< Joshua 19 >
1 Kèké kejì jáde fún ẹ̀yà Simeoni, ní agbo ilé, ní agbo ilé. Ìní wọn sì wà ní àárín ilẹ̀ Juda.
And the second lot came forth to Simeon, [even] for the tribe of the children of Simeon according to their families: and their inheritance was within the inheritance of the children of Judah.
2 Lára ìpín wọn ní: Beerṣeba (tàbí Ṣeba), Molada,
And they had in their inheritance, Beer-sheba, and Sheba, and Moladah.
3 Hasari-Ṣuali, Bala, Esemu,
And Hazar-shual, and Balah, and Azem,
4 Eltoladi, Betuli, Horma,
And Eltolad, and Bethul, and Hormah,
5 Siklagi, Beti-Markaboti, Hasari Susa,
And Ziklag, and Beth-marcaboth, and Hazar-susah,
6 Beti-Lebaoti àti Ṣarueli, ìlú wọn jẹ́ mẹ́tàlá àti ìletò wọn.
And Beth-lebaoth, and Sheruhen; thirteen cities and their villages:
7 Aini, Rimoni, Eteri àti Aṣani, ìlú wọn jẹ́ mẹ́rin àti ìletò wọn,
Ain, Remmon, and Ether, and Ashan; four cities and their villages:
8 àti gbogbo àwọn agbègbè ìlú wọ̀nyí títí dé Baalati-Beeri (Rama ní gúúsù). Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Simeoni, agbo ilé, ní agbo ilé.
And all the villages that [were] around these cities to Baalath-beer, Ramath of the south. This [is] the inheritance of the tribe of the children of Simeon according to their families.
9 A mú ogún ìní àwọn ọmọ Simeoni láti ìpín Juda, nítorí ìpín Juda pọ̀ ju èyí tí wọ́n nílò lọ. Báyìí ni àwọn ọmọ Simeoni gba ìní wọn ní àárín ilẹ̀ Juda.
Out of the portion of the children of Judah [was] the inheritance of the children of Simeon: for the part of the children of Judah was too much for them: therefore the children of Simeon had their inheritance within the inheritance of them.
10 Kèké kẹta jáde fún Sebuluni, ní agbo ilé ní agbo ilé ààlà ìní wọn sì lọ títí dé Saridi.
And the third lot came up for the children of Zebulun according to their families: and the border of their inheritance was to Sarid:
11 Ó sì lọ sí ìwọ̀-oòrùn ní Marala, ó sì dé Dabbeṣeti, ó sì lọ títí dé odo ní ẹ̀bá Jokneamu.
And their border went up towards the sea, and Maralah, and reached to Dabbasheth, and reached to the river that [is] before Jokneam,
12 Ó sì yípadà sí ìlà-oòrùn láti Saridi sí ìhà ìlà-oòrùn dé ilẹ̀ Kisiloti-Tabori, ó sì lọ sí Daberati, ó sì gòkè lọ sí Jafia.
And turned from Sarid eastward, towards the sun-rising, to the border of Chisloth-tabor, and then goeth out to Daberath, and goeth up to Japhia,
13 Nígbà náà ní o lọ sí ìhà ìlà-oòrùn lọ sí Gati-Heferi àti Eti-Kaṣini, ó sì jáde ní Rimoni, ó sì yí sí ìhà Nea.
And from thence passeth along on the east to Gittah-hepher, to Ittah-kazin, and goeth out to Remmon-methoar to Neah;
14 Ní ibẹ̀, ààlà sì yíká ní ìhà àríwá lọ sí Hnatoni ó sì pín ní àfonífojì Ifita-Eli.
And the border compasseth it on the north side to Hannathon: and the limits of it are in the valley of Jiphthah-el:
15 Lára wọn ni Katati, Nahalali, Ṣimroni, Idala àti Bẹtilẹhẹmu. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
And Kattath, and Nahallal, and Shimron, and Idalah, and Beth-lehem; twelve cities with their villages.
16 Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní Sebuluni, ní agbo ilé agbo ilé.
This [is] the inheritance of the children of Zebulun according to their families, these cities with their villages.
17 Kèké kẹrin jáde fún Isakari, agbo ilé ní agbo ilé.
[And] the fourth lot came out to Issachar, for the children of Issachar according to their families.
18 Lára ilẹ̀ wọn ni èyí: Jesreeli, Kesuloti, Ṣunemu,
And their border was towards Jezreel, and Chesulloth, and Shunem,
19 Hafraimu, Ṣihoni, Anaharati,
And Hapharaim, and Shihon, and Anaharath,
20 Rabiti, Kiṣioni, Ebesi,
And Rabbith, and Kishion, and Abez,
21 Remeti, Eni-Gannimu, Eni-Hada àti Beti-Pasesi.
And Remeth, and En-gannim, and En-haddah, and Beth-pazzez;
22 Ààlà náà sì dé Tabori, Ṣahasuma, àti Beti-Ṣemeṣi, ó sì pin ní Jordani. Wọ́n sì jẹ́ ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
And the border reacheth to Tabor, and Shahazimah, and Beth-shemesh, and the limits of their border were at Jordan: sixteen cities with their villages.
23 Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní ẹ̀yà Isakari, ní agbo ilé agbo ilé.
This [is] the inheritance of the tribe of the children of Issachar according to their families, the cities and their villages.
24 Kèké karùn-ún jáde fún ẹ̀yà Aṣeri, ní agbo ilé agbo ilé.
And the fifth lot came out for the tribe of the children of Asher according to their families.
25 Lára ilẹ̀ wọn ni èyí: Helikati, Hali, Beteni, Akṣafu,
And their border was Helkath, and Hali, and Beten, and Achshaph,
26 Allameleki, Amadi, àti Miṣali. Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ààlà náà dé Karmeli àti Ṣihori-Libinati.
And Alammelech, and Amad, and Misheal; and reacheth to Carmel westward, and to Shihor-libnath;
27 Nígbà náà ni o yí sí ìhà ìlà-oòrùn Beti-Dagoni, dé Sebuluni àti àfonífojì Ifita-Eli, ó sì lọ sí àríwá sí Beti-Emeki àti Neieli, ó sì kọjá lọ sí Kabulu ní apá òsì.
And turneth towards the sun-rising to Beth-dagon, and reacheth to Zebulun, and to the valley of Jiphthah-el towards the north side of Beth-emek, and Neiel, and goeth out to Cabul on the left hand,
28 Ó sì lọ sí Abdoni, Rehobu, Hammoni àti Kana títí dé Sidoni ńlá.
And Hebron, and Rehob, and Hammon, and Kanah, [even] to great Zidon;
29 Ààlà náà sì tẹ̀ sí ìhà Rama, ó sì lọ sí ìlú olódi Tire, ó sì yà sí Hosa, ó sì jáde ní Òkun Ńlá ní ilẹ̀ Aksibu,
And [then] the border turneth to Ramah, and to the strong city Tyre; and the border turneth to Hosah: and the limits of it are at the sea from the coast to Achzib:
30 Uma, Afeki àti Rehobu. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlélógún àti ìletò wọn.
Ummah also, and Aphek, and Rehob: twenty and two cities with their villages.
31 Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Aṣeri, ní agbo ilé agbo ilé.
This [is] the inheritance of the tribe of the children of Asher according to their families, these cities with their villages.
32 Ìpín kẹfà jáde fún Naftali, agbo ilé ní agbo ilé,
The sixth lot came out to the children of Naphtali, [even] for the children of Naphtali according to their families.
33 ààlà wọn lọ láti Helefi àti igi ńlá ní Saananimu nímù; kọjá lọ sí Adami Nekebu àti Jabneeli dé Lakkumu, ó sì pín ní Jordani.
And their border was from Heleph, from Allon to Zaanannim, and Adami, Nekeb, and Jabneel, to Lakum; and the limits thereof were at Jordan:
34 Ààlà náà gba ìhà ìwọ̀-oòrùn lọ sí Asnoti-Tabori ó sì jáde ní Hukoki. Ó sì dé Sebuluni, ní ìhà gúúsù Aṣeri ní ìhà ìwọ̀-oòrùn àti Juda ní Jordani ní ìhà ìlà-oòrùn.
And [then] the border turneth westward to Aznoth-tabor, and goeth out from thence to Hukkok, and reacheth to Zebulun on the south side, and reacheth to Asher on the west side, and to Judah upon Jordan towards the sun-rising.
35 Àwọn ìlú olódi sì Siddimu, Seri, Hamati, Rakàti, Kinnereti,
And the fortified cities [are] Ziddim, Zer, and Hammath, Rakkath, and Chinnereth,
And Adamah, and Ramah, and Hazor,
37 Kedeṣi, Edrei, Eni-Aṣọri,
And Kedesh, and Edrei, and En-hazor,
38 Ironi, Migdali-Eli, Horemu, Beti-Anati àti Beti-Ṣemeṣi. Wọ́n sì jẹ́ ìlú mọ́kàndínlógún àti ìletò wọn.
And Iron, and Migdal-el, Horem, and Beth-anath, and Beth-shemesh; nineteen cities with their villages.
39 Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Naftali, ní agbo ilé sí agbo ilé.
This [is] the inheritance of the tribe of the children of Naphtali according to their families, the cities and their villages.
40 Ìbò kéje jáde fún ẹ̀yà Dani, ní agbo ilé ní agbo ilé.
[And] the seventh lot came out for the tribe of the children of Dan according to their families.
41 Ilẹ̀ ìní wọn nìwọ̀nyí: Sora, Eṣtaoli, Iri-Ṣemesi,
And the border of their inheritance was Zorah, and Eshtaol, and Ir-shemesh,
42 Ṣaalabini, Aijaloni, Itila,
And Shaalabbim, and Ajalon, and Jethlah,
And Elon, and Thimnathah, and Ekron,
44 Elteke, Gibetoni, Baalati,
And Eltekeh, and Gibbethon, and Baalath,
45 Jehudu, Bene-Beraki, Gati-Rimoni,
And Jehud, and Bene-berak, and Gath-rimmon,
46 Me Jakoni àti Rakkoni, pẹ̀lú ilẹ̀ tí ó kọjú sí Joppa.
And Me-jarkon, and Rakkon, with the border before Japho.
47 (Ṣùgbọ́n àwọn ará Dani ní ìṣòro láti gba ilẹ̀ ìní wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gòkè lọ, wọ́n sì kọlu Leṣemu, wọ́n sì gbà á, wọ́n sì fi idà kọlù ú, wọ́n sì ń gbé ibẹ̀. Wọ́n sì ń gbé ní Leṣemu, wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Dani orúkọ baba ńlá wọn).
And the border of the children of Dan, went out [too little] for them: therefore the children of Dan went up to fight against Leshem, and took it, and smote it with the edge of the sword, and possessed it, and dwelt in it, and called Leshem, Dan, after the name of Dan their father.
48 Àwọn ìlú wọ́n yí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Dani, ní agbo ilé agbo ilé.
This [is] the inheritance of the tribe of the children of Dan according to their families, these cities with their villages.
49 Nígbà tí wọ́n ti parí pínpín ilẹ̀ náà ní ìpín ti olúkúlùkù, àwọn ará Israẹli fún Joṣua ọmọ Nuni ní ìní ní àárín wọn,
When they had made an end of dividing the land for inheritance by their borders, the children of Israel gave an inheritance to Joshua the son of Nun among them:
50 bí Olúwa ti pàṣẹ, wọ́n fún un ni ìlú tí ó béèrè fún, Timnati Serah ní ìlú òkè Efraimu. Ó sì kọ́ ìlú náà, ó sì ń gbé ibẹ̀.
According to the word of the LORD they gave him the city which he asked, [even] Timnath-serah in mount Ephraim: and he built the city, and dwelt in it.
51 Wọ̀nyí ni àwọn ilẹ̀ tí Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti àwọn olórí ẹ̀yà agbo ilé Israẹli fi ìbò pín ní Ṣilo ní iwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Báyìí ni wọ́n parí pínpín ilẹ̀ náà.
These [are] the inheritances which Eleazar the priest, and Joshua the son of Nun, and the heads of the fathers of the tribes of the children of Israel, divided for an inheritance by lot in Shiloh before the LORD, at the door of the tabernacle of the congregation. So they made an end of dividing the country.