< Joshua 15 >

1 Ìpín fún ẹ̀yà Juda, ní agbo ilé agbo ilé, títí dé agbègbè Edomu, títí dé aginjù Sini ní òpin ìhà gúúsù.
And the lot for the tribe of the children of Judah according to their families was unto the border of Edom, even to the wilderness of Zin southward, at the uttermost part of the south.
2 Ààlà wọn ní ìhà gúúsù bẹ̀rẹ̀ láti etí òpin ìhà gúúsù Òkun Iyọ̀,
And their south border was from the uttermost part of the Salt Sea, from the bay that looked southward.
3 ó sì gba gúúsù Akrabbimu lọ, títí dé Sini àti sí iwájú ìhà gúúsù Kadeṣi-Barnea. Nígbà náà ó sì tún kọjá Hesroni lọ sí Adari, ó sì tún yípo yíká lọ sí Karka.
And it went out southward of the ascent of Akrabbim, and passed along to Zin, and went up by the south of Kadesh-barnea, and passed along by Hezron, and went up to Addar, and turned about to Karka.
4 Ó tún kọjá lọ sí Asmoni, ó sì papọ̀ mọ́ Wadi ti Ejibiti, ó parí sí Òkun. Èyí ni ààlà wọn ní ìhà gúúsù.
And it passed along to Azmon, and went out at the Brook of Egypt; and the goings out of the border were at the sea; this shall be your south border.
5 Ààlà wọn ní ìhà ìlà-oòrùn ní Òkun Iyọ̀ títí dé ẹnu Jordani. Ààlà àríwá bẹ̀rẹ̀ láti etí òkun ní ẹnu Jordani,
And the east border was the Salt Sea, even unto the end of the Jordan. And the border of the north side was from the bay of the sea at the end of the Jordan.
6 ààlà náà sì tún dé Beti-Hogla, ó sì lọ sí ìhà àríwá Beti-Araba. Ààlà náà sì tún dé ibi Òkúta Bohani ti ọmọ Reubeni.
And the border went up to Beth-hoglah, and passed along by the north of Beth-arabah; and the border went up to the Stone of Bohan the son of Reuben.
7 Ààlà náà gòkè lọ títí dé Debiri láti àfonífojì Akori, ó sì yípadà sí àríwá Gilgali, èyí tí ń bẹ ní iwájú òkè Adummimu, tí ń bẹ ní ìhà gúúsù odò náà. Ó sì tẹ̀síwájú sí apá omi En-Ṣemeṣi, ó sì jáde sí En-Rogeli.
And the border went up to Debir from the valley of Achor, and so northward, looking toward Gilgal, that is over against the ascent of Adummim, which is on the south side of the brook; and the border passed along to the waters of En-shemesh, and the goings out thereof were at En-rogel.
8 Ààlà náà sì tún gòkè lọ sí àfonífojì Beni-Hinnomu ní ìhà gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ gúúsù ti Jebusi (tí í ṣe Jerusalẹmu). Ó sì gòkè lọ sí orí òkè tí ó wà lórí àfonífojì Hinnomu tí ń bẹ ní ìpẹ̀kun àfonífojì Refaimu ní ìhà àríwá.
And the border went up by the Valley of the son of Hinnom unto the side of the Jebusite southward — the same is Jerusalem — and the border went up to the top of the mountain that lieth before the Valley of Hinnom westward, which is at the uttermost part of the vale of Rephaim northward.
9 Ààlà náà sì lọ láti orí òkè lọ sí ìsun omi Nefitoa, ó sì jáde sí ìlú òkè Efroni, ó sì lọ sí apá ìsàlẹ̀ Baalahi (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu).
And the border was drawn from the top of the mountain unto the fountain of the waters of Nephtoah, and went out to the cities of mount Ephron; and the border was drawn to Baalah — the same is Kiriath-jearim.
10 Ààlà tí ó yípo láti Baalahi lọ sí ìhà ìwọ̀-oòrùn sí òkè Seiri, ó sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Jearimu (tí í ṣe, Kesaloni), ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Beti-Ṣemeṣi, ó sì kọjá lọ sí Timna.
And the border turned about from Baalah westward unto mount Seir, and passed along unto the side of mount Jearim on the north — the same is Chesalon — and went down to Beth-shemesh, and passed along by Timnah.
11 Ààlà náà sì lọ sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ àríwá òkè Ekroni, ó sì yípadà lọ sí Ṣikkeroni, ó sì yípadà lọ sí òkè Baalahi, ó sì dé Jabneeli, ààlà náà sì parí sí Òkun.
And the border went out unto the side of Ekron northward; and the border was drawn to Shikkeron, and passed along to mount Baalah, and went out at Jabneel; and the goings out of the border were at the sea.
12 Ààlà ìwọ̀-oòrùn sì jẹ́ agbègbè Òkun Ńlá. Ìwọ̀nyí ni ààlà àyíká ènìyàn Juda ní agbo ilé wọn.
And as for the west border, the Great Sea was the border thereof. This is the border of the children of Judah round about according to their families.
13 Gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Olúwa pa fún Joṣua, ó fi ìpín fún Kalebu ọmọ Jefunne, ìpín ní Juda—Kiriati-Arba, tí í ṣe Hebroni. (Arba sì ní baba ńlá Anaki.)
And unto Caleb the son of Jephunneh he gave a portion among the children of Judah, according to the commandment of the LORD to Joshua, even Kiriath-arba, which Arba was the father of Anak — the same is Hebron.
14 Kalebu sì lé àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta jáde láti Hebroni; Ṣeṣai, Ahimani, àti Talmai, ìran Anaki.
And Caleb drove out thence the three sons of Anak, Sheshai, and Ahiman, and Talmai, the children of Anak.
15 Ó sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
And he went up thence against the inhabitants of Debir — now the name of Debir beforetime was Kiriath-sepher.
16 Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
And Caleb said: 'He that smiteth Kiriath-sepher, and taketh it, to him will I give Achsah my daughter to wife.'
17 Otnieli ọmọ Kenasi, arákùnrin Kalebu, sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
And Othniel the son of Kenaz, the brother of Caleb, took it; and he gave him Achsah his daughter to wife.
18 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
And it came to pass, when she came unto him, that she persuaded him to ask of her father a field; and she alighted from off her ass; and Caleb said unto her: 'What wouldest thou?'
19 Ó sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
And she said: 'Give me a blessing; for that thou hast set me in the Southland, give me therefore springs of water.' And he gave her the Upper Springs and the Nether Springs.
20 Èyí ni ilẹ̀ ìní ẹ̀yà àwọn ọmọ Juda gẹ́gẹ́ bi ìdílé wọn.
This is the inheritance of the tribe of the children of Judah according to their families.
21 Ìlú ìpẹ̀kun gúúsù ti ẹ̀yà Juda ní gúúsù ní ààlà Edomu nìwọ̀nyí: Kabṣeeli, Ederi, Jaguri,
And the cities at the uttermost part of the tribe of the children of Judah toward the border of Edom in the South were Kabzeel, and Eder, and Jagur;
22 Kina, Dimona, Adada,
and Kinah, and Dimonah, and Adadah;
23 Kedeṣi, Hasori, Itina,
and Kedesh, and Hazor, and Ithnan;
24 Sifi, Telemu, Bealoti,
Ziph, and Telem, and Bealoth;
25 Hasori Hadatta, Kerioti Hesroni (tí í ṣe Hasori),
and Hazor, and Hadattah, and Kerioth, and Hezron — the same is Hazor;
26 Amamu, Ṣema, Molada,
Amam, and Shema, and Moladah;
27 Hasari Gada, Heṣmoni, Beti-Peleti,
and Hazar-gaddah, and Heshmon, and Beth-pelet;
28 Hasari-Ṣuali, Beerṣeba, Bisiotia,
and Hazar-shual, and Beer-sheba, and Biziothiah;
29 Baalahi, Limu, Esemu,
Baalah, and Iim, and Ezem;
30 Eltoladi, Kesili, Horma,
and Eltolad, and Chesil, and Hormah;
31 Siklagi, Madmana, Sansanna,
and Ziklag, and Madmannah, and Sansannah;
32 Leboati, Ṣilhimu, Aini àti Rimoni, àpapọ̀ ìlú mọ́kàndínlọ́gbọ̀n àti àwọn ìletò wọn.
and Lebaoth, and Shilhim, and Ain, and Rimmon; all the cities are twenty and nine, with their villages.
33 Ní ìhà ìwọ̀-oòrùn ẹsẹ̀ òkè: Eṣtaoli, Sora, Aṣna,
In the Lowland: Eshtaol, and Zorah, and Ashnah;
34 Sanoa, Eni-Gannimu, Tapua, Enamu,
and Zanoah, and En-gannim, Tappuah, and Enam;
35 Jarmatu, Adullamu, Soko, Aseka,
Jarmuth, and Adullam, Socoh, and Azekah;
36 Ṣaaraimu, Adittaimu àti Gedera (tàbí Gederotaimu). Ìlú mẹ́rìnlá àti àwọn ìletò wọn.
and Shaaraim, and Adithaim, and Gederah, with Gederothaim; fourteen cities with their villages.
37 Senani, Hadaṣa, Migdali Gadi,
Zenan, and Hadashah, and Migdal-gad;
38 Dileani, Mispa, Jokteeli,
and Dilan, and Mizpeh, and Joktheel;
39 Lakiṣi, Boskati, Egloni,
Lachish, and Bozkath, and Eglon;
40 Kabboni, Lamasi, Kitlisi,
and Cabbon, and Lahmas, and Chithlish;
41 Gederoti, Beti-Dagoni, Naama àti Makkeda, ìlú mẹ́rìndínlógún àti ìletò wọn.
and Gederoth, Beth-dagon, and Naamah, and Makkedah; sixteen cities with their villages.
42 Libina, Eteri, Aṣani,
Libnah, and Ether, and Ashan;
43 Hifita, Aṣna, Nesibu,
and Iphtah, and Ashnah, and Nezib;
44 Keila, Aksibu àti Meraṣa: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò wọn.
and Keilah, and Achzib, and Mareshah; nine cities with their villages.
45 Ekroni, pẹ̀lú ibùgbé àti àwọn ìletò rẹ̀ tó yí i ká,
Ekron, with its towns and its villages;
46 ìwọ̀-oòrùn Ekroni, gbogbo èyí tí ń bẹ nítòsí Aṣdodu, pẹ̀lú àwọn ìletò wọn,
from Ekron even unto the sea, all that were by the side of Ashdod, with their villages.
47 Aṣdodu, agbègbè ìlú rẹ̀ àti ìletò; àti Gasa, ìlú rẹ̀ àti ìletò, títí ó fi dé odò Ejibiti àti agbègbè Òkun Ńlá.
Ashdod, its towns and its villages; Gaza, its towns and its villages; unto the Brook of Egypt, the Great Sea being the border thereof.
48 Ní ilẹ̀ òkè náà: Ṣamiri, Jattiri, Soko,
And in the hill-country: Shamir, and Jattir, and Socoh;
49 Dannah, Kiriati-Sannnah (tí í ṣe Debiri),
and Dannah, and Kiriath-sannah — the same is Debir;
50 Anabu, Eṣitemo, Animu,
and Anab, and Eshtemoh, and Anim;
51 Goṣeni, Holoni àti Giloni, ìlú mọ́kànlá àti ìletò wọn.
and Goshen, and Holon, and Giloh; eleven cities with their villages.
52 Arabu, Duma, Eṣani,
Arab, and Rumah, and Eshan;
53 Janimu, Beti-Tapua, Afeka,
and Janum, and Beth-tappuah, and Aphekah;
54 Hamuta, Kiriati-Arba (tí í ṣe, Hebroni) àti Ṣiori: ìlú mẹ́sàn-án àti àwọn ìletò rẹ̀
and Humtah, and Kiriath-arba — the same is Hebron, and Zior; nine cities with their villages.
55 Maoni, Karmeli, Sifi, Jutta,
Maon, Carmel, and Ziph, and Juttah;
56 Jesreeli, Jokdeamu, Sanoa,
and Jezreel, and Jokdeam, and Zanoah;
57 Kaini, Gibeah àti Timna: ìlú mẹ́wàá àti àwọn ìletò wọn.
Kain, Gibeah, and Timnah; ten cities with their villages.
58 Halhuli, Beti-Suri, Gedori,
Halhul, Beth-zur, and Gedor;
59 Maarati, Beti-Anoti àti Eltekoni: ìlú mẹ́fà àti àwọn ìletò wọn.
and Maarath, and Beth-anoth, and Eltekon; six cities with their villages.
60 Kiriati-Baali (tí í ṣe, Kiriati-Jearimu) àti Rabba ìlú méjì àti ìletò wọn.
Kiriath-baal — the same is Kiriath-jearim, and Rabbah; two cities with their villages.
61 Ní aginjù: Beti-Araba, Middini, Sekaka,
In the wilderness: Beth-arabah, Middin, and Secacah;
62 Nibṣani, Ìlú Iyọ̀ àti En-Gedi: ìlú mẹ́fà àti ìletò wọn.
and Nibshan, and the City of Salt, and En-gedi; six cities with their villages.
63 Juda kò lè lé àwọn ọmọ Jebusi jáde, tí wọ́n ń gbé ní Jerusalẹmu. Àwọn ará Jebusi sì ń gbé pẹ̀lú àwọn ènìyàn Juda títí dí òní.
And as for the Jebusites, the inhabitants of Jerusalem, the children of Judah could not drive them out; but the Jebusites dwelt with the children of Judah at Jerusalem, unto this day.

< Joshua 15 >