< Joshua 11 >

1 Nígbà tí Jabini ọba Hasori gbọ́ nǹkan wọ̀nyí, ó ránṣẹ́ sí Jobabu ọba Madoni, sí ọba Ṣimroni àti Akṣafu,
Lorsque Jabin, roi de Hatsor, en eut connaissance, il envoya vers Jobab, roi de Madon, vers le roi de Shimron, vers le roi d'Achshaph,
2 àti sí àwọn ọba ìhà àríwá tí wọ́n wà ní orí òkè ní aginjù, gúúsù ti Kinnereti, ní ẹsẹ̀ òkè ìwọ̀-oòrùn àti ní Nafoti Dori ní ìwọ̀-oòrùn;
vers les rois qui étaient au nord, dans la montagne, dans la plaine au sud de Chinneroth, dans la plaine et sur les hauteurs de Dor, à l'ouest,
3 sí àwọn ará Kenaani ní ìlà-oòrùn àti ìwọ̀-oòrùn; sí àwọn Amori, Hiti, Peresi àti Jebusi ní orí òkè; àti sí àwọn Hifi ní ìsàlẹ̀ Hermoni ní agbègbè Mispa.
aux Cananéens, à l'est et à l'ouest, aux Amoréens, aux Hittites, aux Phéréziens, aux Jébusiens, dans la montagne, et aux Héviens, au pied de l'Hermon, dans le pays de Mitspa.
4 Wọ́n sì jáde pẹ̀lú gbogbo ogun wọn àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹṣin àti kẹ̀kẹ́ ogun ńlá, wọ́n sì pọ̀, gẹ́gẹ́ bí iyanrìn etí òkun.
Ils sortirent, eux et toutes leurs armées avec eux, un peuple nombreux, comme le sable qui est au bord de la mer, en multitude, avec un très grand nombre de chevaux et de chars.
5 Gbogbo àwọn ọba yìí pa ọmọ-ogun wọn pọ̀, wọ́n sì pa ibùdó sí ibi omi Meromu láti bá Israẹli jà.
Tous ces rois se réunirent, et ils vinrent camper ensemble près des eaux de Mérom, pour combattre Israël.
6 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Má ṣe bẹ̀rù wọn, nítorí ní àkókò yìí ní ọ̀la, gbogbo wọn ni èmi yóò fi lé Israẹli lọ́wọ́ ní pípa. Ìwọ yóò já iṣan ẹ̀yìn ẹṣin wọn, ìwọ yóò sì sun kẹ̀kẹ́ ogun wọn.”
Yahvé dit à Josué: « N'aie pas peur à cause d'eux, car demain, à cette heure, je les livrerai tous tués devant Israël. Tu enchaîneras leurs chevaux et tu brûleras au feu leurs chars. »
7 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua àti gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ yọ sí wọn ní òjijì ní ibi omi Meromu, wọ́n sì kọlù wọ́n,
Josué arriva soudain contre eux, avec tous les guerriers, près des eaux de Mérom, et il les attaqua.
8 Olúwa sì fi wọ́n lé Israẹli lọ́wọ́. Wọ́n ṣẹ́gun wọn, wọ́n sì lépa wọn ní gbogbo ọ̀nà títí dé Sidoni ńlá, sí Misrefoti-Maimu, àti sí àfonífojì Mispa ní ìlà-oòrùn, títí tí kò fi ku ẹnìkankan sílẹ̀.
L'Éternel les livra entre les mains d'Israël, qui les battit et les poursuivit jusqu'à la grande Sidon, jusqu'à Misrephoth Maïm, et jusqu'à la vallée de Mitspa, à l'orient. Ils les frappèrent jusqu'à ce qu'il ne restât plus personne.
9 Joṣua sì ṣe sí wọn gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ: Ó sì já iṣan ẹ̀yìn ẹsẹ̀ ẹṣin wọn ó sì sun kẹ̀kẹ́ ogun wọn.
Josué leur fit ce que Yahvé lui avait dit. Il paralysa leurs chevaux et brûla leurs chars par le feu.
10 Ní àkókò náà Joṣua sì padà sẹ́yìn, ó sì ṣẹ́gun Hasori, ó sì fi idà pa ọba rẹ̀. (Hasori tí jẹ́ olú fún gbogbo àwọn ìlú wọ̀nyí kó tó di àkókò yí.)
En ce temps-là, Josué revint sur ses pas, prit Hatsor et frappa son roi par l'épée, car Hatsor était le chef de tous ces royaumes.
11 Wọ́n sì fi idà pa gbogbo àwọn ènìyàn tí ó wà ní ibẹ̀. Wọ́n sì pa wọ́n run pátápátá, wọn kò sì fi ohun alààyè kan sílẹ̀; ó sì fi iná sun Hasori fúnra rẹ̀.
Ils frappèrent du tranchant de l'épée tous ceux qui s'y trouvaient, et les dévorèrent par interdit. Il n'y avait plus personne qui respirait. Il brûla Hazor par le feu.
12 Joṣua sì kó gbogbo àwọn ìlú ọba àti ọba wọn, ó sì fi idà pa wọ́n. Ó sì run gbogbo wọn, gẹ́gẹ́ bí Mose ìránṣẹ́ Olúwa ti pàṣẹ.
Josué prit toutes les villes de ces rois, avec leurs rois, et il les frappa du tranchant de l'épée et les dévoua par interdit, comme l'avait ordonné Moïse, serviteur de l'Éternel.
13 Síbẹ̀ Israẹli kò sun ọ̀kankan nínú àwọn ìlú tó wà lórí òkè kéékèèké, àyàfi Hasori nìkan tí Joṣua sun.
Mais Israël ne brûla aucune des villes situées sur leurs monticules, à l'exception de Hatsor seulement. Josué la brûla.
14 Àwọn ará Israẹli sì kó gbogbo ìkógun àti ohun ọ̀sìn ti ìlú náà fún ara wọn. Wọ́n sì fi idà pa gbogbo ènìyàn títí wọ́n fi run wọ́n pátápátá, kò sí ẹni tí ó wà láààyè.
Les enfants d'Israël prirent tout le butin de ces villes, avec le bétail, comme butin pour eux-mêmes; mais ils frappèrent tous les hommes du tranchant de l'épée, jusqu'à ce qu'ils les eussent détruits. Ils n'ont laissé aucun de ceux qui respiraient.
15 Bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ní Mose pàṣẹ fún Joṣua, Joṣua sì ṣe bẹ́ẹ̀. Kò fi ọ̀kankan sílẹ̀ láìṣe nínú gbogbo ohun tí Olúwa pàṣẹ fún Mose.
Comme Yahvé l'avait ordonné à Moïse, son serviteur, Moïse l'ordonna à Josué. Josué fit ainsi. Il ne négligea rien de tout ce que Yahvé avait ordonné à Moïse.
16 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua gba gbogbo ilẹ̀ náà: ilẹ̀ òkè, gbogbo gúúsù, gbogbo agbègbè Goṣeni, ẹsẹ̀ òkè ti ìwọ̀-oòrùn, aginjù àti àwọn òkè àti pẹ̀tẹ́lẹ̀ Israẹli,
Josué s'empara de tout ce pays, de la montagne, de tout le midi, de tout le pays de Gosen, de la plaine, de la plaine d'Arabie, de la montagne d'Israël et de sa plaine,
17 láti òkè Halaki títí dé òkè Seiri, sí Baali-Gadi ní àfonífojì Lebanoni ní ìsàlẹ̀ òkè Hermoni. Ó sì mú gbogbo ọba wọn, ó sì kọlù wọ́n, ó sì pa wọ́n.
depuis la montagne de Halak, qui monte vers Séir, jusqu'à Baal Gad, dans la vallée du Liban, sous la montagne de l'Hermon. Il prit tous leurs rois, les frappa et les fit mourir.
18 Joṣua sì bá gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí jagun ní ọjọ́ pípẹ́.
Josué fit longtemps la guerre à tous ces rois.
19 Kò sí ìlú kan tí ó bá àwọn ará Israẹli ṣe àdéhùn àlàáfíà, àyàfi àwọn ará Hifi tí wọ́n ń gbé ní Gibeoni, gbogbo wọn ló bá a jagun.
Il n'y eut pas une seule ville qui fit la paix avec les enfants d'Israël, sauf les Hivvites, habitants de Gabaon. Ils les prirent tous dans la bataille.
20 Nítorí Olúwa fúnra rẹ̀ ní ó sé ọkàn wọn le, kí wọn kí ó lè bá Israẹli jagun, kí òun lè pa wọ́n run pátápátá, kí wọn má sì ṣe rí ojúrere, ṣùgbọ́n kí ó lè pa wọ́n, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose.
Car c'était la volonté de l'Éternel d'endurcir leur cœur, de venir contre Israël dans la bataille, pour les dévaster, pour qu'ils n'aient aucune faveur, mais pour les détruire, comme l'Éternel l'avait ordonné à Moïse.
21 Ní àkókò náà ni Joṣua lọ tí ó sì run àwọn ará Anaki kúrò ní ilẹ̀ òkè, láti Hebroni, Debiri, àti ní Anabu, àti gbogbo ilẹ̀ Juda, àti kúrò ní gbogbo ilẹ̀ òkè Israẹli. Joṣua sì run gbogbo wọn pátápátá àti ìlú wọn.
Josué arriva en ce temps-là, et il extermina les Anakim de la montagne, d'Hébron, de Debir, d'Anab, de toute la montagne de Juda et de toute la montagne d'Israël. Josué les dévoua par interdit, avec leurs villes.
22 Kò sí ará Anaki kankan tí ó ṣẹ́kù ní ilẹ̀ Israẹli: bí kò ṣe ní Gasa, Gati àti Aṣdodu.
Il ne resta aucun des Anakim dans le pays des enfants d'Israël. Il en resta seulement à Gaza, à Gath et à Asdod.
23 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gba gbogbo ilẹ̀ náà, gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti pàṣẹ fún Mose, ó sì fi fún Israẹli ní ilẹ̀ ìní gẹ́gẹ́ bí ìpín wọn nípa ẹ̀yà wọn. Ilẹ̀ náà sì sinmi ogun.
Josué prit tout le pays, selon tout ce que l'Éternel avait dit à Moïse, et il le donna en héritage à Israël, selon ses tribus. Et le pays fut en repos de la guerre.

< Joshua 11 >