< Joshua 1 >

1 Lẹ́yìn ikú u Mose ìránṣẹ́ Olúwa, Olúwa sọ fún Joṣua ọmọ Nuni, olùrànlọ́wọ́ ọ Mose,
Na rĩrĩ, thuutha wa gĩkuũ kĩa Musa ndungata ya Ngai, Jehova akĩĩra Joshua mũrũ wa Nuni, ũrĩa watungatagĩra Musa, atĩrĩ:
2 “Mose ìránṣẹ́ mi ti kú. Nísinsin yìí, ìwọ àti gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí, ẹ múra láti kọjá odò Jordani lọ sí ilẹ̀ tí Èmi ó fi fún wọn fún àwọn ará Israẹli.
“Musa ndungata yakwa nĩakuĩte. Na rĩrĩ, wee na andũ aya othe, mwĩhaarĩriei kũringa Rũũĩ rwa Jorodani mũtoonye bũrũri ũrĩa ngũmũhe, o ũcio ngũhe andũ a Isiraeli.
3 Èmi yóò fún un yín ní gbogbo ibi tí ẹ bá fi ẹsẹ̀ ẹ yín tẹ̀, gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe ìlérí fún Mose.
Na rĩrĩ, handũ o hothe harĩa mũgaakinya na makinya manyu nĩngamũhe, o ta ũrĩa ndeerire Musa.
4 Ilẹ̀ ẹ yín yóò fẹ̀ láti aginjù Lebanoni, àti láti odò ńlá, ti Eufurate—gbogbo orílẹ̀-èdè Hiti títí ó fi dé Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
Bũrũri wanyu ũgaatambũrũka kuuma werũ-inĩ o nginya Lebanoni, na kuuma rũũĩ rũrĩa rũnene rwa Farati, nĩguo bũrũri wothe wa Ahiti, o nginya Iria-inĩ rĩrĩa Inene rĩa mwena wa ithũĩro.
5 Kì yóò sí ẹnikẹ́ni tí yóò le è dúró níwájú rẹ ní ọjọ́ ayé è rẹ gbogbo. Bí mo ti wà pẹ̀lú u Mose, bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò wà pẹ̀lú rẹ, Èmi kì yóò fi ọ́ sílẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni Èmi kì yóò kọ̀ ọ́.
Gũtikagĩa mũndũ ũkaahota gũgwĩtiiria matukũ mothe ma muoyo waku. O ta ũrĩa ndaarĩ na Musa, ũguo noguo ngũkorwo hamwe nawe; ndigagũtiganĩria kana ngũtirike.
6 “Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le, nítorí ìwọ ni yóò ṣe amọ̀nà àwọn ènìyàn wọ̀nyí, láti lè jogún ilẹ̀ tí mo ti búra fún àwọn baba ńlá a wọn láti fi fún wọn.
“Gĩa na hinya na ũũmĩrĩrie, nĩgũkorwo nĩwe ũgũtongoria andũ aya mathiĩ makagae bũrũri ũrĩa ndehĩtire na mwĩhĩtwa kũrĩ maithe mao atĩ nĩngamahe.
7 Jẹ́ alágbára, kí o sì mú àyà le gidigidi. Kí o sì ṣọ́ra láti pa gbogbo òfin tí Mose ìránṣẹ́ mi fún ọ mọ́, má ṣe yà kúrò nínú u rẹ̀ sí ọ̀tún tàbí sí òsì, kí ìwọ kí ó lè ṣe rere níbikíbi tí ìwọ bá ń lọ.
Gĩa na hinya na ũũmĩrĩrie mũno. Menyagĩrĩra gwathĩkagĩra watho wothe ũrĩa ndungata yakwa Musa aagwathire wĩkage; ndũkanagarũrũke na mwena wa ũrĩo kana wa ũmotho ũũtige, nĩgeetha ũgĩĩage na ũhootani kũrĩa guothe ũrĩthiiaga.
8 Má ṣe jẹ́ kí ìwé òfin yìí kúrò ní ẹnu rẹ, máa ṣe àṣàrò nínú u rẹ̀ ní ọ̀sán àti ní òru, kí ìwọ kí ó lè ṣọ́ra láti ṣe gbogbo nǹkan tí a kọ sí inú u rẹ̀. Nígbà náà ni yóò dára fún ọ, ìwọ yóò sì ní àṣeyọrí.
Ciugo cia Ibuku rĩĩrĩ rĩa Watho itikanatige kwario nĩ kanua gaku; no wĩcũũranagie ũhoro warĩo mũthenya na ũtukũ, nĩgeetha ũmenyagĩrĩre gwĩka maũndũ marĩa mothe maandĩkĩtwo thĩinĩ warĩo. Hĩndĩ ĩyo nĩ ũkaagaacĩra, na ũgĩe na ũhootani.
9 Èmi kò ha ti pàṣẹ fún ọ bí? Jẹ́ alágbára kí o sì mú àyà le. Má ṣe bẹ̀rù, má sì ṣe rẹ̀wẹ̀sì, nítorí pé Olúwa à rẹ yóò wà pẹ̀lú rẹ ní ibikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”
Githĩ ti-niĩ ngwathĩte? Wee gĩa o na hinya na ũũmĩrĩrie. Ndũkanetigĩre o na kana; ũũrwo nĩ hinya, nĩgũkorwo Jehova Ngai waku arĩ hamwe nawe kũrĩa guothe ũrĩthiiaga.”
10 Báyìí ni Joṣua pàṣẹ fún olórí àwọn ènìyàn rẹ̀,
Nĩ ũndũ ũcio Joshua agĩatha anene arĩa maaroraga andũ atĩrĩ:
11 “Ẹ la ibùdó já, kí ẹ sì sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Ẹ pèsè oúnjẹ yín sílẹ̀. Ní ìwòyí ọ̀túnla, ẹ̀yin yóò la Jordani yìí kọjá, láti gba ilẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín láti ní.’”
“Tuĩkanĩriai kambĩ-inĩ mũkĩĩraga andũ atĩrĩ, ‘Haarĩriai rĩĩgu mũige, nĩ ũndũ mĩthenya ĩtatũ kuuma ũmũthĩ yathira nĩguo mũkaaringa Rũũĩ rwa Jorodani nĩgeetha mũthiĩ mũtoonye na mwĩgwatĩre bũrũri ũrĩa Jehova Ngai wanyu ekũmũhe ũtuĩke wanyu.’”
12 Ṣùgbọ́n Joṣua sọ fún àwọn ará a Reubeni, àwọn ará Gadi àti fún ìdajì ẹ̀yà Manase pé,
Ningĩ Joshua akĩarĩria andũ a mũhĩrĩga wa Rubeni, na wa Gadi, na nuthu ya mũhĩrĩga wa Manase, akĩmeera atĩrĩ,
13 “Rántí àṣẹ tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pa fún yín: ‘Olúwa Ọlọ́run yín á fún yin ní ìsinmi, òun yóò sì fún un yín ní ilẹ̀ yìí.’
“Ririkanai watho ũrĩa mwaheirwo nĩ Musa ndungata ya Jehova, akiuga atĩrĩ, ‘Jehova Ngai wanyu nĩamũheete ũhurũko na nĩamũheete bũrũri ũyũ.’
14 Àwọn ìyàwó yín, àwọn ọmọ yín àti àwọn ẹran ọ̀sìn yín lè dúró ní ilẹ̀ tí Mose fún un yin ní ìlà-oòrùn Jordani; ṣùgbọ́n gbogbo àwọn jagunjagun un yín, pẹ̀lú ìhámọ́ra ogun gbọdọ̀ kọjá síwájú àwọn arákùnrin yín. Ẹ̀yin yóò sì rán àwọn arákùnrin yín lọ́wọ́
Atumia anyu, na ciana cianyu, na ũhiũ wanyu no maikare bũrũri ũrĩa mwaheirwo nĩ Musa mwena wa irathĩro rĩa Rũũĩ rwa Jorodani, no arũme othe anyu othe arĩa njamba cia ita meeohete indo cia mbaara, no nginya maringe mũrĩmo ũũrĩa ũngĩ matongoretie ariũ a ithe wanyu. No nginya mũgateithie ariũ a ithe wanyu.
15 títí Olúwa yóò fi fún wọn ní ìsinmi, gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe fún un yín, àti títí tí àwọn pẹ̀lú yóò fi gba ilẹ̀ náà tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún wọn. Lẹ́yìn náà, ẹ̀yin lè padà sí ilẹ̀ ìní in yín, tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún un yin ní agbègbè ìlà-oòrùn ti Jordani.”
nginya rĩrĩa Jehova akaamahe ũhurũko o ta ũrĩa amũheete inyuĩ, na nginya rĩrĩa o nao makegwatĩra bũrũri ũrĩa Jehova Ngai wanyu ekũmahe. Thuutha ũcio, no mũcooke mũgaikare bũrũri wanyu inyuĩ ene, ũrĩa mwaheirwo nĩ Musa ndungata ya Jehova mwena wa irathĩro wa Jorodani, ũcio ũrorete mwena ũrĩa riũa rĩrathagĩra.”
16 Nígbà náà ni wọ́n dá Joṣua lóhùn pé, “Ohunkóhun tí ìwọ pàṣẹ fún wa ni àwa yóò ṣe, ibikíbi tí ìwọ bá rán wa ni àwa yóò lọ.
Hĩndĩ ĩyo magĩcookeria Joshua, makĩmwĩra atĩrĩ, “Nĩtũgwĩka ũrĩa wothe ũgũtwatha na nĩ tũgũthiĩ kũrĩa guothe ũgũtũtũma.
17 Gẹ́gẹ́ bí àwa ti gbọ́rọ̀ sí Mose nínú ohun gbogbo, bẹ́ẹ̀ ni àwa yóò máa gbọ́ tìrẹ. Kí Olúwa Ọlọ́run rẹ wà pẹ̀lú rẹ, gẹ́gẹ́ bí ó ṣe wà pẹ̀lú u Mose.
O ta ũrĩa twaathĩkĩire Musa maũndũ-inĩ mothe-rĩ, ũguo noguo tũrĩgwathĩkagĩra. No rĩrĩ, Jehova Ngai waku arokorwo hamwe nawe o ta ũrĩa aarĩ hamwe na Musa.
18 Ẹnikẹ́ni tí ó bá tàpá sí ọ̀rọ̀ rẹ, tí kò sì ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ nínú ohun gbogbo tí ìwọ yóò pàṣẹ fún wọn, pípa ni a ó pa á. Kí ìwọ sá à ṣe gírí, kí ó sì mú àyà le!”
Mũndũ wothe ũkaaremera uuge waku na arege gwathĩkĩra maũndũ mothe marĩa ũkaamatha, no nginya mũndũ ũcio akooragwo. No rĩrĩ, gĩa na hinya na ũũmĩrĩrie!”

< Joshua 1 >