< Jonah 3 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jona wá nígbà kejì wí pé:
Tedy się stało słowo Pańskie do Jonasza powtóre, mówiąc:
2 “Dìde lọ sí Ninefe, ìlú ńlá a nì, kí o sì kéde sí i, ìkéde tí mo sọ fún ọ.”
Wstań, idź do Niniwy, tego miasta wielkiego, a każ przeciwko niemu to, coć rozkazuję.
3 Jona sì dìde ó lọ sí Ninefe gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa. Ninefe jẹ́ ìlú títóbi gidigidi, ó tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta.
Wstał tedy Jonasz, i poszedł do Niniwy według słowa Pańskiego. (A Niniwe było miasto bardzo wielkie na trzy dni drogi.)
4 Jona sì bẹ̀rẹ̀ sí wọ ìlú náà lọ ní ìrìn ọjọ́ kan, ó sì ń kéde, ó sì wí pé, “Níwọ́n ogójì ọjọ́ sí i, a ó bi Ninefe wó.”
Tedy Jonasz począł chodzić po mieście, ile mógł za jeden dzień ujść, i wołał mówiąc: Po czterdziestu dniach Niniwe będzie wywrócone.
5 Àwọn ènìyàn Ninefe sì gba Ọlọ́run gbọ́. Wọ́n sì kéde àwẹ̀, gbogbo wọ́n sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, bẹ̀rẹ̀ láti orí ọmọdé títí dé orí àgbà wọn.
I uwierzyli Niniwczycy Bogu; a zapowiedziawszy post oblekli się w wory, od największego z nich aż do najmniejszego z nich.
6 Ọ̀rọ̀ náà sì dé ọ̀dọ̀ ọba Ninefe, ó sì dìde kúrò lórí ìtẹ́ rẹ̀, ó sì bọ́ aṣọ ìgúnwà rẹ̀ kúrò lára rẹ̀, ó sì da aṣọ ọ̀fọ̀ bora, ó sì jókòó nínú eérú.
Bo gdy ta rzecz przyszła do króla Niniwskiego, powstawszy z stolicy swojej złożył z siebie odzienie swoje, a oblekłszy się w wór, siedział w popiele.
7 Nígbà náà ní ó kéde rẹ̀ ni Ninefe pé, “Kí a la Ninefe já nípa àṣẹ ọba, àti àwọn àgbàgbà rẹ̀ pé: “Má ṣe jẹ́ kí ènìyàn, tàbí ẹranko, ọ̀wọ́ ẹran tàbí agbo ẹran, tọ́ ohunkóhun wò, má jẹ́ kí wọn jẹ tàbí mu omi.
I rozkazał wywołać i opowiadać w Niniwie z dekretu królewskiego, i książąt swoich, tak mówiąc: Ludzie i bydło, woły i owce niech nic nie ukuszają, i niech się nie pasą, i wody nie piją;
8 Ṣùgbọ́n jẹ́ kí ènìyàn àti ẹranko da aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara, kí wọn sì kígbe kíkan sí Ọlọ́run, sì jẹ́ kí wọn yípadà, olúkúlùkù kúrò ní ọ̀nà ibi rẹ̀ àti kúrò ní ìwà ìpa tí ó wà lọ́wọ́ wọn.
Ale się niech okryją worami ludzie i bydło, a niech do Boga gorliwie wołają, a niech się odwróci każdy od złej drogi swojej i od łupiestwa, które jest w ręku jego.
9 Ta ni ó lè mọ̀ bí Ọlọ́run yóò yípadà kí ó sì ronúpìwàdà, kí ó sì yípadà kúrò ní ìbínú gbígbóná rẹ̀, kí àwa má ṣègbé?”
Kto wie, jeźli się nie obróci Bóg, a nie użali się tego, nie odwrócili się, mówię, od popędliwości gniewu swego, abyśmy nie zginęli.
10 Ọlọ́run sì rí ìṣe wọn pé wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀nà ibi wọn, Ọlọ́run sì ronúpìwàdà ibi tí òun ti wí pé òun yóò ṣe sí wọn, òun kò sì ṣe e mọ́.
I widział Bóg sprawy ich, iż się odwrócili od złej drogi swej i użalił się Bóg nad tem złem, które rzekł, że im miał uczynić, a nie uczynił.

< Jonah 3 >