< Joshua 15 >

1 Ìpín fún ẹ̀yà Juda, ní agbo ilé agbo ilé, títí dé agbègbè Edomu, títí dé aginjù Sini ní òpin ìhà gúúsù.
Ce fut ici le sort de la Tribu des enfants de Juda selon leurs familles. Aux confins d'Edom, le désert de Tsin vers le Midi, fut le dernier bout [de leurs pays] vers le Midi.
2 Ààlà wọn ní ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ láti etí òpin ìhà gúúsù Òkun Iyọ̀,
Tellement que leur frontière du côté du Midi fut le dernier bout de la mer salée, depuis le bras qui regarde vers le Midi.
3 ó sì gba gúúsù Akrabbimu lọ, títí dé Sini àti sí iwájú ìhà gúúsù Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà ó sì tún kọjá Hesroni lọ sí Adari, ó sì tún yípo yíká lọ sí Karka.
Et elle devait sortir vers le Midi de la montée de Hakrabbim, et passer à Tsin; et, montant du Midi de Kadès-barné passer à Hetsron; puis montant vers Addar se tourner vers Karkah;
4 Ó tún kọjá lọ sí Asmoni, ó sì papọ̀ mọ́ Wadi ti Ejibiti, ó parí sí Òkun. Èyí ni ààlà wọn ní ìhà gúúsù.
Puis passant vers Hatsmon, sortir au torrent d'Egypte; tellement que les extrémités, de cette frontière devaient se rendre à la mer. Ce sera là, [dit Josué], votre frontière du côté du Midi.
5 Ààlà wọn ní ìhà ìlà-oòrùn ní Òkun Iyọ̀ títí dé ẹnu Jordani. Ààlà àríwá bẹ̀rẹ̀ láti etí òkun ní ẹnu Jordani,
Et la frontière vers l'Orient sera la mer salée jusqu'au bout du Jourdain; et la frontière du côté du Septentrion sera depuis le bras de la mer, qui est au bout du Jourdain.
6 ààlà náà sì tún dé Beti-Hogla, ó sì lọ sí ìhà àríwá Beti-Araba. Ààlà náà sì tún dé ibi Òkúta Bohani ti ọmọ Reubeni.
Et cette frontière montera jusqu'à Bethhogla, et passera du côté du Septentrion de Bethharaba; et cette frontière montera jusqu'à la pierre de Bohan, fils de Ruben.
7 Ààlà náà gòkè lọ títí dé Debiri láti àfonífojì Akori, ó sì yípadà sí àríwá Gilgali, èyí tí ń bẹ ní iwájú òkè Adummimu, tí ń bẹ ní ìhà gúúsù odò náà. Ó sì tẹ̀síwájú sí apá omi En-Ṣemeṣi, ó sì jáde sí En-Rogeli.
Puis cette frontière montera vers Débir, depuis la vallée de Hacor, même vers le Septentrion, regardant Guilgal; laquelle est vis-à-vis de la montée d Adummim, qui est au Midi du torrent; puis cette frontière passera vers les eaux de Hen-semès, et ses extrémités se rendront à Hen-roguel.
8 Ààlà náà sì tún gòkè lọ sí àfonífojì Beni-Hinnomu ní ìhà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ gúúsù ti Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu). Ó sì gòkè lọ sí orí òkè tí ó wà lórí àfonífojì Hinnomu tí ń bẹ ní ìpẹ̀kun àfonífojì Refaimu ní ìhà àríwá.
Puis cette frontière montera par la vallée du fils de Hinnom, jusqu'au côté de Jébusi vers le Midi, qui est Jérusalem; puis cette frontière montera jusqu'au sommet de la montagne, qui est vis-à-vis de la vallée de Hinnom, vers l'Occident, [et] qui est au bout de la vallée des Réphaïms, vers le Septentrion.
9 Ààlà náà sì lọ láti orí òkè lọ sí ìsun omi Nefitoa, ó sì jáde sí ìlú òkè Efroni, ó sì lọ sí apá ìsàlẹ̀ Baalahi (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu).
Et cette frontière s'alignera depuis le sommet de la montagne jusqu'à la fontaine des eaux de Nephtoah, et sortira vers les villes de la montagne de Héphron; puis cette frontière s'alignera à Bahala, qui est Kirjath-jéharim.
10 Ààlà tí ó yípo láti Baalahi lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn sí òkè Seiri, ó sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Jearimu (tí í ṣe, Kesaloni), ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beti-Ṣemeṣi, ó sì kọjá lọ sí Timna.
Et cette frontière se tournera depuis Bahala vers l'Occident, jusqu'à la montagne de Séhir; puis elle passera jusqu'au côté de la montagne de Jeharim vers le Septentrion, qui [est] Késalon; puis descendant à Beth-semes, elle passera à Timna.
11 Ààlà náà sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Ekroni, ó sì yípadà lọ sí Ṣikkeroni, ó sì yípadà lọ sí òkè Baalahi, ó sì dé Jabneeli, ààlà náà sì parí sí Òkun.
Et cette frontière sortira jusqu'au côté de Hekron, vers le Septentrion, et cette frontière s'alignera vers Sikkeron; puis ayant passé la montagne de Bahala, elle sortira à Jabnéël; tellement que les extrémités de cette frontière se rendront à la mer.
12 Ààlà ìwọ̀-oòrùn sì jẹ́ agbègbè Òkun Ńlá. Ìwọ̀nyí ni ààlà àyíká ènìyàn Juda ní agbo ilé wọn.
Or la frontière du côté de l'Occident sera ce qui est vers la grande mer, et ses limites. Ce furent les frontières des enfants de Juda de tous les côtés, selon leurs familles.
13 Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Olúwa pa fún Joṣua, ó fi ìpín fún Kalebu ọmọ Jefunne, ìpín ní Juda—Kiriati-Arba, tí í ṣe Hebroni. (Arba sì ní baba ńlá Anaki.)
Au reste on avait donné à Caleb, fils de Jéphunné, une portion au milieu des enfants de Juda, suivant le commandement de l'Eternel fait à Josué, [savoir] Kirjath-Arbah, [or Arbah était] père de Hanak; [et Kirjath-Arbah] c'est Hébron.
14 Kalebu sì lé àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta jáde láti Hebroni; Ṣeṣai, Ahimani, àti Talmai, ìran Anaki.
Et Caleb déposséda de là les trois fils de Hanak, [savoir] Sesaï, Ahiman, et Talmaï, enfants de Hanak.
15 Ó sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
Et de là il monta vers les habitants de Débir, dont le nom était auparavant Kirjath-sépher.
16 Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
Et Caleb dit: Je donnerai ma fille Hacsa pour femme à celui qui battra Kirjath-sépher, et la prendra.
17 Otnieli ọmọ Kenasi, arákùnrin Kalebu, sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
Et Hothniel fils de Kénaz, frère de Caleb, la prit; et [Caleb] lui donna sa fille Hacsa pour femme.
18 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
Et il arriva que comme elle s'en allait, elle l'incita à demander à son père un champ; puis elle descendit impétueusement de dessus son âne, et Caleb lui dit: Qu'as-tu?
19 Ó sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
Et elle répondit: Donne-moi un présent; puisque tu m'as donné une terre sèche, donne-moi aussi des sources d'eau. Et il lui donna les fontaines de dessus et les fontaines de dessous.
20 Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bi ìdílé wọn.
C'est ici l'héritage de la Tribu des enfants de Juda selon leurs familles.
21 Ìlú ìpẹ̀kun gúúsù ti ẹ̀yà Juda ní gúúsù ní ààlà Edomu nìwọ̀nyí: Kabṣeeli, Ederi, Jaguri,
Les villes de l'extrémité de la Tribu des enfants de Juda près des limites d'Edom, tirant vers le Midi, furent Kabtséel, Héder, Jagur,
22 Kina, Dimona, Adada,
Kina, Dimona, Hadhada,
23 Kedeṣi, Hasori, Itina,
Kedès, Hatsor, Jithnan,
24 Sifi, Telemu, Bealoti,
Ziph, Télem, Béhaloth,
25 Hasori Hadatta, Kerioti Hesroni (tí í ṣe Hasori),
Hatsor, Hadatta, Kérijoth, Hetsron qui [est] Hatsor,
26 Amamu, Ṣema, Molada,
Amam, Semah, Molada,
27 Hasari Gada, Heṣmoni, Beti-Peleti,
Hatsar-gadda, Hesmon, Beth-pelet,
28 Hasari-Ṣuali, Beerṣeba, Bisiotia,
Hatsar-suhal, Béersebah, Bizjotheja,
29 Baalahi, Limu, Esemu,
Bahala, Hijim, Hetsem,
30 Eltoladi, Kesili, Horma,
Eltolad, Kesil, Hormah,
31 Siklagi, Madmana, Sansanna,
Tsiklag, Madmanna, Sansanna,
32 Leboati, Ṣilhimu, Aini àti Rimoni, àpapọ̀ ìlú mọ́kàndínlọ́gbọ̀n àti àwọn ìletò wọn.
Lebaoth, Silhim, Hajin et Rimmon; en tout vingt-neuf villes, et leurs villages.
33 Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹsẹ̀ òkè: Eṣtaoli, Sora, Aṣna,
Dans la plaine, Estaol, Tsorha, Asna,
34 Sanoa, Eni-Gannimu, Tapua, Enamu,
Zanoah, Hengannim, Tappuah, Hénam,
35 Jarmatu, Adullamu, Soko, Aseka,
Jarmuth, Hadullam, Soco, Hazeka,
36 Ṣaaraimu, Adittaimu àti Gedera (tàbí Gederotaimu). Ìlú mẹ́rìnlá àti àwọn ìletò wọn.
Saharajim, Hadithajim, Guedera et Guederothajim; quatorze villes, et leurs villages.
37 Senani, Hadaṣa, Migdali Gadi,
Tsénan, Hedasa, Migdal-Gad,
38 Dileani, Mispa, Jokteeli,
Dilhan, Mitspé, Jokthéël,
39 Lakiṣi, Boskati, Egloni,
Lakis, Botskath, Héglon,
40 Kabboni, Lamasi, Kitlisi,
Cabbon, Lahmas, Kithlis,
41 Gederoti, Beti-Dagoni, Naama àti Makkeda, ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
Guederoth, Beth-Dahon, Nahama, et Makkéda; seize villes, et leurs villages.
42 Libina, Eteri, Aṣani,
Libna, Hether, Hasan,
43 Hifita, Aṣna, Nesibu,
Jiphtah, Asna, Netsib,
44 Keila, Aksibu àti Meraṣa: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò wọn.
Kehila, Aczib et Maresa; neuf villes, et leurs villages.
45 Ekroni, pẹ̀lú ibùgbé àti àwọn ìletò rẹ̀ tó yí i ká,
Hekron, et les villes de son ressort, et ses villages.
46 ìwọ̀-oòrùn Ekroni, gbogbo èyí tí ń bẹ nítòsí Aṣdodu, pẹ̀lú àwọn ìletò wọn,
Depuis Hekron, tirant même vers la mer, toutes celles qui [sont] joignant le ressort d'Asdod, et leurs villages.
47 Aṣdodu, agbègbè ìlú rẹ̀ àti ìletò; àti Gasa, ìlú rẹ̀ àti ìletò, títí ó fi dé odò Ejibiti àti agbègbè Òkun Ńlá.
Asdod, les villes de son ressort, et ses villages, Gaza, les villes de son ressort, et ses villages, jusqu'au torrent d'Egypte; et la grande mer, et ses limites.
48 Ní ilẹ̀ òkè náà: Ṣamiri, Jattiri, Soko,
Et dans la montagne, Samir, Jattir, Soco,
49 Dannah, Kiriati-Sannnah (tí í ṣe Debiri),
Danna, Kirjath-sanna, qui est Débir,
50 Anabu, Eṣitemo, Animu,
Hanab, Estemo, Hanim,
51 Goṣeni, Holoni àti Giloni, ìlú mọ́kànlá àti ìletò wọn.
Gosen, Holon, et Guilo; onze villes et leurs villages.
52 Arabu, Duma, Eṣani,
Arab, Duma, Hesehan,
53 Janimu, Beti-Tapua, Afeka,
Janum, Beth-tappuah, Apheka,
54 Hamuta, Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) àti Ṣiori: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò rẹ̀
Humta, Kirjath-Arbah, qui est Hébron, et Tsihor; neuf villes, et leurs villages.
55 Maoni, Karmeli, Sifi, Jutta,
Mahon, Carmel, Ziph, Juta,
56 Jesreeli, Jokdeamu, Sanoa,
Jizrehel, Jokdeham, Zanoah,
57 Kaini, Gibeah àti Timna: ìlú mẹ́wàá àti àwọn ìletò wọn.
Kajin, Guibha, et Timna; dix villes, et leurs villages.
58 Halhuli, Beti-Suri, Gedori,
Halhul, Beth-tsur, Guédor,
59 Maarati, Beti-Anoti àti Eltekoni: ìlú mẹ́fà àti àwọn ìletò wọn.
Maharath, Beth-hanoth, et Eltekon; six villes, et leurs villages.
60 Kiriati-Baali (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu) àti Rabba ìlú méjì àti ìletò wọn.
Kirjath-bahal, qui est Kirjath-jéharim, et Rabba; deux villes, et leurs villages.
61 Ní aginjù: Beti-Araba, Middini, Sekaka,
Au désert, Beth-haraba, Middin, Secaca,
62 Nibṣani, Ìlú Iyọ̀ àti En-Gedi: ìlú mẹ́fà àti ìletò wọn.
Nibsan, et la ville du sel, et Henguédi: six villes et leurs villages.
63 Juda kò lè lé àwọn ọmọ Jebusi jáde, tí wọ́n ń gbé ní Jerusalẹmu. Àwọn ará Jebusi sì ń gbé pẹ̀lú àwọn ènìyàn Juda títí dí òní.
Au reste, les enfants de Juda ne purent point déposséder les Jébusiens qui habitaient à Jérusalem; c'est pourquoi le Jébusien a demeuré avec les enfants de Juda à Jérusalem jusqu'à ce jour.

< Joshua 15 >