< Jonah 3 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jona wá nígbà kejì wí pé:
And there is a word of YHWH to Jonah a second time, saying,
2 “Dìde lọ sí Ninefe, ìlú ńlá a nì, kí o sì kéde sí i, ìkéde tí mo sọ fún ọ.”
“Rise, go to Nineveh, the great city, and proclaim to it the proclamation that I am speaking to you”;
3 Jona sì dìde ó lọ sí Ninefe gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa. Ninefe jẹ́ ìlú títóbi gidigidi, ó tó ìrìn ọjọ́ mẹ́ta.
and Jonah rises, and he goes to Nineveh, according to the word of YHWH. And Nineveh has been a great city before God, a journey of three days.
4 Jona sì bẹ̀rẹ̀ sí wọ ìlú náà lọ ní ìrìn ọjọ́ kan, ó sì ń kéde, ó sì wí pé, “Níwọ́n ogójì ọjọ́ sí i, a ó bi Ninefe wó.”
And Jonah begins to go into the city—a journey of one day—and proclaims and says, “Yet forty days and Nineveh is overturned!”
5 Àwọn ènìyàn Ninefe sì gba Ọlọ́run gbọ́. Wọ́n sì kéde àwẹ̀, gbogbo wọ́n sì wọ aṣọ ọ̀fọ̀, bẹ̀rẹ̀ láti orí ọmọdé títí dé orí àgbà wọn.
And the men of Nineveh believe in God, and proclaim a fast, and put on sackcloth, from their greatest even to their least,
6 Ọ̀rọ̀ náà sì dé ọ̀dọ̀ ọba Ninefe, ó sì dìde kúrò lórí ìtẹ́ rẹ̀, ó sì bọ́ aṣọ ìgúnwà rẹ̀ kúrò lára rẹ̀, ó sì da aṣọ ọ̀fọ̀ bora, ó sì jókòó nínú eérú.
seeing the word comes to the king of Nineveh, and he rises from his throne, and removes his honorable robe from off him, and spreads out sackcloth, and sits on the ashes,
7 Nígbà náà ní ó kéde rẹ̀ ni Ninefe pé, “Kí a la Ninefe já nípa àṣẹ ọba, àti àwọn àgbàgbà rẹ̀ pé: “Má ṣe jẹ́ kí ènìyàn, tàbí ẹranko, ọ̀wọ́ ẹran tàbí agbo ẹran, tọ́ ohunkóhun wò, má jẹ́ kí wọn jẹ tàbí mu omi.
and he cries and says in Nineveh by a decree of the king and his great ones, saying, “Man and beast, herd and flock—do not let them taste anything, do not let them feed, do not even let them drink water;
8 Ṣùgbọ́n jẹ́ kí ènìyàn àti ẹranko da aṣọ ọ̀fọ̀ bo ara, kí wọn sì kígbe kíkan sí Ọlọ́run, sì jẹ́ kí wọn yípadà, olúkúlùkù kúrò ní ọ̀nà ibi rẹ̀ àti kúrò ní ìwà ìpa tí ó wà lọ́wọ́ wọn.
and let man and beast cover themselves [with] sackcloth, and let them call to God mightily, and let them each turn back from his evil way, and from the violence that [is] in their hands.
9 Ta ni ó lè mọ̀ bí Ọlọ́run yóò yípadà kí ó sì ronúpìwàdà, kí ó sì yípadà kúrò ní ìbínú gbígbóná rẹ̀, kí àwa má ṣègbé?”
Who knows? He turns back, and God has relented, and has turned back from the heat of His anger, and we do not perish.”
10 Ọlọ́run sì rí ìṣe wọn pé wọ́n yípadà kúrò ní ọ̀nà ibi wọn, Ọlọ́run sì ronúpìwàdà ibi tí òun ti wí pé òun yóò ṣe sí wọn, òun kò sì ṣe e mọ́.
And God sees their works, that they have turned back from their evil way, and God relents of the evil that He spoke of doing to them, and He has not done [it].