< Joshua 18 >

1 Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli péjọ ní Ṣilo, wọ́n si kọ́ àgọ́ ìpàdé ní ibẹ̀. Gbogbo ilẹ̀ náà sì wà ní abẹ́ àkóso wọn,
And all the company of the sons of Israel are assembled [at] Shiloh, and they cause the tent of meeting to tabernacle there, and the land hath been subdued before them.
2 ṣùgbọ́n ó ku ẹ̀yà méje nínú àwọn ọmọ Israẹli tí kò tí ì gba ogún ìní wọn.
And there are left among the sons of Israel who have not shared their inheritance, seven tribes,
3 Báyìí ni Joṣua sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe dúró pẹ́ tó, kí ẹ tó gba ilẹ̀ ìní tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín ti fi fún yín?
and Joshua saith unto the sons of Israel, 'Till when are ye remiss to go in to possess the land which He hath given to you, Jehovah, God of your fathers?
4 Ẹ yan àwọn ọkùnrin mẹ́ta nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Èmi yóò rán wọn jáde láti lọ bojú wo ilẹ̀ náà káàkiri, wọn yóò sì ṣe àpèjúwe rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìní ẹni kọ̀ọ̀kan. Nígbà náà ni wọn yóò padà tọ̀ mí wá.
Give for you three men for a tribe, and I send them, and they rise and go up and down through the land, and describe it according to their inheritance, and come in unto me,
5 Ẹ̀yin yóò sì pín ilẹ̀ náà sí ọ̀nà méje kí Juda dúró sí ilẹ̀ rẹ̀ ni ìhà gúúsù àti ilé Josẹfu ní ilẹ̀ rẹ̀ ní ìhà àríwá.
and they have divided it into seven portions — Judah doth stay by its border on the south, and the house of Joseph do stay by their border on the north —
6 Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá kọ àpèjúwe ọ̀nà méjèèje ilẹ̀ náà, ẹ mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi ní ibí, èmi ó sì ṣẹ́ kèké fún yín ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
and ye describe the land [in] seven portions, and have brought [it] in unto me hither, and I have cast for you a lot here before Jehovah our God;
7 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi kò ní ìpín ní àárín yín, nítorí iṣẹ́ àlùfáà. Olúwa ni ìní wọ́n. Gadi, Reubeni àti ìdajì ẹ̀yà Manase, ti gba ìní wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani. Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.”
for there is no portion to the Levites in your midst, for the priesthood of Jehovah [is] their inheritance, and Gad, and Reuben, and the half of the tribe of Manasseh received their inheritance beyond the Jordan eastward, which Moses servant of Jehovah gave to them.'
8 Bí àwọn ọkùnrin náà ti bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn láti fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà, Joṣua pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà káàkiri, kí ẹ sì kọ àpèjúwe rẹ̀. Lẹ́yìn náà kí ẹ padà tọ̀ mí wá, kí èmi kí ò lè ṣẹ́ kèké fún yin ní ibí ní Ṣilo ní iwájú Olúwa.”
And the men rise and go; and Joshua commandeth those who are going to describe the land, saying, 'Go, and walk up and down through the land, and describe it, and turn back unto me, and here I cast for you a lot before Jehovah in Shiloh.'
9 Báyìí ni àwọn ọkùnrin náà lọ, wọ́n sì la ilẹ̀ náà já. Wọ́n sì kọ àpèjúwe rẹ̀ sí orí ìwé kíká ní ìlú, ní ọ̀nà méje, wọ́n sì padà tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Ṣilo.
And the men go, and pass over through the land, and describe it by cities, in seven portions, on a book, and they come in unto Joshua, unto the camp, [at] Shiloh.
10 Joṣua sì ṣẹ́ gègé fún wọn ní Ṣilo ní iwájú Olúwa, Joṣua sì pín ilẹ̀ náà fún àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn ní ibẹ̀.
And Joshua casteth for them a lot in Shiloh before Jehovah, and there Joshua apportioneth the land to the sons of Israel, according to their divisions.
11 Ìbò náà sì wá sórí ẹ̀yà Benjamini, ní agbo ilé, agbo ilé. Ilẹ̀ ìpín wọn sì wà láàrín ti ẹ̀yà Juda àti Josẹfu.
And a lot goeth up [for] the tribe of the sons of Benjamin, for their families; and the border of their lot goeth out between the sons of Judah and the sons of Joseph.
12 Ní ìhà àríwá ààlà wọn bẹ̀rẹ̀ ní Jordani, ó kọjá lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Jeriko ní ìhà àríwá, ó sì forí lé ìwọ̀-oòrùn sí ìlú òkè, jáde sí aginjù Beti-Afeni.
And the border is to them at the north side from the Jordan, and the border hath gone up unto the side of Jericho on the north, and gone up through the hill-country westward, and its outgoings have been at the wilderness of Beth-Aven;
13 Láti ibẹ̀ ààlà náà tún kọjá lọ sí ìhà gúúsù ní ọ̀nà Lusi (tí í ṣe Beteli) ó sì dé Atarotu-Addari, ní orí òkè tí ó wà ní gúúsù Beti-Horoni.
and the border hath gone over thence to Luz, unto the side of Luz (it [is] Beth-El) southward, and the border hath gone down [to] Atroth-Addar, by the hill that [is] on the south of the lower Beth-Horon;
14 Láti òkè tí ó kọjú sí Beti-Horoni ní gúúsù ààlà náà yà sí gúúsù ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó sì jáde sí Kiriati-Baali (tí í ṣe Kiriati-Jearimu), ìlú àwọn ènìyàn Juda. Èyí ni ìhà ìwọ̀-oòrùn.
and the border hath been marked out, and hath gone round to the corner of the sea southward, from the hill which [is] at the front of Beth-Horon southward, and its outgoings have been unto Kirjath-Baal (it [is] Kirjath-Jearim), a city of the sons of Judah: this [is] the west quarter.
15 Ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ ní ìpẹ̀kun Kiriati-Jearimu ní ìwọ̀-oòrùn, ààlà náà wà ní ibi ìsun omi Nefitoa.
And the south quarter [is] from the end of Kirjath-Jearim, and the border hath gone out westward, and gone out unto the fountain of the waters of Nephtoah;
16 Ààlà náà lọ sí ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè tí ó kọjú sí àfonífojì Beni-Hinnomu, àríwá àfonífojì Refaimu. O sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí àfonífojì Hinnomu sí apá gúúsù gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè ìlú Jebusi, ó sì lọ bẹ́ẹ̀ títí dé En-Rogeli.
and the border hath come down unto the extremity of the hill which [is] on the front of the valley of the son of Hinnom, which [is] in the valley of the Rephaim northward, and hath gone down the valley of Hinnom unto the side of Jebusi southward, and gone down [to] En-Rogel,
17 Nígbà náà ni ó yípo sí ìhà àríwá, ó sì lọ sí Ẹni-Ṣemeṣi, ó tẹ̀síwájú dé Geliloti tí ó kọjú sí òkè Adummimu, ó sì sọ̀kalẹ̀ sí ibi Òkúta Bohani ọmọ Reubeni.
and hath been marked out on the north, and gone out to En-Shemesh, and gone out unto Geliloth, which [is] over-against the ascent of Adummim, and gone down [to] the stone of Bohan son of Reuben,
18 Ó tẹ̀síwájú títí dé gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Araba, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí aginjù.
and passed over unto the side over-against Arabah northward, and gone down to Arabah;
19 Nígbà náà ni ó lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Hogla, ó sì jáde ní àríwá etí bèbè Òkun Iyọ̀, ní ẹnu odò Jordani ní gúúsù. Èyí ni ààlà ti gúúsù.
and the border hath passed over unto the side of Beth-Hoglah northward, and the outgoings of the border have been unto the north bay of the salt sea, unto the south extremity of the Jordan; this [is] the south border;
20 Odò Jordani sí jẹ́ ààlà ní ìhà ìlà-oòrùn. Ìwọ̀nyí ní àwọn ààlà ti ó sàmì sí ìní àwọn ìdílé Benjamini ní gbogbo àwọn àyíká wọn.
and the Jordan doth border it at the east quarter; this [is] the inheritance of the sons of Benjamin, by its borders round about, for their families.
21 Ẹ̀yà Benjamini ní agbo ilé, agbo ilé ni àwọn ìlú wọ̀nyí: Jeriko, Beti-Hogla, Emeki-Keṣiṣi,
And the cities for the tribe of the sons of Benjamin, for their families, have been Jericho, and Beth-Hoglah, and the valley of Keziz,
22 Beti-Araba, Semaraimu, Beteli,
and Beth-Arabah, Zemaraim, and Beth-El,
23 Affimu, Para, Ofira
and Avim, and Parah, and Ophrah,
24 Kefari, Ammoni, Ofini àti Geba; àwọn ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
and Chephar-Haammonai, and Ophni, and Gaba; twelve cities and their villages.
25 Gibeoni, Rama, Beeroti,
Gibeon, and Ramah, and Beeroth,
26 Mispa, Kefira, Mosa,
and Mizpeh, and Chephirah, and Mozah,
27 Rekemu, Irpeeli, Tarala,
and Rekem, and Irpeel, and Taralah,
28 Ṣela, Haelefi, ìlú Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu), Gibeah àti Kiriati, àwọn ìlú mẹ́rìnlá àti ìletò wọn. Èyí ni ìní Benjamini fún ìdílé rẹ̀.
and Zelah, Eleph, and Jebusi (it [is] Jerusalem), Gibeath, Kirjath: fourteen cities and their villages. This [is] the inheritance of the sons of Benjamin, for their families.

< Joshua 18 >