< Joshua 15 >

1 Ìpín fún ẹ̀yà Juda, ní agbo ilé agbo ilé, títí dé agbègbè Edomu, títí dé aginjù Sini ní òpin ìhà gúúsù.
So then the boundary of the tribe of the sons of Judah, by their families, —reached unto the boundary of Edom, the desert of Zin southward, on the extreme south;
2 Ààlà wọn ní ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ láti etí òpin ìhà gúúsù Òkun Iyọ̀,
so their south boundary beginneth at the end of the Salt Sea, —from the bay that turneth to the south;
3 ó sì gba gúúsù Akrabbimu lọ, títí dé Sini àti sí iwájú ìhà gúúsù Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà ó sì tún kọjá Hesroni lọ sí Adari, ó sì tún yípo yíká lọ sí Karka.
and goeth forth on the south of the cliffs of Akrabbim, and crosseth over to Zin, and goeth up on the south of Kadesh-barnea, —and passeth over by Hezron, and goeth up to Addar, and turneth round to Karka;
4 Ó tún kọjá lọ sí Asmoni, ó sì papọ̀ mọ́ Wadi ti Ejibiti, ó parí sí Òkun. Èyí ni ààlà wọn ní ìhà gúúsù.
and passeth over to Azmon, and goeth forth at the ravine of Egypt, and so the extensions of the boundary are to the sea. This, shall be your south boundary.
5 Ààlà wọn ní ìhà ìlà-oòrùn ní Òkun Iyọ̀ títí dé ẹnu Jordani. Ààlà àríwá bẹ̀rẹ̀ láti etí òkun ní ẹnu Jordani,
And, a boundary eastward, is the Salt Sea, as far as the end of the Jordan. And, the boundary on the north side, is from the bay of the sea, from the end of the Jordan.
6 ààlà náà sì tún dé Beti-Hogla, ó sì lọ sí ìhà àríwá Beti-Araba. Ààlà náà sì tún dé ibi Òkúta Bohani ti ọmọ Reubeni.
And the boundary goeth up Beth-hoglah, and passeth over, on the north, by Beth-arabah, —and the boundary goeth up by the Stone of Bohan, son of Reuben;
7 Ààlà náà gòkè lọ títí dé Debiri láti àfonífojì Akori, ó sì yípadà sí àríwá Gilgali, èyí tí ń bẹ ní iwájú òkè Adummimu, tí ń bẹ ní ìhà gúúsù odò náà. Ó sì tẹ̀síwájú sí apá omi En-Ṣemeṣi, ó sì jáde sí En-Rogeli.
and the boundary goeth up towards Debir, out of the vale of Achor, then northward, turning unto Gilgal, which is over against the ascent of Adummim, which is on the south side of the ravine, —then the boundary passeth over unto the waters of En-shemesh, and so the extensions thereof are unto En-rogel:
8 Ààlà náà sì tún gòkè lọ sí àfonífojì Beni-Hinnomu ní ìhà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ gúúsù ti Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu). Ó sì gòkè lọ sí orí òkè tí ó wà lórí àfonífojì Hinnomu tí ń bẹ ní ìpẹ̀kun àfonífojì Refaimu ní ìhà àríwá.
then ascendeth the boundary by the valley of the son of Hinnom, to the side of the Jebusite, on the south, the same, is Jerusalem, —and the boundary goeth up unto the top of the mountain which faceth the valley of Hinnom, to the west, which is at the end of the Vale of Giants, northwards;
9 Ààlà náà sì lọ láti orí òkè lọ sí ìsun omi Nefitoa, ó sì jáde sí ìlú òkè Efroni, ó sì lọ sí apá ìsàlẹ̀ Baalahi (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu).
and the boundary turneth round, from the top of the mountain, unto the fountain of the waters of Nephtoah, and goeth out unto the cities of Mount Ephron, —then the boundary turneth round to Baalah, the same, is Kiriath-jearim;
10 Ààlà tí ó yípo láti Baalahi lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn sí òkè Seiri, ó sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Jearimu (tí í ṣe, Kesaloni), ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beti-Ṣemeṣi, ó sì kọjá lọ sí Timna.
then the boundary goeth round from Baalah westward, unto Mount Seir, and passeth over unto the slope of Mount Yearim, on the north, the same, is Chesalon, —and descendeth Bethshemesh, and passeth over Timnah;
11 Ààlà náà sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Ekroni, ó sì yípadà lọ sí Ṣikkeroni, ó sì yípadà lọ sí òkè Baalahi, ó sì dé Jabneeli, ààlà náà sì parí sí Òkun.
then the boundary goeth forth unto the side of Ekron, northward, then the boundary turneth round towards Shikkeron, and crosseth over Mount Baalah, and goeth out at Jabneel, —and the extensions of the boundary are to the sea.
12 Ààlà ìwọ̀-oòrùn sì jẹ́ agbègbè Òkun Ńlá. Ìwọ̀nyí ni ààlà àyíká ènìyàn Juda ní agbo ilé wọn.
And, as a west boundary, are the great sea and coast. This, is the boundary of the sons of Judah, round about, by their families.
13 Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Olúwa pa fún Joṣua, ó fi ìpín fún Kalebu ọmọ Jefunne, ìpín ní Juda—Kiriati-Arba, tí í ṣe Hebroni. (Arba sì ní baba ńlá Anaki.)
And, to Caleb, son of Jephunneh, gave he a portion, in the midst of the sons of Judah, at the bidding of Yahweh, by Joshua, —even the City of Arba, father of Anak, the same, is Hebron.
14 Kalebu sì lé àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta jáde láti Hebroni; Ṣeṣai, Ahimani, àti Talmai, ìran Anaki.
And Caleb dispossessed from thence, the three sons of Anak, —Sheshai, and Ahiman, and Talmai, the descendants of Anak.
15 Ó sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
And he went up from thence, against the inhabitants of Debir, —now, the name of Debir, formerly, was Kiriath-sepher.
16 Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
Then said Caleb, He that smiteth Kiriath-sepher, and captureth it, I will give unto him Achsah, my daughter, to wife.
17 Otnieli ọmọ Kenasi, arákùnrin Kalebu, sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
And Othniel son of Kenaz, brother of Caleb, captured it, —so he gave unto him Achsah, his daughter, to wife.
18 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
And it came to pass, when she came, that she moved him to ask of her father a field, and, when she alighted from off the ass, Caleb said unto her—What aileth thee?
19 Ó sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
And she said—Give me a present, for, dry land, hast thou given me, therefore must thou give me, pools of water. So he gave her upper pools and lower pools.
20 Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bi ìdílé wọn.
This, is the inheritance of the tribe of the sons of Judah, by their families.
21 Ìlú ìpẹ̀kun gúúsù ti ẹ̀yà Juda ní gúúsù ní ààlà Edomu nìwọ̀nyí: Kabṣeeli, Ederi, Jaguri,
And the uttermost cities of the tribe of the sons of Judah, towards the boundary of Edom in the south, were, —Kabzeel and Eder, and Jagur,
22 Kina, Dimona, Adada,
and Kinah and Dimonah, and Adadah, —
23 Kedeṣi, Hasori, Itina,
and Kedesh and Hazor, and Ithnan,
24 Sifi, Telemu, Bealoti,
Ziph and Talem, and Bealoth,
25 Hasori Hadatta, Kerioti Hesroni (tí í ṣe Hasori),
and Hazor-hadattah and Kerioth-hezron, the same, is Hazor;
26 Amamu, Ṣema, Molada,
Amam and Shema, and Moladah,
27 Hasari Gada, Heṣmoni, Beti-Peleti,
and Hazar-gaddah and Heshmon, and Beth-pelet.
28 Hasari-Ṣuali, Beerṣeba, Bisiotia,
and Hazarshual and Beer-sheba, with the hamlets thereof,
29 Baalahi, Limu, Esemu,
Baalah and Iyyim, and Ezem,
30 Eltoladi, Kesili, Horma,
and Eltolad and Chesil, and Hormah,
31 Siklagi, Madmana, Sansanna,
and Ziklag and Madmannah, and Sansannah,
32 Leboati, Ṣilhimu, Aini àti Rimoni, àpapọ̀ ìlú mọ́kàndínlọ́gbọ̀n àti àwọn ìletò wọn.
and Lebaoth and Shilhim, and En-rimmon, —all the cities are twenty-nine, with their villages.
33 Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹsẹ̀ òkè: Eṣtaoli, Sora, Aṣna,
In the lowland, —Eshtaol and Zorah, and Ashnah,
34 Sanoa, Eni-Gannimu, Tapua, Enamu,
and Zanoah and En-gannim, Tappuah, and Enam;
35 Jarmatu, Adullamu, Soko, Aseka,
Jarmuth, and Adullam, Socoh, and Azekah;
36 Ṣaaraimu, Adittaimu àti Gedera (tàbí Gederotaimu). Ìlú mẹ́rìnlá àti àwọn ìletò wọn.
and Shaaraim, and Adithaim, and Gederah, and Gederothaim, —fourteen cities, with their villages.
37 Senani, Hadaṣa, Migdali Gadi,
Zenan and Hadashah, and Migdal-gad,
38 Dileani, Mispa, Jokteeli,
and Dilan and Mizpeh, and Joktheel,
39 Lakiṣi, Boskati, Egloni,
Lachish and Bozkath, and Eglon,
40 Kabboni, Lamasi, Kitlisi,
and Cabbon and Lahmas, and Chithlish,
41 Gederoti, Beti-Dagoni, Naama àti Makkeda, ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
and Gederoth, Beth-dagon and Naamah, and Makkedah, —sixteen cities, with their villages.
42 Libina, Eteri, Aṣani,
Libnah and Ether, and Ashan,
43 Hifita, Aṣna, Nesibu,
and Iphtah and Ashnah, and Nezib,
44 Keila, Aksibu àti Meraṣa: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò wọn.
and Keilah and Achzib, and Mareshah, —nine cities, with their villages.
45 Ekroni, pẹ̀lú ibùgbé àti àwọn ìletò rẹ̀ tó yí i ká,
Ekron with her towns, and her villages.
46 ìwọ̀-oòrùn Ekroni, gbogbo èyí tí ń bẹ nítòsí Aṣdodu, pẹ̀lú àwọn ìletò wọn,
From Ekron, even unto the sea, —all that were by the side of Ashdod with their villages.
47 Aṣdodu, agbègbè ìlú rẹ̀ àti ìletò; àti Gasa, ìlú rẹ̀ àti ìletò, títí ó fi dé odò Ejibiti àti agbègbè Òkun Ńlá.
Ashdod, her towns and her villages. Gaza, her towns and her villages, as far as the ravine of Egypt, —and the great sea and coast.
48 Ní ilẹ̀ òkè náà: Ṣamiri, Jattiri, Soko,
And in the hill-country, —Shamir and Jattir, and Socoh,
49 Dannah, Kiriati-Sannnah (tí í ṣe Debiri),
and Dannah and Kiriath-sannah, the same, is Debir,
50 Anabu, Eṣitemo, Animu,
and Anab and Eshtemoh, and Anim,
51 Goṣeni, Holoni àti Giloni, ìlú mọ́kànlá àti ìletò wọn.
and Goshen and Holon, and Giloh, —eleven cities, with their villages.
52 Arabu, Duma, Eṣani,
Arab and Rumah and Eshan,
53 Janimu, Beti-Tapua, Afeka,
and Janim and Beth-tappuah and Aphekah,
54 Hamuta, Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) àti Ṣiori: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò rẹ̀
and Humtah, and Kiriath-arba, the same, is Hebron, and Zior, —nine cities, with their villages.
55 Maoni, Karmeli, Sifi, Jutta,
Maon, Carmel, and Ziph and Jutah,
56 Jesreeli, Jokdeamu, Sanoa,
and Jezreel and Jokdeam, and Zanoah,
57 Kaini, Gibeah àti Timna: ìlú mẹ́wàá àti àwọn ìletò wọn.
Kain, Gibeah and Timnah, —ten cities, with their villages.
58 Halhuli, Beti-Suri, Gedori,
Halhul, Beth-zur, and Gedor,
59 Maarati, Beti-Anoti àti Eltekoni: ìlú mẹ́fà àti àwọn ìletò wọn.
and Maarath and Beth-anoth, and Eltekon, —six cities, with their villages.
60 Kiriati-Baali (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu) àti Rabba ìlú méjì àti ìletò wọn.
Kiriath-baal, the same, is Kiriath-jearim, and Rabbah, —two cities, with their villages.
61 Ní aginjù: Beti-Araba, Middini, Sekaka,
In the desert, —Beth-arabah, Middin, and Secacah,
62 Nibṣani, Ìlú Iyọ̀ àti En-Gedi: ìlú mẹ́fà àti ìletò wọn.
and Nibshan and the City of Salt, and En-gedi, —six cities, with their villages.
63 Juda kò lè lé àwọn ọmọ Jebusi jáde, tí wọ́n ń gbé ní Jerusalẹmu. Àwọn ará Jebusi sì ń gbé pẹ̀lú àwọn ènìyàn Juda títí dí òní.
But, as for the Jebusites, the inhabitants of Jerusalem, the sons of Judah could not dispossess them, —so the Jebusites have dwelt with the sons of Judah, in Jerusalem, until this day.

< Joshua 15 >