< Joshua 10 >

1 Ní báyìí tí Adoni-Sedeki ọba Jerusalẹmu gbọ́ pé Joṣua ti gba Ai, tí ó sì ti pa wọ́n pátápátá; tí ó sì ṣe sí Ai àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Jeriko àti ọba rẹ̀, àti bí àwọn ènìyàn Gibeoni ti ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú Israẹli, tí wọ́n sì ń gbé nítòsí wọn.
Agora quando Adoni-Zedeque, rei de Jerusalém, ouviu como Josué havia tomado Ai, e o havia destruído completamente; como havia feito com Jericó e seu rei, assim fez com Ai e seu rei; e como os habitantes de Gibeon haviam feito as pazes com Israel, e estavam entre eles,
2 Ìbẹ̀rù sì mú òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀ torí pé Gibeoni jẹ́ ìlú tí ó ṣe pàtàkì, bí ọ̀kan nínú àwọn ìlú ọba; ó tóbi ju Ai lọ, gbogbo ọkùnrin rẹ̀ ní ó jẹ́ jagunjagun.
eles tinham muito medo, porque Gibeon era uma grande cidade, como uma das cidades reais, e porque era maior que Ai, e todos os seus homens eram poderosos.
3 Nítorí náà Adoni-Sedeki ọba Jerusalẹmu bẹ Hohamu ọba Hebroni, Piramu ọba Jarmatu, Jafia ọba Lakiṣi àti Debiri ọba Egloni. Wí pe,
Portanto Adoni-Zedek, rei de Jerusalém, enviou a Hoham rei de Hebron, Piram rei de Jarmuth, Japhia rei de Laquis, e Debir rei de Eglon, dizendo:
4 “Ẹ gòkè wá, kí ẹ sì ràn mi lọ́wọ́ láti kọlu Gibeoni, nítorí tí ó ti wà ní ìrẹ́pọ̀ pẹ̀lú Joṣua àti àwọn ará Israẹli.”
“Venha até mim e me ajude”. Vamos atacar Gibeon; pois eles fizeram as pazes com Josué e com os filhos de Israel”.
5 Àwọn ọba Amori márààrún, ọba Jerusalẹmu, Hebroni, Jarmatu, Lakiṣi àti Egloni, kó ara wọn jọ, wọ́n sì gòkè, àwọn àti gbogbo ogun wọn, wọ́n sì dojúkọ Gibeoni, wọ́n sì kọlù ú.
Therefore os cinco reis dos amorreus, o rei de Jerusalém, o rei de Hebron, o rei de Jarmute, o rei de Laquis e o rei de Eglon, se reuniram e subiram, eles e todos os seus exércitos, e acamparam contra Gibeon, e fizeram guerra contra ele.
6 Àwọn ará Gibeoni sì ránṣẹ́ sí Joṣua ní ibùdó ní Gilgali pé, “Ẹ má ṣe fi ìránṣẹ́ yín sílẹ̀. Ẹ gòkè tọ̀ wà wá ní kánkán kí ẹ sì gbà wá là. Ẹ ràn wá lọ́wọ́, nítorí gbogbo àwọn ọba Amori tí ń gbé ní orílẹ̀-èdè òkè dojú ìjà kọ wá.”
Os homens de Gibeon enviaram a Josué no acampamento em Gilgal, dizendo: “Não abandone seus servos! Venha até nós rapidamente e nos salve! Ajude-nos; pois todos os reis dos amorreus que habitam na região montanhosa se reuniram contra nós”.
7 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua gòkè lọ láti Gilgali pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, àti akọni nínú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
Então Josué subiu de Gilgal, ele e todo o exército com ele, incluindo todos os poderosos homens de valor.
8 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Má ṣe bẹ̀rù wọn, Mo ti fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́. Kò sí ẹnikẹ́ni nínú wọn ti yóò lè dojúkọ ọ́.”
Yahweh disse a Joshua: “Não tenha medo deles, pois eu os entreguei em suas mãos”. Nem um homem deles estará diante de você”.
9 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti wọ́de ogun ní gbogbo òru náà láti Gilgali, Joṣua sì yọ sí wọn lójijì.
Joshua, portanto, chegou a eles de repente. Ele marchou de Gilgal a noite toda.
10 Olúwa mú kí wọn dààmú níwájú àwọn Israẹli, wọ́n sì pa wọ́n ní ìpakúpa ní Gibeoni. Israẹli sì lépa wọn ní ọ̀nà tí ó lọ sí Beti-Horoni, ó sì pa wọ́n dé Aseka, àti Makkeda.
Yahweh confundiu-os diante de Israel. Ele os matou com uma grande matança em Gibeon, e os perseguiu pelo caminho da ascensão de Beth Horon, e os atingiu até Azekah e até Makkedah.
11 Bí wọ́n sì tí ń sá ní iwájú Israẹli ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ ní ọ̀nà láti Beti-Horoni títí dé Aseka, Olúwa rọ yìnyín ńlá sí wọn láti ọ̀run wá, àwọn tí ó ti ipa yìnyín kú sì pọ̀ ju àwọn tí àwọn ará Israẹli fi idà pa lọ.
Quando fugiram de antes de Israel, enquanto estavam na descida de Beth Horon, Yahweh atirou grandes pedras do céu sobre eles para Azekah, e eles morreram. Havia mais pessoas que morreram das pedras de granizo do que aquelas que os filhos de Israel mataram com a espada.
12 Ní ọjọ́ tí Olúwa fi àwọn ọmọ Amori lé Israẹli lọ́wọ́, Joṣua sọ fún Olúwa níwájú àwọn ará Israẹli, “Ìwọ oòrùn, dúró jẹ́ẹ́ ní orí Gibeoni, Ìwọ òṣùpá, dúró jẹ́ẹ́ lórí àfonífojì Aijaloni.”
Então Josué falou a Javé no dia em que Javé entregou os amorreus diante dos filhos de Israel. Ele disse aos olhos de Israel: “Sol, fique parado em Gibeon! Tu, lua, pára no vale de Aijalon”!
13 Bẹ́ẹ̀ ni oòrùn náà sì dúró jẹ́ẹ́, òṣùpá náà sì dúró, títí tí ìlú náà fi gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ́ nínú ìwé Jaṣari. Oòrùn sì dúró ní agbede-méjì ọ̀run, kò sì wọ̀ ní ìwọ̀n odindi ọjọ́ kan.
O sol ficou parado, e a lua permaneceu, até que a nação se vingasse de seus inimigos. Isto não está escrito no livro de Jashar? O sol permaneceu no meio do céu, e não se apressou a se pôr por um dia inteiro.
14 Kò sí ọjọ́ tí o dàbí rẹ̀ ṣáájú tàbí ní ẹ̀yìn rẹ̀, ọjọ́ tí Olúwa gbọ́ ohùn ènìyàn. Dájúdájú Olúwa jà fún Israẹli!
Não havia um dia assim antes ou depois, que Iavé ouvisse a voz de um homem; pois Iavé lutou por Israel.
15 Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli padà sí ibùdó ní Gilgali.
Josué voltou, e todo Israel com ele, ao acampamento em Gilgal.
16 Ní báyìí àwọn ọba Amori márùn-ún ti sálọ, wọ́n sì fi ara pamọ́ nínú ihò àpáta kan ní Makkeda,
Estes cinco reis fugiram, e se esconderam na caverna em Makkedah.
17 nígbà tí wọ́n sọ fún Joṣua pé, a ti rí àwọn ọba márààrún, ti ó fi ara pamọ́ nínú ihò àpáta ní Makkeda,
Foi dito a Josué, dizendo: “Os cinco reis foram encontrados, escondidos na caverna em Makkedah”.
18 ó sì wí pé, “Ẹ yí òkúta ńlá dí ẹnu ihò àpáta náà, kí ẹ sì yan àwọn ọkùnrin sí ibẹ̀ láti ṣọ́ ọ.
Joshua disse: “Enrole grandes pedras para cobrir a entrada da caverna, e coloque homens ao seu lado para protegê-los;
19 Ṣùgbọ́n, ẹ má ṣe dúró! Ẹ lépa àwọn ọ̀tá yín, ẹ kọlù wọ́n láti ẹ̀yìn, kí ẹ má ṣe jẹ́ kí wọn kí ó dé ìlú wọn, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín tí fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
mas não fique lá. Persiga seus inimigos e ataque-os pela retaguarda”. Não permita que entrem em suas cidades; pois Yahweh seu Deus os entregou em suas mãos”.
20 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli pa wọ́n ní ìpakúpa wọ́n sì pa gbogbo ọmọ-ogun àwọn ọba márààrún run, àyàfi àwọn díẹ̀ tí wọ́n tiraka láti dé ìlú olódi wọn.
Quando Josué e as crianças de Israel terminaram de matá-los com um grande massacre até serem consumidos, e o resto que restava deles tinha entrado nas cidades fortificadas,
21 Gbogbo àwọn ọmọ-ogun sì padà sí ọ̀dọ̀ Joṣua ní ibùdó ogun ní Makkeda ní àlàáfíà, kò sí àwọn tí ó dábàá láti tún kọlu Israẹli.
todo o povo voltou ao acampamento para Josué em Makkedah em paz. Nenhum mexeu sua língua contra nenhuma das crianças de Israel.
22 Joṣua sì wí pe, “Ẹ ṣí ẹnu ihò náà, kí ẹ sì mú àwọn ọba márààrún jáde wá fún mi.”
Então Josué disse: “Abra a entrada da caverna e traga aqueles cinco reis para fora da caverna até mim”.
23 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú àwọn ọba márààrún náà kúrò nínú ihò àpáta, àwọn ọba Jerusalẹmu, Hebroni, Jarmatu, Lakiṣi àti Egloni.
Eles o fizeram e lhe trouxeram aqueles cinco reis da caverna: o rei de Jerusalém, o rei de Hebron, o rei de Jarmuth, o rei de Laquis e o rei de Eglon.
24 Nígbà tí wọ́n mú àwọn ọba náà tọ Joṣua wá, ó pe gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli, ó sì sọ fún àwọn olórí ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pé, “Ẹ súnmọ́ bí, kí ẹ sì fi ẹsẹ̀ yín lé ọrùn àwọn ọba wọ̀nyí.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wá sí iwájú, wọ́n sì gbé ẹsẹ̀ lé ọrùn wọn.
Quando eles trouxeram aqueles reis para Josué, Josué chamou todos os homens de Israel e disse aos chefes dos homens de guerra que foram com ele: “Cheguem perto. Ponham seus pés no pescoço desses reis”. Eles se aproximaram e colocaram seus pés no pescoço.
25 Joṣua sì sọ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ ṣe gírí, kí ẹ sì mú àyà le. Báyìí ni Olúwa yóò ṣe sí gbogbo àwọn ọ̀tá yín, tí ẹ̀yin yóò bá jà.”
Joshua disse-lhes: “Não tenham medo, nem se desesperem. Sejam fortes e corajosos, pois Yahweh fará isso com todos os seus inimigos contra os quais vocês lutam”.
26 Nígbà náà ni Joṣua kọlù wọ́n, ó sì pa àwọn ọba márààrún náà, ó sì so wọ́n rọ̀ ní orí igi ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ márùn-ún, wọ́n sì fi wọ́n sí orí igi títí di ìrọ̀lẹ́.
Depois disso, Joshua os atingiu, os matou e os enforcou em cinco árvores. Eles foram pendurados nas árvores até a noite.
27 Nígbà tí oòrùn wọ̀, Joṣua pàṣẹ, wọ́n sì sọ̀ wọ́n kalẹ̀ kúrò ní orí igi, wọ́n sì gbé wọn jù sí inú ihò àpáta ní ibi tí wọ́n sá pamọ́ sí. Wọ́n sì fi òkúta ńlá dí ẹnu ihò náà, tí ó sì wà níbẹ̀ di òní yìí.
No momento do pôr do sol, Josué ordenou, e eles os tiraram das árvores, e os jogaram na caverna em que se haviam escondido, e colocaram grandes pedras na boca da caverna, que permanecem até hoje.
28 Ní ọjọ́ náà Joṣua gba Makkeda. Ó sì fi ojú idà kọlu ìlú náà àti ọba rẹ̀, ó sì run gbogbo wọn pátápátá, kò fi ẹnìkan sílẹ̀. Ó sì ṣe sí ọba Makkeda gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe sí ọba Jeriko.
Josué tomou Makkedah naquele dia, e o golpeou com o fio da espada, com seu rei. Ele a destruiu completamente e a todas as almas que estavam nela. Ele não deixou ninguém restante. Ele fez com o rei de Makkedah como havia feito com o rei de Jericó.
29 Nígbà náà ní Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Makkeda lọ sí Libina wọ́n sì kọlù ú.
Josué passou de Makkedah, e todo Israel com ele, para Libnah, e lutou contra Libnah.
30 Olúwa sì fi ìlú náà àti ọba rẹ̀ lé Israẹli lọ́wọ́. Ìlú náà àti gbogbo àwọn ènìyàn ibẹ̀ ni Joṣua fi idà pa. Kò fi ẹnìkan sílẹ̀ ní ibẹ̀: Ó sì ṣe sí ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí ọba Jeriko.
Yahweh também o entregou, com seu rei, nas mãos de Israel. Ele a golpeou com o fio da espada, e todas as almas que estavam nela. Ele não deixou ninguém que nela permanecesse. Ele fez com seu rei, como havia feito com o rei de Jericó.
31 Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo ará Israẹli, tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Libina lọ sí Lakiṣi; ó sì dó tì í, ó sì kọlù ú.
Josué passou de Libnah, e todo Israel com ele, para Laquis, e se acampou contra ele, e lutou contra ele.
32 Olúwa sì fi Lakiṣi lé Israẹli lọ́wọ́, Joṣua sì gbà á ní ọjọ́ kejì. Ìlú náà àti gbogbo ènìyàn ibẹ̀ ní ó fi idà pa gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Libina.
Yahweh entregou Laquis nas mãos de Israel. Ele o tomou no segundo dia, e o atingiu com o fio da espada, com todas as almas que estavam nele, de acordo com tudo o que ele havia feito a Libnah.
33 Ní àkókò yìí, Horamu ọba Geseri gòkè láti ran Lakiṣi lọ́wọ́, ṣùgbọ́n Joṣua ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ títí ti kò fi ku ẹnìkan sílẹ̀.
Então Horam, rei de Gezer, subiu para ajudar Laquis; e Josué bateu nele e em seu povo, até que ele não lhe deixou mais ninguém.
34 Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Lakiṣi lọ sí Egloni; wọ́n sì dó tì í, wọ́n sì kọlù ú.
Josué passou de Laquis, e todo Israel com ele, para Eglon; e eles acamparam contra ele e lutaram contra ele.
35 Wọ́n gbà á ní ọjọ́ náà, wọ́n sì fi ojú idà kọlù ú, wọ́n sì run gbogbo ènìyàn ibẹ̀ pátápátá, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe sí Lakiṣi.
Eles a pegaram naquele dia, e a golpearam com o fio da espada. Ele destruiu completamente todas as almas que estavam nele naquele dia, de acordo com tudo o que ele havia feito a Laquis.
36 Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli ṣí láti Egloni lọ sí Hebroni, wọ́n sì kọlù ú.
Josué subiu de Eglon, e todo Israel com ele, para Hebron; e eles lutaram contra isso.
37 Wọ́n gba ìlú náà, wọ́n sì ti idà bọ̀ ọ́, pẹ̀lú ọba rẹ̀, gbogbo ìletò wọn àti gbogbo ènìyàn ibẹ̀. Wọn kò dá ẹnìkan sí. Gẹ́gẹ́ bí ti Egloni, wọ́n run un pátápátá àti gbogbo ènìyàn inú rẹ̀.
Eles a pegaram, e a golpearam com o fio da espada, com seu rei e todas as suas cidades, e todas as almas que estavam dentro dela. Ele não deixou ninguém restante, de acordo com tudo o que havia feito a Eglon; mas ele a destruiu totalmente, e todas as almas que estavam nela.
38 Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ yí padà, wọ́n sì kọlu Debiri.
Josué voltou, e todo Israel com ele, a Debir, e lutou contra isso.
39 Wọ́n gba ìlú náà, ọba rẹ̀ àti gbogbo ìlú wọn, wọ́n sì fi idà pa wọ́n. Gbogbo ènìyàn inú rẹ̀ ni wọ́n parun pátápátá. Wọn kò sì dá ẹnìkankan sí. Wọ́n ṣe sí Debiri àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí wọn ti ṣe sí Libina àti ọba rẹ̀ àti sí Hebroni.
Ele o levou, com seu rei e todas as suas cidades. Eles os atingiram com o fio da espada, e destruíram completamente todas as almas que estavam nela. Ele não deixou ninguém restante. Como havia feito com Hebron, assim fez com Debir, e com seu rei; como havia feito também com Libnah, e com seu rei.
40 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ṣẹ́gun gbogbo agbègbè náà, ìlú òkè, gúúsù, ìlú ẹsẹ̀ òkè ti ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè pẹ̀lú gbogbo ọba, wọn kò dá ẹnìkankan sí. Ó pa gbogbo ohun alààyè run pátápátá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti pàṣẹ.
Então Josué atingiu toda a terra, a região montanhosa, o Sul, as terras baixas, as encostas e todos os seus reis. Ele não deixou ninguém restante, mas destruiu completamente tudo o que respirava, como ordenou Yahweh, o Deus de Israel.
41 Joṣua sì ṣẹ́gun wọn láti Kadeṣi-Barnea sí Gasa àti láti gbogbo agbègbè Goṣeni lọ sí Gibeoni.
Josué os atingiu desde Kadesh Barnea até Gaza, e todo o país de Goshen, até Gibeon.
42 Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí àti ilẹ̀ wọn ní Joṣua ṣẹ́gun ní ìwọ́de ogun ẹ̀ẹ̀kan, nítorí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, jà fún Israẹli.
Josué tomou todos esses reis e suas terras de uma só vez porque Javé, o Deus de Israel, lutou por Israel.
43 Nígbà náà ni Joṣua padà sí ibùdó ní Gilgali pẹ̀lú gbogbo Israẹli.
Josué voltou, e todo Israel com ele, ao acampamento em Gilgal.

< Joshua 10 >