Amaad et Messal: et pervenit usque ad Carmelum maris et Sihor et Labanath.
27 Nígbà náà ni o yí sí ìhà ìlà-oòrùn Beti-Dagoni, dé Sebuluni àti àfonífojì Ifita-Eli, ó sì lọ sí àríwá sí Beti-Emeki àti Neieli, ó sì kọjá lọ sí Kabulu ní apá òsì.
Ac revertitur contra orientem Bethdagon: et pertransit usque Zabulon et Vallem Iephthael contra Aquilonem in Bethemec et Nehiel. Egrediturque ad laevam Cabul,
28 Ó sì lọ sí Abdoni, Rehobu, Hammoni àti Kana títí dé Sidoni ńlá.
et Abran et Rohob et Hamon et Cana, usque ad Sidonem magnam.
29 Ààlà náà sì tẹ̀ sí ìhà Rama, ó sì lọ sí ìlú olódi Tire, ó sì yà sí Hosa, ó sì jáde ní Òkun Ńlá ní ilẹ̀ Aksibu,
revertiturque in Horma usque ad civitatem munitissimam Tyrum, et usque Hosa: eruntque exitus eius in mare de funiculo Achziba:
30 Uma, Afeki àti Rehobu. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlélógún àti ìletò wọn.
et Amma et Aphec et Rohob. civitates viginti duae, et villae earum.
31 Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Aṣeri, ní agbo ilé agbo ilé.
Haec est possessio filiorum Aser per cognationes suas, urbesque et viculi earum.
32 Ìpín kẹfà jáde fún Naftali, agbo ilé ní agbo ilé,
Filiorum Nephthali sexta sors cecidit per familias suas:
33 ààlà wọn lọ láti Helefi àti igi ńlá ní Saananimu nímù; kọjá lọ sí Adami Nekebu àti Jabneeli dé Lakkumu, ó sì pín ní Jordani.
et coepit terminus de Heleph et Elon in Saananim, et Adami, quae est Neceb, et Iebnael usque Lecum: et egressus eorum usque ad Iordanem:
34 Ààlà náà gba ìhà ìwọ̀-oòrùn lọ sí Asnoti-Tabori ó sì jáde ní Hukoki. Ó sì dé Sebuluni, ní ìhà gúúsù Aṣeri ní ìhà ìwọ̀-oòrùn àti Juda ní Jordani ní ìhà ìlà-oòrùn.
revertiturque terminus contra Occidentem in Azanotthabor, atque inde egreditur in Hucuca, et pertransit in Zabulon contra Meridiem, et in Aser contra Occidentem, et in Iuda ad Iordanem contra ortum solis.
35 Àwọn ìlú olódi sì Siddimu, Seri, Hamati, Rakàti, Kinnereti,
civitates munitissimae, Assedim, Ser, et Emath, et Reccath et Cenereth,
36 Adama, Rama Hasori,
et Edema et Arama, Asor
37 Kedeṣi, Edrei, Eni-Aṣọri,
et Cedes et Edrai, Enhasor
38 Ironi, Migdali-Eli, Horemu, Beti-Anati àti Beti-Ṣemeṣi. Wọ́n sì jẹ́ ìlú mọ́kàndínlógún àti ìletò wọn.
et Ieron et Magdalel, Horem et Bethanath et Bethsames: civitates decem et novem, et villae earum.
39 Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Naftali, ní agbo ilé sí agbo ilé.
Haec est possessio tribus filiorum Nephthali per cognationes suas, urbes et viculi earum.
40 Ìbò kéje jáde fún ẹ̀yà Dani, ní agbo ilé ní agbo ilé.
Tribui filiorum Dan per familias suas egressa est sors septima:
41 Ilẹ̀ ìní wọn nìwọ̀nyí: Sora, Eṣtaoli, Iri-Ṣemesi,
et fuit terminus possessionis eius Sara et Esthaol, et Hirsemes, id est civitas solis.
42 Ṣaalabini, Aijaloni, Itila,
Selebin et Aialon et Iethela,
43 Eloni, Timna, Ekroni,
Elon et Themna et Acron,
44 Elteke, Gibetoni, Baalati,
Elthece, Gebbethon et Balaath,
45 Jehudu, Bene-Beraki, Gati-Rimoni,
et Iud et Bane et Barach et Gethremmon:
46 Me Jakoni àti Rakkoni, pẹ̀lú ilẹ̀ tí ó kọjú sí Joppa.
et Meiarcon et Arecon, cum termino qui respicit Ioppen,
47 (Ṣùgbọ́n àwọn ará Dani ní ìṣòro láti gba ilẹ̀ ìní wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gòkè lọ, wọ́n sì kọlu Leṣemu, wọ́n sì gbà á, wọ́n sì fi idà kọlù ú, wọ́n sì ń gbé ibẹ̀. Wọ́n sì ń gbé ní Leṣemu, wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Dani orúkọ baba ńlá wọn).
et ipso fine concluditur. Ascenderuntque filii Dan, et pugnaverunt contra Lesem, ceperuntque eam: et percusserunt eam in ore gladii, et possederunt, et habitaverunt in ea, vocantes nomen eius Lesem Dan, ex nomine Dan patris sui.
48 Àwọn ìlú wọ́n yí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Dani, ní agbo ilé agbo ilé.
Haec est possessio tribus filiorum Dan, per cognationes suas, urbes et viculi earum.
49 Nígbà tí wọ́n ti parí pínpín ilẹ̀ náà ní ìpín ti olúkúlùkù, àwọn ará Israẹli fún Joṣua ọmọ Nuni ní ìní ní àárín wọn,
Cumque complesset sorte dividere Terram singulis per tribus suas, dederunt filii Israel possessionem Iosue filio Nun in medio sui,
50 bí Olúwa ti pàṣẹ, wọ́n fún un ni ìlú tí ó béèrè fún, Timnati Serah ní ìlú òkè Efraimu. Ó sì kọ́ ìlú náà, ó sì ń gbé ibẹ̀.
iuxta praeceptum Domini, urbem quam postulavit, Thamnath Saraa in monte Ephraim: et aedificavit civitatem, habitavitque in ea.
51 Wọ̀nyí ni àwọn ilẹ̀ tí Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti àwọn olórí ẹ̀yà agbo ilé Israẹli fi ìbò pín ní Ṣilo ní iwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Báyìí ni wọ́n parí pínpín ilẹ̀ náà.
Hae sunt possessiones, quas sorte diviserunt Eleazar sacerdos, et Iosue filius Nun, et principes familiarum, ac tribuum filiorum Israel in Silo, coram Domino ad ostium tabernaculi testimonii, partitique sunt Terram.

< Joshua 19 >