< Jonah 3 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jona wá nígbà kejì wí pé:
Et la parole du Seigneur vint à Jonas pour la seconde fois, disant
2 “Dìde lọ sí Ninefe, ìlú ńlá a nì, kí o sì kéde sí i, ìkéde tí mo sọ fún ọ.”
Lève-toi, et pars pour Ninive, la grande ville, et proclame dans ses murs la prédiction que Je t'ai déjà prescrit de proclamer.
3 Jona sì dìde ó lọ sí Ninefe gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa. Ninefe jẹ́ ìlú títóbi gidigidi, ó tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta.
Et Jonas se leva; et il s'en alla à Ninive, comme lui avait dit le Seigneur. Or la ville de Ninive était grande de trois jours de marche.
4 Jona sì bẹ̀rẹ̀ sí wọ ìlú náà lọ ní ìrìn ọjọ́ kan, ó sì ń kéde, ó sì wí pé, “Níwọ́n ogójì ọjọ́ sí i, a ó bi Ninefe wó.”
Et Jonas commença par entrer dans la ville et par faire environ un jour de marche, et il cria, et il dit: Encore trois jours, et Ninive sera détruite!
5 Àwọn ènìyàn Ninefe sì gba Ọlọ́run gbọ́. Wọ́n sì kéde àwẹ̀, gbogbo wọ́n sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, bẹ̀rẹ̀ láti orí ọmọdé títí dé orí àgbà wọn.
Et les hommes de Ninive crurent en Dieu, et ils proclamèrent un jeûne, et ils se ceignirent de cilices, depuis le grand jusqu'au petit.
6 Ọ̀rọ̀ náà sì dé ọ̀dọ̀ ọba Ninefe, ó sì dìde kúrò lórí ìtẹ́ rẹ̀, ó sì bọ́ aṣọ ìgúnwà rẹ̀ kúrò lára rẹ̀, ó sì da aṣọ ọ̀fọ̀ bora, ó sì jókòó nínú eérú.
Et la parole de Jonas arriva au roi de Ninive, et il se leva de son trône, et il ôta sa robe, et il se ceignit d'un cilice, et il s'assit sur la cendre.
7 Nígbà náà ní ó kéde rẹ̀ ni Ninefe pé, “Kí a la Ninefe já nípa àṣẹ ọba, àti àwọn àgbàgbà rẹ̀ pé: “Má ṣe jẹ́ kí ènìyàn, tàbí ẹranko, ọ̀wọ́ ẹran tàbí agbo ẹran, tọ́ ohunkóhun wò, má jẹ́ kí wọn jẹ tàbí mu omi.
Et il fut proclamé, et il fut dit en Ninive de la part du roi et de la part de ses grands, ce qui suit: Que ni hommes, ni bêtes, ni bœufs, ni brebis ne mangent, ne paissent, ne boivent même de l'eau.
8 Ṣùgbọ́n jẹ́ kí ènìyàn àti ẹranko da aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara, kí wọn sì kígbe kíkan sí Ọlọ́run, sì jẹ́ kí wọn yípadà, olúkúlùkù kúrò ní ọ̀nà ibi rẹ̀ àti kúrò ní ìwà ìpa tí ó wà lọ́wọ́ wọn.
Et les hommes et les bêtes furent couverts de cilices, et les hommes crièrent sans relâche au Seigneur. Et chacun revint de sa voie coupable et de l'iniquité de ses mains, disant:
9 Ta ni ó lè mọ̀ bí Ọlọ́run yóò yípadà kí ó sì ronúpìwàdà, kí ó sì yípadà kúrò ní ìbínú gbígbóná rẹ̀, kí àwa má ṣègbé?”
Qui sait si le Seigneur ne Se repentira pas, et s'Il ne calmera pas les transports de Sa colère, pour que nous ne périssions point?
10 Ọlọ́run sì rí ìṣe wọn pé wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀nà ibi wọn, Ọlọ́run sì ronúpìwàdà ibi tí òun ti wí pé òun yóò ṣe sí wọn, òun kò sì ṣe e mọ́.
Et Dieu vit leurs œuvres; Il vit qu'ils revenaient de leurs voies coupables; et Dieu Se repentit du mal qu'Il avait voulu leur faire, et Il ne le leur fit pas.