< Joshua 14 >

1 Ìwọ̀nyí ni ilẹ̀ tí àwọn ọmọ Israẹli gbà gẹ́gẹ́ bí ogún ní ilẹ̀ Kenaani, tí Eleasari àlùfáà, Joṣua ọmọ Nuni àti olórí ẹ̀yà àwọn agbo ilé Israẹli pín fún wọn.
To nu Israēla bērni iemantojuši Kanaāna zemē, ko viņiem ir izdalījuši Eleazars, tas priesteris, un Jozuas, Nuna dēls, un tie augstie Israēla bērnu cilts tēvi.
2 Ìbò ni a fi pín ìní wọn fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án ààbọ̀ gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ láti ọwọ́ Mose.
Caur meslošanu tiem dalīja, kā Tas Kungs caur Mozu bija pavēlējis, dot tām deviņām ciltīm un tai pusciltij.
3 Mose ti fún àwọn ẹ̀yà méjì àti ààbọ̀ ní ogún wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Lefi ni kò fi ìní fún ní àárín àwọn tí ó kù.
Jo tām divām ciltīm un tai pusciltij Mozus bija devis daļu viņpus Jardānes, bet Levitiem viņš nekādu zemes daļu nebija devis viņu starpā.
4 Àwọn ọmọ Josẹfu sì di ẹ̀yà méjì, Manase àti Efraimu. Àwọn ọmọ Lefi kò gba ìpín ní ilẹ̀ náà bí kò ṣe àwọn ìlú tí wọn yóò máa gbé, pẹ̀lú pápá oko tútù fún ọ̀wọ́ ẹran àti agbo ẹran wọn.
Jo Jāzepa bērnu bija divas ciltis, Manasus un Efraīms; un Levitiem nedeva nekādu īpašu daļu tai zemē, bet pilsētas vien, kur dzīvot, un ganības priekš viņu lopiem un priekš viņu īpašuma.
5 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ará Israẹli pín ilẹ̀ náà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Kā Tas Kungs Mozum bija pavēlējis, tā Israēla bērni darīja un izdalīja to zemi.
6 Àwọn ọkùnrin Juda wá sí ọ̀dọ̀ Joṣua ní Gilgali. Kalebu ọmọ Jefunne ti Kenissiti wí fún un pé, “Ìwọ rántí ohun tí Olúwa sọ fún Mose ènìyàn Ọlọ́run ní Kadeṣi-Barnea nípa ìwọ àti èmi.
Tad Jūda bērni piegāja pie Jozuas Gilgalā, un Kālebs, Jefunna dēls, no Ķenasa bērniem, sacīja uz viņu: tu zini to vārdu, ko Tas Kungs uz Mozu, to Dieva vīru, ir runājis Kādeš Barneā manis pēc un tevis pēc.
7 Mo jẹ́ ọmọ ogójì ọdún nígbà tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa rán mi láti Kadeṣi-Barnea lọ rin ilẹ̀ náà wò. Mo sì mú ìròyìn wá fún un gẹ́gẹ́ bí o ti dá mi lójú,
Es biju četrdesmit gadus vecs, kad Mozus, Tā Kunga kalps, mani sūtīja no Kādeš Barneas, to zemi izlūkot, un es viņam atsacīju, tā kā tas bija manā sirdī.
8 ṣùgbọ́n àwọn arákùnrin mi tí wọ́n bá mi lọ mú àyà àwọn ènìyàn já. Ṣùgbọ́n ní tèmi, èmi fi gbogbo ọkàn tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run mi.
Bet mani brāļi, kas man bija gājuši līdz, tie darīja to ļaužu sirdi bailīgu, bet es Tam Kungam, savam Dievam, pareizi klausīju.
9 Ní ọjọ́ náà, Mose búra fún mi pé, ‘Ilẹ̀ tí ẹsẹ̀ rẹ ti rìn ni yóò jẹ́ ìní rẹ àti ti àwọn ọmọ rẹ láéláé, nítorí pé ìwọ fi tọkàntọkàn wà pẹ̀lú Olúwa Ọlọ́run mi.’
Tad Mozus tai dienā zvērēja un sacīja: tā zeme, kur tu ar savu kāju esi minis, tev un taviem bērniem būs par daļu mūžam; jo tu Tam Kungam, manam Dievam, esi pareizi klausījis.
10 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, kíyèsi i Olúwa dá mi sí gẹ́gẹ́ bí ó ti wí, láti ọdún márùndínláàádọ́ta yìí wá, láti ìgbà tí Olúwa ti sọ ọ̀rọ̀ yìí fún Mose, nígbà tí Israẹli ń rìn kiri nínú aginjù, sì kíyèsi i nísinsin yìí, èmi nìyìí lónìí, ọmọ àrùndínláàdọ́rùn-ún ọdún.
Un nu redzi, Tas Kungs manu dzīvību ir uzturējis, tā kā Viņš ir runājis, un ir četrdesmit un pieci gadi no tā laika, kad Tas Kungs šo vārdu uz Mozu runāja, Israēlim tuksnesī staigājot, un nu redzi, es šodien esmu astoņdesmit piecus gadus vecs.
11 Síbẹ̀ èmi ní agbára lónìí, bí ìgbà tí Mose rán mi jáde. Èmi sì ní agbára láti jáde fún ogun nísinsin yìí gẹ́gẹ́ bí mo ti wà ní ìgbà náà.
Es vēl šodien esmu tik stiprs, kā tai dienā kad Mozus mani izsūtīja; kāds mans spēks bija to brīdi, tāds ir mans spēks šo brīdi uz karu, uz iziešanu un ieiešanu.
12 Nísinsin yìí fi ìlú orí òkè fún mi èyí tí Olúwa ṣe ìlérí fún mi ní ọjọ́ náà. Ìwọ gbọ́ ní ìgbà náà pé àwọn ọmọ Anaki ti wà ní ibẹ̀, àti àwọn ìlú wọn tóbi, pé ó sì ṣe olódi, ṣùgbọ́n bí Olúwa ba fẹ́, èmi yóò lé wọn jáde, gẹ́gẹ́ bí ó ti sọ.”
Un nu, dod man šo kalnu zemi, par ko Tas Kungs tai dienā runājis, jo tu tai dienā esi dzirdējis, ka tur dzīvo Enaķieši, un tur ir lielas stipras pilsētas; varbūt Tas Kungs būs ar mani, ka es tos varu izdzīt, tā kā Tas Kungs runājis.
13 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua súre fun Kalebu ọmọ Jefunne ó si fun un ní Hebroni ni ilẹ̀ ìní.
Tad Jozuas viņu svētīja un deva Kālebam, Jefunna dēlam, Hebroni par daļu.
14 Bẹ́ẹ̀ ni Hebroni jẹ́ ti Kalebu ọmọ Jefunne ará Kenissiti láti ìgbà náà, nítorí tí ó tẹ̀lé Olúwa Ọlọ́run Israẹli tọkàntọkàn.
Tā tad Hebrone Kālebam, Jefunna dēlam, no Ķenasa bērniem, tika par daļu līdz šai dienai, tāpēc ka tas Tam Kungam, Israēla Dievam, pareizi bija klausījis.
15 (Hebroni a sì máa jẹ́ Kiriati-Arba ní ẹ̀yìn Arba, èyí tí ó jẹ́ ènìyàn ńlá nínú àwọn ọmọ Anaki.) Nígbà náà ni ilẹ̀ náà sinmi ogun.
Bet Hebrones vārds bija vecos laikos Kiriat Arba (Arbas pilsēta), tas ir bijis viens liels cilvēks starp Enaķiešiem. Un zemei bija miers no karošanas.

< Joshua 14 >