< Joshua 12 >

1 Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí àwọn ará Israẹli ṣẹ́gun, tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, láti odò Arnoni dé òkè Hermoni, pẹ̀lú gbogbo ìhà ìlà-oòrùn aginjù:
Estes pois são os reis da terra, aos quais os filhos de Israel feriram e possuiram a sua terra de além do Jordão ao nascente do sol: desde o ribeiro de Arnon, até ao monte de Hermon, e toda a planície do oriente.
2 Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni. Ó ṣe àkóso láti Aroeri tí ń bẹ ní etí odò Arnoni, láti ìlú tó wà ní àárín àfonífojì náà dé odò Jabbok, èyí tí ó jẹ́ ààlà àwọn ọmọ Ammoni. Pẹ̀lú ìdajì àwọn ará Gileadi.
Sehon, rei dos amorreus, que habitava em Hesbon e que senhoreava desde Aroer, que está à borda do ribeiro de Arnon, e desde o meio do ribeiro, e desde a metade de Gilead, e até ao ribeiro de Jabbok, o termo dos filhos de Ammon;
3 Ó sì ṣe àkóso ní orí ìlà-oòrùn aginjù láti Òkun Kinnereti sí ìhà Òkun ti aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀), sí Beti-Jeṣimoti, àti láti gúúsù lọ dé ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè Pisga.
E desde a campina até ao mar de Cinneroth para o oriente, e até ao mar da campina, o mar salgado para o oriente, pelo caminho de Beth-jesimoth: e desde o sul abaixo de Asdoth-Pisga.
4 Àti agbègbè Ogu ọba Baṣani, ọ̀kan nínú àwọn tí ó kù nínú àwọn ará Refaimu, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei.
Como também o termo de Og, rei de Basan, que era do resto dos gigantes, e que habitava em Astaroth e em Edrei;
5 Ó ṣe àkóso ní orí òkè Hermoni, Saleka, Baṣani títí dé ààlà àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, àti ìdajì Gileadi dé ààlà Sihoni ọba Heṣboni.
E senhoreava no monte Hermon, e em Salcha, e em toda a Basan, até ao termo dos gesureus e dos maacateus, e metade de Gilead, termo de Sehon, rei de Hesbon.
6 Mose ìránṣẹ́ Olúwa àti àwọn ọmọ Israẹli sì borí wọn. Mose ìránṣẹ́ Olúwa sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Reubeni, àwọn ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase kí ó jẹ́ ohun ìní wọn.
A estes Moisés, servo do Senhor, e os filhos de Israel feriram: e Moisés, servo do Senhor, deu esta terra aos rubenitas, e aos gaditas, e à meia tribo de Manasseh em possessão.
7 Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani, láti Baali-Gadi ní àfonífojì Lebanoni sí òkè Halaki, èyí tí o lọ sí ọ̀nà Seiri (Joṣua sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn:
E estes são os reis da terra aos quais feriu Josué e os filhos de Israel de aquém do Jordão para o ocidente, desde Baal-gad, no vale do líbano, até ao monte calvo, que sobe a Seir: e Josué a deu às tribos de Israel em possessão, segundo as suas divisões;
8 ilẹ̀ òkè, ní ẹsẹ̀ òkè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn òkè aginjù, ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè, ní aginjù àti nì gúúsù ilẹ̀ àwọn ará: Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi).
O que havia nas montanhas, e nas planícies, e nas campinas, e nas descidas das águas, e no deserto, e para o sul: o heteu, o amorreu, e o Cananeo, o pherezeu, o heveu, e o jebuseu.
9 Ọba Jeriko, ọ̀kan ọba Ai (tí ó wà nítòsí Beteli), ọ̀kan
O rei de Jericó, um; o rei de Ai, que está ao lado de Bethel, outro;
10 ọba Jerusalẹmu, ọ̀kan ọba Hebroni, ọ̀kan
O rei de Jerusalém, outro; o rei de Hebron, outro;
11 ọba Jarmatu, ọ̀kan ọba Lakiṣi, ọ̀kan
O rei de Jarmuth, outro; o rei de Lachis, outro;
12 ọba Egloni, ọ̀kan ọba Geseri, ọ̀kan
O rei de Eglon, outro; o rei de Geser, outro;
13 ọba Debiri, ọ̀kan ọba Gederi, ọ̀kan
O rei de Debir, outro; o rei de Geder, outro;
14 ọba Horma, ọ̀kan ọba Aradi, ọ̀kan
O rei de Horma, outro; o rei de Harad, outro;
15 ọba Libina, ọ̀kan ọba Adullamu, ọ̀kan
O rei de Libna, outro; o rei de Adullam, outro;
16 ọba Makkeda, ọ̀kan ọba Beteli, ọ̀kan
O rei de Makeda, outro; o rei de Bethel, outro;
17 ọba Tapua, ọ̀kan ọba Heferi, ọ̀kan
O rei de Tappuah, outro; o rei de Hepher, outro;
18 ọba Afeki, ọ̀kan ọba Laṣaroni, ọ̀kan
O rei de Aphek, outro; o rei de Lassaron, outro;
19 ọba Madoni, ọ̀kan ọba Hasori, ọ̀kan
O rei de Madon, outro; o rei de Hazor, outro;
20 ọba Ṣimroni-Meroni, ọ̀kan ọba Akṣafu, ọ̀kan
O rei de Simron-meron, outro; o rei de Achsaph, outro;
21 ọba Taanaki, ọ̀kan ọba Megido, ọ̀kan
O rei de Taanach, outro; o rei de Megiddo, outro;
22 ọba Kedeṣi, ọ̀kan ọba Jokneamu ni Karmeli, ọ̀kan
O rei de Kedes, outro; o rei de Jokneam do Carmel, outro;
23 ọba Dori (ní Nafoti Dori), ọ̀kan ọba Goyimu ní Gilgali, ọ̀kan
O rei de Dor em Nafath-dor, outro; o rei das nações em Gilgal, outro;
24 ọba Tirsa, ọ̀kan. Gbogbo àwọn ọba náà jẹ́ mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
O rei de Tirza, outro: trinta e um reis por todos.

< Joshua 12 >