< Joshua 11 >
1 Nígbà tí Jabini ọba Hasori gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ó ránṣẹ́ sí Jobabu ọba Madoni, sí ọba Ṣimroni àti Akṣafu,
Егда же услыша Иавин царь Асорск, посла ко Иоваву царю Мадонску, и к царю Семеронску и к царю Ахиавску,
2 àti sí àwọn ọba ìhà àríwá tí wọ́n wà ní orí òkè ní aginjù, gúúsù ti Kinnereti, ní ẹsẹ̀ òkè ìwọ̀-oòrùn àti ní Nafoti Dori ní ìwọ̀-oòrùn;
и к царем иже в Сидоне велицем и в горней, и в Араву прямо Хенерефу, и на поляну, и в Нафеддор,
3 sí àwọn ará Kenaani ní ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn; sí àwọn Amori, Hiti, Peresi àti Jebusi ní orí òkè; àti sí àwọn Hifi ní ìsàlẹ̀ Hermoni ní agbègbè Mispa.
и к приморским Хананеам от восток, и к приморским Аморреом и Хеттеом, и Ферезеом и Иевусеом, иже на горе, и Евеом, и иже под Аермоном, в землю Массифа.
4 Wọ́n sì jáde pẹ̀lú gbogbo ogun wọn àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun ńlá, wọ́n sì pọ̀, gẹ́gẹ́ bí iyanrìn etí òkun.
И изыдоша сии и царие их с ними, людие мнози, яко песок иже при краи моря множеством, и кони и колесницы многи зело.
5 Gbogbo àwọn ọba yìí pa ọmọ-ogun wọn pọ̀, wọ́n sì pa ibùdó sí ibi omi Meromu láti bá Israẹli jà.
И снидошася вси царие сии, и приидоша вкупе, и ополчишася при воде Маррон воевати на Израиля.
6 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí ní àkókò yìí ní ọ̀la, gbogbo wọn ni èmi yóò fi lé Israẹli lọ́wọ́ ní pípa. Ìwọ yóò já iṣan ẹ̀yìn ẹṣin wọn, ìwọ yóò sì sun kẹ̀kẹ́ ogun wọn.”
И рече Господь ко Иисусу: не убойся от лица их, яко заутра в сей час Аз предам их язвенных пред сыны Израилевы: конем их жилы пресечеши и колесницы их да сожжеши огнем.
7 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ yọ sí wọn ní òjijì ní ibi omi Meromu, wọ́n sì kọlù wọ́n,
И прииде Иисус и вси людие воинстии с ним на них к воде Марронстей внезапу, и нападоша на ня в горней.
8 Olúwa sì fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́. Wọ́n ṣẹ́gun wọn, wọ́n sì lépa wọn ní gbogbo ọ̀nà títí dé Sidoni ńlá, sí Misrefoti-Maimu, àti sí àfonífojì Mispa ní ìlà-oòrùn, títí tí kò fi ku ẹnìkankan sílẹ̀.
И предаде их Господь под руце Израилевы: и секуще их, прогнаша даже до Сидона великаго и до Масрефоф-Маима и до поль Массифских к востоком: и изсекоша их, дондеже не остася в них ни един цел и избегший.
9 Joṣua sì ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ: Ó sì já iṣan ẹ̀yìn ẹsẹ̀ ẹṣin wọn ó sì sun kẹ̀kẹ́ ogun wọn.
И сотвори им Иисус, якоже заповеда ему Господь: конем их жилы пресече и колесницы их сожже огнем.
10 Ní àkókò náà Joṣua sì padà sẹ́yìn, ó sì ṣẹ́gun Hasori, ó sì fi idà pa ọba rẹ̀. (Hasori tí jẹ́ olú fún gbogbo àwọn ìlú wọ̀nyí kó tó di àkókò yí.)
И обратися Иисус в то время, и взя Асор, и царя его уби мечем: Асор бо бе прежде обладающий всеми царствы сими:
11 Wọ́n sì fi idà pa gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀. Wọ́n sì pa wọ́n run pátápátá, wọn kò sì fi ohun alààyè kan sílẹ̀; ó sì fi iná sun Hasori fúnra rẹ̀.
и изби все дышущее, еже в нем бысть, острием меча, и потребиша вся, и не остася в нем все дышущее: и Асор запалиша огнем.
12 Joṣua sì kó gbogbo àwọn ìlú ọba àti ọba wọn, ó sì fi idà pa wọ́n. Ó sì run gbogbo wọn, gẹ́gẹ́ bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ.
И вся грады царств сих и вся цари их взя Иисус и изби я мечем, и потреби их, якоже повеле им Моисей раб Господень.
13 Síbẹ̀ Israẹli kò sun ọ̀kankan nínú àwọn ìlú tó wà lórí òkè kéékèèké, àyàfi Hasori nìkan tí Joṣua sun.
Но вся грады крепки не запали Израиль, точию Асор един запали Иисус.
14 Àwọn ará Israẹli sì kó gbogbo ìkógun àti ohun ọ̀sìn ti ìlú náà fún ara wọn. Wọ́n sì fi idà pa gbogbo ènìyàn títí wọ́n fi run wọ́n pátápátá, kò sí ẹni tí ó wà láààyè.
И вся корысти их и вся скоты их плениша себе сынове Израилевы: людий же всех потребиша мечем, дондеже погубиша их, и не оставиша от них ни единаго дышущаго.
15 Bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ní Mose pàṣẹ fún Joṣua, Joṣua sì ṣe bẹ́ẹ̀. Kò fi ọ̀kankan sílẹ̀ láìṣe nínú gbogbo ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose.
Якоже повеле Господь Моисею рабу Своему, тако Моисей заповеда Иисусу: и тако сотвори Иисус, не преступи ни единаго же от всех, яже заповеда Господь Моисею.
16 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua gba gbogbo ilẹ̀ náà: ilẹ̀ òkè, gbogbo gúúsù, gbogbo agbègbè Goṣeni, ẹsẹ̀ òkè ti ìwọ̀-oòrùn, aginjù àti àwọn òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀ Israẹli,
И взя Иисус всю землю горную и всю землю нагев, и всю землю Госомску, и равную, и яже на запад, и гору Израилеву, и поля яже при горе,
17 láti òkè Halaki títí dé òkè Seiri, sí Baali-Gadi ní àfonífojì Lebanoni ní ìsàlẹ̀ òkè Hermoni. Ó sì mú gbogbo ọba wọn, ó sì kọlù wọ́n, ó sì pa wọ́n.
от горы Хелха, и яже восходит к Сеиру, и даже до Валгада, и поле Ливана под горою Аермон: и вся цари их взя и изби.
18 Joṣua sì bá gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí jagun ní ọjọ́ pípẹ́.
И многи дни сотвори Иисус с цари сими брань:
19 Kò sí ìlú kan tí ó bá àwọn ará Israẹli ṣe àdéhùn àlàáfíà, àyàfi àwọn ará Hifi tí wọ́n ń gbé ní Gibeoni, gbogbo wọn ló bá a jagun.
и не бе ни единаго града, егоже не предаде Господь сыном Израилевым, кроме Евеа обитающаго в Гаваоне: всех взяша бранию:
20 Nítorí Olúwa fúnra rẹ̀ ní ó sé ọkàn wọn le, kí wọn kí ó lè bá Israẹli jagun, kí òun lè pa wọ́n run pátápátá, kí wọn má sì ṣe rí ojúrere, ṣùgbọ́n kí ó lè pa wọ́n, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
яко Господем бысть укрепитися их сердцу, сопротивитися на брани противу Израиля, да потребят их, яко да не дастся им милость, но да потребятся, якоже глагола Господь к Моисею.
21 Ní àkókò náà ni Joṣua lọ tí ó sì run àwọn ará Anaki kúrò ní ilẹ̀ òkè, láti Hebroni, Debiri, àti ní Anabu, àti gbogbo ilẹ̀ Juda, àti kúrò ní gbogbo ilẹ̀ òkè Israẹli. Joṣua sì run gbogbo wọn pátápátá àti ìlú wọn.
И прииде Иисус в то время, и потреби (вся) Енакимы от горныя, от Хеврона и от Давира и от Анова, и от всея горы Израилевы и от всея горы Иудины, с грады их, и потреби я Иисус:
22 Kò sí ará Anaki kankan tí ó ṣẹ́kù ní ilẹ̀ Israẹli: bí kò ṣe ní Gasa, Gati àti Aṣdodu.
не остася ни един Енаким от сынов Израилевых, но точию в Газе и в Гефе и во Асидофе осташася.
23 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gba gbogbo ilẹ̀ náà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, ó sì fi fún Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn nípa ẹ̀yà wọn. Ilẹ̀ náà sì sinmi ogun.
И взя Иисус всю землю, якоже заповеда Господь Моисею: и даде ю Иисус в наследие Израилю, разделением по племеном их. И преста земля воюема быти.