< Joshua 15 >

1 Ìpín fún ẹ̀yà Juda, ní agbo ilé agbo ilé, títí dé agbègbè Edomu, títí dé aginjù Sini ní òpin ìhà gúúsù.
E foi a sorte da tribu dos filhos de Judah, segundo as suas familias, até ao termo d'Edom, o deserto de Sin para o sul, até a extremidade da banda do sul.
2 Ààlà wọn ní ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ láti etí òpin ìhà gúúsù Òkun Iyọ̀,
E foi o seu termo para o sul, desde a ribeira do mar salgado, desde a bahia que olha para o sul;
3 ó sì gba gúúsù Akrabbimu lọ, títí dé Sini àti sí iwájú ìhà gúúsù Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà ó sì tún kọjá Hesroni lọ sí Adari, ó sì tún yípo yíká lọ sí Karka.
E sae para o sul, até á subida d'Akrabbim, e passa a Sin, e sobe do sul a Cades Barnea, e passa por Hezron, e sobe a Adar, e rodeia a Carca:
4 Ó tún kọjá lọ sí Asmoni, ó sì papọ̀ mọ́ Wadi ti Ejibiti, ó parí sí Òkun. Èyí ni ààlà wọn ní ìhà gúúsù.
E passa Asmon, e sae ao ribeiro do Egypto, e as saidas d'este termo irão até ao mar: este será o vosso termo da banda do sul.
5 Ààlà wọn ní ìhà ìlà-oòrùn ní Òkun Iyọ̀ títí dé ẹnu Jordani. Ààlà àríwá bẹ̀rẹ̀ láti etí òkun ní ẹnu Jordani,
O termo porém para o oriente será o mar salgado, até á extremidade do Jordão: e o termo para o norte será da bahia do mar, desde a extremidade do Jordão.
6 ààlà náà sì tún dé Beti-Hogla, ó sì lọ sí ìhà àríwá Beti-Araba. Ààlà náà sì tún dé ibi Òkúta Bohani ti ọmọ Reubeni.
E este termo subirá até Beth-hogla, e passará do norte a Beth-araba, e este termo subirá até á pedra de Bohan, filho de Ruben
7 Ààlà náà gòkè lọ títí dé Debiri láti àfonífojì Akori, ó sì yípadà sí àríwá Gilgali, èyí tí ń bẹ ní iwájú òkè Adummimu, tí ń bẹ ní ìhà gúúsù odò náà. Ó sì tẹ̀síwájú sí apá omi En-Ṣemeṣi, ó sì jáde sí En-Rogeli.
Subirá mais este termo a Debir desde o valle d'Acor, e olhará pelo norte para Gilgal, a qual está á subida d'Adummim, que está para o sul do ribeiro: então este termo passará até ás aguas d'En-semes: e as suas saidas estarão da banda d'En-rogel.
8 Ààlà náà sì tún gòkè lọ sí àfonífojì Beni-Hinnomu ní ìhà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ gúúsù ti Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu). Ó sì gòkè lọ sí orí òkè tí ó wà lórí àfonífojì Hinnomu tí ń bẹ ní ìpẹ̀kun àfonífojì Refaimu ní ìhà àríwá.
E este termo passará pelo valle do filho d'Hinnom, da banda dos jebuseos do sul: esta é Jerusalem: e subirá este termo até ao cume do monte que está diante do valle d'Hinnom para o occidente, que está no fim do valle dos rephains da banda do norte
9 Ààlà náà sì lọ láti orí òkè lọ sí ìsun omi Nefitoa, ó sì jáde sí ìlú òkè Efroni, ó sì lọ sí apá ìsàlẹ̀ Baalahi (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu).
Então este termo irá desde a altura do monte até á fonte das aguas de Nephtoah; e sairá até ás cidades do monte d'Ephron; irá mais este termo até Baala; esta é Kiriath-jearim:
10 Ààlà tí ó yípo láti Baalahi lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn sí òkè Seiri, ó sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Jearimu (tí í ṣe, Kesaloni), ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beti-Ṣemeṣi, ó sì kọjá lọ sí Timna.
Então tornará este termo desde Baala para o occidente, até ás montanhas de Seir, e passará ao lado do monte de Jearim da banda do norte; esta é Kesalon, e descerá a Beth-semes, e passará por Timna.
11 Ààlà náà sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Ekroni, ó sì yípadà lọ sí Ṣikkeroni, ó sì yípadà lọ sí òkè Baalahi, ó sì dé Jabneeli, ààlà náà sì parí sí Òkun.
Sairá este termo mais ao lado d'Ek- ron para o norte, e este termo irá a Sicron, e passará o monte de Baala, e sairá em Jabneel: e as saidas d'este termo eram no mar
12 Ààlà ìwọ̀-oòrùn sì jẹ́ agbègbè Òkun Ńlá. Ìwọ̀nyí ni ààlà àyíká ènìyàn Juda ní agbo ilé wọn.
Será porém o termo da banda do occidente o mar grande, e o seu termo: este é o termo dos filhos de Judah ao redor, segundo as suas familias.
13 Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Olúwa pa fún Joṣua, ó fi ìpín fún Kalebu ọmọ Jefunne, ìpín ní Juda—Kiriati-Arba, tí í ṣe Hebroni. (Arba sì ní baba ńlá Anaki.)
Mas a Caleb, filho de Jefoné, deu uma parte no meio dos filhos de Judah, conforme ao dito do Senhor a Josué: a saber, a cidade de Arba, pae d'Enak; este é Hebron.
14 Kalebu sì lé àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta jáde láti Hebroni; Ṣeṣai, Ahimani, àti Talmai, ìran Anaki.
E expelliu Caleb d'ali os tres filhos d'Enak: Sesai, e Ahiman, e Talmai, gerados d'Enak.
15 Ó sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
E d'ali subiu aos habitantes de Debir: e fôra d'antes o nome de Debir Kiriath-sepher.
16 Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
E disse Caleb: Quem ferir a Kiriath-sepher, e a tomar, lhe darei a minha filha Acsa por mulher.
17 Otnieli ọmọ Kenasi, arákùnrin Kalebu, sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
Tomou-a pois Othniel, filho de Kenaz, irmão de Caleb: e deu-lhe a sua filha Acsa por mulher.
18 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
E succedeu que, vindo ella a elle o persuadiu que pedisse um campo a seu pae: e ella se apeou do jumento: então Caleb lhe disse: Que é que tens?
19 Ó sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
E ella disse; Dá-me uma benção; pois me déste terra secca, dá-me tambem fontes de aguas. Então lhe deu as fontes superiores e as fontes inferiores.
20 Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bi ìdílé wọn.
Esta é a herança da tribu dos filhos de Judah, segundo as suas familias.
21 Ìlú ìpẹ̀kun gúúsù ti ẹ̀yà Juda ní gúúsù ní ààlà Edomu nìwọ̀nyí: Kabṣeeli, Ederi, Jaguri,
São pois as cidades da extremidade da tribu dos filhos de Judah até ao termo d'Edom para o sul: Cabzeel, e Eder, e Jagur,
22 Kina, Dimona, Adada,
E Kina, e Dimona, e Adada,
23 Kedeṣi, Hasori, Itina,
E Kedes, e Hasor, e Itnan,
24 Sifi, Telemu, Bealoti,
Zif, e Telem, e Bealoth,
25 Hasori Hadatta, Kerioti Hesroni (tí í ṣe Hasori),
E Hasor, Hadattha, e Kirioth-hesron (que é Hasor),
26 Amamu, Ṣema, Molada,
Aman, e Sema, e Molada,
27 Hasari Gada, Heṣmoni, Beti-Peleti,
E Hasar-gadda, e Hesmone, e Beth-palet,
28 Hasari-Ṣuali, Beerṣeba, Bisiotia,
E Hasar-sual, e Beer-seba, e Bizjo-theja,
29 Baalahi, Limu, Esemu,
Baala, e Jim, e Ezem,
30 Eltoladi, Kesili, Horma,
E Eltolad, e Chesil, e Horma,
31 Siklagi, Madmana, Sansanna,
E Siklag, e Madmanna, e Sansanna,
32 Leboati, Ṣilhimu, Aini àti Rimoni, àpapọ̀ ìlú mọ́kàndínlọ́gbọ̀n àti àwọn ìletò wọn.
E Lebaoth, e Silhim, e Ain, e Rimmon: todas as cidades e as suas aldeias, vinte e nove.
33 Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹsẹ̀ òkè: Eṣtaoli, Sora, Aṣna,
Nas planicies: Esthaol, e Sora, e Asna,
34 Sanoa, Eni-Gannimu, Tapua, Enamu,
E Zanoah, e En-gannim, Tappuah, e Enam,
35 Jarmatu, Adullamu, Soko, Aseka,
Iarmuth, e Adullam, Socho, e Azeka,
36 Ṣaaraimu, Adittaimu àti Gedera (tàbí Gederotaimu). Ìlú mẹ́rìnlá àti àwọn ìletò wọn.
E Saaraim, e Adithaim, e Gedera, e Gederothaim, quatorze cidades e as suas aldeias.
37 Senani, Hadaṣa, Migdali Gadi,
Senan, e Hadasa, e Migdal-gad,
38 Dileani, Mispa, Jokteeli,
E Dilan, e Mispah, e Jokteel,
39 Lakiṣi, Boskati, Egloni,
Lachis, e Boscath, e Eglon,
40 Kabboni, Lamasi, Kitlisi,
E Cabbon, e Lahmas, e Chitlis,
41 Gederoti, Beti-Dagoni, Naama àti Makkeda, ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
E Gederoth, Beth-dagon, e Naama, e Makeda: dezeseis cidades e as suas aldeias.
42 Libina, Eteri, Aṣani,
Libna, e Ether, e Asan,
43 Hifita, Aṣna, Nesibu,
E Iphtah, e Asna, e Nezib,
44 Keila, Aksibu àti Meraṣa: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò wọn.
E Keila, e Aczib, e Maresa: nove cidades e as suas aldeias.
45 Ekroni, pẹ̀lú ibùgbé àti àwọn ìletò rẹ̀ tó yí i ká,
Ekron, e os logares da sua jurisdicção, e as suas aldeias:
46 ìwọ̀-oòrùn Ekroni, gbogbo èyí tí ń bẹ nítòsí Aṣdodu, pẹ̀lú àwọn ìletò wọn,
Desde Ekron, e até ao mar, todas as que estão da banda d'Asdod, e as suas aldeias.
47 Aṣdodu, agbègbè ìlú rẹ̀ àti ìletò; àti Gasa, ìlú rẹ̀ àti ìletò, títí ó fi dé odò Ejibiti àti agbègbè Òkun Ńlá.
Asdod, os logares da sua jurisdicção, e as suas aldeias; Gaza, os logares da sua jurisdicção, e as suas aldeias, até ao rio do Egypto: e o mar grande e o seu termo.
48 Ní ilẹ̀ òkè náà: Ṣamiri, Jattiri, Soko,
E nas montanhas, Samir, Iatthir, e Socoh,
49 Dannah, Kiriati-Sannnah (tí í ṣe Debiri),
E Danna, e Kiriath-sanna, que é Debir,
50 Anabu, Eṣitemo, Animu,
E Anab, Estemo, e Anim,
51 Goṣeni, Holoni àti Giloni, ìlú mọ́kànlá àti ìletò wọn.
E Gosen, e Holon, e Gilo: onze cidades e as suas aldeias.
52 Arabu, Duma, Eṣani,
Arab, e Duma, e Esan,
53 Janimu, Beti-Tapua, Afeka,
E Ianum, e Beth-tappuah, e Apheka,
54 Hamuta, Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) àti Ṣiori: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò rẹ̀
E Humta, e Kiriath-arba (que é Hebron), e Sihor: nove cidades e as suas aldeias.
55 Maoni, Karmeli, Sifi, Jutta,
Maon, Carmel, e Zif, e Iuta,
56 Jesreeli, Jokdeamu, Sanoa,
E Jezreel, e Jokdeam, e Zanoah,
57 Kaini, Gibeah àti Timna: ìlú mẹ́wàá àti àwọn ìletò wọn.
Cain, Gibea, e Timna: dez cidades e as suas aldeias.
58 Halhuli, Beti-Suri, Gedori,
Halhul, Beth-sur, e Gedor,
59 Maarati, Beti-Anoti àti Eltekoni: ìlú mẹ́fà àti àwọn ìletò wọn.
E Maarath, e Beth-anoth, e Eltekon: seis cidades e as suas aldeias.
60 Kiriati-Baali (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu) àti Rabba ìlú méjì àti ìletò wọn.
Kiriath-baal (que é, Kiriath-jearim), e Rabba: duas cidades e as suas aldeias.
61 Ní aginjù: Beti-Araba, Middini, Sekaka,
No deserto: Beth-araba, Middin, e Secaca,
62 Nibṣani, Ìlú Iyọ̀ àti En-Gedi: ìlú mẹ́fà àti ìletò wọn.
E Nibsan, e a cidade do sal, e En-gedi: seis cidades e as suas aldeias.
63 Juda kò lè lé àwọn ọmọ Jebusi jáde, tí wọ́n ń gbé ní Jerusalẹmu. Àwọn ará Jebusi sì ń gbé pẹ̀lú àwọn ènìyàn Juda títí dí òní.
Não poderam porém os filhos de Judah expellir os jebuseos que habitavam em Jerusalem; assim habitaram os jebuseos com os filhos de Judah em Jerusalem, até ao dia de hoje.

< Joshua 15 >