< Joshua 1 >

1 Lẹ́yìn ikú u Mose ìránṣẹ́ Olúwa, Olúwa sọ fún Joṣua ọmọ Nuni, olùrànlọ́wọ́ ọ Mose,
Efter Mose, Herrans tjenares död, sade Herren till Josua, Nuns son, Mose tjenare:
2 “Mose ìránṣẹ́ mi ti kú. Nísinsin yìí, ìwọ àti gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹ múra láti kọjá odò Jordani lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ó fi fún wọn fún àwọn ará Israẹli.
Min tjenare Mose är död; så gör dig nu redo och drag öfver denna Jordan, du och allt detta folket, in uti det land, som jag dem, nämliga Israels barnom, gifvit hafver.
3 Èmi yóò fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe ìlérí fún Mose.
Allt rum, der edart fotbjelle på trädandes varder, hafver jag gifvit eder, såsom jag Mose sagt hafver;
4 Ilẹ̀ ẹ yín yóò fẹ̀ láti aginjù Lebanoni, àti láti odò ńlá, ti Eufurate—gbogbo orílẹ̀-èdè Hiti títí ó fi dé Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
Ifrån öknene och denna Libanon, intill den stora älfvena Phrath, hela Hetheers land, intill det stora hafvet vesterut, skola edor landamäre vara.
5 Kì yóò sí ẹnikẹ́ni tí yóò le è dúró níwájú rẹ ní ọjọ́ ayé è rẹ gbogbo. Bí mo ti wà pẹ̀lú u Mose, bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, Èmi kì yóò fi ọ́ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Èmi kì yóò kọ̀ ọ́.
Ingen skall stå emot dig i dina lifsdagar; såsom jag hafver varit med Mose, så skall jag ock vara med dig; jag skall icke öfvergifva eller förgäta dig.
6 “Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le, nítorí ìwọ ni yóò ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, láti lè jogún ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fi fún wọn.
Var tröst och frimodig; ty du skall utskifta desso folkena landet, som jag deras fäder svorit hafver, att jag dem det gifva skulle.
7 Jẹ́ alágbára, kí o sì mú àyà le gidigidi. Kí o sì ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin tí Mose ìránṣẹ́ mi fún ọ mọ́, má ṣe yà kúrò nínú u rẹ̀ sí ọ̀tún tàbí sí òsì, kí ìwọ kí ó lè ṣe rere níbikíbi tí ìwọ bá ń lọ.
Var nu tröst och ganska frimodig, att du håller och gör all ting efter lagen, som Mose min tjenare dig budit hafver; vik icke derifrån, antingen på högra sidon eller den venstra, på det att du må handla visliga i allt det du göra skall.
8 Má ṣe jẹ́ kí ìwé òfin yìí kúrò ní ẹnu rẹ, máa ṣe àṣàrò nínú u rẹ̀ ní ọ̀sán àti ní òru, kí ìwọ kí ó lè ṣọ́ra láti ṣe gbogbo nǹkan tí a kọ sí inú u rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dára fún ọ, ìwọ yóò sì ní àṣeyọrí.
Och låt denna lagbokena icke komma utu dinom mun; utan haf dina tankar deruti dag och natt, på det att du skall hålla och göra all ting derefter, som deruti skrifvet står; så skall dig lyckas i allt det du gör, och du skall kunna handla visliga.
9 Èmi kò ha ti pàṣẹ fún ọ bí? Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le. Má ṣe bẹ̀rù, má sì ṣe rẹ̀wẹ̀sì, nítorí pé Olúwa à rẹ yóò wà pẹ̀lú rẹ ní ibikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”
Si, jag hafver budit dig, att du skall vara tröst, och vid godt mod; grufva dig för ingen ting, och frukta intet; ty Herren din Gud är med dig i allt det du företager.
10 Báyìí ni Joṣua pàṣẹ fún olórí àwọn ènìyàn rẹ̀,
Då böd Josua höfvitsmännerna öfver folket, och sade:
11 “Ẹ la ibùdó já, kí ẹ sì sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Ẹ pèsè oúnjẹ yín sílẹ̀. Ní ìwòyí ọ̀túnla, ẹ̀yin yóò la Jordani yìí kọjá, láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín láti ní.’”
Går igenom lägret, och bjuder folkena, och säger: Bereder eder spisning; ty efter tre dagar skolen I gå öfver denna Jordanen, att I mågen inkomma till att intaga landet, som Herren edar Gud eder gifva skall.
12 Ṣùgbọ́n Joṣua sọ fún àwọn ará a Reubeni, àwọn ará Gadi àti fún ìdajì ẹ̀yà Manase pé,
Och sade Josua till de Rubeniter, Gaditer, och till de halfva slägtena Manasse:
13 “Rántí àṣẹ tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pa fún yín: ‘Olúwa Ọlọ́run yín á fún yin ní ìsinmi, òun yóò sì fún un yín ní ilẹ̀ yìí.’
Tänker uppå det ord, som Mose Herrans tjenare eder böd, och sade: Herren edar Gud hafver låtit eder komma till ro, och gifvit eder detta landet.
14 Àwọn ìyàwó yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ẹran ọ̀sìn yín lè dúró ní ilẹ̀ tí Mose fún un yin ní ìlà-oòrùn Jordani; ṣùgbọ́n gbogbo àwọn jagunjagun un yín, pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín. Ẹ̀yin yóò sì rán àwọn arákùnrin yín lọ́wọ́
Edra hustrur, barn och boskap låter blifva i landena, som Mose eder gifvit hafver, på denna sidone Jordan; men I skolen gå för edra bröder väpnade, alle de som väraktige män äro, och hjelpa dem;
15 títí Olúwa yóò fi fún wọn ní ìsinmi, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún un yín, àti títí tí àwọn pẹ̀lú yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún wọn. Lẹ́yìn náà, ẹ̀yin lè padà sí ilẹ̀ ìní in yín, tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún un yin ní agbègbè ìlà-oòrùn ti Jordani.”
Intilldess Herren låter ock edra bröder komma till ro, så väl som eder, att de ock måga intaga det land, som Herren edar Gud dem gifva skall. Sedan skolen I vända om igen till edart land, att I det besitten, som Mose Herrans tjenare eder gifvit hafver, på denna sidone Jordan österut.
16 Nígbà náà ni wọ́n dá Joṣua lóhùn pé, “Ohunkóhun tí ìwọ pàṣẹ fún wa ni àwa yóò ṣe, ibikíbi tí ìwọ bá rán wa ni àwa yóò lọ.
Och de svarade Josua, och sade: Allt det du oss budit hafver, det vilje vi göra, och hvart du sänder oss, dit vilje vi gå.
17 Gẹ́gẹ́ bí àwa ti gbọ́rọ̀ sí Mose nínú ohun gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò máa gbọ́ tìrẹ. Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà pẹ̀lú u Mose.
Såsom vi hafve varit Mose lydige, så vilje vi ock vara dig lydige; allenast vare Herren din Gud med dig, såsom han var med Mose.
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tàpá sí ọ̀rọ̀ rẹ, tí kò sì ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ nínú ohun gbogbo tí ìwọ yóò pàṣẹ fún wọn, pípa ni a ó pa á. Kí ìwọ sá à ṣe gírí, kí ó sì mú àyà le!”
Hvilken som din mun emotstår, och icke lyder din ord i allt det du bjuder oss, han skall dö; allenast var du tröst, och vid godt mod.

< Joshua 1 >