< Jonah 3 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jona wá nígbà kejì wí pé:
La parole de Yahvé fut adressée à Jonas pour la seconde fois, en ces termes:
2 “Dìde lọ sí Ninefe, ìlú ńlá a nì, kí o sì kéde sí i, ìkéde tí mo sọ fún ọ.”
« Lève-toi, va à Ninive, la grande ville, et prêche-lui le message que je te donne. »
3 Jona sì dìde ó lọ sí Ninefe gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa. Ninefe jẹ́ ìlú títóbi gidigidi, ó tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta.
Et Jonas se leva, et alla à Ninive, selon la parole de l'Éternel. Or Ninive était une ville extrêmement grande, à trois jours de marche.
4 Jona sì bẹ̀rẹ̀ sí wọ ìlú náà lọ ní ìrìn ọjọ́ kan, ó sì ń kéde, ó sì wí pé, “Níwọ́n ogójì ọjọ́ sí i, a ó bi Ninefe wó.”
Jonas commença à entrer dans la ville à une journée de marche, et il s'écria: « Dans quarante jours, Ninive sera renversée! »
5 Àwọn ènìyàn Ninefe sì gba Ọlọ́run gbọ́. Wọ́n sì kéde àwẹ̀, gbogbo wọ́n sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, bẹ̀rẹ̀ láti orí ọmọdé títí dé orí àgbà wọn.
Les habitants de Ninive crurent en Dieu, proclamèrent un jeûne et se couvrirent de sacs, depuis le plus grand jusqu'au plus petit.
6 Ọ̀rọ̀ náà sì dé ọ̀dọ̀ ọba Ninefe, ó sì dìde kúrò lórí ìtẹ́ rẹ̀, ó sì bọ́ aṣọ ìgúnwà rẹ̀ kúrò lára rẹ̀, ó sì da aṣọ ọ̀fọ̀ bora, ó sì jókòó nínú eérú.
La nouvelle parvint au roi de Ninive, qui se leva de son trône, ôta sa robe royale, se couvrit d'un sac et s'assit dans la cendre.
7 Nígbà náà ní ó kéde rẹ̀ ni Ninefe pé, “Kí a la Ninefe já nípa àṣẹ ọba, àti àwọn àgbàgbà rẹ̀ pé: “Má ṣe jẹ́ kí ènìyàn, tàbí ẹranko, ọ̀wọ́ ẹran tàbí agbo ẹran, tọ́ ohunkóhun wò, má jẹ́ kí wọn jẹ tàbí mu omi.
Il fit une proclamation et la publia dans Ninive par l'ordre du roi et de ses nobles, en disant: « Que ni les hommes ni les bêtes, ni le bétail ni le cheptel, ne goûtent rien; qu'ils ne se nourrissent pas et ne boivent pas d'eau;
8 Ṣùgbọ́n jẹ́ kí ènìyàn àti ẹranko da aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara, kí wọn sì kígbe kíkan sí Ọlọ́run, sì jẹ́ kí wọn yípadà, olúkúlùkù kúrò ní ọ̀nà ibi rẹ̀ àti kúrò ní ìwà ìpa tí ó wà lọ́wọ́ wọn.
mais qu'ils se couvrent d'un sac, hommes et bêtes, et qu'ils crient puissamment à Dieu. Oui, qu'ils détournent chacun de sa mauvaise voie et de la violence qui est dans ses mains.
9 Ta ni ó lè mọ̀ bí Ọlọ́run yóò yípadà kí ó sì ronúpìwàdà, kí ó sì yípadà kúrò ní ìbínú gbígbóná rẹ̀, kí àwa má ṣègbé?”
Qui sait si Dieu ne reviendra pas et ne s'apaisera pas, s'il ne détournera pas son ardente colère, afin que nous ne périssions pas? ».
10 Ọlọ́run sì rí ìṣe wọn pé wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀nà ibi wọn, Ọlọ́run sì ronúpìwàdà ibi tí òun ti wí pé òun yóò ṣe sí wọn, òun kò sì ṣe e mọ́.
Dieu a vu leurs œuvres, et ils se sont détournés de leur mauvaise voie. Dieu a renoncé au désastre qu'il avait dit qu'il leur ferait subir, et il ne l'a pas fait.

< Jonah 3 >