< Jonah 1 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jona ọmọ Amittai wá, wí pé:
Słowo PANA doszło do Jonasza, syna Amittaja, mówiące:
2 “Dìde lọ sí ìlú ńlá Ninefe kí o sì wàásù sí i, nítorí ìwà búburú rẹ̀ gòkè wá iwájú mi.”
Wstań, idź do Niniwy, tego wielkiego miasta, i wołaj przeciwko niej, bo jej niegodziwość wzniosła się przed moje oblicze.
3 Ṣùgbọ́n Jona dìde kúrò láti sálọ sí Tarṣiṣi kúrò níwájú Olúwa, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Joppa, ìbí ti ó tí rí ọkọ̀ kan tí ń lọ sí Tarṣiṣi: lẹ́yìn ti ó sanwó ọkọ̀, ó wọlé sínú rẹ̀, láti bá wọn lọ sí Tarṣiṣi kúrò níwájú Olúwa.
Ale Jonasz wstał, aby uciec do Tarszisz sprzed oblicza PANA, i przybył do Jafy. Znalazł okręt, który płynął do Tarszisz, zapłacił za przejazd i wsiadł na niego, aby płynąć z nimi do Tarszisz [i uciec] sprzed oblicza PANA.
4 Nígbà náà ni Olúwa rán ìjì ńlá jáde sí ojú Òkun, ìjì líle sì wà nínú Òkun tó bẹ́ẹ̀ tí ọkọ̀ náà dàbí ẹni pé yóò fọ́.
Lecz PAN zesłał gwałtowny wiatr na morze i powstała potężna burza na morzu, tak że zdawało się, że okręt się rozbije.
5 Nígbà náà ni àwọn atukọ̀ bẹ̀rù, olúkúlùkù sì ń kígbe sí ọlọ́run rẹ̀, wọ́n kó ẹrù tí ó wà nínú ọkọ̀ dà sínú Òkun, kí ó bá à lè fúyẹ́. Ṣùgbọ́n Jona sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ ọkọ̀ ó sì dùbúlẹ̀, ó sùn wọra.
A żeglarze przestraszyli się i każdy z nich wołał do swego boga, a wyrzucali do morza ładunek, który był na okręcie, aby ten był lżejszy. Ale Jonasz zszedł wcześniej na niższy pokład okrętu, położył się i twardo zasnął.
6 Bẹ́ẹ̀ ni olórí ọkọ̀ tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi sùn, ìwọ olóòórùn? Dìde kí o ké pe Ọlọ́run rẹ! Bóyá yóò ro tiwa, kí àwa má ba à ṣègbé.”
Przyszedł więc do niego sternik i zapytał go: Cóż ty czynisz, śpiochu? Wstań, wołaj do swego Boga, może Bóg wspomni na nas, abyśmy nie zginęli.
7 Nígbà náà ni àwọn atukọ̀ sọ fún ara wọn pé, “Wá, ẹ jẹ́ kí a sẹ́ kèké, kí àwa kí o le mọ̀ nítorí ta ni búburú yìí ṣe wá sórí wa.” Wọ́n ṣẹ́ kèké, kèké sì mú Jona.
Wtedy powiedzieli jeden do drugiego: Chodźcie, rzućmy losy, abyśmy się dowiedzieli, przez kogo [spadło] na nas to nieszczęście. Rzucili więc losy i padło na Jonasza.
8 Nígbà náà ni wọn wí fún un pé, “Sọ fún wa, àwa bẹ̀ ọ́, nítorí ta ni búburú yìí ṣe wá sórí wa? Kí ni iṣẹ́ rẹ? Níbo ni ìwọ ti wá? Kí ni orúkọ ìlú rẹ? Ẹ̀yà orílẹ̀-èdè wo sì ni ìwọ sì í ṣe?”
I powiedzieli do niego: Powiedz nam, prosimy, przez kogo [spadło] na nas to nieszczęście. Jaki jest twój zawód? Skąd pochodzisz? Z jakiego kraju i z jakiego narodu jesteś?
9 Òun sì dá wọn lóhùn pé, “Heberu ni èmi, mo sì bẹ̀rù Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run ẹni tí ó dá Òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀.”
Odpowiedział im: Jestem Hebrajczykiem i boję się PANA, Boga nieba, który stworzył morze i ziemię.
10 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin náà bẹ̀rù gidigidi, wọn sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ṣe èyí?” (Nítorí àwọn ọkùnrin náà mọ̀ pé ó ń sá kúrò ní iwájú Olúwa ni, nítorí òun ti sọ fun wọn bẹ́ẹ̀).
Wtedy ci mężczyźni bardzo się zlękli i zapytali: Czemu tak uczyniłeś? Oni bowiem dowiedzieli się, że ucieka sprzed oblicza PANA, bo im to powiedział.
11 Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “Kí ni kí àwa ó ṣe sí ọ kí Òkun lè dákẹ́ fún wa?” Nítorí Òkun ru, ó sì ja ẹ̀fúùfù líle.
Powiedzieli jeszcze do niego: Cóż mamy z tobą uczynić, aby morze się uspokoiło? Morze bowiem coraz bardziej się burzyło.
12 Òun sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé mi, kí ẹ sì sọ mi sínú Òkun, bẹ́ẹ̀ ni okun yóò sì dákẹ́ fún un yin. Nítorí èmi mọ̀ pé, nítorí mi ni ẹ̀fúùfù líle yìí ṣe dé bá a yín.”
Odpowiedział im: Weźcie mnie i wrzućcie do morza, a ono uspokoi się dla was, gdyż wiem, że z mojego powodu ta wielka burza [przyszła] na was.
13 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà gbìyànjú gidigidi láti mú ọkọ̀ wà sí ilẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò lè ṣe é: nítorí tí Òkun túbọ̀ ru sí i, ó sì ja ẹ̀fúùfù líle sí wọn.
Lecz ci mężczyźni wiosłowali silniej, aby dotrzeć do brzegu, ale nie mogli, bo morze coraz bardziej się burzyło przeciwko nim.
14 Nítorí náà wọ́n kígbe sí Olúwa, wọ́n sì wí pé, “Olúwa àwa bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí àwa ṣègbé nítorí ẹ̀mí ọkùnrin yìí. Má sì ka ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sí wa ní ọrùn, nítorí ìwọ, Olúwa, ti ṣe bí ó ti wù ọ́.”
Zawołali więc do PANA: PANIE, prosimy, nie pozwól nam zginąć z powodu życia tego człowieka i nie obciążaj nas krwią niewinną. Ty bowiem, PANIE, uczyniłeś, jak ci się spodobało.
15 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé Jona, tí wọ́n sì sọ ọ́ sínú Òkun, Òkun sì dẹ́kun ríru rẹ̀.
Potem wzięli Jonasza i wrzucili do morza, a morze przestało się burzyć.
16 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin náà bẹ̀rù Olúwa gidigidi, wọn si rú ẹbọ sí Olúwa, wọ́n sì jẹ́ ẹ̀jẹ́.
Wtedy ci mężczyźni, zdjęci wielkim strachem przed PANEM, złożyli PANU ofiarę i uczynili śluby.
17 Ṣùgbọ́n Olúwa ti pèsè ẹja ńlá kan láti gbé Jona mì. Jona sì wà nínú ẹja náà ni ọ̀sán mẹ́ta àti òru mẹ́ta.
A PAN przygotował wielką rybę, która połknęła Jonasza. I Jonasz był we wnętrznościach tej ryby trzy dni i trzy noce.