< Jonah 4 >

1 Ṣùgbọ́n ó ba Jona nínú jẹ́ gidigidi, ó sì bínú púpọ̀.
No rĩrĩ, Jona nĩaiguire ũũru mũno na akĩrakara.
2 Ó sì gbàdúrà sí Olúwa, ó sì wí pé, “Èmí bẹ̀ ọ́, Olúwa, ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ ti mo sọ kọ́ ni èyí nígbà tí mo wà ní ilẹ̀ mi? Nítorí èyí ni mo ṣé sálọ sí Tarṣiṣi ní ìṣáájú: nítorí èmi mọ̀ pé, Ọlọ́run olóore-ọ̀fẹ́ ní ìwọ, àti aláàánú, O lọ́ra láti bínú, O sì ṣeun púpọ̀, O sì ronúpìwàdà ibi náà.
Akĩhooya Jehova, akiuga atĩrĩ, “Wee Jehova-rĩ, githĩ ũũ toguo ndoigĩte itoimĩte mũciĩ? Nĩkĩo ndaahiũhaga kũũrĩra Tarishishi. Nĩndoĩ atĩ wee wĩ Mũrungu mũtugi na ũrĩ tha, na ndũhiũhaga kũrakara, na ũiyũrĩtwo nĩ wendani, Ngai ũiguaga tha akericũkwo akaaga gwĩka ũũru.
3 Ǹjẹ́ báyìí, Olúwa, èmi bẹ̀ ọ, gba ẹ̀mí mi kúrò lọ́wọ́ mi nítorí ó sàn fún mi láti kú ju àti wà láààyè lọ.”
No rĩrĩ, Wee Jehova, ndagũthaitha ũndute muoyo; nĩgũkorwo nĩ kwagĩrĩire ngue, gũkĩra ndũũre muoyo.”
4 Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Ìwọ́ ha ni ẹ̀tọ́ láti bínú bí?”
No Jehova akĩmũũria atĩrĩ, “Ũrĩ na kĩhooto o na kĩrĩkũ gĩa gũtũma ũrakare?”
5 Jona sì jáde kúrò ní ìlú náà, ó sì jókòó níhà ìlà-oòrùn ìlú náà. Ó sì pa àgọ́ kan níbẹ̀ fún ara rẹ̀, ó sì jókòó ni òjìji ní abẹ́ rẹ̀ títí yóò fi rí ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ sí ìlú náà.
Jona akiuma kũu, agĩthiĩ agĩikara thĩ handũ mwena wa irathĩro wa itũũra rĩu inene. Akĩĩakĩra gĩthũnũ hau, agĩikara kĩĩruru-inĩ gĩakĩo, agĩeterera one ũrĩa itũũra rĩu inene rĩgwĩkwo.
6 Olúwa Ọlọ́run sì pèsè ìtàkùn kan, ó ṣe é kí ó gòkè wá sórí Jona; kí ó lè ṣe ìji bò ó lórí; láti gbà á kúrò nínú ìbànújẹ́ rẹ̀. Jona sì yọ ayọ̀ ńlá nítorí ìtàkùn náà.
Nake Jehova Ngai akĩrehe rũũngũ na agĩtũma rũtambe igũrũ rĩa hau Jona aarĩ, nĩguo rũmũhe kĩĩruru, kĩmũhumbĩre atige gũthĩĩnĩka. Nake Jona agĩkenera rũũngũ rũu mũno.
7 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run pèsè kòkòrò kan nígbà tí ilẹ̀ mọ́ ní ọjọ́ kejì, ó sì jẹ ìtàkùn náà ó sì rọ.
No rĩrĩ, kwarooka gũkĩa mũthenya ũyũ ũngĩ, Ngai akĩrehe kĩgunyũ gĩkĩrĩa rũũngũ rũu, nĩ ũndũ ũcio rũkĩhooha.
8 Ó sì ṣe, nígbà tí oòrùn yọ, Ọlọ́run pèsè ẹ̀fúùfù gbígbóná tí ìlà-oòrùn; oòrùn sì pa Jona lórí tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi rẹ̀ ẹ́. Ó sì fẹ́ nínú ara rẹ̀ láti kú, ó sì wí pé, “Ó sàn fún mi láti kú ju àti wà láààyè lọ.”
Hĩndĩ ĩrĩa riũa rĩarathire, Ngai akĩrehithia rũhuho ruumĩte na irathĩro rũrĩ na ũrugarĩ mũnene, narĩo riũa rĩgĩcina Jona mũtwe, o nginya akĩringĩka. Akĩĩrirĩria gũkua, akiuga atĩrĩ, “Nĩ wega ngue gũkĩra ndũũre muoyo.”
9 Ọlọ́run sì wí fún Jona pé, “O ha tọ́ fún ọ láti bínú nítorí ìtàkùn náà?” Òun sì wí pé, “Mo ni ẹ̀tọ́, o tọ́ fún mi láti bínú títí dé ikú.”
Nake Ngai akĩũria Jona atĩrĩ, “Ũrĩ na kĩhooto gĩa kũrakara nĩ ũndũ wa rũũngũ rũu?” Nake agĩcookia atĩrĩ, “Ĩĩ, ndĩ nakĩo; ndakarĩte o ũndũ ingĩkua.”
10 Nígbà náà ni Olúwa wí pé, “Ìwọ kẹ́dùn ìtàkùn náà, nítorí èyí tí ìwọ kò ṣiṣẹ́ fun, tí ìwọ kò mu dàgbà; tí ó hù jáde ní òru kan tí ó sì kú ni òru kan.
No Jehova akĩmwĩra atĩrĩ, “Wee-rĩ, ũraiguĩra rũũngũ rũrũ tha, o na harĩa ũtarũrutĩire wĩra kana ũgatũma rũkũre. Rũrakũrire na ũtukũ ũmwe, na rũrathira na ũtukũ ũmwe.
11 Ṣùgbọ́n Ninefe ní jù ọ̀kẹ́ mẹ́fà ènìyàn nínú rẹ̀, tí wọn kò mọ ọwọ́ ọ̀tún wọn yàtọ̀ sí ti òsì, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ ohun ọ̀sìn pẹ̀lú. Ṣé èmí kò ha ní kẹ́dùn nípa ìlú ńlá náà?”
No Nineve nĩ kũrĩ na andũ makĩria ma ngiri igana rĩa mĩrongo ĩĩrĩ arĩa matangĩkũũrana guoko kwa ũrĩo kana guoko kwa ũmotho, o na ningĩ rĩrĩ na mahiũ maingĩ. Githĩ o na niĩ ndiagĩrĩirwo nĩkũiguĩra tha itũũra rĩu inene?”

< Jonah 4 >