< Joshua 1 >
1 Lẹ́yìn ikú u Mose ìránṣẹ́ Olúwa, Olúwa sọ fún Joṣua ọmọ Nuni, olùrànlọ́wọ́ ọ Mose,
Volt Mózesnek, az Örökkévaló szolgájának halála után, szólt az Örökkévaló Józsuához, Nún fiához, Mózes szolgájához, mondván:
2 “Mose ìránṣẹ́ mi ti kú. Nísinsin yìí, ìwọ àti gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹ múra láti kọjá odò Jordani lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ó fi fún wọn fún àwọn ará Israẹli.
Mózes szolgám meghalt; most hát kelj föl, vonulj át e Jordánon, te és ez az egész nép, azon országba, melyet adok nekik, Izraél fiainak.
3 Èmi yóò fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe ìlérí fún Mose.
Minden hely, melyre majd lép lábatok talpa – nektek adom azt, amint szóltam Mózesnek:
4 Ilẹ̀ ẹ yín yóò fẹ̀ láti aginjù Lebanoni, àti láti odò ńlá, ti Eufurate—gbogbo orílẹ̀-èdè Hiti títí ó fi dé Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
a pusztától és ama Libánontól egészen a nagy folyamig, az Eufrátes folyamig, a chittiták egész országa, a nagy tengerig napnyugat felé, lesz a határatok.
5 Kì yóò sí ẹnikẹ́ni tí yóò le è dúró níwájú rẹ ní ọjọ́ ayé è rẹ gbogbo. Bí mo ti wà pẹ̀lú u Mose, bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, Èmi kì yóò fi ọ́ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Èmi kì yóò kọ̀ ọ́.
Nem fog megállani előtted senki életed minden napjaiban; amint voltam Mózessel, leszek te veled: nem engedlek ellankadni és nem hagylak el.
6 “Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le, nítorí ìwọ ni yóò ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, láti lè jogún ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fi fún wọn.
Légy erős és bátor, mert te adod birtokba e népnek az országot, melyről megesküdtem őseiknek, hogy nekik adom.
7 Jẹ́ alágbára, kí o sì mú àyà le gidigidi. Kí o sì ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin tí Mose ìránṣẹ́ mi fún ọ mọ́, má ṣe yà kúrò nínú u rẹ̀ sí ọ̀tún tàbí sí òsì, kí ìwọ kí ó lè ṣe rere níbikíbi tí ìwọ bá ń lọ.
Csak erős és bátor légy nagyon, vigyázva arra, hogy cselekedjél az egész tan szerint, melyet neked parancsolt Mózes szolgám; ne térj el attól sem jobbra, sem balra, azért hogy boldogulj, bármerre jársz.
8 Má ṣe jẹ́ kí ìwé òfin yìí kúrò ní ẹnu rẹ, máa ṣe àṣàrò nínú u rẹ̀ ní ọ̀sán àti ní òru, kí ìwọ kí ó lè ṣọ́ra láti ṣe gbogbo nǹkan tí a kọ sí inú u rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dára fún ọ, ìwọ yóò sì ní àṣeyọrí.
Ne mozduljon el szád-ból a tannak e könyve, s elmélkedjél róla nappal s éjjel, azért, hogy vigyázz arra, hogy cselekedjél mind a szerint, ami írva van benne, mert akkor szerencsés lész utjaidon és akkor boldogulni fogsz.
9 Èmi kò ha ti pàṣẹ fún ọ bí? Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le. Má ṣe bẹ̀rù, má sì ṣe rẹ̀wẹ̀sì, nítorí pé Olúwa à rẹ yóò wà pẹ̀lú rẹ ní ibikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”
Nemde megparancsoltam neked: légy erős és bátor, ne ijedj meg és ne rettegj; mert veled van az Örökkévaló a te Istened, bármerre jársz.
10 Báyìí ni Joṣua pàṣẹ fún olórí àwọn ènìyàn rẹ̀,
És megparancsolta Józsua a nép felügyelőinek, mondván:
11 “Ẹ la ibùdó já, kí ẹ sì sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Ẹ pèsè oúnjẹ yín sílẹ̀. Ní ìwòyí ọ̀túnla, ẹ̀yin yóò la Jordani yìí kọjá, láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín láti ní.’”
Járjátok be a tábort és parancsoljátok a népnek, mondván: készítsetek magatoknak eleséget, mert három nap múlva átkeltek e Jordánon, hogy bemenjetek elfoglalni az országot, melyet az Örökkévaló, a ti Istentek nektek ad, hogy elfoglaljátok.
12 Ṣùgbọ́n Joṣua sọ fún àwọn ará a Reubeni, àwọn ará Gadi àti fún ìdajì ẹ̀yà Manase pé,
A Reúbénihez pedig, a Gádihoz és Menasse fél törzséhez szólt Józsua, mondván:
13 “Rántí àṣẹ tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pa fún yín: ‘Olúwa Ọlọ́run yín á fún yin ní ìsinmi, òun yóò sì fún un yín ní ilẹ̀ yìí.’
Emlékezzetek meg a dologról, melyet parancsolt nektek Mózes, az Örökkévaló szolgája, mondván: az Örökkévaló, a ti Istentek nyugalmat szerez nektek és nektek adja ezt az országot.
14 Àwọn ìyàwó yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ẹran ọ̀sìn yín lè dúró ní ilẹ̀ tí Mose fún un yin ní ìlà-oòrùn Jordani; ṣùgbọ́n gbogbo àwọn jagunjagun un yín, pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín. Ẹ̀yin yóò sì rán àwọn arákùnrin yín lọ́wọ́
Feleségeitek, gyermekeitek és jószágtok maradjanak az országban, melyet adott nektek Mózes a Jordánon innen, ti pedig vonuljatok fegyveresen testvéreitek előtt, mind a derék vitézek, hogy őket segítsétek;
15 títí Olúwa yóò fi fún wọn ní ìsinmi, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún un yín, àti títí tí àwọn pẹ̀lú yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún wọn. Lẹ́yìn náà, ẹ̀yin lè padà sí ilẹ̀ ìní in yín, tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún un yin ní agbègbè ìlà-oòrùn ti Jordani.”
mígnem nyugalmat szerez az Örökkévaló testvéreiteknek, mint nektek, és elfoglalják ők is az országot, melyet az Örökkévaló, a ti Istentek ad nekik. Akkor visszatérhettek birtokotok országába és elfoglalhatjátok azt, amelyet adott nektek Mózes, az Örökkévaló szolgája, a Jordánon innen napkelet felé.
16 Nígbà náà ni wọ́n dá Joṣua lóhùn pé, “Ohunkóhun tí ìwọ pàṣẹ fún wa ni àwa yóò ṣe, ibikíbi tí ìwọ bá rán wa ni àwa yóò lọ.
Feleltek Józsuának, mondván: Mindent, amit nekünk parancsoltál, megteszünk és bárhova küldesz, megyünk.
17 Gẹ́gẹ́ bí àwa ti gbọ́rọ̀ sí Mose nínú ohun gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò máa gbọ́ tìrẹ. Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà pẹ̀lú u Mose.
Egészen úgy, amint hallgattunk Mózesre, akképpen hallgatunk majd reád; csak legyen az Örökkévaló, a te Istened veled, a mint volt Mózessel.
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tàpá sí ọ̀rọ̀ rẹ, tí kò sì ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ nínú ohun gbogbo tí ìwọ yóò pàṣẹ fún wọn, pípa ni a ó pa á. Kí ìwọ sá à ṣe gírí, kí ó sì mú àyà le!”
Minden ember, aki engedetlen lesz parancsod iránt és nem hallgat szavaidra bármiben, amit neki parancsolsz, ölessék meg. Csak légy erős és bátor.