< Jonah 2 >
1 Nígbà náà ni Jona gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run rẹ̀ láti inú ẹja náà wá,
І молився Йона до Господа, Бога свого, з утроби тієї риби,
2 Ó sì wí pé: “Nínú ìpọ́njú mi ni mo kígbe sí Olúwa, òun sì gbọ́ ohùn mi. Mo kígbe láti inú ipò òkú, mo pè fún ìrànwọ́, ìwọ sì gbọ́ ohùn mi. (Sheol )
та й казав: „Я кли́кав з нещастя свого до Господа, — і відповідь дав Він мені, із ну́тра шеолу кричав я, — і почув Ти мій голос! (Sheol )
3 Nítorí tí ìwọ ti sọ mí sínú ibú, ní àárín Òkun, ìṣàn omi sì yí mi káàkiri; gbogbo bíbì omi àti rírú omi rékọjá lórí mi.
І Ти кинув мене в глибочі́нь, у серце моря, і поті́к оточив був мене. Усі хвилі Твої та буру́ни Твої надо мною пройшли́.
4 Nígbà náà ni mo wí pé, ‘A ta mí nù kúrò níwájú rẹ; ṣùgbọ́n síbẹ̀ èmi yóò tún máa wo ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ.’
І сказав я: Я ви́гнаний з-перед очей Твоїх, проте́ ще побачу я храм Твій святий.
5 Omi yí mi káàkiri, àní títí dé ọkàn; ibú yí mi káàkiri, a fi koríko odò wé mi lórí.
Вода аж по душу мене обгорну́ла, безо́дня мене оточи́ла, очере́т обвива́є круго́м мою го́лову!
6 Èmi sọ̀kalẹ̀ lọ sí ìsàlẹ̀ àwọn òkè ńlá; ilẹ̀ ayé pẹ̀lú ìdènà rẹ̀ yí mi ká títí: ṣùgbọ́n ìwọ ti mú ẹ̀mí mi wá sókè láti inú ibú wá, Olúwa Ọlọ́run mi.
Я зійшов аж до спо́ду гори, а земля — її за́суви стали за мною навіки! Та піді́ймеш із ями життя моє, Господи, Боже Ти мій!
7 “Nígbà tí ó rẹ ọkàn mi nínú mi, èmi rántí rẹ, Olúwa, àdúrà mi sì wá sí ọ̀dọ̀ rẹ, nínú tẹmpili mímọ́ rẹ.
Як у мені омлівала душа моя, Господа я спогада́в, — і молитва моя ця до Тебе доли́нула, до храму святого Твого!
8 “Àwọn tí ń fàmọ́ òrìṣà èké kọ àánú ara wọn sílẹ̀.
Ті, що трима́ються ма́рних божкі́в, — свого Милосердного кидають.
9 Ṣùgbọ́n èmi yóò fi orin ọpẹ́, rú ẹbọ sí ọ. Èmi yóò san ẹ̀jẹ́ tí mo ti jẹ́. ‘Ìgbàlà wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa.’”
А я голосно́ю подякою принесу́ Тобі жертву, про що присягав я, те ви́конаю. Спасі́ння — у Господа!“
10 Olúwa sì pàṣẹ fún ẹja náà, ó sì pọ Jona sí orí ilẹ̀ gbígbẹ.
І Господь звелів рибі, — і вона ви́кинула Йону на суході́л.