< Joshua 18 >

1 Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli péjọ ní Ṣilo, wọ́n si kọ́ àgọ́ ìpàdé ní ibẹ̀. Gbogbo ilẹ̀ náà sì wà ní abẹ́ àkóso wọn,
And all the meeting of the children of Israel came together at Shiloh and put up the Tent of meeting there: and the land was crushed before them.
2 ṣùgbọ́n ó ku ẹ̀yà méje nínú àwọn ọmọ Israẹli tí kò tí ì gba ogún ìní wọn.
But there were still seven tribes among the children of Israel who had not taken up their heritage.
3 Báyìí ni Joṣua sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe dúró pẹ́ tó, kí ẹ tó gba ilẹ̀ ìní tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín ti fi fún yín?
Then Joshua said to the children of Israel, Why are you so slow to go in and take up your heritage in the land which the Lord, the God of your fathers, has given you?
4 Ẹ yan àwọn ọkùnrin mẹ́ta nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Èmi yóò rán wọn jáde láti lọ bojú wo ilẹ̀ náà káàkiri, wọn yóò sì ṣe àpèjúwe rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìní ẹni kọ̀ọ̀kan. Nígbà náà ni wọn yóò padà tọ̀ mí wá.
Take from among you three men from every tribe; and I will send them to go through the land and make a record of it for distribution as their heritage; then let them come back to me.
5 Ẹ̀yin yóò sì pín ilẹ̀ náà sí ọ̀nà méje kí Juda dúró sí ilẹ̀ rẹ̀ ni ìhà gúúsù àti ilé Josẹfu ní ilẹ̀ rẹ̀ ní ìhà àríwá.
And let them make division of it into seven parts: let Judah keep inside his limit on the south, and let the children of Joseph keep inside their limit on the north.
6 Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá kọ àpèjúwe ọ̀nà méjèèje ilẹ̀ náà, ẹ mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi ní ibí, èmi ó sì ṣẹ́ kèké fún yín ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
And you are to have the land marked out in seven parts, and come back to me with the record; and I will make the distribution for you here by the decision of the Lord our God.
7 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi kò ní ìpín ní àárín yín, nítorí iṣẹ́ àlùfáà. Olúwa ni ìní wọ́n. Gadi, Reubeni àti ìdajì ẹ̀yà Manase, ti gba ìní wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani. Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.”
For the Levites have no part among you; to be the Lord's priests is their heritage; and Gad and Reuben and the half-tribe of Manasseh have had their heritage on the east side of Jordan, given to them by Moses, the servant of the Lord.
8 Bí àwọn ọkùnrin náà ti bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn láti fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà, Joṣua pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà káàkiri, kí ẹ sì kọ àpèjúwe rẹ̀. Lẹ́yìn náà kí ẹ padà tọ̀ mí wá, kí èmi kí ò lè ṣẹ́ kèké fún yin ní ibí ní Ṣilo ní iwájú Olúwa.”
So the men got up and went; and Joshua gave orders to those who went, to make a record of the land, saying, Go up and down through the land, and make a record of it and come back here to me, and I will make the distribution for you here by the decision of the Lord in Shiloh.
9 Báyìí ni àwọn ọkùnrin náà lọ, wọ́n sì la ilẹ̀ náà já. Wọ́n sì kọ àpèjúwe rẹ̀ sí orí ìwé kíká ní ìlú, ní ọ̀nà méje, wọ́n sì padà tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Ṣilo.
So the men went, travelling through the land, and made a record of it by towns in seven parts in a book, and came back to Joshua to the tent-circle at Shiloh.
10 Joṣua sì ṣẹ́ gègé fún wọn ní Ṣilo ní iwájú Olúwa, Joṣua sì pín ilẹ̀ náà fún àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn ní ibẹ̀.
And Joshua made the distribution for them in Shiloh by the decision of the Lord, marking out the land for the children of Israel by their divisions.
11 Ìbò náà sì wá sórí ẹ̀yà Benjamini, ní agbo ilé, agbo ilé. Ilẹ̀ ìpín wọn sì wà láàrín ti ẹ̀yà Juda àti Josẹfu.
And the first heritage came out for the tribe of Benjamin by their families: and the limit of their heritage went between the children of Judah and the children of Joseph.
12 Ní ìhà àríwá ààlà wọn bẹ̀rẹ̀ ní Jordani, ó kọjá lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Jeriko ní ìhà àríwá, ó sì forí lé ìwọ̀-oòrùn sí ìlú òkè, jáde sí aginjù Beti-Afeni.
And their limit on the north was from the Jordan, and the line goes up to the side of Jericho on the north and through the hill-country to the west, ending at the waste land of Beth-aven.
13 Láti ibẹ̀ ààlà náà tún kọjá lọ sí ìhà gúúsù ní ọ̀nà Lusi (tí í ṣe Beteli) ó sì dé Atarotu-Addari, ní orí òkè tí ó wà ní gúúsù Beti-Horoni.
And from there the line goes south to Luz, to the side of Luz (which is Beth-el), then down to Ataroth-addar, by the mountain to the south of Beth-horon the lower.
14 Láti òkè tí ó kọjú sí Beti-Horoni ní gúúsù ààlà náà yà sí gúúsù ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó sì jáde sí Kiriati-Baali (tí í ṣe Kiriati-Jearimu), ìlú àwọn ènìyàn Juda. Èyí ni ìhà ìwọ̀-oòrùn.
And the limit is marked as coming round to the south on the west side from the mountain which is south of Beth-horon, and ending at Kiriath-baal (which is Kiriath-jearim), a town of the children of Judah: this is the west part.
15 Ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ ní ìpẹ̀kun Kiriati-Jearimu ní ìwọ̀-oòrùn, ààlà náà wà ní ibi ìsun omi Nefitoa.
And the south part is from the farthest point of Kiriath-jearim, and the line goes out to the west to the fountain of the waters of Nephtoah:
16 Ààlà náà lọ sí ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè tí ó kọjú sí àfonífojì Beni-Hinnomu, àríwá àfonífojì Refaimu. O sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí àfonífojì Hinnomu sí apá gúúsù gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè ìlú Jebusi, ó sì lọ bẹ́ẹ̀ títí dé En-Rogeli.
And the line goes down to the farthest part of the mountain facing the valley of the son of Hinnom, which is on the north of the valley of Rephaim: from there it goes down to the valley of Hinnom, to the side of the Jebusite on the south as far as En-rogel;
17 Nígbà náà ni ó yípo sí ìhà àríwá, ó sì lọ sí Ẹni-Ṣemeṣi, ó tẹ̀síwájú dé Geliloti tí ó kọjú sí òkè Adummimu, ó sì sọ̀kalẹ̀ sí ibi Òkúta Bohani ọmọ Reubeni.
And it goes to En-shemesh and on to Geliloth, opposite the way up to Adummim, and it goes down to the stone of Bohan, the son of Reuben;
18 Ó tẹ̀síwájú títí dé gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Araba, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí aginjù.
And it goes on to the side facing the Arabah to the north, and down to the Arabah;
19 Nígbà náà ni ó lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Hogla, ó sì jáde ní àríwá etí bèbè Òkun Iyọ̀, ní ẹnu odò Jordani ní gúúsù. Èyí ni ààlà ti gúúsù.
And on to the north side of Beth-hoglah, ending at the north inlet of the Salt Sea at the south end of Jordan; this is their limit on the south.
20 Odò Jordani sí jẹ́ ààlà ní ìhà ìlà-oòrùn. Ìwọ̀nyí ní àwọn ààlà ti ó sàmì sí ìní àwọn ìdílé Benjamini ní gbogbo àwọn àyíká wọn.
And the limit of the east part is the Jordan. This is the heritage of the children of Benjamin, marked out for their families by these limits on all sides.
21 Ẹ̀yà Benjamini ní agbo ilé, agbo ilé ni àwọn ìlú wọ̀nyí: Jeriko, Beti-Hogla, Emeki-Keṣiṣi,
And the towns of the children of Benjamin, given to them in the order of their families, are Jericho and Beth-hoglah and Emek-kezziz
22 Beti-Araba, Semaraimu, Beteli,
And Beth-arabah and Zemaraim and Beth-el
23 Affimu, Para, Ofira
And Avvim and Parah and Ophrah
24 Kefari, Ammoni, Ofini àti Geba; àwọn ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
And Chephar-Ammoni and Ophni and Geba; twelve towns with their unwalled places;
25 Gibeoni, Rama, Beeroti,
Gibeon and Ramah and Beeroth
26 Mispa, Kefira, Mosa,
And Mizpeh and Chephirah and Mozah
27 Rekemu, Irpeeli, Tarala,
And Rekem and Irpeel and Taralah
28 Ṣela, Haelefi, ìlú Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu), Gibeah àti Kiriati, àwọn ìlú mẹ́rìnlá àti ìletò wọn. Èyí ni ìní Benjamini fún ìdílé rẹ̀.
And Zela, Eleph and the Jebusite (which is Jerusalem), Gibeath and Kiriath; fourteen towns with their unwalled places. This is the heritage of the children of Benjamin by their families.

< Joshua 18 >