< Joshua 13 >

1 Nígbà tí Joṣua sì darúgbó tí ọjọ́ orí rẹ̀ sì pọ̀ jọjọ, Olúwa sọ fún un pé, “Ìwọ ti darúgbó púpọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ilẹ̀ sì kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀ fún yín láti gbà.
I gdy Jozue zestarzał się i był w podeszłym wieku, PAN powiedział do niego: Zestarzałeś się i posunąłeś się w latach, a pozostało jeszcze dużo ziemi do zdobycia.
2 “Èyí ni ilẹ̀ tí ó kù: “gbogbo àwọn agbègbè àwọn Filistini, àti ti ara Geṣuri:
Oto ziemia, która pozostała: wszystkie okręgi Filistynów i Geszurytów;
3 láti odò Ṣihori ní ìlà-oòrùn Ejibiti sí agbègbè Ekroni ìhà àríwá, gbogbo rẹ̀ ni a kà kún Kenaani (agbègbè ìjòyè Filistini márùn-ún ní Gasa, Aṣdodu, Aṣkeloni, Gitti àti Ekroni; ti àwọn ará Affimu);
Od Szichoru, który jest naprzeciw Egiptu, aż do granicy Akaronu na północy – [jest to ziemia] przynależąca do Kananejczyków, pięciu książąt filistyńskich: z Gazy, Aszdodu, Aszkelonu, Gat i Ekronu, oraz Awwici;
4 láti gúúsù; gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Kenaani, láti Arah ti àwọn ará Sidoni títí ó fi dé Afeki, agbègbè àwọn ará Amori,
Od południa: cała ziemia Kananejczyków oraz Meara, która należy do Sydończyków, aż do Afek [i] aż do granicy Amorytów;
5 àti ilẹ̀ àwọn ará Gebali; àti gbogbo àwọn Lebanoni dé ìlà-oòrùn, láti Baali-Gadi ní ìsàlẹ̀ òkè Hermoni dé Lebo-Hamati.
I ziemia Gibilitów i cały Liban na wschodzie, od Baal-Gad pod górę Hermon, aż do wejścia do Chamat.
6 “Ní ti gbogbo àwọn olùgbé agbègbè òkè, láti Lebanoni sí Misrefoti-Maimu, àní, gbogbo àwọn ará Sidoni, èmi fúnra mi ní yóò lé wọn jáde ní iwájú àwọn ará Israẹli. Kí o ri dájú pé o pín ilẹ̀ yí fún Israẹli ní ilẹ̀ ìní, gẹ́gẹ́ bí mo ṣe fi àṣẹ fún ọ,
Wszystkich mieszkańców gór od Libanu aż do Misrefot-Maim [i] wszystkich Sydończyków wypędzę przed synami Izraela. Tylko podziel ją losem między Izraelitów jako dziedzictwo, tak jak ci rozkazałem.
7 pín ilẹ̀ yìí ní ilẹ̀ ìní fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án àti ìdajì ẹ̀yà Manase.”
Rozdziel więc teraz tę ziemię jako dziedzictwo dziewięciu pokoleniom i połowie pokolenia Manassesa;
8 Àwọn ìdajì ẹ̀yà Manase tí ó kù, àti àwọn Reubeni àti àwọn Gadi ti gba ilẹ̀ ìní, tí Mose ti fún wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.
Gdyż z drugą [połową] Rubenici i Gadyci otrzymali już swoje dziedzictwo, które dał im Mojżesz za Jordanem na wschodzie, jak przydzielał im Mojżesz, sługa PANA;
9 Ó sì lọ títí láti Aroeri tí ń bẹ létí àfonífojì Arnoni, àti láti ìlú náà tí ń bẹ ní àárín àfonífojì náà, àti pẹ̀lú gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Medeba títí dé Diboni.
Od Aroeru, leżącego nad brzegiem rzeki Arnon, i od miasta, które jest w środku rzeki, wraz z całą równiną Medeby aż do Dibonu;
10 Gbogbo ìlú Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó ṣe àkóso ní Heṣboni, títí dé ààlà àwọn ará Ammoni.
I wszystkie miasta Sichona, króla Amorytów, który królował w Cheszbonie, aż do granicy synów Ammona;
11 Àti Gileadi, ní agbègbè àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, gbogbo òkè Hermoni àti gbogbo Baṣani títí dé Saleka,
Także Gilead i obszar Geszurytów i Maakatytów, całą górę Hermon i cały Baszan aż do Salka;
12 ìyẹn, gbogbo ilẹ̀ ọba Ogu ní Baṣani, tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei, ẹni tí ó kù nínú àwọn Refaimu ìyókù. Mose ti ṣẹ́gun wọn, ó sì ti gba ilẹ̀ wọn.
Całe królestwo Oga w Baszanie, który królował w Asztarot i w Edrei; był on ostatnim z Refaitów, których Mojżesz pobił i wypędził.
13 Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli kò lé àwọn ará Geṣuri àti Maakati jáde, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé ní àárín àwọn ará Israẹli títí di òní yìí.
Lecz synowie Izraela nie wypędzili Geszurytów i Maakatytów, dlatego Geszuryci i Maakatyci mieszkają pośród Izraelitów do dziś.
14 Ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Lefi ni kò fi ogún kankan fún, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ pé ọrẹ àfinásun sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ni ogún tiwọn, gẹ́gẹ́ bí o ti ṣèlérí fún wọn.
Tylko pokoleniu Lewiego nie dał dziedzictwa; ofiary spalane dla PANA, Boga Izraela, są jego dziedzictwem, jak mu [Bóg] powiedział.
15 Èyí ni Mose fi fún ẹ̀yà Reubeni ni agbo ilé sí agbo ilé,
Mojżesz dał więc pokoleniu synów Rubena [dziedzictwo] według ich rodzin.
16 láti agbègbè Aroeri ní etí Arnoni Jọ́ọ́jì àti láti ìlú tí ń bẹ láàrín Jọ́ọ́jì, àti gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ìkọjá Medeba
Ich granica była od Aroeru, leżącego nad brzegiem rzeki Arnon, i od miasta, które jest w środku rzeki, wraz z całą równiną ku Medebie;
17 sí Heṣboni àti gbogbo ìlú rẹ̀ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú Diboni, Bamoti Baali, Beti-Baali-Mioni,
Cheszbon i wszystkie przyległe do niego miasta, które były na równinie: Dibon, Bamot-Baal i Bet-Baal-Meon;
18 Jahisa, Kedemoti, Mefaati,
Jahaza, Kedemot i Mefaat;
19 Kiriataimu, Sibma, Sereti Ṣahari lórí òkè ní àfonífojì.
Kiriataim, Sibma i Seret-Haszszachar na górze w dolinie;
20 Beti-Peori, gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga, àti Beti-Jeṣimoti
Bet-Peor, Aszdod-Pisga i Bet-Jeszimot.
21 gbogbo ìlú tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti gbogbo agbègbè Sihoni ọba Amori, tí ó ṣe àkóso Heṣboni. Mose sì ti ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ ìjòyè Midiani, Efi, Rekemu, Suri, Huri àti Reba, àwọn ọmọ ọba pawọ́pọ̀ pẹ̀lú Sihoni tí ó gbé ilẹ̀ náà.
I wszystkie miasta na równinie oraz całe królestwo Sichona, króla Amorytów, który królował w Cheszbonie, a którego Mojżesz zabił tak jak książąt Midianu: Ewi, Rekem, Sur, Chur, Reba, książęta Sichona zamieszkali w [tej] ziemi.
22 Ní àfikún àwọn tí a pa ní ogun, àwọn ọmọ Israẹli fi idà pa Balaamu ọmọ Beori alásọtẹ́lẹ̀.
I wróżbitę Balaama, syna Beora, wraz z innymi zabitymi synowie Izraela zabili mieczem.
23 Ààlà àwọn ọmọ Reubeni ni etí odò Jordani. Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ ni ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Reubeni ní agbo ilé ní agbo ilé.
Granicą synów Rubena był Jordan ze [swymi] granicami. Oto dziedzictwo synów Rubena według ich rodzin, miast i przyległych do nich wsi.
24 Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ẹ̀yà Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
Mojżesz dał też [dziedzictwo] pokoleniu Gada, synom Gada według ich rodzin.
25 Agbègbè ìlú Jaseri, gbogbo ìlú Gileadi àti ìdajì orílẹ̀-èdè àwọn ọmọ ará Ammoni títí dé Aroeri, ní ẹ̀bá Rabba;
A ich granice obejmowały Jazer i wszystkie miasta Gileadu oraz połowę ziemi synów Ammona aż do Aroeru [leżącego] naprzeciw Rabby;
26 àti láti Heṣboni lọ sí Ramati-Mispa àti Betonimu, àti láti Mahanaimu sí agbègbè ìlú Debiri,
I od Cheszbonu aż do Ramat-Mispa i Betonim oraz od Machanaim aż do granicy Debiru.
27 àti ní àfonífojì Beti-Haramu, Beti-Nimra, Sukkoti àti Safoni pẹ̀lú ìyókù agbègbè ilẹ̀ Sihoni ọba Heṣboni (ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani, agbègbè rẹ̀ títí dé òpin Òkun Kinnereti).
W dolinie zaś: Bet-Haram, Bet-Nimra, Sukkot i Safon, resztę królestwa Sichona, króla Cheszbonu, Jordan i [jego] pogranicze aż do końca morza Kinneret po wschodniej stronie Jordanu.
28 Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ jẹ́ ogún àwọn ọmọ Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
Oto dziedzictwo synów Gada według ich rodzin, miast i przyległych do nich wsi.
29 Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ìdajì ẹ̀yà Manase, èyí ni pé, fún ìdajì ìdílé irú-ọmọ Manase, ní agbo ilé ní agbo ilé.
Mojżesz dał też [posiadłość] połowie pokolenia Manassesa; przypadła ona połowie pokolenia synów Manassesa według ich rodzin.
30 Ilẹ̀ náà fẹ̀ dé Mahanaimu àti gbogbo Baṣani, gbogbo agbègbè ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani, èyí tí í ṣe ibùgbé Jairi ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú,
Ich granica była od Machanaim, obejmowała cały Baszan [i] całe królestwo Oga, króla Baszanu oraz wszystkie wsie Jaira, które są w Baszanie, sześćdziesiąt miast.
31 ìdajì Gileadi, àti Aṣtarotu àti Edrei (àwọn ìlú ọba Ogu ní Baṣani). Èyí ni fún irú àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase fún ààbọ̀ àwọn ọmọ Makiri, ní agbo ilé ní agbo ilé.
Połowę Gileadu, Asztarot i Erdei, miasta królestwa Oga w Baszanie, [dał] synom Makira, syna Manassesa, a ściśle – połowie synów Makira według ich rodzin.
32 Èyí ni ogún tí Mose fi fún wọn nígbà tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní ìhà kejì Jordani ní ìlà-oòrùn Jeriko.
Oto [posiadłości], które Mojżesz podzielił na polach Moabu za Jordanem, [naprzeciw] Jerycha na wschodzie.
33 Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yà Lefi, Mose kò fi ogún fún un; Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ní ogún wọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.
Lecz pokoleniu Lewiego Mojżesz nie dał dziedzictwa, gdyż PAN, Bóg Izraela, sam [jest] ich dziedzictwem, jak im to powiedział.

< Joshua 13 >