< Joshua 19 >

1 Kèké kejì jáde fún ẹ̀yà Simeoni, ní agbo ilé, ní agbo ilé. Ìní wọn sì wà ní àárín ilẹ̀ Juda.
And the second lot came out to Simeon, euen for the tribe of the children of Simeon according to their families: and their inheritance was in the middes of the inheritance of the children of Iudah.
2 Lára ìpín wọn ní: Beerṣeba (tàbí Ṣeba), Molada,
Nowe they had in their inheritance, Beersheba, and Sheba, and Moladah,
3 Hasari-Ṣuali, Bala, Esemu,
And Hazur-shual, and Balah, and Azem,
4 Eltoladi, Betuli, Horma,
And Eltolad, and Bethul, and Hormah,
5 Siklagi, Beti-Markaboti, Hasari Susa,
And Ziklag, and Beth-marcaboth, and Hazar-susah,
6 Beti-Lebaoti àti Ṣarueli, ìlú wọn jẹ́ mẹ́tàlá àti ìletò wọn.
And Beth-lebaoth, and Sharuhen: thirteene cities with their villages.
7 Aini, Rimoni, Eteri àti Aṣani, ìlú wọn jẹ́ mẹ́rin àti ìletò wọn,
Ain, Remmon, and Ether, and Ashan: foure cities with their villages.
8 àti gbogbo àwọn agbègbè ìlú wọ̀nyí títí dé Baalati-Beeri (Rama ní gúúsù). Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Simeoni, agbo ilé, ní agbo ilé.
And all the villages that were round about these cities, vnto Baalathbeer, and Ramath Southward: this is the inheritance of the tribe of the children of Simeon according to their families.
9 A mú ogún ìní àwọn ọmọ Simeoni láti ìpín Juda, nítorí ìpín Juda pọ̀ ju èyí tí wọ́n nílò lọ. Báyìí ni àwọn ọmọ Simeoni gba ìní wọn ní àárín ilẹ̀ Juda.
Out of the portion of the children of Iudah came ye inheritance of the childre of Simeon: for the part of ye children of Iudah was too much for them: therefore the children of Simeon had their inheritance within their inheritance.
10 Kèké kẹta jáde fún Sebuluni, ní agbo ilé ní agbo ilé ààlà ìní wọn sì lọ títí dé Saridi.
Also the third lot arose for the children of Zebulun according to their families: and the coastes of their inheritance came to Sarid,
11 Ó sì lọ sí ìwọ̀-oòrùn ní Marala, ó sì dé Dabbeṣeti, ó sì lọ títí dé odo ní ẹ̀bá Jokneamu.
And their border goeth vp Westwarde, euen to Maralah, and reacheth to Dabbasheth, and meeteth with the riuer that lyeth before Iokneam,
12 Ó sì yípadà sí ìlà-oòrùn láti Saridi sí ìhà ìlà-oòrùn dé ilẹ̀ Kisiloti-Tabori, ó sì lọ sí Daberati, ó sì gòkè lọ sí Jafia.
And turneth from Sarid Eastward towarde the sunne rising vnto the border of Chisloth-tabor, and goeth out to Daberath, and ascendeth to Iaphia,
13 Nígbà náà ní o lọ sí ìhà ìlà-oòrùn lọ sí Gati-Heferi àti Eti-Kaṣini, ó sì jáde ní Rimoni, ó sì yí sí ìhà Nea.
And from thence goeth along Eastwarde towarde the sunne rising to Gittah-hepher to Ittah-kazin, and goeth foorth to Rimmon, and turneth to Neah.
14 Ní ibẹ̀, ààlà sì yíká ní ìhà àríwá lọ sí Hnatoni ó sì pín ní àfonífojì Ifita-Eli.
And this border compasseth it on ye North side to Hannathon, and the endes thereof are in the valley of Iiphtah-el,
15 Lára wọn ni Katati, Nahalali, Ṣimroni, Idala àti Bẹtilẹhẹmu. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
And Kattath, and Nahallal, and Shimron, and Idalah, and Beth-lehem: twelue cities with their villages.
16 Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní Sebuluni, ní agbo ilé agbo ilé.
This is the inheritance of the children of Zebulun according to their families: that is, these cities and their villages.
17 Kèké kẹrin jáde fún Isakari, agbo ilé ní agbo ilé.
The fourth lot came out to Issachar, euen for the children of Issachar according to their families.
18 Lára ilẹ̀ wọn ni èyí: Jesreeli, Kesuloti, Ṣunemu,
And their coast was Izreelah, and Chesulloth, and Shunem,
19 Hafraimu, Ṣihoni, Anaharati,
And Hapharaim, and Shion, and Anaharath,
20 Rabiti, Kiṣioni, Ebesi,
And Harabbith, and Kishion, and Abez,
21 Remeti, Eni-Gannimu, Eni-Hada àti Beti-Pasesi.
And Remeth, and En-gannim, and Enhaddah, and Beth-pazzez.
22 Ààlà náà sì dé Tabori, Ṣahasuma, àti Beti-Ṣemeṣi, ó sì pin ní Jordani. Wọ́n sì jẹ́ ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
And this coast reacheth to Tabor, and Shahazimath, and Beth-shemesh, and the endes of their coast reach to Iorden: sixteene cities with their villages.
23 Ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn jẹ́ ìní ẹ̀yà Isakari, ní agbo ilé agbo ilé.
This is the inheritance of the tribe of the children of Issachar according to their families: that is, the cities, and their villages.
24 Kèké karùn-ún jáde fún ẹ̀yà Aṣeri, ní agbo ilé agbo ilé.
Also the fift lot came out for the tribe of the children of Asher according to their families.
25 Lára ilẹ̀ wọn ni èyí: Helikati, Hali, Beteni, Akṣafu,
And their coast was Helcath, and Hali, and Beten, and Achshaph,
26 Allameleki, Amadi, àti Miṣali. Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ààlà náà dé Karmeli àti Ṣihori-Libinati.
And Alammelech, and Amad, and Misheal, and came to Carmel Westward, and to Shihor Libnath,
27 Nígbà náà ni o yí sí ìhà ìlà-oòrùn Beti-Dagoni, dé Sebuluni àti àfonífojì Ifita-Eli, ó sì lọ sí àríwá sí Beti-Emeki àti Neieli, ó sì kọjá lọ sí Kabulu ní apá òsì.
And turneth towarde the sunne rising to Beth-dagon, and commeth to Zebulun, and to the valley of Iiphtah-el, toward the Northside of Beth-emek, and Neiel, and goeth out on the left side of Cabul,
28 Ó sì lọ sí Abdoni, Rehobu, Hammoni àti Kana títí dé Sidoni ńlá.
And to Ebron, and Rehob, and Hammon, and Kanah, vnto great Zidon.
29 Ààlà náà sì tẹ̀ sí ìhà Rama, ó sì lọ sí ìlú olódi Tire, ó sì yà sí Hosa, ó sì jáde ní Òkun Ńlá ní ilẹ̀ Aksibu,
Then the coast turneth to Ramah and to the strong citie of Zor, and this border turneth to Hosah, and the ends thereof are at the Sea from Hebel to Achzib,
30 Uma, Afeki àti Rehobu. Wọ́n sì jẹ́ ìlú méjìlélógún àti ìletò wọn.
Vmmah also and Aphek, and Rehob: two and twentie cities with their villages.
31 Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Aṣeri, ní agbo ilé agbo ilé.
This is the inheritance of the tribe of the children of Asher according to their families: that is, these cities and their villages.
32 Ìpín kẹfà jáde fún Naftali, agbo ilé ní agbo ilé,
The sixt lot came out to the children of Naphtali, euen to the children of Naphtali according to their families.
33 ààlà wọn lọ láti Helefi àti igi ńlá ní Saananimu nímù; kọjá lọ sí Adami Nekebu àti Jabneeli dé Lakkumu, ó sì pín ní Jordani.
And their coast was from Heleph, and from Allon in Zaanannim, and Adaminekeb, and Iabneel, euen to Lakum, and the ends thereof are at Iorden.
34 Ààlà náà gba ìhà ìwọ̀-oòrùn lọ sí Asnoti-Tabori ó sì jáde ní Hukoki. Ó sì dé Sebuluni, ní ìhà gúúsù Aṣeri ní ìhà ìwọ̀-oòrùn àti Juda ní Jordani ní ìhà ìlà-oòrùn.
So this coast turneth Westwarde to Aznoth-tabor, and goeth out from thence to Hukkok, and reacheth to Zebulun on the Southside, and goeth to Asher on the Westside, and to Iudah by Iorden toward the sunne rising.
35 Àwọn ìlú olódi sì Siddimu, Seri, Hamati, Rakàti, Kinnereti,
And the strong cities are Ziddim, Zer, and Hammath, Rakkath, and Cinneereth,
36 Adama, Rama Hasori,
And Adamah, and Ramah, and Hazor,
37 Kedeṣi, Edrei, Eni-Aṣọri,
And Kedesh, and Edrei, and En-hazor,
38 Ironi, Migdali-Eli, Horemu, Beti-Anati àti Beti-Ṣemeṣi. Wọ́n sì jẹ́ ìlú mọ́kàndínlógún àti ìletò wọn.
And Iron, and Migdal-el, Horem, and Beth-anah, and Beth-shemesh: nineteene cities with their villages.
39 Àwọn ìlú wọ̀nyí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Naftali, ní agbo ilé sí agbo ilé.
This is the inheritance of the tribe of the children of Naphtali according to their families: that is, the cities and their villages.
40 Ìbò kéje jáde fún ẹ̀yà Dani, ní agbo ilé ní agbo ilé.
The seuenth lot came out for the tribe of the children of Dan according to their families.
41 Ilẹ̀ ìní wọn nìwọ̀nyí: Sora, Eṣtaoli, Iri-Ṣemesi,
And the coast of their inheritance was Zorah, and Eshtaol, and Ir-shemesh,
42 Ṣaalabini, Aijaloni, Itila,
And Shaalabbin, and Aiialon, and Ithlah,
43 Eloni, Timna, Ekroni,
And Elon, and Temnathah, and Ekron,
44 Elteke, Gibetoni, Baalati,
And Eltekeh, and Gibbethon, and Baalah,
45 Jehudu, Bene-Beraki, Gati-Rimoni,
And Iehud, and Bene-berak, and Gath-rimmon,
46 Me Jakoni àti Rakkoni, pẹ̀lú ilẹ̀ tí ó kọjú sí Joppa.
And Me-iarkon, and Rakkon, with the border that lieth before Iapho.
47 (Ṣùgbọ́n àwọn ará Dani ní ìṣòro láti gba ilẹ̀ ìní wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gòkè lọ, wọ́n sì kọlu Leṣemu, wọ́n sì gbà á, wọ́n sì fi idà kọlù ú, wọ́n sì ń gbé ibẹ̀. Wọ́n sì ń gbé ní Leṣemu, wọ́n sì pe orúkọ rẹ̀ ní Dani orúkọ baba ńlá wọn).
But the coastes of the children of Dan fell out too litle for them: therefore the children of Dan went vp to fight against Leshem, and tooke it, and smote it with the edge of the sworde, and possessed it, and dwelt therein, and called Leshem, Dan after the name of Dan their father.
48 Àwọn ìlú wọ́n yí àti ìletò wọn ní ìní ẹ̀yà Dani, ní agbo ilé agbo ilé.
This is the inheritance of the tribe of the childre of Dan according to their families: that is, these cities and their villages.
49 Nígbà tí wọ́n ti parí pínpín ilẹ̀ náà ní ìpín ti olúkúlùkù, àwọn ará Israẹli fún Joṣua ọmọ Nuni ní ìní ní àárín wọn,
When they had made an ende of deuiding the lande by the coastes thereof, then the children of Israel gaue an inheritance vnto Ioshua the sonne of Nun among them.
50 bí Olúwa ti pàṣẹ, wọ́n fún un ni ìlú tí ó béèrè fún, Timnati Serah ní ìlú òkè Efraimu. Ó sì kọ́ ìlú náà, ó sì ń gbé ibẹ̀.
According to the worde of the Lord they gaue him the citie which hee asked, euen Timnath-serah in mount Ephraim: and hee built the citie and dwelt therein.
51 Wọ̀nyí ni àwọn ilẹ̀ tí Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti àwọn olórí ẹ̀yà agbo ilé Israẹli fi ìbò pín ní Ṣilo ní iwájú Olúwa ní ẹnu-ọ̀nà àgọ́ ìpàdé. Báyìí ni wọ́n parí pínpín ilẹ̀ náà.
These are ye heritages which Eleazar the Priest, and Ioshua the sonne of Nun, and the chiefe fathers of the tribes of the children of Israel deuided by lot in Shiloh before the Lord at the doore of the Tabernacle of the Congregation: so they made an ende of deuiding the countrey.

< Joshua 19 >