< Joshua 13 >
1 Nígbà tí Joṣua sì darúgbó tí ọjọ́ orí rẹ̀ sì pọ̀ jọjọ, Olúwa sọ fún un pé, “Ìwọ ti darúgbó púpọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ilẹ̀ sì kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀ fún yín láti gbà.
Józsua öreg lett, előre haladt a korban; ekkor szólt hozzá az Örökkévaló: Te öreg lettél, előre haladtál a korban, az országból pedig igen sok maradt elfoglalásra.
2 “Èyí ni ilẹ̀ tí ó kù: “gbogbo àwọn agbègbè àwọn Filistini, àti ti ara Geṣuri:
Ez ami az országból megmaradt: mind a filiszteusok kerületei és az egész Gesúri.
3 láti odò Ṣihori ní ìlà-oòrùn Ejibiti sí agbègbè Ekroni ìhà àríwá, gbogbo rẹ̀ ni a kà kún Kenaani (agbègbè ìjòyè Filistini márùn-ún ní Gasa, Aṣdodu, Aṣkeloni, Gitti àti Ekroni; ti àwọn ará Affimu);
A Síchórtól, mely Egyiptom előtt van, egészen Ekrón határáig északról, a kanaánihoz számíttatik; a filiszteusok öt fejedelme: az Azzabeli, az Asdódbeli, az Askelónbeli, a Gátbeli, az Ekrónbeli, meg az Avvim;
4 láti gúúsù; gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Kenaani, láti Arah ti àwọn ará Sidoni títí ó fi dé Afeki, agbègbè àwọn ará Amori,
dél felől a kanaáni egész földje és Meára, mely a Cídónbelieké, Afékáig, az emórí határáig;
5 àti ilẹ̀ àwọn ará Gebali; àti gbogbo àwọn Lebanoni dé ìlà-oòrùn, láti Baali-Gadi ní ìsàlẹ̀ òkè Hermoni dé Lebo-Hamati.
a Gibli földje és az egész Libánon napkeletről, Báal-Gádtól, a Chermón hegy alján egészen Chamát felé;
6 “Ní ti gbogbo àwọn olùgbé agbègbè òkè, láti Lebanoni sí Misrefoti-Maimu, àní, gbogbo àwọn ará Sidoni, èmi fúnra mi ní yóò lé wọn jáde ní iwájú àwọn ará Israẹli. Kí o ri dájú pé o pín ilẹ̀ yí fún Israẹli ní ilẹ̀ ìní, gẹ́gẹ́ bí mo ṣe fi àṣẹ fún ọ,
mind a hegység lakói a Libánontól Miszrefót-Májimig, mind a Cidónbeliek: én el fogom őket űzni Izraél fiai elől; csak juttasd Izraélnek birtokul, amint megparancsoltam neked.
7 pín ilẹ̀ yìí ní ilẹ̀ ìní fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án àti ìdajì ẹ̀yà Manase.”
Most pedig oszd fel ezt az országot birtokul a kilenc törzsnek és Menasse fél törzsének.
8 Àwọn ìdajì ẹ̀yà Manase tí ó kù, àti àwọn Reubeni àti àwọn Gadi ti gba ilẹ̀ ìní, tí Mose ti fún wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.
Vele a Reúbéni és a Gádi elvették birtokukat, melyet adott nekik Mózes a Jordánon túl keletről, amiképpen adta nekik Mózes, az Örökkévaló szolgája:
9 Ó sì lọ títí láti Aroeri tí ń bẹ létí àfonífojì Arnoni, àti láti ìlú náà tí ń bẹ ní àárín àfonífojì náà, àti pẹ̀lú gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Medeba títí dé Diboni.
Aróértól, mely az Arnón patak partján van és a várost, mely a völgy közepén van és az egész sík földet, Médebától Dibónig;
10 Gbogbo ìlú Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó ṣe àkóso ní Heṣboni, títí dé ààlà àwọn ará Ammoni.
és mind a városait Szíchónnak; az emóri királyának, aki uralkodott Chesbónban, Ammón fiai határáig;
11 Àti Gileadi, ní agbègbè àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, gbogbo òkè Hermoni àti gbogbo Baṣani títí dé Saleka,
meg Gileádot, a Gesúri és a Máakháti határát, Chermón egész hegységét és az egész Básánt Szalkháig;
12 ìyẹn, gbogbo ilẹ̀ ọba Ogu ní Baṣani, tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei, ẹni tí ó kù nínú àwọn Refaimu ìyókù. Mose ti ṣẹ́gun wọn, ó sì ti gba ilẹ̀ wọn.
egész Básánbeli királyságát Ógnak, aki király volt Astárótban és Edréiben – ő maradt meg az óriások maradékából: megverte őket Mózes és kiűzte.
13 Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli kò lé àwọn ará Geṣuri àti Maakati jáde, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé ní àárín àwọn ará Israẹli títí di òní yìí.
És nem űzték ki Izraél fiai a Gesúrit és a Máakhátit; és így lakott Gesúr és Máakhát Izraél között mind e mai napig.
14 Ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Lefi ni kò fi ogún kankan fún, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ pé ọrẹ àfinásun sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ni ogún tiwọn, gẹ́gẹ́ bí o ti ṣèlérí fún wọn.
Csak Lévi törzsének nem adott birtokot; az Örökkévalónak, Izraél Istenének tűzáldozatai – az a birtoka, amint szólt neki.
15 Èyí ni Mose fi fún ẹ̀yà Reubeni ni agbo ilé sí agbo ilé,
Adott Mózes Reúbén fiai törzsének családjaik szerint.
16 láti agbègbè Aroeri ní etí Arnoni Jọ́ọ́jì àti láti ìlú tí ń bẹ láàrín Jọ́ọ́jì, àti gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ìkọjá Medeba
S volt nekik határul: Aróértól, mely az Arnón patak partján van és a város, mely a völgy közepében van és az egész sík föld Médeba mellett.
17 sí Heṣboni àti gbogbo ìlú rẹ̀ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú Diboni, Bamoti Baali, Beti-Baali-Mioni,
Chesbón és mind a városai, melyek a sík földön vannak: Díbón és Bámót-Báal és Bét-Báal-Meón;
18 Jahisa, Kedemoti, Mefaati,
Jahca, Kedémót és Méfáat.
19 Kiriataimu, Sibma, Sereti Ṣahari lórí òkè ní àfonífojì.
Kirjatájim, Szibma és Céret-Hassáchar a Völgy hegyén.
20 Beti-Peori, gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga, àti Beti-Jeṣimoti
Bét-Peór, a Piszga lejtői és Bét-Hajesímót.
21 gbogbo ìlú tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti gbogbo agbègbè Sihoni ọba Amori, tí ó ṣe àkóso Heṣboni. Mose sì ti ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ ìjòyè Midiani, Efi, Rekemu, Suri, Huri àti Reba, àwọn ọmọ ọba pawọ́pọ̀ pẹ̀lú Sihoni tí ó gbé ilẹ̀ náà.
A sík földnek mind a városai és egész királysága Szíchónnak az emóri királyának, aki uralkodott Chesbónban, akit megvert Mózes, őt és Midján fejedelmeit, Evít, Rékemet, Cúrt, Chúrt és Rébát, Szíchón vazallusait, az országban lakókat.
22 Ní àfikún àwọn tí a pa ní ogun, àwọn ọmọ Israẹli fi idà pa Balaamu ọmọ Beori alásọtẹ́lẹ̀.
Bileámot pedig Beór fiát, a varázslót, megölték Izraél fiai karddal az általuk elejtettekhez.
23 Ààlà àwọn ọmọ Reubeni ni etí odò Jordani. Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ ni ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Reubeni ní agbo ilé ní agbo ilé.
S volt Reúbén fiainak határa a Jordán mint határ. Ez Reúbén fiainak birtoka családjaik szerint, a városok meg tanyáik.
24 Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ẹ̀yà Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
És adott Mózes Gád törzsének, Gád fiainak, családjaik szerint.
25 Agbègbè ìlú Jaseri, gbogbo ìlú Gileadi àti ìdajì orílẹ̀-èdè àwọn ọmọ ará Ammoni títí dé Aroeri, ní ẹ̀bá Rabba;
Volt nekik határul: Jáezér és mind a Gileád városai és Ammón fiainak fél országa azon Aróérig, mely Rabba előtt van;
26 àti láti Heṣboni lọ sí Ramati-Mispa àti Betonimu, àti láti Mahanaimu sí agbègbè ìlú Debiri,
és Chesbóntól Rámat-Micpéig és Betónímig, Máchanájimtól Lidebír határáig.
27 àti ní àfonífojì Beti-Haramu, Beti-Nimra, Sukkoti àti Safoni pẹ̀lú ìyókù agbègbè ilẹ̀ Sihoni ọba Heṣboni (ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani, agbègbè rẹ̀ títí dé òpin Òkun Kinnereti).
És a völgyben: Bét-Hárám, Bét-Nimra, Szukkót és Cáfón, Szichón, Chesbón királya, királyságának többi része, a Jordán mint határ a Kinnéret tenger széléig, a Jordánon túl keletről.
28 Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ jẹ́ ogún àwọn ọmọ Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
Ez Gád fiainak birtoka családjaik szerint, a városok meg tanyáik.
29 Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ìdajì ẹ̀yà Manase, èyí ni pé, fún ìdajì ìdílé irú-ọmọ Manase, ní agbo ilé ní agbo ilé.
És adott Mózes Menasse fél törzsének; és volt Menasse fiai fél törzsének családjaik szerint.
30 Ilẹ̀ náà fẹ̀ dé Mahanaimu àti gbogbo Baṣani, gbogbo agbègbè ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani, èyí tí í ṣe ibùgbé Jairi ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú,
Volt a határuk: Máchanájimtól az egész Básán, egész királysága Ógnak, Básánkirályának és mind a Jáír falvai, melyek Básánban vannak, hatvan város;
31 ìdajì Gileadi, àti Aṣtarotu àti Edrei (àwọn ìlú ọba Ogu ní Baṣani). Èyí ni fún irú àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase fún ààbọ̀ àwọn ọmọ Makiri, ní agbo ilé ní agbo ilé.
és fél Gileád, Astárót és Edréi, Óg királyságának városai Básánban Mákhír Menasse fia fiainak, Mákhír fiai felének, családjaik szerint.
32 Èyí ni ogún tí Mose fi fún wọn nígbà tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní ìhà kejì Jordani ní ìlà-oòrùn Jeriko.
Ezek azok, akiknek birtokot adott Mózes Móáb síkságain túl a jeríchói Jordánon keletről.
33 Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yà Lefi, Mose kò fi ogún fún un; Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ní ogún wọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.
Lévi törzsének pedig nem adott Mózes birtokot; az Örökkévaló, Izraél Istene – ő a birtokuk, amint szólt hozzájuk.