< Joshua 1 >

1 Lẹ́yìn ikú u Mose ìránṣẹ́ Olúwa, Olúwa sọ fún Joṣua ọmọ Nuni, olùrànlọ́wọ́ ọ Mose,
Ie añe te nihomake t’i Mosè mpitoro’ Iehovà, le nitsara am’ Iehosoa ana’ i None, mpitoro’ i Mosè, t’Iehovà, ami’ty hoe:
2 “Mose ìránṣẹ́ mi ti kú. Nísinsin yìí, ìwọ àti gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹ múra láti kọjá odò Jordani lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ó fi fún wọn fún àwọn ará Israẹli.
Fa vilasy t’i Mosè mpitoroko; aa le miongaha, itsaho Iardeney, ihe naho ze hene ondaty retiañe, mb’ an-tane atoloko iareo, toe ho amo ana’ Israeleo;
3 Èmi yóò fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe ìlérí fún Mose.
fa natoloko anahareo ze toetse lian-delam-pandia’ areo, ty amy asako amy Mosèy.
4 Ilẹ̀ ẹ yín yóò fẹ̀ láti aginjù Lebanoni, àti láti odò ńlá, ti Eufurate—gbogbo orílẹ̀-èdè Hiti títí ó fi dé Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
Mifototse am-patrambey añe miharo amy Lebanone etia, pak’ amy saka beiy, i Peratey, naho ze hene tanen-te-Kète, pak’ amy Riake beiy, mb’ amy firoña’ i àndroy añey ty ho efe-tane’ areo.
5 Kì yóò sí ẹnikẹ́ni tí yóò le è dúró níwájú rẹ ní ọjọ́ ayé è rẹ gbogbo. Bí mo ti wà pẹ̀lú u Mose, bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, Èmi kì yóò fi ọ́ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Èmi kì yóò kọ̀ ọ́.
Leo raike t’indaty tsy hiongake hiatrek’ azo amo hene andro hiveloma’oo; manahake ty nindrezako amy Mosè ty hindrezako ama’o; tsy hilesa ama’o iraho, tsy haforintseko ka.
6 “Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le, nítorí ìwọ ni yóò ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, láti lè jogún ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fi fún wọn.
Mihafatrara vaho mahasibeha; fa ihe ty hampandova ondaty retoañe i tane nifantàko aman-droae’ iareo hatoloko iareoy.
7 Jẹ́ alágbára, kí o sì mú àyà le gidigidi. Kí o sì ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin tí Mose ìránṣẹ́ mi fún ọ mọ́, má ṣe yà kúrò nínú u rẹ̀ sí ọ̀tún tàbí sí òsì, kí ìwọ kí ó lè ṣe rere níbikíbi tí ìwọ bá ń lọ.
Aa le mihaozara naho mahavania, hañambeñe naho hañorike i Tsara iaby linili’ i Mosè mpitoroko azoy; ko mitolike mb’ am-pitàn-kavana ndra havia, soa te hiraorao ndra aia’ aia ty homba’o.
8 Má ṣe jẹ́ kí ìwé òfin yìí kúrò ní ẹnu rẹ, máa ṣe àṣàrò nínú u rẹ̀ ní ọ̀sán àti ní òru, kí ìwọ kí ó lè ṣọ́ra láti ṣe gbogbo nǹkan tí a kọ sí inú u rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dára fún ọ, ìwọ yóò sì ní àṣeyọrí.
Tsy hienga am-palie’o ty Boke Hake toy, ie haereñere’o handro naho haleñe, hañambeñe naho hanao ze hene misokitse ao; le hiraorao o sata’oo, vaho haharongatse.
9 Èmi kò ha ti pàṣẹ fún ọ bí? Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le. Má ṣe bẹ̀rù, má sì ṣe rẹ̀wẹ̀sì, nítorí pé Olúwa à rẹ yóò wà pẹ̀lú rẹ ní ibikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”
Aa vaho tsy liniliko hao? Mihafatrara naho mahasibeha; ko hemban-drehe ko miroreke: fa ama’o t’Iehovà Andrianañahare’o ndra aia’aia ty homba’o.
10 Báyìí ni Joṣua pàṣẹ fún olórí àwọn ènìyàn rẹ̀,
Aa le linili’ Iehosoa o mpiaolo’ ondatio ami’ty hoe:
11 “Ẹ la ibùdó já, kí ẹ sì sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Ẹ pèsè oúnjẹ yín sílẹ̀. Ní ìwòyí ọ̀túnla, ẹ̀yin yóò la Jordani yìí kọjá, láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín láti ní.’”
Mirangà anteñateña’ i tobey mb’eo le afantoho ondatio ami’ty hoe: Maña­lankaña fivatiañe, fa hitsake Iardeney nahareo añate’ ty telo andro, himoak’ amy taney, hitavañe ze natolo’ Iehovà Andrianañahare’ areo ho fanañañe.
12 Ṣùgbọ́n Joṣua sọ fún àwọn ará a Reubeni, àwọn ará Gadi àti fún ìdajì ẹ̀yà Manase pé,
Le nisaontsy amo nte-Reobeneo naho amo nte-Gadeo naho amo vakin-te Menasèo t’Iehosoa ami’ty hoe:
13 “Rántí àṣẹ tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pa fún yín: ‘Olúwa Ọlọ́run yín á fún yin ní ìsinmi, òun yóò sì fún un yín ní ilẹ̀ yìí.’
Tiahio i tsara linili’ i Mosè mpitoro’ Iehovà anahareoy, ami’ty hoe: Manolotse fitofàñe ama’ areo t’Iehovà Andrianañahare’ areo vaho hatolo’e ama’ areo o tane atoio.
14 Àwọn ìyàwó yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ẹran ọ̀sìn yín lè dúró ní ilẹ̀ tí Mose fún un yin ní ìlà-oòrùn Jordani; ṣùgbọ́n gbogbo àwọn jagunjagun un yín, pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín. Ẹ̀yin yóò sì rán àwọn arákùnrin yín lọ́wọ́
Hitobok’ an-tane natolo’ i Mosè anahareo alafe’ Iardeney atoy o vali’ areoo naho o keleia’ areoo naho o añombe’ areoo, f’ie hitsak’ aolo’ o rahalahi’ areoo reke-pialiañe, songa fanalolahy maozatse hañolo­rañe iareo;
15 títí Olúwa yóò fi fún wọn ní ìsinmi, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún un yín, àti títí tí àwọn pẹ̀lú yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún wọn. Lẹ́yìn náà, ẹ̀yin lè padà sí ilẹ̀ ìní in yín, tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún un yin ní agbègbè ìlà-oòrùn ti Jordani.”
ampara’ te hampitofà’ Iehovà o rahalahi’ areoo, manahake ty nanoa’e anahareo, ie fa tinava’ iareo ka i tane nitolora’ Iehovà Andrianañahare’ areo; le himpoly an-tane fanaña’ areo atoa nahareo vaho ho tavane’ areo i natolo’ i Mosè mpitoro’ Iehovà anahareo alafe’ Iardeney atoa mb’am-panjirihan’ andro añe.
16 Nígbà náà ni wọ́n dá Joṣua lóhùn pé, “Ohunkóhun tí ìwọ pàṣẹ fún wa ni àwa yóò ṣe, ibikíbi tí ìwọ bá rán wa ni àwa yóò lọ.
Tinoi’ iareo ami’ty hoe t’Iehosoa: Hene hanoe’ay ze nandilia’o anay vaho hañaveloa’ay ndra aia aia ty añiraha’o.
17 Gẹ́gẹ́ bí àwa ti gbọ́rọ̀ sí Mose nínú ohun gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò máa gbọ́ tìrẹ. Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà pẹ̀lú u Mose.
Manahake ty nañaoña’ay amy Mosè amy ze he’e, ty hañaoña’ay azo naho indreza’ Iehovà Andrianañahare’o hambañe amy nindreza’e amy Mo­sèy.
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tàpá sí ọ̀rọ̀ rẹ, tí kò sì ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ nínú ohun gbogbo tí ìwọ yóò pàṣẹ fún wọn, pípa ni a ó pa á. Kí ìwọ sá à ṣe gírí, kí ó sì mú àyà le!”
Aa ndra ia’ia ty hiola amy an­dilia’oy, tsy hañaoñe ze hene saontsy amantoha’o aze, le havetrake, f’ihe mihaozara vaho mahasibeha.

< Joshua 1 >