< Joshua 12 >

1 Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí àwọn ará Israẹli ṣẹ́gun, tí wọ́n sì gba ilẹ̀ wọn ní ìlà-oòrùn Jordani, láti odò Arnoni dé òkè Hermoni, pẹ̀lú gbogbo ìhà ìlà-oòrùn aginjù:
Voici les rois que battirent les enfants d’Israël, et dont ils possédèrent la terre au-delà du Jourdain, vers le levant, depuis le torrent d’Arnon jusqu’à la montagne d’Hermon, et toute la contrée orientale qui regarde le désert.
2 Sihoni ọba àwọn Amori, tí ó jẹ ọba ní Heṣboni. Ó ṣe àkóso láti Aroeri tí ń bẹ ní etí odò Arnoni, láti ìlú tó wà ní àárín àfonífojì náà dé odò Jabbok, èyí tí ó jẹ́ ààlà àwọn ọmọ Ammoni. Pẹ̀lú ìdajì àwọn ará Gileadi.
Séhon, roi des Amorrhéens qui habita à Hésébon, et qui régna depuis Aroer, qui est située sur le bord du torrent d’Arnon, au milieu de la vallée, et dans la moitié de Galaad jusqu’au torrent de Jaboc, qui est la frontière des enfants d’Ammon;
3 Ó sì ṣe àkóso ní orí ìlà-oòrùn aginjù láti Òkun Kinnereti sí ìhà Òkun ti aginjù (ti o túmọ̀ sí Òkun Iyọ̀), sí Beti-Jeṣimoti, àti láti gúúsù lọ dé ìsàlẹ̀ ẹsẹ̀ òkè Pisga.
Et depuis le désert jusqu’à la mer du Cénéroth contre l’οrient, et jusqu’à la mer du désert, qui est la mer très salée, vers le côté oriental, par la voie qui mène à Bethsimoth; et depuis la partie australe qui est au-dessous d’Asédoth, jusqu’à Phasga.
4 Àti agbègbè Ogu ọba Baṣani, ọ̀kan nínú àwọn tí ó kù nínú àwọn ará Refaimu, ẹni tí ó jẹ ọba ní Aṣtarotu àti Edrei.
Les limites d’Og, roi de Basan, qui était des restes des Raphaïm, et qui habita à Astaroth et à Edraï, et qui régna à la montagne d’Hermon, à Salécha et dans tout le Basan, s’étendaient jusqu’aux frontières
5 Ó ṣe àkóso ní orí òkè Hermoni, Saleka, Baṣani títí dé ààlà àwọn ènìyàn Geṣuri àti Maakati, àti ìdajì Gileadi dé ààlà Sihoni ọba Heṣboni.
De Gessuri, de Machati et de la moitié de Galaad: frontières de Séhon, roi d’Hésébon.
6 Mose ìránṣẹ́ Olúwa àti àwọn ọmọ Israẹli sì borí wọn. Mose ìránṣẹ́ Olúwa sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Reubeni, àwọn ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase kí ó jẹ́ ohun ìní wọn.
Moïse, serviteur du Seigneur, et les enfants d’Israël battirent ces rois, et Moïse livra leur terre en possession aux Rubénites, aux Gadites et à la demi-tribu de Manassé.
7 Ìwọ̀nyí ní àwọn ọba ilẹ̀ náà tí Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli ṣẹ́gun ní ìhà ìwọ̀-oòrùn Jordani, láti Baali-Gadi ní àfonífojì Lebanoni sí òkè Halaki, èyí tí o lọ sí ọ̀nà Seiri (Joṣua sì fi ilẹ̀ wọn fún àwọn ẹ̀yà Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín ẹ̀yà wọn:
Voici les rois du pays que battirent Josué et les enfants d’Israël au-delà du Jourdain, du côté occidental, depuis Baalgad dans la campagne du Liban jusqu’à la montagne dont une partie s’élève vers Séir: et Josué le donna en possession aux tribus d’Israël, à chacune sa part,
8 ilẹ̀ òkè, ní ẹsẹ̀ òkè ní ìhà ìwọ̀-oòrùn òkè aginjù, ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè, ní aginjù àti nì gúúsù ilẹ̀ àwọn ará: Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti àwọn ará Jebusi).
Tant au milieu des montagnes, que dans la plaine et la campagne. Dans Asédoth, dans le désert et au midi, étaient l’Héthéen et l’Amorrhéen, le Chananéen et le Phérézéen, l’Hévéen et le Jébuséen:
9 Ọba Jeriko, ọ̀kan ọba Ai (tí ó wà nítòsí Beteli), ọ̀kan
Un roi de Jéricho, un roi de Haï, laquelle est à côté de Béthel,
10 ọba Jerusalẹmu, ọ̀kan ọba Hebroni, ọ̀kan
Un roi de Jérusalem, un roi d’Hébron,
11 ọba Jarmatu, ọ̀kan ọba Lakiṣi, ọ̀kan
Un roi de Jérimoth, un roi de Lachis,
12 ọba Egloni, ọ̀kan ọba Geseri, ọ̀kan
Un roi d’Eglon, un roi de Gazer,
13 ọba Debiri, ọ̀kan ọba Gederi, ọ̀kan
Un roi de Dabir, un roi de Gader,
14 ọba Horma, ọ̀kan ọba Aradi, ọ̀kan
Un roi d’Herma, un roi d’Héred,
15 ọba Libina, ọ̀kan ọba Adullamu, ọ̀kan
Un roi de Lebna, un roi d’Odullam,
16 ọba Makkeda, ọ̀kan ọba Beteli, ọ̀kan
Un roi de Macéda, un roi de Béthel,
17 ọba Tapua, ọ̀kan ọba Heferi, ọ̀kan
Un roi de Taphua, un roi d’Opher,
18 ọba Afeki, ọ̀kan ọba Laṣaroni, ọ̀kan
Un roi d’Aphec, un roi de Saron,
19 ọba Madoni, ọ̀kan ọba Hasori, ọ̀kan
Un roi de Madon, un roi d’Asor,
20 ọba Ṣimroni-Meroni, ọ̀kan ọba Akṣafu, ọ̀kan
Un roi de Séméron, un roi d’Achsaph,
21 ọba Taanaki, ọ̀kan ọba Megido, ọ̀kan
Un roi de Thénac, un roi de Mageddo,
22 ọba Kedeṣi, ọ̀kan ọba Jokneamu ni Karmeli, ọ̀kan
Un roi de Cadès, un roi de Jachanan du Carmel,
23 ọba Dori (ní Nafoti Dori), ọ̀kan ọba Goyimu ní Gilgali, ọ̀kan
Un roi de Dor, et de la province de Dor, un roi des nations de Galgal,
24 ọba Tirsa, ọ̀kan. Gbogbo àwọn ọba náà jẹ́ mọ́kànlélọ́gbọ̀n.
Un roi de Thersa: en tout, trente-un rois.

< Joshua 12 >