< Joshua 13 >

1 Nígbà tí Joṣua sì darúgbó tí ọjọ́ orí rẹ̀ sì pọ̀ jọjọ, Olúwa sọ fún un pé, “Ìwọ ti darúgbó púpọ̀, bẹ́ẹ̀ ni ilẹ̀ sì kù lọ́pọ̀lọ́pọ̀ fún yín láti gbà.
And Joshua he was old he had come in days and he said Yahweh to him you you are old you have come in days and the land it remains much very to take possession of it.
2 “Èyí ni ilẹ̀ tí ó kù: “gbogbo àwọn agbègbè àwọn Filistini, àti ti ara Geṣuri:
This [is] the land which remains all [the] territories of the Philistines and all the Geshurite[s].
3 láti odò Ṣihori ní ìlà-oòrùn Ejibiti sí agbègbè Ekroni ìhà àríwá, gbogbo rẹ̀ ni a kà kún Kenaani (agbègbè ìjòyè Filistini márùn-ún ní Gasa, Aṣdodu, Aṣkeloni, Gitti àti Ekroni; ti àwọn ará Affimu);
From the Shihor which - [is] on [the] face of Egypt and to [the] border of Ekron north-ward to the Canaanite[s] it is reckoned [the] five - [the] rulers of [the] Philistines the Gazite[s] and the Ashdodite[s] the Ashkelonite[s] the Gittite[s] and the Ekronite[s] and the Avvite[s].
4 láti gúúsù; gbogbo ilẹ̀ àwọn ará Kenaani, láti Arah ti àwọn ará Sidoni títí ó fi dé Afeki, agbègbè àwọn ará Amori,
From [the] south all [the] land of the Canaanite[s] and Mearah which [belongs] to the Sidonians to Aphek towards to [the] border of the Amorite[s].
5 àti ilẹ̀ àwọn ará Gebali; àti gbogbo àwọn Lebanoni dé ìlà-oòrùn, láti Baali-Gadi ní ìsàlẹ̀ òkè Hermoni dé Lebo-Hamati.
And the land of the Gebalite[s] and all Lebanon [the] rising of the sun from Baal Gad under [the] mountain of Hermon to Lebo Hamath.
6 “Ní ti gbogbo àwọn olùgbé agbègbè òkè, láti Lebanoni sí Misrefoti-Maimu, àní, gbogbo àwọn ará Sidoni, èmi fúnra mi ní yóò lé wọn jáde ní iwájú àwọn ará Israẹli. Kí o ri dájú pé o pín ilẹ̀ yí fún Israẹli ní ilẹ̀ ìní, gẹ́gẹ́ bí mo ṣe fi àṣẹ fún ọ,
All [the] inhabitants of the hill country from Lebanon to Misrephoth Maim all [the] Sidonians I I will dispossess them from before [the] people of Israel only make fall it to Israel an inheritance just as I have commanded you.
7 pín ilẹ̀ yìí ní ilẹ̀ ìní fún àwọn ẹ̀yà mẹ́sàn-án àti ìdajì ẹ̀yà Manase.”
And therefore apportion the land this an inheritance to [the] nine the tribes and [the] half of the tribe Manasseh.
8 Àwọn ìdajì ẹ̀yà Manase tí ó kù, àti àwọn Reubeni àti àwọn Gadi ti gba ilẹ̀ ìní, tí Mose ti fún wọn ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti fi fún wọn.
With it the Reubenite[s] and the Gadite[s] they had received inheritance their which he had given to them Moses on [the] other side of the Jordan east-ward just as he had given to them Moses [the] servant of Yahweh.
9 Ó sì lọ títí láti Aroeri tí ń bẹ létí àfonífojì Arnoni, àti láti ìlú náà tí ń bẹ ní àárín àfonífojì náà, àti pẹ̀lú gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ Medeba títí dé Diboni.
From Aroer which [is] on [the] edge of [the] wadi of Arnon and the city which [is] in [the] middle of the wadi and all the plain Medeba to Dibon.
10 Gbogbo ìlú Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó ṣe àkóso ní Heṣboni, títí dé ààlà àwọn ará Ammoni.
And all [the] cities of Sihon [the] king of the Amorite[s] who he reigned in Heshbon to [the] border of [the] people of Ammon.
11 Àti Gileadi, ní agbègbè àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, gbogbo òkè Hermoni àti gbogbo Baṣani títí dé Saleka,
And Gilead and [the] territory of the Geshurite[s] and the Maacathite[s] and all [the] mountain of Hermon and all Bashan to Salecah.
12 ìyẹn, gbogbo ilẹ̀ ọba Ogu ní Baṣani, tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei, ẹni tí ó kù nínú àwọn Refaimu ìyókù. Mose ti ṣẹ́gun wọn, ó sì ti gba ilẹ̀ wọn.
All [the] kingdom of Og in Bashan who he reigned in Ashtaroth and in Edrei he he was left one of [the] remnant of the Rephaites and he had defeated them Moses and he had dispossessed them.
13 Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli kò lé àwọn ará Geṣuri àti Maakati jáde, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń gbé ní àárín àwọn ará Israẹli títí di òní yìí.
And not they dispossessed [the] people of Israel the Geshurite[s] and the Maacathite[s] and it has dwelt Geshur and Maacah in [the] midst of Israel until the day this.
14 Ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Lefi ni kò fi ogún kankan fún, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ pé ọrẹ àfinásun sí Olúwa Ọlọ́run Israẹli ni ogún tiwọn, gẹ́gẹ́ bí o ti ṣèlérí fún wọn.
Only to [the] tribe of the Levite[s] not he gave an inheritance [the] fire offerings of Yahweh [the] God of Israel that [was] inheritance its just as he had spoken to it.
15 Èyí ni Mose fi fún ẹ̀yà Reubeni ni agbo ilé sí agbo ilé,
And he gave Moses to [the] tribe of [the] descendants of Reuben to clans their.
16 láti agbègbè Aroeri ní etí Arnoni Jọ́ọ́jì àti láti ìlú tí ń bẹ láàrín Jọ́ọ́jì, àti gbogbo pẹ̀tẹ́lẹ̀ ní ìkọjá Medeba
And it belonged to them the territory from Aroer which [is] on [the] edge of [the] wadi of Arnon and the city which [is] in [the] middle of the wadi and all the plain at Medeba.
17 sí Heṣboni àti gbogbo ìlú rẹ̀ ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, pẹ̀lú Diboni, Bamoti Baali, Beti-Baali-Mioni,
Heshbon and all cities its which [are] in the plain Dibon and Bamoth Baal and Beth Baal Meon.
18 Jahisa, Kedemoti, Mefaati,
And Jahaz and Kedemoth and Mephaath.
19 Kiriataimu, Sibma, Sereti Ṣahari lórí òkè ní àfonífojì.
And Kiriathaim and Sibmah and Zereth Shahar on [the] hill of the valley.
20 Beti-Peori, gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ Pisga, àti Beti-Jeṣimoti
And Beth Peor and [the] slopes of Pisgah and Beth Jeshimoth.
21 gbogbo ìlú tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ àti gbogbo agbègbè Sihoni ọba Amori, tí ó ṣe àkóso Heṣboni. Mose sì ti ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ ìjòyè Midiani, Efi, Rekemu, Suri, Huri àti Reba, àwọn ọmọ ọba pawọ́pọ̀ pẹ̀lú Sihoni tí ó gbé ilẹ̀ náà.
And all [the] cities of the plain and all [the] kingdom of Sihon [the] king of the Amorite[s] who he reigned in Heshbon whom he had defeated Moses him - and [the] leaders of Midian Evi and Rekem and Zur and Hur and Reba [the] princes of Sihon [who] dwelt of the land.
22 Ní àfikún àwọn tí a pa ní ogun, àwọn ọmọ Israẹli fi idà pa Balaamu ọmọ Beori alásọtẹ́lẹ̀.
And Balaam [the] son of Beor the diviner they killed [the] people of Israel with the sword to slain [ones] their.
23 Ààlà àwọn ọmọ Reubeni ni etí odò Jordani. Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ ni ilẹ̀ ìní àwọn ọmọ Reubeni ní agbo ilé ní agbo ilé.
And it was [the] border of [the] descendants of Reuben the Jordan and a territory this [was] [the] inheritance of [the] descendants of Reuben to clans their the cities and villages their.
24 Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ẹ̀yà Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
And he gave Moses to [the] tribe of Gad to [the] descendants of Gad to clans their.
25 Agbègbè ìlú Jaseri, gbogbo ìlú Gileadi àti ìdajì orílẹ̀-èdè àwọn ọmọ ará Ammoni títí dé Aroeri, ní ẹ̀bá Rabba;
And it belonged to them the territory Jazer and all [the] cities of Gilead and [the] half of [the] land of [the] people of Ammon to Aroer which [is] on [the] face of Rabbah.
26 àti láti Heṣboni lọ sí Ramati-Mispa àti Betonimu, àti láti Mahanaimu sí agbègbè ìlú Debiri,
And from Heshbon to Ramath Mizpah and Betonim and from Mahanaim to [the] territory of Lo Debar.
27 àti ní àfonífojì Beti-Haramu, Beti-Nimra, Sukkoti àti Safoni pẹ̀lú ìyókù agbègbè ilẹ̀ Sihoni ọba Heṣboni (ní ìhà ìlà-oòrùn Jordani, agbègbè rẹ̀ títí dé òpin Òkun Kinnereti).
And in the valley Beth Haram and Beth Nimrah and Succoth and Zaphon [the] remainder of [the] kingdom of Sihon [the] king of Heshbon the Jordan and a border to [the] end of [the] sea of Kinnereth [the] other side of the Jordan east-ward.
28 Àwọn ìlú wọ̀nyí àti abúlé rẹ̀ jẹ́ ogún àwọn ọmọ Gadi, ní agbo ilé ní agbo ilé.
This [was] [the] inheritance of [the] descendants of Gad to clans their the cities and villages their.
29 Èyí ni ohun tí Mose ti fi fún ìdajì ẹ̀yà Manase, èyí ni pé, fún ìdajì ìdílé irú-ọmọ Manase, ní agbo ilé ní agbo ilé.
And he gave Moses to [the] half of [the] tribe of Manasseh and it belonged to [the] half of [the] tribe of [the] descendants of Manasseh to clans their.
30 Ilẹ̀ náà fẹ̀ dé Mahanaimu àti gbogbo Baṣani, gbogbo agbègbè ilẹ̀ Ogu ọba Baṣani, èyí tí í ṣe ibùgbé Jairi ní Baṣani, ọgọ́ta ìlú,
And it was territory their from Mahanaim all Bashan all [the] kingdom of - Og [the] king of Bashan and all [the] villages of Jair which [are] in Bashan sixty citi[es].
31 ìdajì Gileadi, àti Aṣtarotu àti Edrei (àwọn ìlú ọba Ogu ní Baṣani). Èyí ni fún irú àwọn ọmọ Makiri ọmọ Manase fún ààbọ̀ àwọn ọmọ Makiri, ní agbo ilé ní agbo ilé.
And [the] half of Gilead and Ashtaroth and Edrei [the] cities of [the] kingdom of Og in Bashan [belong] to [the] descendants of Makir [the] son of Manasseh to [the] half of [the] descendants of Makir to clans their.
32 Èyí ni ogún tí Mose fi fún wọn nígbà tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ Moabu ní ìhà kejì Jordani ní ìlà-oòrùn Jeriko.
These [are that] which he gave as a possession Moses in [the] plains of Moab from [the] other side of [the] Jordan of Jericho east-ward.
33 Ṣùgbọ́n fún ẹ̀yà Lefi, Mose kò fi ogún fún un; Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ní ogún wọn, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí fún wọn.
And to [the] tribe of the Levite[s] not he gave Moses an inheritance Yahweh [the] God of Israel he [was] inheritance their just as he had spoken to them.

< Joshua 13 >