< Joshua 16 >
1 Ìpín ti àwọn ọmọ Josẹfu láti Jordani lẹ́bàá Jeriko, ní omi Jeriko ní ìhà ìlà-oòrùn, àní aginjù, tí ó gòkè láti Jeriko lọ dé ilẹ̀ òkè Beteli.
And the lot of the children of Joseph fell from Jordan by Jericho, to the water of Jericho on the east, to the wilderness that goeth up from Jericho throughout mount Bethel,
2 Ó sì tẹ̀síwájú láti Beteli (tí í ṣe Lusi) kọjá lọ sí agbègbè àwọn ará Arki ní Atarotu,
And goeth out from Bethel to Luz, and passeth along to the borders of Archi to Ataroth,
3 Ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn agbègbè àwọn ará Jefileti, títí dé ilẹ̀ ìsàlẹ̀ Beti-Horoni, àní dé Geseri, ó sì parí sí etí Òkun.
And goeth down westward to the border of Japhleti, to the border of Bethhoron the lower, and to Gezer: and the ends of it are at the sea.
4 Báyìí ni Manase àti Efraimu, àwọn ọmọ Josẹfu, gba ilẹ̀ ìní wọn.
So the children of Joseph, Manasseh and Ephraim, took their inheritance.
5 Èyí ni ilẹ̀ Efraimu, ní agbo ilé agbo ilé. Ààlà ìní wọn lọ láti Atarotu-Addari ní ìlà-oòrùn lọ sí òkè Beti-Horoni.
And the border of the children of Ephraim according to their families was thus: even the border of their inheritance on the east side was Atarothaddar, to Bethhoron the upper;
6 Ó sì lọ títí dé Òkun. Láti Mikmeta ní ìhà àríwá, ó sì yí lọ sí ìhà ìlà-oòrùn lọ sí Taanati-Ṣilo, ó sì kọjá ní ẹ̀bá rẹ̀ lọ sí Janoa ní ìlà-oòrùn.
And the border went out toward the sea to Michmethah on the north side; and the border went about eastward to Taanathshiloh, and passed by it on the east to Janohah;
7 Láti Janoa ó yípo lọ sí gúúsù sí Atarotu àti Naara, ó sì dé Jeriko, ó sì pín sí odò Jordani.
And it went down from Janohah to Ataroth, and to Naarath, and came to Jericho, and came out at Jordan.
8 Láti Tapua ààlà náà sì lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn, ní Kana-Rafini, ó sì parí ní Òkun. Èyí ni ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Efraimu, ní agbo ilé agbo ilé.
The border went out from Tappuah westward to the river Kanah; and the ends of it were at the sea. This is the inheritance of the tribe of the children of Ephraim by their families.
9 Ó tún mú àwọn ìlú àti ìletò wọn tí ó yà sọ́tọ̀ fún àwọn ọmọ Efraimu tí ó wà ní àárín ìní àwọn ọmọ Manase.
And the separate cities for the children of Ephraim were among the inheritance of the children of Manasseh, all the cities with their villages.
10 Wọn kò lé àwọn ara Kenaani tí ń gbé ni Geseri kúrò, títí di òní yìí ni àwọn ará Kenaani ń gbé láàrín àwọn ènìyàn Efraimu, ṣùgbọ́n wọ́n mú wọ́n sìn.
And they did not drive out the Canaanites that dwelt in Gezer: but the Canaanites dwell among the Ephraimites to this day, and serve at forced labour.