< Joshua 15 >

1 Ìpín fún ẹ̀yà Juda, ní agbo ilé agbo ilé, títí dé agbègbè Edomu, títí dé aginjù Sini ní òpin ìhà gúúsù.
And the lot for the tribe of the children of Judah after their families came by the border of Edom, with the wilderness of Zin, southward, as the uttermost southern boundary.
2 Ààlà wọn ní ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ láti etí òpin ìhà gúúsù Òkun Iyọ̀,
And their southern boundary was from the end of the salt sea, from the bay that bendeth southward:
3 ó sì gba gúúsù Akrabbimu lọ, títí dé Sini àti sí iwájú ìhà gúúsù Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà ó sì tún kọjá Hesroni lọ sí Adari, ó sì tún yípo yíká lọ sí Karka.
And it went out to the south of the heights of 'Akrabbim, and passed along to Zin, and ascended up on the south side unto Kadesh-barnea, and passed along to Chezron, and went up to Adar, and fetched a compass to Karka';
4 Ó tún kọjá lọ sí Asmoni, ó sì papọ̀ mọ́ Wadi ti Ejibiti, ó parí sí Òkun. Èyí ni ààlà wọn ní ìhà gúúsù.
And it passed on toward 'Azmon, and went out unto the river of Egypt; and the terminations of the boundary were at the sea: this shall be your southern boundary.
5 Ààlà wọn ní ìhà ìlà-oòrùn ní Òkun Iyọ̀ títí dé ẹnu Jordani. Ààlà àríwá bẹ̀rẹ̀ láti etí òkun ní ẹnu Jordani,
And the east boundary was the salt sea, unto the end of the Jordan. And the boundary in the north quarter was from the bay of the sea at the end of the Jordan;
6 ààlà náà sì tún dé Beti-Hogla, ó sì lọ sí ìhà àríwá Beti-Araba. Ààlà náà sì tún dé ibi Òkúta Bohani ti ọmọ Reubeni.
And the boundary went up to Beth-choglah, and passed along by the north of Beth'arabah; and the boundary went up to Ebenbohan the son of Reuben;
7 Ààlà náà gòkè lọ títí dé Debiri láti àfonífojì Akori, ó sì yípadà sí àríwá Gilgali, èyí tí ń bẹ ní iwájú òkè Adummimu, tí ń bẹ ní ìhà gúúsù odò náà. Ó sì tẹ̀síwájú sí apá omi En-Ṣemeṣi, ó sì jáde sí En-Rogeli.
And the boundary went up toward Debir from the Valley of 'Achor, and at the north it bent toward Gilgal, that is opposite the heights of Adummim, which is on the south side of the valley; and the boundary passed toward the waters of 'En-shemesh, and its terminations were at En-rogel;
8 Ààlà náà sì tún gòkè lọ sí àfonífojì Beni-Hinnomu ní ìhà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ gúúsù ti Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu). Ó sì gòkè lọ sí orí òkè tí ó wà lórí àfonífojì Hinnomu tí ń bẹ ní ìpẹ̀kun àfonífojì Refaimu ní ìhà àríwá.
And the boundary went up to the valley of the son of Hinnom unto the south side of the Jebusite, the same is Jerusalem; and the boundary went up to the top of the mount that lieth before the valley of Hinnom westward, which is at the end of the valley of Rephaim northward;
9 Ààlà náà sì lọ láti orí òkè lọ sí ìsun omi Nefitoa, ó sì jáde sí ìlú òkè Efroni, ó sì lọ sí apá ìsàlẹ̀ Baalahi (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu).
And the boundary extended from the top of the mount unto the spring of the waters of Nephtoach, and went out to the cities of mount 'Ephron; and the boundary extended to Ba'alah, which is Kiryath-ye'arim;
10 Ààlà tí ó yípo láti Baalahi lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn sí òkè Seiri, ó sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Jearimu (tí í ṣe, Kesaloni), ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beti-Ṣemeṣi, ó sì kọjá lọ sí Timna.
And the boundary compassed from Ba'alah westward unto mount Seir, and passed along unto the side of mount Ye'arim, which is Kessalon, on the north side, and went down to Beth-shemesh, and passed on to Timnah;
11 Ààlà náà sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Ekroni, ó sì yípadà lọ sí Ṣikkeroni, ó sì yípadà lọ sí òkè Baalahi, ó sì dé Jabneeli, ààlà náà sì parí sí Òkun.
And the boundary went out unto the side of 'Ekron northward; and the boundary extended to Shikron, and passed along to the mount of Ba'alah, and went out unto Yabneel; and the terminations of the boundary were at the sea.
12 Ààlà ìwọ̀-oòrùn sì jẹ́ agbègbè Òkun Ńlá. Ìwọ̀nyí ni ààlà àyíká ènìyàn Juda ní agbo ilé wọn.
And the west boundary was by the great sea, and the coast thereof. This is the boundary of the children of Judah round about according to their families.
13 Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Olúwa pa fún Joṣua, ó fi ìpín fún Kalebu ọmọ Jefunne, ìpín ní Juda—Kiriati-Arba, tí í ṣe Hebroni. (Arba sì ní baba ńlá Anaki.)
And unto Caleb the son of Yephunneh he gave as a portion among the children of Judah, according to the order of the Lord to Joshua, Kiryath-arba' the father of 'Anak, which is Hebron.
14 Kalebu sì lé àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta jáde láti Hebroni; Ṣeṣai, Ahimani, àti Talmai, ìran Anaki.
And Caleb drove out from there the three sons of 'Anak, Sheshai, and Achiman, and Talmai, the children of 'Anak.
15 Ó sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
And he went up from there to the inhabitants of Debir; and the name of Debir before was Kiryath-sepher.
16 Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
And Caleb said, He that will smite Kiryath-sepher, and capture it, to him will I give 'Achsah my daughter for wife.
17 Otnieli ọmọ Kenasi, arákùnrin Kalebu, sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
And 'Othniel the son of Kenaz, the brother of Caleb, captured it; and he gave him 'Achsah his daughter for wife.
18 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
And it came to pass, as she came thither, that she persuaded him to ask of her father a field: and she alighted from her ass; and Caleb said unto her, What aileth thee?
19 Ó sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
And she said, Give me a blessing; for a dry land hast thou given me: give me then also springs of water. And he gave her the upper springs and the lower springs.
20 Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bi ìdílé wọn.
This is the inheritance of the tribe of the children of Judah according to their families.
21 Ìlú ìpẹ̀kun gúúsù ti ẹ̀yà Juda ní gúúsù ní ààlà Edomu nìwọ̀nyí: Kabṣeeli, Ederi, Jaguri,
And the cities of the boundary line of the tribe of the children of Judah toward the border of Edom, on the south, were Kabzeel, and 'Eder, and Yagur,
22 Kina, Dimona, Adada,
And Kinah, and Dimonah, and 'Ad'adah,
23 Kedeṣi, Hasori, Itina,
And Kedesh, and Chazor, and Yithnan,
24 Sifi, Telemu, Bealoti,
Ziph, and Telem, and Be'aloth,
25 Hasori Hadatta, Kerioti Hesroni (tí í ṣe Hasori),
And Chazor-chadattah, and Keriyoth-chezron, which is Chazor,
26 Amamu, Ṣema, Molada,
Amam, and Shema', and Moladah,
27 Hasari Gada, Heṣmoni, Beti-Peleti,
And Chazar-gaddah, and Cheshmon, and Beth-palet,
28 Hasari-Ṣuali, Beerṣeba, Bisiotia,
And Chazar-shual, and Beer-sheba, and Bizyotheyah,
29 Baalahi, Limu, Esemu,
Ba'alah, and 'Iyim, and 'Azem,
30 Eltoladi, Kesili, Horma,
And Eltolad, and Kessil, and Chormah,
31 Siklagi, Madmana, Sansanna,
And Ziklag, and Madmannah, and Sansannah,
32 Leboati, Ṣilhimu, Aini àti Rimoni, àpapọ̀ ìlú mọ́kàndínlọ́gbọ̀n àti àwọn ìletò wọn.
And Lebaoth, and Shilchim, and 'Ayin, and Rimmon: in all twenty and nine cities, with their villages.
33 Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹsẹ̀ òkè: Eṣtaoli, Sora, Aṣna,
And in the lowlands, Eshtaol, and Zor'ah, and Ashnah.
34 Sanoa, Eni-Gannimu, Tapua, Enamu,
And Zanoach, and 'En-gannim, Tappuach, and 'Enam,
35 Jarmatu, Adullamu, Soko, Aseka,
Yarmuth, and 'Adullam, Sochoh, and 'Azekah,
36 Ṣaaraimu, Adittaimu àti Gedera (tàbí Gederotaimu). Ìlú mẹ́rìnlá àti àwọn ìletò wọn.
And Sha'arayim, and 'Adithayim, and Gederah, and Gede-rothayim: fourteen cities with their villages.
37 Senani, Hadaṣa, Migdali Gadi,
Zenan, and Chadashah, and Migdalgad,
38 Dileani, Mispa, Jokteeli,
And Dil'an, and Mizpeh, and Yoktheel,
39 Lakiṣi, Boskati, Egloni,
Lachish, and Bozkath, and 'Eglon,
40 Kabboni, Lamasi, Kitlisi,
And Cabbon, and Lachmass, and Kithlish,
41 Gederoti, Beti-Dagoni, Naama àti Makkeda, ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
And Gederoth, Beth-dagon, and Na'amah, and Makkedah: sixteen cities with their villages.
42 Libina, Eteri, Aṣani,
Libnah, and 'Ether, and 'Ashan,
43 Hifita, Aṣna, Nesibu,
And Yiphtach, and Ashnah, and Nezib,
44 Keila, Aksibu àti Meraṣa: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò wọn.
And Ke'ilah, and Achzib, and Mareshah: nine cities with their villages.
45 Ekroni, pẹ̀lú ibùgbé àti àwọn ìletò rẹ̀ tó yí i ká,
'Ekron, with its towns and its villages:
46 ìwọ̀-oòrùn Ekroni, gbogbo èyí tí ń bẹ nítòsí Aṣdodu, pẹ̀lú àwọn ìletò wọn,
From 'Ekron even unto the sea, all that lay alongside of Ashdod, with their villages.
47 Aṣdodu, agbègbè ìlú rẹ̀ àti ìletò; àti Gasa, ìlú rẹ̀ àti ìletò, títí ó fi dé odò Ejibiti àti agbègbè Òkun Ńlá.
Ashdod with its towns and its villages, Gazzah, with its towns and its villages, up to the brook of Egypt, and the great sea, and its territory.
48 Ní ilẹ̀ òkè náà: Ṣamiri, Jattiri, Soko,
And in the mountains, Shamir, and Yattir, and Sochoh,
49 Dannah, Kiriati-Sannnah (tí í ṣe Debiri),
And Dannah and Kiryath-sannah, which is Debir,
50 Anabu, Eṣitemo, Animu,
And 'Anab, and Eshtemoh, and 'Anim.
51 Goṣeni, Holoni àti Giloni, ìlú mọ́kànlá àti ìletò wọn.
And Goshen, and Cholon, and Giloh: eleven cities with their villages.
52 Arabu, Duma, Eṣani,
Arab, and Dumah, and Esh'an,
53 Janimu, Beti-Tapua, Afeka,
And Vanum, and Beth-tappuach, and Aphekah,
54 Hamuta, Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) àti Ṣiori: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò rẹ̀
And Chumtah, and Kiryath-arba', which is Hebron, and Zi'or: nine cities with their villages.
55 Maoni, Karmeli, Sifi, Jutta,
Ma'on, Carmel, and Ziph, and Yutah,
56 Jesreeli, Jokdeamu, Sanoa,
And Yizre'el, and Yokde'am, and Zanoach,
57 Kaini, Gibeah àti Timna: ìlú mẹ́wàá àti àwọn ìletò wọn.
Kayin, Gib'ah, and Timnah: ten cities with their villages.
58 Halhuli, Beti-Suri, Gedori,
Chatchul, Beth-zur, and Gedor,
59 Maarati, Beti-Anoti àti Eltekoni: ìlú mẹ́fà àti àwọn ìletò wọn.
And Ma'arath, and Beth-'anoth, and Eltekon: six cities with their village.
60 Kiriati-Baali (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu) àti Rabba ìlú méjì àti ìletò wọn.
Kiryath-baal, which is Kiryath-ye'arim, and Rabbah; two cities with their villages.
61 Ní aginjù: Beti-Araba, Middini, Sekaka,
In the wilderness, Beth-ha'arabah, Middin, and Sechachah,
62 Nibṣani, Ìlú Iyọ̀ àti En-Gedi: ìlú mẹ́fà àti ìletò wọn.
And Nibshan, and 'Ir-hammelach, and 'En-gedi: six cities with their villages.
63 Juda kò lè lé àwọn ọmọ Jebusi jáde, tí wọ́n ń gbé ní Jerusalẹmu. Àwọn ará Jebusi sì ń gbé pẹ̀lú àwọn ènìyàn Juda títí dí òní.
As for the Jebusites the inhabitants of Jerusalem, these the children of Judah could not drive out; but the Jebusites dwelt with the children of Judah at Jerusalem, even unto this day.

< Joshua 15 >