< Jonah 1 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jona ọmọ Amittai wá, wí pé:
És lőn az Úrnak szava Jónáshoz, az Amittai fiához, mondván:
2 “Dìde lọ sí ìlú ńlá Ninefe kí o sì wàásù sí i, nítorí ìwà búburú rẹ̀ gòkè wá iwájú mi.”
Kelj fel, menj Ninivébe, a nagy városba, és kiálts ellene, mert gonoszságuk felhatolt elémbe!
3 Ṣùgbọ́n Jona dìde kúrò láti sálọ sí Tarṣiṣi kúrò níwájú Olúwa, ó sì sọ̀kalẹ̀ lọ sí Joppa, ìbí ti ó tí rí ọkọ̀ kan tí ń lọ sí Tarṣiṣi: lẹ́yìn ti ó sanwó ọkọ̀, ó wọlé sínú rẹ̀, láti bá wọn lọ sí Tarṣiṣi kúrò níwájú Olúwa.
És felkele Jónás, hogy Tarsisba szaladna az Úr elől. Leméne azért Jáfóba, és talála ott egy hajót, a mely méne Tarsisba, és megadván a hajóbért, beszálla abba, hogy Tarsisba menne velök az Úr színe elől.
4 Nígbà náà ni Olúwa rán ìjì ńlá jáde sí ojú Òkun, ìjì líle sì wà nínú Òkun tó bẹ́ẹ̀ tí ọkọ̀ náà dàbí ẹni pé yóò fọ́.
Az Úr pedig nagy szelet bocsáta a tengerre, és nagy vihar lőn a tengeren, és a hajó már-már töredezik vala.
5 Nígbà náà ni àwọn atukọ̀ bẹ̀rù, olúkúlùkù sì ń kígbe sí ọlọ́run rẹ̀, wọ́n kó ẹrù tí ó wà nínú ọkọ̀ dà sínú Òkun, kí ó bá à lè fúyẹ́. Ṣùgbọ́n Jona sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ ọkọ̀ ó sì dùbúlẹ̀, ó sùn wọra.
Megfélemlének azért a hajósok és kiáltának, kiki az ő istenéhez, és a hajóban lévő holmit a tengerbe hányák, hogy könnyítsenek magukon. Jónás pedig leméne a hajó aljába, és lefeküdt és elaludt.
6 Bẹ́ẹ̀ ni olórí ọkọ̀ tọ̀ ọ́ wá, ó sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi sùn, ìwọ olóòórùn? Dìde kí o ké pe Ọlọ́run rẹ! Bóyá yóò ro tiwa, kí àwa má ba à ṣègbé.”
De hozzáméne a kormányos mester, és mondá néki: Mi lelt, te nagy alvó? Kelj fel, kiálts a te Istenedhez; hát ha gondol velünk az Isten, és nem veszünk el!
7 Nígbà náà ni àwọn atukọ̀ sọ fún ara wọn pé, “Wá, ẹ jẹ́ kí a sẹ́ kèké, kí àwa kí o le mọ̀ nítorí ta ni búburú yìí ṣe wá sórí wa.” Wọ́n ṣẹ́ kèké, kèké sì mú Jona.
Egymásnak pedig ezt mondák: Jertek, vessünk sorsot, hogy megtudhassuk: mi miatt van rajtunk e veszedelem? És sorsot vetének, és a sors Jónásra esék.
8 Nígbà náà ni wọn wí fún un pé, “Sọ fún wa, àwa bẹ̀ ọ́, nítorí ta ni búburú yìí ṣe wá sórí wa? Kí ni iṣẹ́ rẹ? Níbo ni ìwọ ti wá? Kí ni orúkọ ìlú rẹ? Ẹ̀yà orílẹ̀-èdè wo sì ni ìwọ sì í ṣe?”
Mondák azért néki: Kérünk, beszéld el nékünk: mi miatt van rajtunk e veszedelem? Mi a te foglalkozásod és honnan jösz? Melyik a te hazád és miféle népből való vagy te?
9 Òun sì dá wọn lóhùn pé, “Heberu ni èmi, mo sì bẹ̀rù Olúwa, Ọlọ́run ọ̀run ẹni tí ó dá Òkun àti ìyàngbẹ ilẹ̀.”
És monda nékik: Héber vagyok én, és az Urat, az egek Istenét félem én, a ki a tengert és a szárazt teremtette.
10 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin náà bẹ̀rù gidigidi, wọn sì wí fún un pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ṣe èyí?” (Nítorí àwọn ọkùnrin náà mọ̀ pé ó ń sá kúrò ní iwájú Olúwa ni, nítorí òun ti sọ fun wọn bẹ́ẹ̀).
És megfélemlének az emberek nagy félelemmel, és mondák néki: Mit cselekedtél? Mert megtudták azok az emberek, hogy az Úr színe elől fut, mivelhogy elbeszélé nékik.
11 Nígbà náà ni wọ́n wí fún un pé, “Kí ni kí àwa ó ṣe sí ọ kí Òkun lè dákẹ́ fún wa?” Nítorí Òkun ru, ó sì ja ẹ̀fúùfù líle.
Mondák azután néki: Mit cselekedjünk veled, hogy a tenger megcsendesedjék ellenünk? Mert a tenger háborgása növekedék.
12 Òun sì wí fún wọn pé, “Ẹ gbé mi, kí ẹ sì sọ mi sínú Òkun, bẹ́ẹ̀ ni okun yóò sì dákẹ́ fún un yin. Nítorí èmi mọ̀ pé, nítorí mi ni ẹ̀fúùfù líle yìí ṣe dé bá a yín.”
Ő pedig monda nékik: Fogjatok meg és vessetek engem a tengerbe, és megcsendesedik a tenger ellenetek; mert tudom én, hogy miattam van ez a nagy vihar rajtatok.
13 Ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin náà gbìyànjú gidigidi láti mú ọkọ̀ wà sí ilẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò lè ṣe é: nítorí tí Òkun túbọ̀ ru sí i, ó sì ja ẹ̀fúùfù líle sí wọn.
És erőlködtek azok az emberek, hogy visszajussanak a szárazra; de nem tudtak, mert a tenger háborgása növekedék ellenök.
14 Nítorí náà wọ́n kígbe sí Olúwa, wọ́n sì wí pé, “Olúwa àwa bẹ̀ ọ́, má ṣe jẹ́ kí àwa ṣègbé nítorí ẹ̀mí ọkùnrin yìí. Má sì ka ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ sí wa ní ọrùn, nítorí ìwọ, Olúwa, ti ṣe bí ó ti wù ọ́.”
Kiáltának azért az Úrhoz, és mondák: Kérünk Uram, kérünk, ne veszszünk el ez ember lelkéért, és ne háríts reánk ártatlan vért; mert te, Uram, úgy cselekedtél, a mint akartad!
15 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n gbé Jona, tí wọ́n sì sọ ọ́ sínú Òkun, Òkun sì dẹ́kun ríru rẹ̀.
És felragadák Jónást és beveték őt a tengerbe, és megszűnék a tenger az ő háborgásától.
16 Nígbà náà ni àwọn ọkùnrin náà bẹ̀rù Olúwa gidigidi, wọn si rú ẹbọ sí Olúwa, wọ́n sì jẹ́ ẹ̀jẹ́.
Azok az emberek pedig nagy félelemmel félék az Urat, és áldozattal áldozának az Úrnak, és fogadásokat fogadának.
17 Ṣùgbọ́n Olúwa ti pèsè ẹja ńlá kan láti gbé Jona mì. Jona sì wà nínú ẹja náà ni ọ̀sán mẹ́ta àti òru mẹ́ta.
Az Úr pedig egy nagy halat rendelt, hogy benyelje Jónást. És lőn Jónás a halnak gyomrában három nap és három éjjel.

< Jonah 1 >