< Joshua 10 >

1 Ní báyìí tí Adoni-Sedeki ọba Jerusalẹmu gbọ́ pé Joṣua ti gba Ai, tí ó sì ti pa wọ́n pátápátá; tí ó sì ṣe sí Ai àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Jeriko àti ọba rẹ̀, àti bí àwọn ènìyàn Gibeoni ti ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú Israẹli, tí wọ́n sì ń gbé nítòsí wọn.
And it was when heard Adoni-Zedek [the] king of Jerusalem that he had captured Joshua Ai and he had totally destroyed it just as he had done to Jericho and to king its so he had done to Ai and to king its and that they had made peace [the] inhabitants of Gibeon with Israel and they were in midst their.
2 Ìbẹ̀rù sì mú òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀ torí pé Gibeoni jẹ́ ìlú tí ó ṣe pàtàkì, bí ọ̀kan nínú àwọn ìlú ọba; ó tóbi ju Ai lọ, gbogbo ọkùnrin rẹ̀ ní ó jẹ́ jagunjagun.
And they were afraid very for [was] a city great Gibeon like one of [the] cities of royalty and for it [was] great more than Ai and all men its [were] warriors.
3 Nítorí náà Adoni-Sedeki ọba Jerusalẹmu bẹ Hohamu ọba Hebroni, Piramu ọba Jarmatu, Jafia ọba Lakiṣi àti Debiri ọba Egloni. Wí pe,
And he sent Adoni-Zedek [the] king of Jerusalem to Hoham [the] king of Hebron and to Piram [the] king of Jarmuth and to Japhia [the] king of Lachish and to Debir [the] king of Eglon saying.
4 “Ẹ gòkè wá, kí ẹ sì ràn mi lọ́wọ́ láti kọlu Gibeoni, nítorí tí ó ti wà ní ìrẹ́pọ̀ pẹ̀lú Joṣua àti àwọn ará Israẹli.”
Come up to me and help me so we may attack Gibeon for it has made peace with Joshua and with [the] people of Israel.
5 Àwọn ọba Amori márààrún, ọba Jerusalẹmu, Hebroni, Jarmatu, Lakiṣi àti Egloni, kó ara wọn jọ, wọ́n sì gòkè, àwọn àti gbogbo ogun wọn, wọ́n sì dojúkọ Gibeoni, wọ́n sì kọlù ú.
And they gathered and they went up [the] five - [the] kings of the Amorite[s] [the] king of Jerusalem [the] king of Hebron [the] king of Jarmuth [the] king of Lachish [the] king of Eglon they and all armies their and they encamped on Gibeon and they waged war on it.
6 Àwọn ará Gibeoni sì ránṣẹ́ sí Joṣua ní ibùdó ní Gilgali pé, “Ẹ má ṣe fi ìránṣẹ́ yín sílẹ̀. Ẹ gòkè tọ̀ wà wá ní kánkán kí ẹ sì gbà wá là. Ẹ ràn wá lọ́wọ́, nítorí gbogbo àwọn ọba Amori tí ń gbé ní orílẹ̀-èdè òkè dojú ìjà kọ wá.”
And they sent [the] men of Gibeon to Joshua to the camp Gilgal towards saying may not you let drop hands your from servants your come up to us quickly and save! us and help us for they have gathered together against us all [the] kings of the Amorite[s] [the] inhabitants of the hill country.
7 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua gòkè lọ láti Gilgali pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, àti akọni nínú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
And he went up Joshua from Gilgal he and all [the] people of war with him and all [the] mighty [men] of strength.
8 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Má ṣe bẹ̀rù wọn, Mo ti fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́. Kò sí ẹnikẹ́ni nínú wọn ti yóò lè dojúkọ ọ́.”
And he said Yahweh to Joshua may not you be afraid from them for in hand your I have given them not he will make a stand anyone from them in face your.
9 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti wọ́de ogun ní gbogbo òru náà láti Gilgali, Joṣua sì yọ sí wọn lójijì.
And he came to them Joshua suddenly all the night he had gone up from Gilgal.
10 Olúwa mú kí wọn dààmú níwájú àwọn Israẹli, wọ́n sì pa wọ́n ní ìpakúpa ní Gibeoni. Israẹli sì lépa wọn ní ọ̀nà tí ó lọ sí Beti-Horoni, ó sì pa wọ́n dé Aseka, àti Makkeda.
And he routed them Yahweh before Israel and he struck down them a defeat great at Gibeon and he pursued them [the] direction of [the] ascent of Beth Horon and he struck down them to Azekah and to Makkedah.
11 Bí wọ́n sì tí ń sá ní iwájú Israẹli ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ ní ọ̀nà láti Beti-Horoni títí dé Aseka, Olúwa rọ yìnyín ńlá sí wọn láti ọ̀run wá, àwọn tí ó ti ipa yìnyín kú sì pọ̀ ju àwọn tí àwọn ará Israẹli fi idà pa lọ.
And it was when fled they - from before Israel they [were] at [the] descent of Beth Horon and Yahweh he threw on them stones large from the heavens to Azekah and they died [were] many [those] who they died by [the] stones of the hail more than [those] whom they killed [the] people of Israel with the sword.
12 Ní ọjọ́ tí Olúwa fi àwọn ọmọ Amori lé Israẹli lọ́wọ́, Joṣua sọ fún Olúwa níwájú àwọn ará Israẹli, “Ìwọ oòrùn, dúró jẹ́ẹ́ ní orí Gibeoni, Ìwọ òṣùpá, dúró jẹ́ẹ́ lórí àfonífojì Aijaloni.”
Then he spoke Joshua to Yahweh on [the] day delivered up Yahweh the Amorite[s] before [the] people of Israel and he said - to [the] eyes of Israel O sun at Gibeon be still and O moon in [the] valley Aijalon.
13 Bẹ́ẹ̀ ni oòrùn náà sì dúró jẹ́ẹ́, òṣùpá náà sì dúró, títí tí ìlú náà fi gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ́ nínú ìwé Jaṣari. Oòrùn sì dúró ní agbede-méjì ọ̀run, kò sì wọ̀ ní ìwọ̀n odindi ọjọ́ kan.
And it was still the sun and [the] moon it stood still until it avenged itself on [the] nation enemies its ¿ not [is] it written on [the] scroll of Jashar and it stood still the sun in [the] middle of the heavens and not it hastened to go about a day complete.
14 Kò sí ọjọ́ tí o dàbí rẹ̀ ṣáájú tàbí ní ẹ̀yìn rẹ̀, ọjọ́ tí Olúwa gbọ́ ohùn ènìyàn. Dájúdájú Olúwa jà fún Israẹli!
And not it has been like the day that before it and after it to listen Yahweh to [the] voice of a man for Yahweh [was] fighting for Israel.
15 Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli padà sí ibùdó ní Gilgali.
And he returned Joshua and all Israel with him to the camp Gilgal towards.
16 Ní báyìí àwọn ọba Amori márùn-ún ti sálọ, wọ́n sì fi ara pamọ́ nínú ihò àpáta kan ní Makkeda,
And they fled [the] five the kings these and they hid themselves in the cave at Makkedah.
17 nígbà tí wọ́n sọ fún Joṣua pé, a ti rí àwọn ọba márààrún, ti ó fi ara pamọ́ nínú ihò àpáta ní Makkeda,
And it was told to Joshua saying they have been found [the] five the kings hidden in the cave at Makkedah.
18 ó sì wí pé, “Ẹ yí òkúta ńlá dí ẹnu ihò àpáta náà, kí ẹ sì yan àwọn ọkùnrin sí ibẹ̀ láti ṣọ́ ọ.
And he said Joshua roll stones large into [the] mouth of the cave and appoint over it men to guard them.
19 Ṣùgbọ́n, ẹ má ṣe dúró! Ẹ lépa àwọn ọ̀tá yín, ẹ kọlù wọ́n láti ẹ̀yìn, kí ẹ má ṣe jẹ́ kí wọn kí ó dé ìlú wọn, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín tí fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
And you may not you delay pursue after enemies your and you will attack in [the] rear them may not you permit them to go into cities their for he has given them Yahweh God your in hand your.
20 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli pa wọ́n ní ìpakúpa wọ́n sì pa gbogbo ọmọ-ogun àwọn ọba márààrún run, àyàfi àwọn díẹ̀ tí wọ́n tiraka láti dé ìlú olódi wọn.
And it was when finished Joshua and [the] people of Israel to strike down them a defeat great very until were finished they and the survivors they survived of them and they went into [the] cities of fortification.
21 Gbogbo àwọn ọmọ-ogun sì padà sí ọ̀dọ̀ Joṣua ní ibùdó ogun ní Makkeda ní àlàáfíà, kò sí àwọn tí ó dábàá láti tún kọlu Israẹli.
And they returned all the people to the camp to Joshua Makkedah in peace not he sharpened to [the] people of Israel to anyone tongue his.
22 Joṣua sì wí pe, “Ẹ ṣí ẹnu ihò náà, kí ẹ sì mú àwọn ọba márààrún jáde wá fún mi.”
And he said Joshua open [the] mouth of the cave and bring out to me [the] five the kings these from the cave.
23 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú àwọn ọba márààrún náà kúrò nínú ihò àpáta, àwọn ọba Jerusalẹmu, Hebroni, Jarmatu, Lakiṣi àti Egloni.
And they did thus and they brought out to him [the] five the kings these from the cave - [the] king of Jerusalem [the] king of Hebron [the] king of Jarmuth [the] king of Lachish [the] king of Eglon.
24 Nígbà tí wọ́n mú àwọn ọba náà tọ Joṣua wá, ó pe gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli, ó sì sọ fún àwọn olórí ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pé, “Ẹ súnmọ́ bí, kí ẹ sì fi ẹsẹ̀ yín lé ọrùn àwọn ọba wọ̀nyí.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wá sí iwájú, wọ́n sì gbé ẹsẹ̀ lé ọrùn wọn.
And it was when brought out they the kings these to Joshua and he summoned Joshua every man of Israel and he said to [the] commanders of [the] men of war who had gone with him draw near put feet your on [the] necks of the kings these and they drew near and they put feet their on necks their.
25 Joṣua sì sọ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ ṣe gírí, kí ẹ sì mú àyà le. Báyìí ni Olúwa yóò ṣe sí gbogbo àwọn ọ̀tá yín, tí ẹ̀yin yóò bá jà.”
And he said to them Joshua may not you be afraid and may not you be dismayed be strong and be bold for thus he will do Yahweh to all enemies your whom you [are] fighting them.
26 Nígbà náà ni Joṣua kọlù wọ́n, ó sì pa àwọn ọba márààrún náà, ó sì so wọ́n rọ̀ ní orí igi ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ márùn-ún, wọ́n sì fi wọ́n sí orí igi títí di ìrọ̀lẹ́.
And he struck them Joshua after thus and he killed them and he hanged them on five trees and they were hanged on the trees until the evening.
27 Nígbà tí oòrùn wọ̀, Joṣua pàṣẹ, wọ́n sì sọ̀ wọ́n kalẹ̀ kúrò ní orí igi, wọ́n sì gbé wọn jù sí inú ihò àpáta ní ibi tí wọ́n sá pamọ́ sí. Wọ́n sì fi òkúta ńlá dí ẹnu ihò náà, tí ó sì wà níbẹ̀ di òní yìí.
And it was to [the] time of - [the] going of the sun he commanded Joshua and people took down them from on the trees and they threw them into the cave where they had hidden themselves there and they put stones large over [the] mouth of the cave until [the] substance of the day this.
28 Ní ọjọ́ náà Joṣua gba Makkeda. Ó sì fi ojú idà kọlu ìlú náà àti ọba rẹ̀, ó sì run gbogbo wọn pátápátá, kò fi ẹnìkan sílẹ̀. Ó sì ṣe sí ọba Makkeda gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe sí ọba Jeriko.
And Makkedah he captured Joshua on the day that and he struck it to [the] mouth of [the] sword and king its he totally destroyed them and every person who [was] in it not he left a survivor and he did to [the] king of Makkedah just as he had done to [the] king of Jericho.
29 Nígbà náà ní Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Makkeda lọ sí Libina wọ́n sì kọlù ú.
And he passed on Joshua and all Israel with him from Makkedah Libnah and he engaged in battle with Libnah.
30 Olúwa sì fi ìlú náà àti ọba rẹ̀ lé Israẹli lọ́wọ́. Ìlú náà àti gbogbo àwọn ènìyàn ibẹ̀ ni Joṣua fi idà pa. Kò fi ẹnìkan sílẹ̀ ní ibẹ̀: Ó sì ṣe sí ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí ọba Jeriko.
And he gave Yahweh also it in [the] hand of Israel and king its and he struck it to [the] mouth of [the] sword and every person who [was] in it not he left in it a survivor and he did to king its just as he had done to [the] king of Jericho.
31 Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo ará Israẹli, tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Libina lọ sí Lakiṣi; ó sì dó tì í, ó sì kọlù ú.
And he passed on Joshua and all Israel with him from Libnah Lachish towards and he encamped on it and he engaged in battle against it.
32 Olúwa sì fi Lakiṣi lé Israẹli lọ́wọ́, Joṣua sì gbà á ní ọjọ́ kejì. Ìlú náà àti gbogbo ènìyàn ibẹ̀ ní ó fi idà pa gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Libina.
And he gave Yahweh Lachish in [the] hand of Israel and he captured it on the day second and he struck it to [the] mouth of [the] sword and every person who [was] in it according to all that he had done to Libnah.
33 Ní àkókò yìí, Horamu ọba Geseri gòkè láti ran Lakiṣi lọ́wọ́, ṣùgbọ́n Joṣua ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ títí ti kò fi ku ẹnìkan sílẹ̀.
Then he came up Horam [the] king of Gezer to help Lachish and he attacked him Joshua and people his until not he had left to him a survivor.
34 Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Lakiṣi lọ sí Egloni; wọ́n sì dó tì í, wọ́n sì kọlù ú.
And he passed on Joshua and all Israel with him from Lachish Eglon towards and they encamped on it and they engaged in battle on it.
35 Wọ́n gbà á ní ọjọ́ náà, wọ́n sì fi ojú idà kọlù ú, wọ́n sì run gbogbo ènìyàn ibẹ̀ pátápátá, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe sí Lakiṣi.
And they captured it on the day that and they struck it to [the] mouth of [the] sword and every person who [was] in it on the day that he totally destroyed according to all that he had done to Lachish.
36 Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli ṣí láti Egloni lọ sí Hebroni, wọ́n sì kọlù ú.
And he went up Joshua and all Israel with him from Eglon Hebron towards and they engaged in battle on it.
37 Wọ́n gba ìlú náà, wọ́n sì ti idà bọ̀ ọ́, pẹ̀lú ọba rẹ̀, gbogbo ìletò wọn àti gbogbo ènìyàn ibẹ̀. Wọn kò dá ẹnìkan sí. Gẹ́gẹ́ bí ti Egloni, wọ́n run un pátápátá àti gbogbo ènìyàn inú rẹ̀.
And they captured it and they struck it to [the] mouth of [the] sword and king its and all cities its and every person who [was] in it not he left a survivor according to all that he had done to Eglon and he totally destroyed it and every person who [was] in it.
38 Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ yí padà, wọ́n sì kọlu Debiri.
And he turned back Joshua and all Israel with him Debir towards and he engaged in battle on it.
39 Wọ́n gba ìlú náà, ọba rẹ̀ àti gbogbo ìlú wọn, wọ́n sì fi idà pa wọ́n. Gbogbo ènìyàn inú rẹ̀ ni wọ́n parun pátápátá. Wọn kò sì dá ẹnìkankan sí. Wọ́n ṣe sí Debiri àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí wọn ti ṣe sí Libina àti ọba rẹ̀ àti sí Hebroni.
And he captured it and king its and all cities its and they struck them to [the] mouth of [the] sword and they totally destroyed every person who [was] in it not he left a survivor just as he had done to Hebron so he did to Debir and to king its and just as he had done to Libnah and to king its.
40 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ṣẹ́gun gbogbo agbègbè náà, ìlú òkè, gúúsù, ìlú ẹsẹ̀ òkè ti ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè pẹ̀lú gbogbo ọba, wọn kò dá ẹnìkankan sí. Ó pa gbogbo ohun alààyè run pátápátá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti pàṣẹ.
And he defeated Joshua all the land the hill country and the Negev and the Shephelah and the slopes and all kings their not he left a survivor and every breathing thing he totally destroyed just as he had commanded Yahweh [the] God of Israel.
41 Joṣua sì ṣẹ́gun wọn láti Kadeṣi-Barnea sí Gasa àti láti gbogbo agbègbè Goṣeni lọ sí Gibeoni.
And he struck down them Joshua from Kadesh Barnea and to Gaza and all [the] land of Goshen and to Gibeon.
42 Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí àti ilẹ̀ wọn ní Joṣua ṣẹ́gun ní ìwọ́de ogun ẹ̀ẹ̀kan, nítorí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, jà fún Israẹli.
And all the kings these and land their he captured Joshua time one for Yahweh [the] God of Israel [was] fighting for Israel.
43 Nígbà náà ni Joṣua padà sí ibùdó ní Gilgali pẹ̀lú gbogbo Israẹli.
And he returned Joshua and all Israel with him to the camp Gilgal towards.

< Joshua 10 >