< Joshua 14 >

1 Ìwọ̀nyí ni ilẹ̀ tí àwọn ọmọ Israẹli gbà gẹ́gẹ́ bí ogún ní ilẹ̀ Kenaani, tí Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn agbo ilé Israẹli pín fún wọn.
A oto co synowie Izraela odziedziczyli w ziemi Kanaan, co przydzielili im jako dziedzictwo kapłan Eleazar i Jozue, syn Nuna, oraz naczelnicy wśród ojców pokoleń synów Izraela.
2 Ìbò ni a fi pín ìní wọn fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án ààbọ̀ gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ọwọ́ Mose.
Ich dziedzictwa [dokonano] za pomocą losów, jak PAN rozkazał przez Mojżesza, dla dziewięciu i pół pokolenia.
3 Mose ti fún àwọn ẹ̀yà méjì àti ààbọ̀ ní ogún wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi ni kò fi ìní fún ní àárín àwọn tí ó kù.
Gdyż Mojżesz dał dziedzictwo dwom pokoleniom i połowie pokolenia za Jordanem, ale Lewitom nie dał dziedzictwa wśród nich.
4 Àwọn ọmọ Josẹfu sì di ẹ̀yà méjì, Manase àti Efraimu. Àwọn ọmọ Lefi kò gba ìpín ní ilẹ̀ náà bí kò ṣe àwọn ìlú tí wọn yóò máa gbé, pẹ̀lú pápá oko tútù fún ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran wọn.
Synowie Józefa stanowili bowiem dwa pokolenia: Manassesa i Efraima. Lewitom więc nie dano udziału w ziemi oprócz miast do zamieszkania z przyległymi do nich pastwiskami dla ich stad i dobytku.
5 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli pín ilẹ̀ náà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Jak PAN rozkazał Mojżeszowi, tak postąpili synowie Izraela i podzielili ziemię.
6 Àwọn ọkùnrin Juda wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ní Gilgali. Kalebu ọmọ Jefunne ti Kenissiti wí fún un pé, “Ìwọ rántí ohun tí Olúwa sọ fún Mose ènìyàn Ọlọ́run ní Kadeṣi-Barnea nípa ìwọ àti èmi.
Wtedy synowie Judy przyszli do Jozuego w Gilgal i powiedział do niego Kaleb, syn Jefunnego, Kenizzyta: Ty wiesz, co PAN powiedział Mojżeszowi, mężowi Boga, o mnie i o tobie w Kadesz-Barnea.
7 Mo jẹ́ ọmọ ogójì ọdún nígbà tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa rán mi láti Kadeṣi-Barnea lọ rin ilẹ̀ náà wò. Mo sì mú ìròyìn wá fún un gẹ́gẹ́ bí o ti dá mi lójú,
Miałem czterdzieści lat, gdy Mojżesz, sługa PANA, posłał mnie z Kadesz-Barnea na wybadanie ziemi i przyniosłem mu wiadomość zgodnie z tym, co miałem w sercu.
8 ṣùgbọ́n àwọn arákùnrin mi tí wọ́n bá mi lọ mú àyà àwọn ènìyàn já. Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi fi gbogbo ọkàn tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run mi.
Lecz moi bracia, którzy chodzili ze mną, zatrwożyli serce ludu. Ja [zaś] poszedłem całkowicie za PANEM, swoim Bogiem.
9 Ní ọjọ́ náà, Mose búra fún mi pé, ‘Ilẹ̀ tí ẹsẹ̀ rẹ ti rìn ni yóò jẹ́ ìní rẹ àti ti àwọn ọmọ rẹ láéláé, nítorí pé ìwọ fi tọkàntọkàn wà pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run mi.’
W tym dniu Mojżesz przysiągł: Zaprawdę, ziemia, którą deptała twoja noga, stanie się dziedzictwem twoim i twoich synów na wieki, ponieważ całkowicie poszedłeś za PANEM, moim Bogiem.
10 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, kíyèsi i Olúwa dá mi sí gẹ́gẹ́ bí ó ti wí, láti ọdún márùndínláàádọ́ta yìí wá, láti ìgbà tí Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún Mose, nígbà tí Israẹli ń rìn kiri nínú aginjù, sì kíyèsi i nísinsin yìí, èmi nìyìí lónìí, ọmọ àrùndínláàdọ́rùn-ún ọdún.
A teraz oto PAN zachował mnie przy życiu, jak powiedział; już minęło czterdzieści pięć lat od tego czasu, kiedy PAN powiedział to do Mojżesza, gdy Izraelici wędrowali po pustyni. I oto mam dziś osiemdziesiąt pięć lat;
11 Síbẹ̀ èmi ní agbára lónìí, bí ìgbà tí Mose rán mi jáde. Èmi sì ní agbára láti jáde fún ogun nísinsin yìí gẹ́gẹ́ bí mo ti wà ní ìgbà náà.
A jeszcze dziś jestem tak silny, jak byłem w tym dniu, gdy Mojżesz mnie wysłał. Jaka wtedy [była] moja siła, taka jest teraz moja siła do wojny, by wyruszać i wracać.
12 Nísinsin yìí fi ìlú orí òkè fún mi èyí tí Olúwa ṣe ìlérí fún mi ní ọjọ́ náà. Ìwọ gbọ́ ní ìgbà náà pé àwọn ọmọ Anaki ti wà ní ibẹ̀, àti àwọn ìlú wọn tóbi, pé ó sì ṣe olódi, ṣùgbọ́n bí Olúwa ba fẹ́, èmi yóò lé wọn jáde, gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ.”
Teraz więc daj mi tę górę, o której PAN powiedział w owym dniu. Sam bowiem słyszałeś tego dnia, że tam są Anakici, a miasta [są] wielkie i warowne. Jeśli PAN będzie ze mną, wypędzę ich, jak [mi] PAN obiecał.
13 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua súre fun Kalebu ọmọ Jefunne ó si fun un ní Hebroni ni ilẹ̀ ìní.
I Jozue błogosławił mu, i dał Kalebowi, synowi Jefunnego, Hebron w dziedzictwo.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Hebroni jẹ́ ti Kalebu ọmọ Jefunne ará Kenissiti láti ìgbà náà, nítorí tí ó tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run Israẹli tọkàntọkàn.
Dlatego Hebron stał się dziedzictwem Kaleba, syna Jefunnego Kenizzyty, aż do dziś, bo całkowicie [poszedł] za PANEM, Bogiem Izraela.
15 (Hebroni a sì máa jẹ́ Kiriati-Arba ní ẹ̀yìn Arba, èyí tí ó jẹ́ ènìyàn ńlá nínú àwọn ọmọ Anaki.) Nígbà náà ni ilẹ̀ náà sinmi ogun.
A Hebron zwano wcześniej Kiriat-Arba. [Arba] był wielkim człowiekiem wśród Anakitów. A ziemia zaznała pokoju od wojny.

< Joshua 14 >