< Joshua 15 >

1 Ìpín fún ẹ̀yà Juda, ní agbo ilé agbo ilé, títí dé agbègbè Edomu, títí dé aginjù Sini ní òpin ìhà gúúsù.
Ainsi le lot des enfants de Juda, selon leur parenté, fut celui-ci: Depuis la frontière d’Edom, le désert de Sin contre le midi, jusqu’à l’extrémité de la contrée australe.
2 Ààlà wọn ní ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ láti etí òpin ìhà gúúsù Òkun Iyọ̀,
Le commencement de ce pays est à la pointe de la mer très salée, et à cette langue de mer qui regarde le midi;
3 ó sì gba gúúsù Akrabbimu lọ, títí dé Sini àti sí iwájú ìhà gúúsù Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà ó sì tún kọjá Hesroni lọ sí Adari, ó sì tún yípo yíká lọ sí Karka.
Et il sort contre la montée du Scorpion, et passe à Sina; puis, monte vers Cabesbarné, et parvient à Esron, montant vers Addar, et faisant le tour de Carcaa,
4 Ó tún kọjá lọ sí Asmoni, ó sì papọ̀ mọ́ Wadi ti Ejibiti, ó parí sí Òkun. Èyí ni ààlà wọn ní ìhà gúúsù.
Et de là traversant Asémona, et arrivant jusqu’au torrent d’Egypte, et ses limites seront la grande mer: ce seront là ses confins du côté méridional.
5 Ààlà wọn ní ìhà ìlà-oòrùn ní Òkun Iyọ̀ títí dé ẹnu Jordani. Ààlà àríwá bẹ̀rẹ̀ láti etí òkun ní ẹnu Jordani,
Mais à l’orient, le commencement sera la mer très salée jusqu’à l’extrémité du Jourdain, et tout ce qui regarde vers l’aquilon, depuis la langue de mer jusqu’au même fleuve du Jourdain.
6 ààlà náà sì tún dé Beti-Hogla, ó sì lọ sí ìhà àríwá Beti-Araba. Ààlà náà sì tún dé ibi Òkúta Bohani ti ọmọ Reubeni.
Sa frontière monte à Beth-Hagla, et passe de l’aquilon à Beth-Araba, montant vers la pierre de Boën, fils de Ruben,
7 Ààlà náà gòkè lọ títí dé Debiri láti àfonífojì Akori, ó sì yípadà sí àríwá Gilgali, èyí tí ń bẹ ní iwájú òkè Adummimu, tí ń bẹ ní ìhà gúúsù odò náà. Ó sì tẹ̀síwájú sí apá omi En-Ṣemeṣi, ó sì jáde sí En-Rogeli.
S’étendant jusqu’aux frontières de Débéra, de la vallée d’Achor, contre l’aquilon, regardant Galgala qui est vis-à-vis de la montée d’Adommim, du côté austral du torrent; elle passe les eaux qui sont appelées Fontaine du Soleil, et se termine à la Fontaine du Rogel.
8 Ààlà náà sì tún gòkè lọ sí àfonífojì Beni-Hinnomu ní ìhà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ gúúsù ti Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu). Ó sì gòkè lọ sí orí òkè tí ó wà lórí àfonífojì Hinnomu tí ń bẹ ní ìpẹ̀kun àfonífojì Refaimu ní ìhà àríwá.
Elle monte aussi par la vallée du fils d’Ennom du côté du Jébuséen au midi, c’est-à-dire de Jérusalem: et de là montant jusqu’au sommet de la montagne, qui est contre Géennom, à l’occident, à l’extrémité de la vallée des Raphaïm, contre l’aquilon,
9 Ààlà náà sì lọ láti orí òkè lọ sí ìsun omi Nefitoa, ó sì jáde sí ìlú òkè Efroni, ó sì lọ sí apá ìsàlẹ̀ Baalahi (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu).
Elle passe depuis le sommet de la montagne jusqu’à la fontaine de Nephtoa, et arrive jusqu’aux bourgs de la montagne d’Ephron; elle incline ensuite vers Baala, qui est Cariathiarim, c’est-à-dire. Ville des Forêts;
10 Ààlà tí ó yípo láti Baalahi lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn sí òkè Seiri, ó sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Jearimu (tí í ṣe, Kesaloni), ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beti-Ṣemeṣi, ó sì kọjá lọ sí Timna.
Elle tourne de Baala contre l’occident jusqu’à la montagne de Séïr, passe au côté de la montagne de Jarim, vers l’aquilon, à Cheslon, descend à Bethsamès, et passe à Thamna;
11 Ààlà náà sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Ekroni, ó sì yípadà lọ sí Ṣikkeroni, ó sì yípadà lọ sí òkè Baalahi, ó sì dé Jabneeli, ààlà náà sì parí sí Òkun.
Elle parvient contre la partie septentrionale d’Accaron, par le côté, incline ensuite vers Séchrona, passe la montagne de Baala, parvient jusqu’à Jebnéel, et se termine contre l’occident par la grande mer.
12 Ààlà ìwọ̀-oòrùn sì jẹ́ agbègbè Òkun Ńlá. Ìwọ̀nyí ni ààlà àyíká ènìyàn Juda ní agbo ilé wọn.
Telles sont les limites des enfants de Juda, de tous côtés, selon leur parenté.
13 Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Olúwa pa fún Joṣua, ó fi ìpín fún Kalebu ọmọ Jefunne, ìpín ní Juda—Kiriati-Arba, tí í ṣe Hebroni. (Arba sì ní baba ńlá Anaki.)
Mais à Caleb, fils de Jéphoné, Josué donna en partage, au milieu des enfants de Juda, Cariath-Arbé du père d’Enac, la même qu’Hébron.
14 Kalebu sì lé àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta jáde láti Hebroni; Ṣeṣai, Ahimani, àti Talmai, ìran Anaki.
Et Caleb extermina de cette ville les trois enfants d’Enac, Sésaï, Ahiman et Tholmaï, de la race d’Enac.
15 Ó sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
Et montant de là, il vint vers les habitants de Dabir, qui auparavant était appelée Cariath-Sépher, c’est-à-dire Ville des lettres.
16 Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
Et Caleb dit: Celui qui attaquera Cariath-Sépher, et la prendra, je lui donnerai Axa, ma fille, pour femme.
17 Otnieli ọmọ Kenasi, arákùnrin Kalebu, sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
Othoniel, fils de Cénez et jeune frère de Caleb, la prit, et Caleb lui donna sa fille Axa pour femme.
18 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
Axa, lorsqu’ils allaient ensemble, fut engagée par son mari à demander à son père un champ; or, elle soupira pendant qu’elle était montée sur l’âne; alors Caleb: Qu’as-tu? lui dit-il.
19 Ó sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
Et elle répondit: Accorde-moi une grâce: c’est une terre située au midi et aride, que tu m’as donnée, ajoutes-y une terre arrosée. Caleb lui en donna une arrosée en haut et en bas.
20 Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bi ìdílé wọn.
Telle est la possession de la tribu des enfants de Juda, selon leur parenté.
21 Ìlú ìpẹ̀kun gúúsù ti ẹ̀yà Juda ní gúúsù ní ààlà Edomu nìwọ̀nyí: Kabṣeeli, Ederi, Jaguri,
Et aux extrémités de la terre des enfants de Juda, le long des frontières d’Edom, au midi, étaient les villes: Cabséel, Eder, Jagur,
22 Kina, Dimona, Adada,
Cina, Dimona, Adada,
23 Kedeṣi, Hasori, Itina,
Cadès, Asor, Jethnam,
24 Sifi, Telemu, Bealoti,
Ziph, Télem, Baloth,
25 Hasori Hadatta, Kerioti Hesroni (tí í ṣe Hasori),
Asor la nouvelle, Carioth, Hesron, qui est la même qu’Asor,
26 Amamu, Ṣema, Molada,
Amam, Sama, Molada,
27 Hasari Gada, Heṣmoni, Beti-Peleti,
Asergadda, Hassémon, Bethphélet,
28 Hasari-Ṣuali, Beerṣeba, Bisiotia,
Hasersual, Bersabée, Baziothia,
29 Baalahi, Limu, Esemu,
Baala, Jim, Esem,
30 Eltoladi, Kesili, Horma,
Eltholad, Césil, Harma,
31 Siklagi, Madmana, Sansanna,
Sicéleg, Médéména, Sensenna,
32 Leboati, Ṣilhimu, Aini àti Rimoni, àpapọ̀ ìlú mọ́kàndínlọ́gbọ̀n àti àwọn ìletò wọn.
Lébaoth, Sélim, Aen et Remmon: en tout vingt-neuf villes et leurs villages;
33 Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹsẹ̀ òkè: Eṣtaoli, Sora, Aṣna,
Et dans les plaines: Estaol, Saréa, Aséna,
34 Sanoa, Eni-Gannimu, Tapua, Enamu,
Zanoé, Engannim, Taphua, Enaïm,
35 Jarmatu, Adullamu, Soko, Aseka,
Jérimoth, Adullam, Socho, Azéca,
36 Ṣaaraimu, Adittaimu àti Gedera (tàbí Gederotaimu). Ìlú mẹ́rìnlá àti àwọn ìletò wọn.
Saraïm, Adithaïm, Gédéra, et Gédérothaïm: quatorze villes et leurs villages;
37 Senani, Hadaṣa, Migdali Gadi,
Sanam, Hadassa, Magdalgad,
38 Dileani, Mispa, Jokteeli,
Déléan, Masépha, Jecthel,
39 Lakiṣi, Boskati, Egloni,
Lachis, Bascath, Eglon,
40 Kabboni, Lamasi, Kitlisi,
Chebbon, Léhéman, Céthlis,
41 Gederoti, Beti-Dagoni, Naama àti Makkeda, ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
Gidéroth, Bethdagon, Naama et Macéda: seize villes et leurs villages;
42 Libina, Eteri, Aṣani,
Labana, Ether, Asan,
43 Hifita, Aṣna, Nesibu,
Jephtha, Esna, Nésib,
44 Keila, Aksibu àti Meraṣa: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò wọn.
Ceïla, Achzib et Marésa: neuf villes et leurs villages;
45 Ekroni, pẹ̀lú ibùgbé àti àwọn ìletò rẹ̀ tó yí i ká,
Accaron avec ses bourgs et ses petits villages,
46 ìwọ̀-oòrùn Ekroni, gbogbo èyí tí ń bẹ nítòsí Aṣdodu, pẹ̀lú àwọn ìletò wọn,
Depuis Accaron jusqu’à la mer, tout ce qui s’étend vers Azot et ses bourgades;
47 Aṣdodu, agbègbè ìlú rẹ̀ àti ìletò; àti Gasa, ìlú rẹ̀ àti ìletò, títí ó fi dé odò Ejibiti àti agbègbè Òkun Ńlá.
Azot avec ses bourgs et ses petits villages; Gaza avec ses bourgs et ses petits villages, jusqu’au torrent d’Egypte, et la grande mer est sa limite;
48 Ní ilẹ̀ òkè náà: Ṣamiri, Jattiri, Soko,
Et dans la montagne: Samir, Jéther, Socoth,
49 Dannah, Kiriati-Sannnah (tí í ṣe Debiri),
Danna, Chariathsenna, qui est la même que Dabir,
50 Anabu, Eṣitemo, Animu,
Anab, Istémo, Anim,
51 Goṣeni, Holoni àti Giloni, ìlú mọ́kànlá àti ìletò wọn.
Gosen, Olon et Gilo: onze villes et leurs villages,
52 Arabu, Duma, Eṣani,
Arab, Ruma, Esaan,
53 Janimu, Beti-Tapua, Afeka,
Janum, Beththaphua, Aphéca,
54 Hamuta, Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) àti Ṣiori: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò rẹ̀
Athmatha, Cariath-Arbé, qui est la même qu’Hébron, et Sior: neuf villes et leurs villages;
55 Maoni, Karmeli, Sifi, Jutta,
Mahon, Carmel, Ziph, Jota,
56 Jesreeli, Jokdeamu, Sanoa,
Jezraël, Jucadam, Zanoë,
57 Kaini, Gibeah àti Timna: ìlú mẹ́wàá àti àwọn ìletò wọn.
Accaïn, Gabaa et Thamna: dix villes et leurs villages.
58 Halhuli, Beti-Suri, Gedori,
Halhul, Bessur, Gédor,
59 Maarati, Beti-Anoti àti Eltekoni: ìlú mẹ́fà àti àwọn ìletò wọn.
Mareth, Béthanoth et Eltécon: six villes et leurs villages;
60 Kiriati-Baali (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu) àti Rabba ìlú méjì àti ìletò wọn.
Cariathbaal, qui est la même que Cariathiarim, ville des Forêts, et Arebba: deux villes et leurs villages;
61 Ní aginjù: Beti-Araba, Middini, Sekaka,
Dans le désert: Betharaba, Meddin, Sachacha,
62 Nibṣani, Ìlú Iyọ̀ àti En-Gedi: ìlú mẹ́fà àti ìletò wọn.
Nebsan, la ville de sel et Eugaddi: six villes et leurs villages.
63 Juda kò lè lé àwọn ọmọ Jebusi jáde, tí wọ́n ń gbé ní Jerusalẹmu. Àwọn ará Jebusi sì ń gbé pẹ̀lú àwọn ènìyàn Juda títí dí òní.
Quant au Jébuséen, habitant de Jérusalem, les enfants de Juda ne purent le détruire; et le Jébuséen a habité avec les enfants de Juda dans Jérusalem jusqu’au présent jour.

< Joshua 15 >