< Joshua 12 >
1 Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí àwọn ará Israẹli ṣẹ́gun, tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, láti odò Arnoni dé òkè Hermoni, pẹ̀lú gbogbo ìhà ìlà-oòrùn aginjù:
Und dies sind die Könige des Landes, welche die Kinder Israel schlugen, und deren Land sie in Besitz nahmen jenseit des Jordan, gegen Sonnenaufgang, vom Flusse Arnon bis zum Berge Hermon, und die ganze Ebene gegen Osten:
2 Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni. Ó ṣe àkóso láti Aroeri tí ń bẹ ní etí odò Arnoni, láti ìlú tó wà ní àárín àfonífojì náà dé odò Jabbok, èyí tí ó jẹ́ ààlà àwọn ọmọ Ammoni. Pẹ̀lú ìdajì àwọn ará Gileadi.
Sihon, der König der Amoriter, der zu Hesbon wohnte; er herrschte von Aroer an, das am Ufer des Flusses Arnon liegt, und zwar von der Mitte des Flußtales an, und über das halbe Gilead bis an den Fluß Jabbok, die Grenze der Kinder Ammon,
3 Ó sì ṣe àkóso ní orí ìlà-oòrùn aginjù láti Òkun Kinnereti sí ìhà Òkun ti aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀), sí Beti-Jeṣimoti, àti láti gúúsù lọ dé ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè Pisga.
und über die Ebene bis an den See Kinneroth, gegen Osten, und bis an das Meer der Ebene, das Salzmeer, gegen Osten, nach Beth-Jesimoth hin, und gegen Süden unter den Abhängen des Pisga;
4 Àti agbègbè Ogu ọba Baṣani, ọ̀kan nínú àwọn tí ó kù nínú àwọn ará Refaimu, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei.
und das Gebiet Ogs, des Königs von Basan, von dem Überrest der Rephaim, der zu Astaroth und zu Edrei wohnte;
5 Ó ṣe àkóso ní orí òkè Hermoni, Saleka, Baṣani títí dé ààlà àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, àti ìdajì Gileadi dé ààlà Sihoni ọba Heṣboni.
und er herrschte über den Berg Hermon und über Salka und über das ganze Basan, bis an die Grenze der Gesuriter und der Maakathiter, und über das halbe Gilead, die Grenze Sihons, des Königs von Hesbon.
6 Mose ìránṣẹ́ Olúwa àti àwọn ọmọ Israẹli sì borí wọn. Mose ìránṣẹ́ Olúwa sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Reubeni, àwọn ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase kí ó jẹ́ ohun ìní wọn.
Mose, der Knecht Jehovas, und die Kinder Israel schlugen sie; und Mose, der Knecht Jehovas, gab es als Besitztum den Rubenitern und den Gaditern und dem halben Stamme Manasse.
7 Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani, láti Baali-Gadi ní àfonífojì Lebanoni sí òkè Halaki, èyí tí o lọ sí ọ̀nà Seiri (Joṣua sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn:
Und dies sind die Könige des Landes, welche Josua und die Kinder Israel schlugen diesseit des Jordan, nach Westen hin, von Baal-Gad in der Talebene des Libanon, bis an das kahle Gebirge, das gegen Seir aufsteigt. Und Josua gab es den Stämmen Israels als Besitztum, nach ihren Abteilungen,
8 ilẹ̀ òkè, ní ẹsẹ̀ òkè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn òkè aginjù, ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè, ní aginjù àti nì gúúsù ilẹ̀ àwọn ará: Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi).
im Gebirge und in der Niederung und in der Ebene und an den Abhängen und in der Wüste und im Süden: die Hethiter und die Amoriter und die Kanaaniter, die Perisiter, die Hewiter und die Jebusiter:
9 Ọba Jeriko, ọ̀kan ọba Ai (tí ó wà nítòsí Beteli), ọ̀kan
der König von Jericho: einer; der König von Ai, das zur Seite von Bethel liegt, einer;
10 ọba Jerusalẹmu, ọ̀kan ọba Hebroni, ọ̀kan
der König von Jerusalem: einer; der König von Hebron: einer;
11 ọba Jarmatu, ọ̀kan ọba Lakiṣi, ọ̀kan
der König von Jarmuth: einer; der König von Lachis: einer;
12 ọba Egloni, ọ̀kan ọba Geseri, ọ̀kan
der König von Eglon: einer; der König von Geser: einer;
13 ọba Debiri, ọ̀kan ọba Gederi, ọ̀kan
der König von Debir: einer; der König von Geder: einer;
14 ọba Horma, ọ̀kan ọba Aradi, ọ̀kan
der König von Horma: einer; der König von Arad: einer;
15 ọba Libina, ọ̀kan ọba Adullamu, ọ̀kan
der König von Libna: einer; der König von Adullam: einer;
16 ọba Makkeda, ọ̀kan ọba Beteli, ọ̀kan
der König von Makkeda: einer; der König von Bethel: einer;
17 ọba Tapua, ọ̀kan ọba Heferi, ọ̀kan
der König von Tappuach: einer; der König von Hepher: einer;
18 ọba Afeki, ọ̀kan ọba Laṣaroni, ọ̀kan
der König von Aphek: einer; der König von Lascharon: einer;
19 ọba Madoni, ọ̀kan ọba Hasori, ọ̀kan
der König von Madon: einer; der König von Hazor: einer;
20 ọba Ṣimroni-Meroni, ọ̀kan ọba Akṣafu, ọ̀kan
der König von Schimron-Meron: einer; der König von Akschaph: einer;
21 ọba Taanaki, ọ̀kan ọba Megido, ọ̀kan
der König von Taanak: einer; der König von Megiddo: einer;
22 ọba Kedeṣi, ọ̀kan ọba Jokneamu ni Karmeli, ọ̀kan
der König von Kedesch: einer; der König von Jokneam, am Karmel: einer;
23 ọba Dori (ní Nafoti Dori), ọ̀kan ọba Goyimu ní Gilgali, ọ̀kan
der König von Dor, in dem Hügelgebiet von Dor: einer; der König von Gojim zu Gilgal: einer;
24 ọba Tirsa, ọ̀kan. Gbogbo àwọn ọba náà jẹ́ mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
der König von Tirza: einer. Aller Könige waren einunddreißig.