< Joshua 18 >

1 Gbogbo ìjọ àwọn ọmọ Israẹli péjọ ní Ṣilo, wọ́n si kọ́ àgọ́ ìpàdé ní ibẹ̀. Gbogbo ilẹ̀ náà sì wà ní abẹ́ àkóso wọn,
Shromáždilo se pak všecko množství synů Izraelských do Sílo, a tu postavili stánek úmluvy, když již země od nich podmaněna byla.
2 ṣùgbọ́n ó ku ẹ̀yà méje nínú àwọn ọmọ Israẹli tí kò tí ì gba ogún ìní wọn.
Pozůstalo pak z synů Izraelských, jimž ještě nebylo rozděleno dědictví jejich, sedmero pokolení.
3 Báyìí ni Joṣua sọ fún àwọn ọmọ Israẹli, “Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe dúró pẹ́ tó, kí ẹ tó gba ilẹ̀ ìní tí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín ti fi fún yín?
I řekl Jozue synům Izraelským: I dokudž zanedbáváte vjíti, abyste se uvázali v zemi, kterouž vám dal Hospodin Bůh otců vašich?
4 Ẹ yan àwọn ọkùnrin mẹ́ta nínú ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Èmi yóò rán wọn jáde láti lọ bojú wo ilẹ̀ náà káàkiri, wọn yóò sì ṣe àpèjúwe rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí ìní ẹni kọ̀ọ̀kan. Nígbà náà ni wọn yóò padà tọ̀ mí wá.
Vydejte z sebe z každého pokolení tři muže, ať je pošli, aby vstanouce, zchodili zemi, a popsali ji vedlé dědictví svých; potom navrátí se ke mně.
5 Ẹ̀yin yóò sì pín ilẹ̀ náà sí ọ̀nà méje kí Juda dúró sí ilẹ̀ rẹ̀ ni ìhà gúúsù àti ilé Josẹfu ní ilẹ̀ rẹ̀ ní ìhà àríwá.
I rozdělí ji na sedm dílů. Juda zůstane v končinách svých od poledne, a čeledi Jozefovy zůstanou v končinách svých od půlnoci.
6 Lẹ́yìn ìgbà tí ẹ bá kọ àpèjúwe ọ̀nà méjèèje ilẹ̀ náà, ẹ mú wọn wá sí ọ̀dọ̀ mi ní ibí, èmi ó sì ṣẹ́ kèké fún yín ní iwájú Olúwa Ọlọ́run wa.
Vy pak, když popíšete zemi na sedm dílů, přinesete sem ke mně; tedy uvrhu vám losy zde před Hospodinem Bohem naším.
7 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi kò ní ìpín ní àárín yín, nítorí iṣẹ́ àlùfáà. Olúwa ni ìní wọ́n. Gadi, Reubeni àti ìdajì ẹ̀yà Manase, ti gba ìní wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani. Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.”
Nebo nemají dílu Levítové u prostřed vás, proto že kněžství Hospodinovo jest dědictví jejich; Gád pak a Ruben, a polovice pokolení Manassesova, vzali dědictví své před Jordánem na východ, kteréž dal jim Mojžíš, služebník Hospodinův.
8 Bí àwọn ọkùnrin náà ti bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò wọn láti fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà, Joṣua pàṣẹ fún wọn pé, “Ẹ lọ kí ẹ sì fojú díwọ̀n ilẹ̀ náà káàkiri, kí ẹ sì kọ àpèjúwe rẹ̀. Lẹ́yìn náà kí ẹ padà tọ̀ mí wá, kí èmi kí ò lè ṣẹ́ kèké fún yin ní ibí ní Ṣilo ní iwájú Olúwa.”
Protož vstavše muži ti, odešli. A přikázal Jozue těm, kteříž šli, aby popsali zemi, řka: Jděte a projděte zemi, a popište ji; potom navraťte se ke mně, a uvrhu zde losy před Hospodinem v Sílo.
9 Báyìí ni àwọn ọkùnrin náà lọ, wọ́n sì la ilẹ̀ náà já. Wọ́n sì kọ àpèjúwe rẹ̀ sí orí ìwé kíká ní ìlú, ní ọ̀nà méje, wọ́n sì padà tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Ṣilo.
Tedy odešli muži, a prošedše zemi, popsali ji po městech na sedm dílů na knize, a navrátili se k Jozue do stanů v Sílo.
10 Joṣua sì ṣẹ́ gègé fún wọn ní Ṣilo ní iwájú Olúwa, Joṣua sì pín ilẹ̀ náà fún àwọn Israẹli gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn ní ibẹ̀.
I uvrhl jim losy Jozue v Sílo před Hospodinem, a rozdělil tu Jozue zemi synům Izraelským vedlé dílů jejich.
11 Ìbò náà sì wá sórí ẹ̀yà Benjamini, ní agbo ilé, agbo ilé. Ilẹ̀ ìpín wọn sì wà láàrín ti ẹ̀yà Juda àti Josẹfu.
Padl pak los pokolení synů Beniaminových po čeledech jejich, a přišla meze dílu jejich mezi syny Juda a syny Jozefovy.
12 Ní ìhà àríwá ààlà wọn bẹ̀rẹ̀ ní Jordani, ó kọjá lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Jeriko ní ìhà àríwá, ó sì forí lé ìwọ̀-oòrùn sí ìlú òkè, jáde sí aginjù Beti-Afeni.
A byla meze jejich k straně půlnoční od Jordánu, a šla při straně půlnoční Jericha, a táhla se na hory k moři, a skonávala se při poušti Betaven.
13 Láti ibẹ̀ ààlà náà tún kọjá lọ sí ìhà gúúsù ní ọ̀nà Lusi (tí í ṣe Beteli) ó sì dé Atarotu-Addari, ní orí òkè tí ó wà ní gúúsù Beti-Horoni.
A odtud přechází ta meze do Lůz, při straně Lůz polední, (jenž jest Bethel, ) a chýlí se ta meze do Atarot Addar vedlé hory, kteráž jest od poledne Betoron dolního.
14 Láti òkè tí ó kọjú sí Beti-Horoni ní gúúsù ààlà náà yà sí gúúsù ní ìhà ìwọ̀-oòrùn, ó sì jáde sí Kiriati-Baali (tí í ṣe Kiriati-Jearimu), ìlú àwọn ènìyàn Juda. Èyí ni ìhà ìwọ̀-oòrùn.
Odkudž obchází vůkol k straně moře na poledne od hory, kteráž jest proti Betoron ku polední, a konec její jest Kariatbaal, (jenž jest Kariatjeharim), město synů Juda. Ta jest strana západní.
15 Ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ ní ìpẹ̀kun Kiriati-Jearimu ní ìwọ̀-oòrùn, ààlà náà wà ní ibi ìsun omi Nefitoa.
Strana pak ku poledni od konce Kariatjeharim, a vychází ta meze k moři, a přichází až k studnici vod Neftoa.
16 Ààlà náà lọ sí ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè tí ó kọjú sí àfonífojì Beni-Hinnomu, àríwá àfonífojì Refaimu. O sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí àfonífojì Hinnomu sí apá gúúsù gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè ìlú Jebusi, ó sì lọ bẹ́ẹ̀ títí dé En-Rogeli.
A táhne se táž meze k konci hory, kteráž jest naproti údolí synů Hinnom, a jest v údolí Refaim na půlnoci, a běží skrze údolí Hinnom po straně Jebuzea na poledne, a přichází k studnici Rogel.
17 Nígbà náà ni ó yípo sí ìhà àríwá, ó sì lọ sí Ẹni-Ṣemeṣi, ó tẹ̀síwájú dé Geliloti tí ó kọjú sí òkè Adummimu, ó sì sọ̀kalẹ̀ sí ibi Òkúta Bohani ọmọ Reubeni.
Potom točí se od půlnoci, a dochází k Ensemes, a vychází do Gelilot, kteréž jest naproti místu, kudy se jde do Adomim, a sstupuje k kameni Bohana, syna Rubenova.
18 Ó tẹ̀síwájú títí dé gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Araba, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí aginjù.
Odtud přechází k straně, kteráž jest naproti rovinám strany půlnoční, a táhne se do Araba.
19 Nígbà náà ni ó lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè Beti-Hogla, ó sì jáde ní àríwá etí bèbè Òkun Iyọ̀, ní ẹnu odò Jordani ní gúúsù. Èyí ni ààlà ti gúúsù.
Odtud jde k straně Betogla na půlnoci, a skonává se meze ta při zátoce moře slaného od půlnoční strany, tu kdež vpadá Jordán do moře na polední straně. To jest pomezí ku poledni.
20 Odò Jordani sí jẹ́ ààlà ní ìhà ìlà-oòrùn. Ìwọ̀nyí ní àwọn ààlà ti ó sàmì sí ìní àwọn ìdílé Benjamini ní gbogbo àwọn àyíká wọn.
Jordán také je odděluje k straně východní. To jest dědictví synů Beniaminových s mezemi svými vůkol a vůkol po čeledech jejich.
21 Ẹ̀yà Benjamini ní agbo ilé, agbo ilé ni àwọn ìlú wọ̀nyí: Jeriko, Beti-Hogla, Emeki-Keṣiṣi,
A byla města tato pokolení synů Beniaminových po čeledech jejich: Jericho, Betogla a údolí Kasis;
22 Beti-Araba, Semaraimu, Beteli,
A Betaraba, Semaraim a Bethel;
23 Affimu, Para, Ofira
A Avim, též Afara a Ofra;
24 Kefari, Ammoni, Ofini àti Geba; àwọn ìlú méjìlá àti ìletò wọn.
A Cefer, Hamona, Ofni a Gaba, měst dvanácta vsi jejich;
25 Gibeoni, Rama, Beeroti,
Gabaon, Ráma a Berot;
26 Mispa, Kefira, Mosa,
Masfa, Kafira a Mosa;
27 Rekemu, Irpeeli, Tarala,
Rekem, Jarefel a Tarela;
28 Ṣela, Haelefi, ìlú Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu), Gibeah àti Kiriati, àwọn ìlú mẹ́rìnlá àti ìletò wọn. Èyí ni ìní Benjamini fún ìdílé rẹ̀.
A Sela, Elef a Jebus, (jenž jest Jeruzalém, ) Gibat, Kariat, měst čtrnácte i vsi jejich. To jest dědictví synů Beniaminových po čeledech jejich.

< Joshua 18 >