< Jonah 3 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jona wá nígbà kejì wí pé:
És lőn az Úrnak szava Jónáshoz másodszor is, mondván:
2 “Dìde lọ sí Ninefe, ìlú ńlá a nì, kí o sì kéde sí i, ìkéde tí mo sọ fún ọ.”
Kelj fel, menj Ninivébe, a nagy városba, és hirdesd néki azt a beszédet, a mit én parancsolok néked.
3 Jona sì dìde ó lọ sí Ninefe gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa. Ninefe jẹ́ ìlú títóbi gidigidi, ó tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta.
És felkele Jónás, és elméne Ninivébe az Úr szava szerint. Ninive pedig nagy városa vala Istennek, három napi járó föld.
4 Jona sì bẹ̀rẹ̀ sí wọ ìlú náà lọ ní ìrìn ọjọ́ kan, ó sì ń kéde, ó sì wí pé, “Níwọ́n ogójì ọjọ́ sí i, a ó bi Ninefe wó.”
És kezde Jónás bemenni a városba egy napi járóra, és kiálta és monda: Még negyven nap, és elpusztul Ninive!
5 Àwọn ènìyàn Ninefe sì gba Ọlọ́run gbọ́. Wọ́n sì kéde àwẹ̀, gbogbo wọ́n sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, bẹ̀rẹ̀ láti orí ọmọdé títí dé orí àgbà wọn.
A niniveiek pedig hivének Istenben, és bőjtöt hirdetének, és nagyjaiktól fogva kicsinyeikig zsákba öltözének.
6 Ọ̀rọ̀ náà sì dé ọ̀dọ̀ ọba Ninefe, ó sì dìde kúrò lórí ìtẹ́ rẹ̀, ó sì bọ́ aṣọ ìgúnwà rẹ̀ kúrò lára rẹ̀, ó sì da aṣọ ọ̀fọ̀ bora, ó sì jókòó nínú eérú.
És eljuta a beszéd Ninive királyához, és felkele királyi székéből, és leveté magáról az ő királyi ruháját, és zsákba borítkozék, és üle a porba.
7 Nígbà náà ní ó kéde rẹ̀ ni Ninefe pé, “Kí a la Ninefe já nípa àṣẹ ọba, àti àwọn àgbàgbà rẹ̀ pé: “Má ṣe jẹ́ kí ènìyàn, tàbí ẹranko, ọ̀wọ́ ẹran tàbí agbo ẹran, tọ́ ohunkóhun wò, má jẹ́ kí wọn jẹ tàbí mu omi.
És kiáltának és szólának Ninivében, a királynak és főembereinek akaratából, mondván: Emberek és barmok, ökrök és juhok: semmit meg ne kóstoljanak, ne legeljenek és vizet se igyanak!
8 Ṣùgbọ́n jẹ́ kí ènìyàn àti ẹranko da aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara, kí wọn sì kígbe kíkan sí Ọlọ́run, sì jẹ́ kí wọn yípadà, olúkúlùkù kúrò ní ọ̀nà ibi rẹ̀ àti kúrò ní ìwà ìpa tí ó wà lọ́wọ́ wọn.
Hanem öltözzenek zsákba az emberek és barmok, és kiáltsanak az Istenhez erősen, és térjen meg kiki az ő gonosz útáról és az erőszakosságból, a mely az ő kezökben van!
9 Ta ni ó lè mọ̀ bí Ọlọ́run yóò yípadà kí ó sì ronúpìwàdà, kí ó sì yípadà kúrò ní ìbínú gbígbóná rẹ̀, kí àwa má ṣègbé?”
Ki tudja? talán visszatér és megengesztelődik az Isten és elfordul haragjának búsulásától, és nem veszünk el!
10 Ọlọ́run sì rí ìṣe wọn pé wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀nà ibi wọn, Ọlọ́run sì ronúpìwàdà ibi tí òun ti wí pé òun yóò ṣe sí wọn, òun kò sì ṣe e mọ́.
És látá Isten az ő cselekedeteiket, hogy megtértek az ő gonosz útjokról: és megbáná az Isten azt a gonoszt, a melyről mondá, hogy végrehajtja rajtok, és nem hajtá végre.