< Joshua 15 >
1 Ìpín fún ẹ̀yà Juda, ní agbo ilé agbo ilé, títí dé agbègbè Edomu, títí dé aginjù Sini ní òpin ìhà gúúsù.
La part échue par le sort à la tribu des enfants de Juda, selon leurs familles, fut à la frontière d'Édom, au désert de Tsin, vers le midi, à l'extrémité méridionale.
2 Ààlà wọn ní ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ láti etí òpin ìhà gúúsù Òkun Iyọ̀,
Leur frontière méridionale partait de l'extrémité de la mer Salée, depuis le bras qui regarde vers le midi;
3 ó sì gba gúúsù Akrabbimu lọ, títí dé Sini àti sí iwájú ìhà gúúsù Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà ó sì tún kọjá Hesroni lọ sí Adari, ó sì tún yípo yíká lọ sí Karka.
Et elle sortait au midi de la montée d'Akrabbim, passait vers Tsin, montait au midi de Kadès-Barnéa, passait à Hetsron, montait vers Addar, tournait vers Karkaa,
4 Ó tún kọjá lọ sí Asmoni, ó sì papọ̀ mọ́ Wadi ti Ejibiti, ó parí sí Òkun. Èyí ni ààlà wọn ní ìhà gúúsù.
Passait vers Atsmon, sortait au torrent d'Égypte; et la frontière aboutissait à la mer. Ce sera là, dit Josué, votre frontière du côté du midi.
5 Ààlà wọn ní ìhà ìlà-oòrùn ní Òkun Iyọ̀ títí dé ẹnu Jordani. Ààlà àríwá bẹ̀rẹ̀ láti etí òkun ní ẹnu Jordani,
Et la frontière vers l'orient était la mer Salée, jusqu'à l'embouchure du Jourdain; et la frontière de la région du nord partait du bras de mer qui est à l'embouchure du Jourdain.
6 ààlà náà sì tún dé Beti-Hogla, ó sì lọ sí ìhà àríwá Beti-Araba. Ààlà náà sì tún dé ibi Òkúta Bohani ti ọmọ Reubeni.
Et la frontière montait à Beth-Hogla, et passait au nord de Beth-Araba. Et la frontière montait à la pierre de Bohan, fils de Ruben.
7 Ààlà náà gòkè lọ títí dé Debiri láti àfonífojì Akori, ó sì yípadà sí àríwá Gilgali, èyí tí ń bẹ ní iwájú òkè Adummimu, tí ń bẹ ní ìhà gúúsù odò náà. Ó sì tẹ̀síwájú sí apá omi En-Ṣemeṣi, ó sì jáde sí En-Rogeli.
Puis la frontière montait vers Débir, du côté de la vallée d'Acor, et vers le nord, se dirigeant vers Guilgal, qui est vis-à-vis de la montée d'Adummim, au midi du torrent; la frontière passait ensuite près des eaux d'En-Shémèsh et aboutissait à En-Roguel.
8 Ààlà náà sì tún gòkè lọ sí àfonífojì Beni-Hinnomu ní ìhà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ gúúsù ti Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu). Ó sì gòkè lọ sí orí òkè tí ó wà lórí àfonífojì Hinnomu tí ń bẹ ní ìpẹ̀kun àfonífojì Refaimu ní ìhà àríwá.
De là la frontière montait par la vallée du fils de Hinnom, vers le côté méridional de Jébus, qui est Jérusalem. Ensuite la frontière s'élevait au sommet de la montagne qui est en face de la vallée de Hinnom, vers l'occident, et à l'extrémité de la vallée des Réphaïm, au nord.
9 Ààlà náà sì lọ láti orí òkè lọ sí ìsun omi Nefitoa, ó sì jáde sí ìlú òkè Efroni, ó sì lọ sí apá ìsàlẹ̀ Baalahi (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu).
Cette frontière s'étendait du sommet de la montagne vers la source des eaux de Nephthoach, et sortait vers les villes de la montagne d'Éphron; puis la frontière s'étendait à Baala, qui est Kirjath-Jéarim.
10 Ààlà tí ó yípo láti Baalahi lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn sí òkè Seiri, ó sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Jearimu (tí í ṣe, Kesaloni), ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beti-Ṣemeṣi, ó sì kọjá lọ sí Timna.
La frontière tournait ensuite de Baala à l'occident vers la montagne de Séir, et passait, vers le nord, à côté de la montagne de Jéarim qui est Késalon; puis elle descendait à Beth-Shémesh, et passait à Thimna.
11 Ààlà náà sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Ekroni, ó sì yípadà lọ sí Ṣikkeroni, ó sì yípadà lọ sí òkè Baalahi, ó sì dé Jabneeli, ààlà náà sì parí sí Òkun.
De là la frontière sortait du côté septentrional d'Ékron. Puis cette frontière s'étendait vers Shikron, passait par la montagne de Baala, et sortait à Jabnéel; et la frontière aboutissait à la mer.
12 Ààlà ìwọ̀-oòrùn sì jẹ́ agbègbè Òkun Ńlá. Ìwọ̀nyí ni ààlà àyíká ènìyàn Juda ní agbo ilé wọn.
Or, la frontière de l'occident était la grande mer et la côte. Telle fut, de tous les côtés, la frontière des enfants de Juda, selon leurs familles.
13 Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Olúwa pa fún Joṣua, ó fi ìpín fún Kalebu ọmọ Jefunne, ìpín ní Juda—Kiriati-Arba, tí í ṣe Hebroni. (Arba sì ní baba ńlá Anaki.)
On donna à Caleb, fils de Jephunné, une portion au milieu des enfants de Juda, selon le commandement de l'Éternel à Josué: savoir la cité d'Arba, père d'Anak. C'est Hébron.
14 Kalebu sì lé àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta jáde láti Hebroni; Ṣeṣai, Ahimani, àti Talmai, ìran Anaki.
Et Caleb en déposséda les trois fils d'Anak: Shéshaï, Ahiman et Thalmaï, enfants d'Anak.
15 Ó sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
De là il monta vers les habitants de Débir; et le nom de Débir était autrefois Kirjath-Sépher.
16 Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
Et Caleb dit: Je donnerai ma fille Acsa pour femme à celui qui battra Kirjath-Sépher, et la prendra.
17 Otnieli ọmọ Kenasi, arákùnrin Kalebu, sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
Alors Othniel, fils de Kénaz, frère de Caleb, la prit; et il lui donna pour femme sa fille Acsa.
18 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
Or il arriva qu'à son entrée chez Othniel, elle l'incita à demander un champ à son père. Et elle se jeta de dessus son âne, et Caleb lui dit: Qu'as-tu?
19 Ó sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
Et elle répondit: Donne-moi un présent; puisque tu m'as donné une terre du midi, donne-moi aussi des sources d'eaux. Et il lui donna les sources supérieures et les sources inférieures.
20 Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bi ìdílé wọn.
Tel fut l'héritage de la tribu des enfants de Juda, selon leurs familles.
21 Ìlú ìpẹ̀kun gúúsù ti ẹ̀yà Juda ní gúúsù ní ààlà Edomu nìwọ̀nyí: Kabṣeeli, Ederi, Jaguri,
Les villes à l'extrémité de la tribu des enfants de Juda, vers la frontière d'Édom, au midi, furent Kabtséel, Éder, Jagur,
23 Kedeṣi, Hasori, Itina,
Kédès, Hatsor, Jithnan,
24 Sifi, Telemu, Bealoti,
Ziph, Télem, Béaloth,
25 Hasori Hadatta, Kerioti Hesroni (tí í ṣe Hasori),
Hatsor-Hadattha, Kérijoth-Hetsron, qui est Hatsor,
27 Hasari Gada, Heṣmoni, Beti-Peleti,
Hatsar-gadda, Heshmon, Beth-Palet,
28 Hasari-Ṣuali, Beerṣeba, Bisiotia,
Hatsar-Shual, Béer-Shéba, Bizjothja,
30 Eltoladi, Kesili, Horma,
Eltholad, Késil, Horma,
31 Siklagi, Madmana, Sansanna,
Tsiklag, Madmanna, Sansanna,
32 Leboati, Ṣilhimu, Aini àti Rimoni, àpapọ̀ ìlú mọ́kàndínlọ́gbọ̀n àti àwọn ìletò wọn.
Lébaoth, Shilhim, Aïn, et Rimmon; en tout vingt-neuf villes et leurs villages.
33 Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹsẹ̀ òkè: Eṣtaoli, Sora, Aṣna,
Dans la plaine, Eshthaol, Tsoréa, Ashna,
34 Sanoa, Eni-Gannimu, Tapua, Enamu,
Zanoach, En-Gannim, Thappuach, Énam,
35 Jarmatu, Adullamu, Soko, Aseka,
Jarmuth, Adullam, Soco, Azéka,
36 Ṣaaraimu, Adittaimu àti Gedera (tàbí Gederotaimu). Ìlú mẹ́rìnlá àti àwọn ìletò wọn.
Shaaraïm, Adithaïm, Guédéra, et Guédérothaïm, quatorze villes et leurs villages;
37 Senani, Hadaṣa, Migdali Gadi,
Tsénan, Hadasha, Migdal-Gad,
38 Dileani, Mispa, Jokteeli,
Dilan, Mitspé, Jokthéel,
39 Lakiṣi, Boskati, Egloni,
Lakis, Botskath, Églon,
40 Kabboni, Lamasi, Kitlisi,
Cabbon, Lachmas, Kithlish,
41 Gederoti, Beti-Dagoni, Naama àti Makkeda, ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
Guédéroth, Beth-Dagon, Naama, et Makkéda; seize villes et leurs villages;
44 Keila, Aksibu àti Meraṣa: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò wọn.
Keïla, Aczib et Marésha; neuf villes et leurs villages;
45 Ekroni, pẹ̀lú ibùgbé àti àwọn ìletò rẹ̀ tó yí i ká,
Ékron, les villes de son ressort, et ses villages;
46 ìwọ̀-oòrùn Ekroni, gbogbo èyí tí ń bẹ nítòsí Aṣdodu, pẹ̀lú àwọn ìletò wọn,
Depuis Ékron, et à l'occident, toutes celles qui sont dans le voisinage d'Asdod, et leurs villages;
47 Aṣdodu, agbègbè ìlú rẹ̀ àti ìletò; àti Gasa, ìlú rẹ̀ àti ìletò, títí ó fi dé odò Ejibiti àti agbègbè Òkun Ńlá.
Asdod, les villes de son ressort, et ses villages; Gaza, les villes de son ressort, et ses villages, jusqu'au torrent d'Égypte, et à la grande mer et son rivage.
48 Ní ilẹ̀ òkè náà: Ṣamiri, Jattiri, Soko,
Et dans la montagne, Shamir, Jatthir, Soco,
49 Dannah, Kiriati-Sannnah (tí í ṣe Debiri),
Danna, Kirjath-Sanna, qui est Débir,
50 Anabu, Eṣitemo, Animu,
Anab, Eshthemo, Anim,
51 Goṣeni, Holoni àti Giloni, ìlú mọ́kànlá àti ìletò wọn.
Gossen, Holon, et Guilo; onze villes et leurs villages;
53 Janimu, Beti-Tapua, Afeka,
Janum, Beth-Thappuach, Aphéka,
54 Hamuta, Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) àti Ṣiori: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò rẹ̀
Humta, Kirjath-Arba, qui est Hébron, et Tsior; neuf villes et leurs villages;
55 Maoni, Karmeli, Sifi, Jutta,
Maon, Carmel, Ziph, Juta,
56 Jesreeli, Jokdeamu, Sanoa,
Jizréel, Jokdéam, Zanoach,
57 Kaini, Gibeah àti Timna: ìlú mẹ́wàá àti àwọn ìletò wọn.
Kaïn, Guibéa, et Thimna; dix villes et leurs villages;
58 Halhuli, Beti-Suri, Gedori,
Halhul, Beth-Tsur, Guédor,
59 Maarati, Beti-Anoti àti Eltekoni: ìlú mẹ́fà àti àwọn ìletò wọn.
Maarath, Beth-Anoth, et Elthekon; six villes et leurs villages;
60 Kiriati-Baali (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu) àti Rabba ìlú méjì àti ìletò wọn.
Kirjath-Baal, qui est Kirjath-Jéarim, et Rabba; deux villes et leurs villages;
61 Ní aginjù: Beti-Araba, Middini, Sekaka,
Dans le désert, Beth-Araba, Middin, Secaca,
62 Nibṣani, Ìlú Iyọ̀ àti En-Gedi: ìlú mẹ́fà àti ìletò wọn.
Nibshan, et Ir-Hammélach (la ville du sel), et En-Guédi; six villes et leurs villages.
63 Juda kò lè lé àwọn ọmọ Jebusi jáde, tí wọ́n ń gbé ní Jerusalẹmu. Àwọn ará Jebusi sì ń gbé pẹ̀lú àwọn ènìyàn Juda títí dí òní.
Or les enfants de Juda ne purent déposséder les Jébusiens qui habitaient à Jérusalem, et les Jébusiens ont habité avec les enfants de Juda à Jérusalem jusqu'à ce jour.